< Judges 18 >

1 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ọmọ Israẹli kò ní ọba. Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ẹ̀yà Dani ń wá ilẹ̀ tiwọn, níbi tí wọn yóò máa gbé, nítorí pé títí di àkókò náà wọn kò ì tí ì pín ogún ilẹ̀ fún wọn ní ìní láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
În acele zile nu era împărat în Israel, și în acele zile tribul daniților își căuta o moștenire de locuit, pentru că până în ziua aceea nu le căzuse toată moștenirea lor între triburile lui Israel.
2 Nítorí náà àwọn ẹ̀yà Dani rán àwọn jagunjagun márùn-ún lọ láti Sora àti Eṣtaoli láti yọ́ ilẹ̀ náà wò àti láti rìn ín wò. Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣe ojú fún gbogbo àwọn ẹ̀yà wọn. Wọ́n wí fún wọn pé, “Ẹ lọ kí ẹ rin ilẹ̀ náà ká, kí ẹ sì wò ó fínní fínní.” Àwọn ọkùnrin náà wọ àwọn ìlú tí ó wà ní agbègbè òkè Efraimu, wọ́n sì dé ilé Mika, níbi tí wọ́n sùn ní òru náà.
Și copiii lui Dan au trimis din familia lor cinci bărbați din ținuturile lor, războinici viteji din Țoreea și din Eștaol, pentru a spiona țara și să o cerceteze; și le-au spus: Duceți-vă, cercetați țara; și când au ajuns la muntele Efraim, la casa lui Mica, au găzduit acolo.
3 Nígbà tí wọ́n súnmọ́ tòsí ilé e Mika, wọ́n dá ohùn ọ̀dọ́mọkùnrin Lefi náà mọ̀, torí náà wọ́n yípadà, wọ́n sì wọ inú ilé náà lọ wọ́n sì bi í pé, “Tá ni ó mú ọ wa sí ibi? Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín yìí? Èéṣe tí o fi wà ní ibí?”
Când erau lângă casa lui Mica, au cunoscut vocea tânărului, levitul, și s-au abătut pe acolo și i-au spus: Cine te-a adus aici? Și ce faci tu în acest loc? Și ce ai tu aici?
4 Ó sọ ohun tí Mika ti ṣe fún un, ó fi kún un fún wọn pé, “Ó gbà mí sí iṣẹ́, èmi sì ni àlùfáà rẹ̀.”
Și el le-a spus: Așa și așa s-a purtat Mica cu mine și m-a angajat și eu sunt preotul lui.
5 Wọ́n wí fún un pé, “Jọ̀wọ́ béèrè ní ọwọ́ Ọlọ́run, kí àwa lè mọ̀ bí ìrìnàjò wa yóò yọrí sí rere.”
Iar ei i-au spus: Cere sfat, te rugăm, de la Dumnezeu, ca să știm dacă va fi prosperă calea pe care mergem.
6 Àlùfáà náà dá wọn lóhùn pé, “Ẹ máa lọ ní àlàáfíà. Ìrìnàjò yín tí ẹ̀yin ń rìn bá ojúrere Olúwa pàdé.”
Și preotul le-a spus: Duceți-vă în pace, calea voastră, pe care mergeți, este înaintea DOMNULUI.
7 Àwọn ọkùnrin márààrún náà kúrò, wọ́n sì wá sí Laiṣi, níbi tí wọ́n ti rí i pé àwọn ènìyàn tí ń gbé ibẹ̀ ní ààbò, bí àwọn ará Sidoni, láìsí ìfòyà àti ní ìpamọ́. Ní ìgbà tí ilẹ̀ wọn kò ṣe aláìní ohunkóhun, wọ́n ní ọrọ̀ púpọ̀. Ibùgbé wọn tún jìnnà sí ti àwọn ará Sidoni, wọn kò fi ohunkóhun bá ẹnikẹ́ni dàpọ̀.
Atunci cei cinci bărbați au plecat și au venit la Lais și au văzut poporul care era în ea, cum locuiau nepăsători, după felul sidonienilor, liniștiți și în siguranță; și nu era vreun magistrat în țară, care să îi dea de rușine în orice lucru; și erau departe de sidonieni și nu aveau afaceri cu vreun om.
8 Nígbà tí wọ́n padà sí Sora àti Eṣtaoli, àwọn arákùnrin wọn bi wọ́n léèrè pé, “Báwo ni ibi tí ẹ lọ ti rí? Kí ni ìròyìn tí ẹ mú wá?”
Și au venit la frații lor, la Țoreea și Eștaol, iar frații lor le-au zis: Ce spuneți voi?
9 Wọ́n dáhùn pé, “Ẹ dìde ẹ jẹ́ kí a lọ kọlù wọ́n! A wá rí i pé ilẹ̀ náà dára gidigidi. Ṣé ẹ̀yin ó sì jókòó láìsí nǹkan nípa rẹ̀? Ẹ má ṣe lọ́ra láti lọ síbẹ̀ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà.
Iar ei au zis: Ridicați-vă, să ne urcăm împotriva lor, pentru că am văzut țara și, iată, este foarte bună, iar voi stați liniștiți? Nu vă leneviți a merge și a intra să stăpâniți țara.
