< Judges 18 >
1 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ọmọ Israẹli kò ní ọba. Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ẹ̀yà Dani ń wá ilẹ̀ tiwọn, níbi tí wọn yóò máa gbé, nítorí pé títí di àkókò náà wọn kò ì tí ì pín ogún ilẹ̀ fún wọn ní ìní láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
I de dager var det ingen konge i Israel; og i de samme dager søkte danittenes stamme sig en arvelodd til å bo i, for det var ikke til den dag tilfalt dem nogen arv blandt Israels stammer.
2 Nítorí náà àwọn ẹ̀yà Dani rán àwọn jagunjagun márùn-ún lọ láti Sora àti Eṣtaoli láti yọ́ ilẹ̀ náà wò àti láti rìn ín wò. Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣe ojú fún gbogbo àwọn ẹ̀yà wọn. Wọ́n wí fún wọn pé, “Ẹ lọ kí ẹ rin ilẹ̀ náà ká, kí ẹ sì wò ó fínní fínní.” Àwọn ọkùnrin náà wọ àwọn ìlú tí ó wà ní agbègbè òkè Efraimu, wọ́n sì dé ilé Mika, níbi tí wọ́n sùn ní òru náà.
Og Dans barn sendte ut fem menn av hele sin ætt, djerve menn fra Sora og Estaol, for å speide og utforske landet, og de sa til dem: Dra avsted og utforsk landet! Og de kom til Efra'im-fjellet, til Mikas hus, og blev der om natten.
3 Nígbà tí wọ́n súnmọ́ tòsí ilé e Mika, wọ́n dá ohùn ọ̀dọ́mọkùnrin Lefi náà mọ̀, torí náà wọ́n yípadà, wọ́n sì wọ inú ilé náà lọ wọ́n sì bi í pé, “Tá ni ó mú ọ wa sí ibi? Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín yìí? Èéṣe tí o fi wà ní ibí?”
Da de var tett ved Mikas hus, kjente de den unge manns - levittens - røst, bøide av fra veien og gikk bort til ham og sa: Hvem har ført dig hit, og hvad gjør du her, og hvorledes har du det her?
4 Ó sọ ohun tí Mika ti ṣe fún un, ó fi kún un fún wọn pé, “Ó gbà mí sí iṣẹ́, èmi sì ni àlùfáà rẹ̀.”
Han svarte: Så og så har Mika gjort mot mig; han har leid mig til å være prest for sig.
5 Wọ́n wí fún un pé, “Jọ̀wọ́ béèrè ní ọwọ́ Ọlọ́run, kí àwa lè mọ̀ bí ìrìnàjò wa yóò yọrí sí rere.”
Da sa de til ham: Kjære, spør Gud for oss, sa vi kan få vite om den reise vi nu gjør, skal lykkes!
6 Àlùfáà náà dá wọn lóhùn pé, “Ẹ máa lọ ní àlàáfíà. Ìrìnàjò yín tí ẹ̀yin ń rìn bá ojúrere Olúwa pàdé.”
Da sa presten til dem: Far i fred! Gud har øie med eder på den reise I gjør.
7 Àwọn ọkùnrin márààrún náà kúrò, wọ́n sì wá sí Laiṣi, níbi tí wọ́n ti rí i pé àwọn ènìyàn tí ń gbé ibẹ̀ ní ààbò, bí àwọn ará Sidoni, láìsí ìfòyà àti ní ìpamọ́. Ní ìgbà tí ilẹ̀ wọn kò ṣe aláìní ohunkóhun, wọ́n ní ọrọ̀ púpọ̀. Ibùgbé wọn tún jìnnà sí ti àwọn ará Sidoni, wọn kò fi ohunkóhun bá ẹnikẹ́ni dàpọ̀.
De fem menn drog nu sin vei og kom til La'is, og de så at folket der levde sorgløst på samme vis som sidonierne, rolig og sorgløst; det var ingen makthaver i landet som gjorde dem noget mén; de var langt borte fra sidonierne og hadde intet å gjøre med noget menneske.
8 Nígbà tí wọ́n padà sí Sora àti Eṣtaoli, àwọn arákùnrin wọn bi wọ́n léèrè pé, “Báwo ni ibi tí ẹ lọ ti rí? Kí ni ìròyìn tí ẹ mú wá?”
Da de så kom tilbake til sine brødre i Sora og Estaol, sa deres brødre til dem: Hvorledes er det gått eder?
9 Wọ́n dáhùn pé, “Ẹ dìde ẹ jẹ́ kí a lọ kọlù wọ́n! A wá rí i pé ilẹ̀ náà dára gidigidi. Ṣé ẹ̀yin ó sì jókòó láìsí nǹkan nípa rẹ̀? Ẹ má ṣe lọ́ra láti lọ síbẹ̀ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà.
De sa: Kom, la oss dra op mot dem! Vi har sett landet: Det er et ypperlig land. Og I sitter bare og tier? Vær ikke sene til å dra avsted, så I kan komme dit og innta landet!
