< Judges 18 >

1 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ọmọ Israẹli kò ní ọba. Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ẹ̀yà Dani ń wá ilẹ̀ tiwọn, níbi tí wọn yóò máa gbé, nítorí pé títí di àkókò náà wọn kò ì tí ì pín ogún ilẹ̀ fún wọn ní ìní láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
Azokban a napokban nem volt király Izraélben; és azokban a napokban keresett magának Dán törzse birtokot lakásra, mert nem jutott neki ama napig birtok Izraél törzsei közt.
2 Nítorí náà àwọn ẹ̀yà Dani rán àwọn jagunjagun márùn-ún lọ láti Sora àti Eṣtaoli láti yọ́ ilẹ̀ náà wò àti láti rìn ín wò. Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣe ojú fún gbogbo àwọn ẹ̀yà wọn. Wọ́n wí fún wọn pé, “Ẹ lọ kí ẹ rin ilẹ̀ náà ká, kí ẹ sì wò ó fínní fínní.” Àwọn ọkùnrin náà wọ àwọn ìlú tí ó wà ní agbègbè òkè Efraimu, wọ́n sì dé ilé Mika, níbi tí wọ́n sùn ní òru náà.
És küldtek Dán fiai a nemzetségükből öt férfiút mindnyájuk közül, derék férfiakat Czoreából és Estáólból, hogy kikémleljek az országot és átkutassák; így szóltak hozzájuk: Menjetek, kutassátok át az országot. És eljutottak Efraim hegységébe, Míkha házáig és ott megháltak.
3 Nígbà tí wọ́n súnmọ́ tòsí ilé e Mika, wọ́n dá ohùn ọ̀dọ́mọkùnrin Lefi náà mọ̀, torí náà wọ́n yípadà, wọ́n sì wọ inú ilé náà lọ wọ́n sì bi í pé, “Tá ni ó mú ọ wa sí ibi? Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín yìí? Èéṣe tí o fi wà ní ibí?”
Míkha háza mellett voltak, akkor fölismerték a levita ifjú hangját; betértek oda és mondták neki: Ki hozott téged ide és mit csinálsz te erre és mi dolgod van itt?
4 Ó sọ ohun tí Mika ti ṣe fún un, ó fi kún un fún wọn pé, “Ó gbà mí sí iṣẹ́, èmi sì ni àlùfáà rẹ̀.”
Szólt hozzájuk: Így meg úgy cselekedett velem Míkha, bérbe fogadott s lettem neki papjává.
5 Wọ́n wí fún un pé, “Jọ̀wọ́ béèrè ní ọwọ́ Ọlọ́run, kí àwa lè mọ̀ bí ìrìnàjò wa yóò yọrí sí rere.”
És mondták neki: Kérdezd csak meg Istent, hogy megtudjuk, szerencsés lesz-e az utunk, a melyre menni akarunk?
6 Àlùfáà náà dá wọn lóhùn pé, “Ẹ máa lọ ní àlàáfíà. Ìrìnàjò yín tí ẹ̀yin ń rìn bá ojúrere Olúwa pàdé.”
Mondta nekik a pap: Menjetek békében, az Örökkévaló előtt van az utatok, melyen ti jártok.
7 Àwọn ọkùnrin márààrún náà kúrò, wọ́n sì wá sí Laiṣi, níbi tí wọ́n ti rí i pé àwọn ènìyàn tí ń gbé ibẹ̀ ní ààbò, bí àwọn ará Sidoni, láìsí ìfòyà àti ní ìpamọ́. Ní ìgbà tí ilẹ̀ wọn kò ṣe aláìní ohunkóhun, wọ́n ní ọrọ̀ púpọ̀. Ibùgbé wọn tún jìnnà sí ti àwọn ará Sidoni, wọn kò fi ohunkóhun bá ẹnikẹ́ni dàpọ̀.
És elment az öt férfiú és eljutottak Lájisba; s látták a népet, mely benne volt – biztonságban laktak ott a Czídónbeliek módjára – nyugodtnak és biztosnak, senki nem tett semmi zavart az országban, az uralom birtokában; távol voltak a Czídónbeliektől és semmi dolguk nem volt senkivel.
8 Nígbà tí wọ́n padà sí Sora àti Eṣtaoli, àwọn arákùnrin wọn bi wọ́n léèrè pé, “Báwo ni ibi tí ẹ lọ ti rí? Kí ni ìròyìn tí ẹ mú wá?”