10 Nígbà tí ẹ̀yin bá dé ibẹ̀, ẹ yóò rí àwọn ènìyàn tí ọkàn wọn balẹ̀ àti ilẹ̀ tí ó tẹ́jú tí Ọlọ́run ti fi fún yín, ilẹ̀ tí kò ṣe aláìní nǹkan kan.”
Când mergeți, veți ajunge la un popor în siguranță și la o țară întinsă, pentru că Dumnezeu a dat-o în mâinile voastre; un loc în care nu este lipsă de nimic din ceea ce este pe pământ.
11 Nígbà náà ni ẹgbẹ̀ta ọkùnrin tí ó múra ogun láti ìran Dani, jáde lọ láti Sora àti Eṣtaoli ní mímú ra láti jagun.
Și de acolo, din Țoreea și Eștaol, au plecat șase sute de bărbați din familia daniților, încinși cu arme de război.
12 Wọ́n sì jáde lọ, ní ojú ọ̀nà wọn, wọ́n tẹ̀dó ogun sí ẹ̀bá Kiriati-Jearimu ní Juda. Ìdí nìyí tí wọ́n fi ń gbé ìwọ̀-oòrùn Kiriati-Jearimu ni Mahane-Dani títí di òní yìí.
Și s-au urcat și au tăbărât la Chiriat-Iearim în Iuda; de aceea au numit acel loc Mahane-Dan, până în ziua aceasta; iată, este în spatele Chiriat-Iearimului.
13 Láti ibẹ̀ wọ́n kọjá lọ sí àwọn ìlú agbègbè òkè Efraimu, wọ́n sì dé ilé Mika.
Și de acolo au trecut la muntele Efraim și au ajuns până la casa lui Mica.
14 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin márùn-ún tí ó lọ yọ́ ilẹ̀ Laiṣi wò sọ fún àwọn arákùnrin wọn pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin mọ̀ pé ọ̀kan nínú àwọn ilé yìí ní ẹ̀wù efodu, àwọn yòókù ní òrìṣà, ère gbígbẹ́ àti ère dídà? Ẹ mọ ohun tí ó yẹ kí ẹ ṣe báyìí.”
Atunci cei cinci bărbați, care se duseseră să spioneze țara Lais, au răspuns și au spus fraților lor: Știți că în aceste case se află un efod și terafimi și un chip cioplit și un chip turnat? Și acum, luați aminte la ce aveți de făcut.
15 Wọ́n sì yà sí ibẹ̀, wọ́n sì wọ ilé ọ̀dọ́mọkùnrin Lefi náà, sí ilé Mika, wọ́n sì béèrè àlàáfíà rẹ̀.
Și s-au abătut într-acolo și au venit la casa tânărului, levitul, la casa lui Mica și l-au salutat.
16 Àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin ará Dani náà tí ó hámọ́ra ogun, dúró ní àbáwọlé ẹnu odi.
Și cei șase sute de bărbați încinși cu armele lor de război, care erau dintre copiii lui Dan, au stat la intrarea porții.
17 Àwọn ọkùnrin márùn-ún tí wọ́n lọ yọ́ ilẹ̀ náà wò wọlé lọ wọ́n sì kó ère gbígbẹ́ náà, efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé àti ère dídà náà nígbà tí àlùfáà náà àti àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin tí ó hámọ́ra ogun dúró ní à bá wọ ẹnu odi náà.
Și cei cinci bărbați, care merseseră să spioneze țara, s-au urcat, au intrat acolo și au luat chipul cioplit și efodul și terafimii și chipul turnat; și preotul stătea la intrarea porții cu cei șase sute de bărbați care erau încinși cu arme de război.
18 Nígbà tí àwọn ọkùnrin yìí wọ ilé e Mika lọ tí wọ́n sì kó ère fínfín náà, efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé mìíràn àti ère dídà náà, àlùfáà náà béèrè lọ́wọ́ wọn wí pé, “Kí ni ẹ̀yin ń ṣe?”
Și aceștia au intrat în casa lui Mica și au luat chipul cioplit, efodul și terafimii și chipul turnat. Atunci preotul le-a spus: Ce faceți?
19 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Dákẹ́! Ma sọ nǹkan kan, tẹ̀lé wa kí o sì di baba àti àlùfáà wa. Kò ha sàn fún ọ láti máa ṣe ìránṣẹ́ ẹ̀yà àti ìdílé kan tí ó wá láti Israẹli bí àlùfáà ju ilé ẹnìkan ṣoṣo lọ?”
Iar ei i-au spus: Taci, pune-ți mâna la gură și mergi cu noi și să ne fii părinte și preot. Este mai bine pentru tine să fii preot pentru casa unui singur om, sau să fii preot pentru un trib și o familie în Israel?
20 Nígbà náà ni inú àlùfáà náà sì dùn, òun mú efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé mìíràn àti ère fínfín náà, ó sì bá àwọn ènìyàn náà lọ.
Și inima preotului s-a bucurat și a luat efodul și terafimii și chipul cioplit și a mers în mijlocul poporului.