10 Nígbà tí ẹ̀yin bá dé ibẹ̀, ẹ yóò rí àwọn ènìyàn tí ọkàn wọn balẹ̀ àti ilẹ̀ tí ó tẹ́jú tí Ọlọ́run ti fi fún yín, ilẹ̀ tí kò ṣe aláìní nǹkan kan.”
Når I kommer dit, kommer I til et sorgløst folk, og landet strekker sig til alle sider vidt ut; Gud har gitt det i eders hånd - et land hvor det ikke er mangel på nogen verdens ting.
11 Nígbà náà ni ẹgbẹ̀ta ọkùnrin tí ó múra ogun láti ìran Dani, jáde lọ láti Sora àti Eṣtaoli ní mímú ra láti jagun.
Så brøt seks hundre menn av danittenes ætt fullt væbnet op derfra, fra Sora og Estaol.
12 Wọ́n sì jáde lọ, ní ojú ọ̀nà wọn, wọ́n tẹ̀dó ogun sí ẹ̀bá Kiriati-Jearimu ní Juda. Ìdí nìyí tí wọ́n fi ń gbé ìwọ̀-oòrùn Kiriati-Jearimu ni Mahane-Dani títí di òní yìí.
De drog op og leiret sig i Kirjat-Jearim i Juda; derfor har folk kalt dette sted Dans leir til denne dag, det ligger vestenfor Kirjat-Jearim.
13 Láti ibẹ̀ wọ́n kọjá lọ sí àwọn ìlú agbègbè òkè Efraimu, wọ́n sì dé ilé Mika.
Derfra drog de over til Efra'im-fjellet og kom til Mikas hus.
14 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin márùn-ún tí ó lọ yọ́ ilẹ̀ Laiṣi wò sọ fún àwọn arákùnrin wọn pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin mọ̀ pé ọ̀kan nínú àwọn ilé yìí ní ẹ̀wù efodu, àwọn yòókù ní òrìṣà, ère gbígbẹ́ àti ère dídà? Ẹ mọ ohun tí ó yẹ kí ẹ ṣe báyìí.”
Og de fem menn som hadde draget avsted for å utspeide La'islandet, tok til orde og sa til sine brødre: Vet I at i disse hus er det en livkjortel og husguder og et utskåret billede med et støpt fotstykke til? Så skjønner I vel hvad I har å gjøre?
15 Wọ́n sì yà sí ibẹ̀, wọ́n sì wọ ilé ọ̀dọ́mọkùnrin Lefi náà, sí ilé Mika, wọ́n sì béèrè àlàáfíà rẹ̀.
Så bøide de av fra veien og gikk bort til den unge manns - levittens - hus, til Mikas hus, og hilste på ham.
16 Àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin ará Dani náà tí ó hámọ́ra ogun, dúró ní àbáwọlé ẹnu odi.
Men de seks hundre fullt væbnede menn av Dans barn stod ved inngangen til porten.
17 Àwọn ọkùnrin márùn-ún tí wọ́n lọ yọ́ ilẹ̀ náà wò wọlé lọ wọ́n sì kó ère gbígbẹ́ náà, efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé àti ère dídà náà nígbà tí àlùfáà náà àti àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin tí ó hámọ́ra ogun dúró ní à bá wọ ẹnu odi náà.
Og de fem menn som hadde draget avsted for å utspeide landet, steg op og gikk inn og tok det utskårne billede og livkjortelen og husgudene og det støpte fotstykke, mens presten stod ved inngangen til porten sammen med de seks hundre fullt væbnede menn.
18 Nígbà tí àwọn ọkùnrin yìí wọ ilé e Mika lọ tí wọ́n sì kó ère fínfín náà, efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé mìíràn àti ère dídà náà, àlùfáà náà béèrè lọ́wọ́ wọn wí pé, “Kí ni ẹ̀yin ń ṣe?”
Da nu de fem menn hadde gått inn i Mikas hus og hadde tatt det utskårne billede med livkjortelen og husgudene og det støpte fotstykke, sa presten til dem: Hvad er det I gjør?
19 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Dákẹ́! Ma sọ nǹkan kan, tẹ̀lé wa kí o sì di baba àti àlùfáà wa. Kò ha sàn fún ọ láti máa ṣe ìránṣẹ́ ẹ̀yà àti ìdílé kan tí ó wá láti Israẹli bí àlùfáà ju ilé ẹnìkan ṣoṣo lọ?”
De sa til ham: Ti, legg din hånd på din munn og kom med oss og vær far og prest for oss! Hvad er best for dig, å være prest for en manns hus eller for en hel stamme og ætt i Israel?
20 Nígbà náà ni inú àlùfáà náà sì dùn, òun mú efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé mìíràn àti ère fínfín náà, ó sì bá àwọn ènìyàn náà lọ.