21 Wọ́n kó àwọn ọmọdé wọn, àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní wọn síwájú, wọ́n yípadà wọ́n sì lọ.
Astfel ei s-au întors și au plecat; și au pus înaintea lor pruncii și vitele și bagajele.
22 Nígbà tí wọ́n ti rìn jìnnà díẹ̀ sí ilé Mika, àwọn ọkùnrin tí ó wà ní agbègbè Mika kó ara wọn jọ, wọ́n sì lé àwọn ará Dani bá.
Și când erau la o distanță bună de casa lui Mica, bărbații care erau în casele de lângă casa lui Mica s-au adunat și i-au ajuns pe copiii lui Dan.
23 Bí wọ́n ṣe ń pariwo tẹ̀lé wọn lẹ́yìn, àwọn ará Dani yípadà wọ́n sì bi Mika pé, “Kí ló ṣe ọ́ tí o fi pe àwọn ọkùnrin rẹ jáde láti jà?”
Și au strigat la copiii lui Dan. Și ei și-au întors fețele și i-au spus lui Mica: Ce îți este, că ai venit cu o astfel de ceată?
24 Ó dáhùn pé, “Ẹ̀yin kó àwọn ère tí mo ṣe, àti àlùfáà mi lọ. Kí ni ó kù tí mo ní? Báwo ni ẹ̀yin ò ṣe béèrè pé, ‘Kí ló ṣe ọ́?’”
Și el a spus: Mi-ați luat dumnezeii, pe care i-am făcut, și pe preot și ați plecat, și ce mai am eu? Și ce este aceasta ce îmi spuneți: Ce îți este?
25 Àwọn ọkùnrin Dani náà dáhùn pé, “Má ṣe bá wa jiyàn, tàbí àwọn oníbìínú fùfù ènìyàn lè kọlù yín, ìwọ àti àwọn ìdílé yóò sì sọ ẹ̀mí yín nù.”
Și copiii lui Dan i-au spus: Să nu ți se audă vocea printre noi, ca nu cumva niște oameni furioși să vină peste voi și să îți pierzi viața, împreună cu viața celor din casa ta.
26 Àwọn ọkùnrin Dani náà sì bá ọ̀nà wọn lọ. Nígbà tí Mika rí í pé wọ́n lágbára púpọ̀ fún òun, ó sì padà sí ilé rẹ̀.
Și copiii lui Dan au mers pe drumul lor și când Mica a văzut că erau prea puternici pentru el, s-a întors și a mers acasă.
27 Wọ́n sì kó àwọn ohun tí Mika ti ṣe àti àlùfáà rẹ̀, wọ́n sì kọjá lọ sí Laiṣi, ní ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tí ó ní ìbàlẹ̀ ọkàn tí wọ́n sì wà ní àlàáfíà. Wọ́n fi ojú idà kọlù wọ́n, wọ́n sì jó ìlú wọn run.
Și au luat lucrurile, pe care le făcuse Mica, și pe preotul care era la el, și au venit asupra Laisului, asupra unui popor liniștit și în siguranță; și i-au lovit cu ascuțișul sabiei și au ars cetatea cu foc.
28 Kò sì sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀ nítorí pé ibi tí wọ́n ń gbé jìnà sí àwọn ará Sidoni, wọn kò sì ní àṣepọ̀ pẹ̀lú ẹnikẹ́ni. Ìlú náà wà ní inú àfonífojì lẹ́bàá a Beti-Rehobu. Àwọn ará Dani sì tún ìlú náà kọ́, wọ́n sì ń gbé inú rẹ̀.
Și nu era niciun eliberator, pentru că aceasta era departe de Sidon și nu aveau afaceri cu vreun om; și era în valea care se află lângă Bet-Rehob. Și au zidit o cetate și au locuit în ea.
29 Wọ́n sọ orúkọ ìlú náà ní Dani gẹ́gẹ́ bí orúkọ baba ńlá wọn Dani, ẹni tí wọ́n bí fún Israẹli: bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Laiṣi ni orúkọ ìlú náà tẹ́lẹ̀ rí.
Și au pus cetății numele Dan, după numele lui Dan, tatăl lor, care i se născuse lui Israel; totuși, mai înainte numele cetății era Lais.
30 Àwọn ọmọ Dani sì gbé àwọn ère kalẹ̀ fún ara wọn níbẹ̀; Jonatani ọmọ Gerṣomu, ọmọ Mose, àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni àlùfáà fún àwọn ẹ̀yà Dani títí di àkókò tí a kó ilẹ̀ náà ní ìgbèkùn.
Și copiii lui Dan au înălțat chipul cioplit; și Ionatan, fiul lui Gherșom, fiul lui Manase, el și fiii săi au fost preoții tribului lui Dan până în ziua captivității țării.
31 Wọ́n tẹ̀síwájú láti lo àwọn ère tí Mika ṣe, ní gbogbo àkókò tí ilé Ọlọ́run wà ní Ṣilo.
Și și-au înălțat chipul cioplit al lui Mica, pe care îl făcuse el, în toate zilele cât a fost casa lui Dumnezeu în Șilo.

< Judges 18 >