Da blev presten vel til mote; han tok livkjortelen og husgudene og det utskårne billede og gav sig i lag med folkene.
21 Wọ́n kó àwọn ọmọdé wọn, àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní wọn síwájú, wọ́n yípadà wọ́n sì lọ.
Så vendte de sig og drog bort, og de lot barna og buskapen og sine eiendeler være fremst i toget.
22 Nígbà tí wọ́n ti rìn jìnnà díẹ̀ sí ilé Mika, àwọn ọkùnrin tí ó wà ní agbègbè Mika kó ara wọn jọ, wọ́n sì lé àwọn ará Dani bá.
Da de alt var kommet langt fra Mikas hus, blev mennene i Mikas grend kalt sammen, og de innhentet Dans barn.
23 Bí wọ́n ṣe ń pariwo tẹ̀lé wọn lẹ́yìn, àwọn ará Dani yípadà wọ́n sì bi Mika pé, “Kí ló ṣe ọ́ tí o fi pe àwọn ọkùnrin rẹ jáde láti jà?”
De ropte efter Dans barn, og disse vendte sig om og sa til Mika: Hvad vil du siden du har kalt dine folk sammen?
24 Ó dáhùn pé, “Ẹ̀yin kó àwọn ère tí mo ṣe, àti àlùfáà mi lọ. Kí ni ó kù tí mo ní? Báwo ni ẹ̀yin ò ṣe béèrè pé, ‘Kí ló ṣe ọ́?’”
Han svarte: I har tatt mine guder som jeg har gjort mig, og presten med, og har draget bort; hvad har jeg så tilbake? Hvorledes kan I da spørre mig hvad jeg vil?
25 Àwọn ọkùnrin Dani náà dáhùn pé, “Má ṣe bá wa jiyàn, tàbí àwọn oníbìínú fùfù ènìyàn lè kọlù yín, ìwọ àti àwọn ìdílé yóò sì sọ ẹ̀mí yín nù.”
Da sa Dans barn til ham: La oss ikke høre et ord av dig mere, ellers kunde rasende menn falle over eder, så du kom til å volde undergang både for dig og dine.
26 Àwọn ọkùnrin Dani náà sì bá ọ̀nà wọn lọ. Nígbà tí Mika rí í pé wọ́n lágbára púpọ̀ fún òun, ó sì padà sí ilé rẹ̀.
Så drog Dans barn sin vei, og da Mika så at de var sterkere enn han, vendte han om og drog tilbake til sitt hus.
27 Wọ́n sì kó àwọn ohun tí Mika ti ṣe àti àlùfáà rẹ̀, wọ́n sì kọjá lọ sí Laiṣi, ní ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tí ó ní ìbàlẹ̀ ọkàn tí wọ́n sì wà ní àlàáfíà. Wọ́n fi ojú idà kọlù wọ́n, wọ́n sì jó ìlú wọn run.
Da de nu hadde tatt de ting som Mika hadde latt gjøre, og presten som var hos ham, kom de over La'is - over et folk som levde rolig og sorgløst. De slo dem med sverdets egg, og byen brente de op.
28 Kò sì sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀ nítorí pé ibi tí wọ́n ń gbé jìnà sí àwọn ará Sidoni, wọn kò sì ní àṣepọ̀ pẹ̀lú ẹnikẹ́ni. Ìlú náà wà ní inú àfonífojì lẹ́bàá a Beti-Rehobu. Àwọn ará Dani sì tún ìlú náà kọ́, wọ́n sì ń gbé inú rẹ̀.
Og der var ingen som kom dem til hjelp; for byen lå langt fra Sidon, og de hadde intet å gjøre med noget menneske. Den lå i dalen ved Bet-Rehob. De bygget den op igjen og bosatte sig der.
29 Wọ́n sọ orúkọ ìlú náà ní Dani gẹ́gẹ́ bí orúkọ baba ńlá wọn Dani, ẹni tí wọ́n bí fún Israẹli: bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Laiṣi ni orúkọ ìlú náà tẹ́lẹ̀ rí.
Og de kalte byen Dan efter sin stamfar Dan, Israels sønn; før het den La'is.
30 Àwọn ọmọ Dani sì gbé àwọn ère kalẹ̀ fún ara wọn níbẹ̀; Jonatani ọmọ Gerṣomu, ọmọ Mose, àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni àlùfáà fún àwọn ẹ̀yà Dani títí di àkókò tí a kó ilẹ̀ náà ní ìgbèkùn.
Der satte Dans barn op det utskårne billede; og Jonatan, sønn av Gersom, Moses' sønn, og hans efterkommere var prester for danittenes stamme like til den dag da landets innbyggere blev bortført.
31 Wọ́n tẹ̀síwájú láti lo àwọn ère tí Mika ṣe, ní gbogbo àkókò tí ilé Ọlọ́run wà ní Ṣilo.
Det utskårne billede som Mika hadde gjort, hadde de stående hos sig hele den tid Guds hus var i Silo.