És elérkeztek testvéreikhez Czoreába és Estáólba, s mondták nekik testvéreik: Mit hoztok?
9 Wọ́n dáhùn pé, “Ẹ dìde ẹ jẹ́ kí a lọ kọlù wọ́n! A wá rí i pé ilẹ̀ náà dára gidigidi. Ṣé ẹ̀yin ó sì jókòó láìsí nǹkan nípa rẹ̀? Ẹ má ṣe lọ́ra láti lọ síbẹ̀ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà.
Mondták: Föl, vonuljunk föl ellenük, mert láttuk az országot és íme, nagyon jó; hát ti veszteg maradtok? Ne legyetek restek arra, hogy elinduljatok, bemenjetek és elfoglaljátok az országot.
10 Nígbà tí ẹ̀yin bá dé ibẹ̀, ẹ yóò rí àwọn ènìyàn tí ọkàn wọn balẹ̀ àti ilẹ̀ tí ó tẹ́jú tí Ọlọ́run ti fi fún yín, ilẹ̀ tí kò ṣe aláìní nǹkan kan.”
A mint odaértek, biztosságban levő néphez értek, az ország pedig tág határú – mert kezetekbe adta az Isten – oly hely az, a hol nincsen hiány semmi földön levő dologban.
11 Nígbà náà ni ẹgbẹ̀ta ọkùnrin tí ó múra ogun láti ìran Dani, jáde lọ láti Sora àti Eṣtaoli ní mímú ra láti jagun.
S elindult onnét a Dán nemzetségéből, Czoreából és Estáólból, hatszáz ember felövezve hadi fegyverrel.
12 Wọ́n sì jáde lọ, ní ojú ọ̀nà wọn, wọ́n tẹ̀dó ogun sí ẹ̀bá Kiriati-Jearimu ní Juda. Ìdí nìyí tí wọ́n fi ń gbé ìwọ̀-oòrùn Kiriati-Jearimu ni Mahane-Dani títí di òní yìí.
Fölmentek és táboroztak Kirjat-Jeárimban, Jehúdában, azért így nevezték ama helyet: Dán tábora, mind e mai napig, íme Kirjat-Jeárim mögött van.
13 Láti ibẹ̀ wọ́n kọjá lọ sí àwọn ìlú agbègbè òkè Efraimu, wọ́n sì dé ilé Mika.
Onnan átvonultak Efraim hegységébe és eljutottak Míkha házáig.
14 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin márùn-ún tí ó lọ yọ́ ilẹ̀ Laiṣi wò sọ fún àwọn arákùnrin wọn pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin mọ̀ pé ọ̀kan nínú àwọn ilé yìí ní ẹ̀wù efodu, àwọn yòókù ní òrìṣà, ère gbígbẹ́ àti ère dídà? Ẹ mọ ohun tí ó yẹ kí ẹ ṣe báyìí.”
Ekkor megszólalt az öt férfiú, a kik mentek volt az országnak, Lájisnak kikémlelésére, és mondták testvéreiknek: Tudjátok-e, hogy e házakban éfód és teráfim, meg faragott és öntött kép vannak? Most hát tudjátok meg, mit tegyetek.
15 Wọ́n sì yà sí ibẹ̀, wọ́n sì wọ ilé ọ̀dọ́mọkùnrin Lefi náà, sí ilé Mika, wọ́n sì béèrè àlàáfíà rẹ̀.
S betértek oda, bementek a levita ifjúnak házába, Míkha házába és kérdezték őt békéje felől.
16 Àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin ará Dani náà tí ó hámọ́ra ogun, dúró ní àbáwọlé ẹnu odi.
A hatszáz ember pedig, felövezve hadi fegyverükkel, ott állt a kapu bejáratánál, a Dán fiai közül valók.
17 Àwọn ọkùnrin márùn-ún tí wọ́n lọ yọ́ ilẹ̀ náà wò wọlé lọ wọ́n sì kó ère gbígbẹ́ náà, efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé àti ère dídà náà nígbà tí àlùfáà náà àti àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin tí ó hámọ́ra ogun dúró ní à bá wọ ẹnu odi náà.
És fölment az öt férfiú, a kik mentek volt az ország kikémlelésére, bementek oda, vették a faragott képet, az éfódot, a teráfimot és az öntött képet; a pap pedig ott állt a kapu bejáratánál, meg a hadi fegyverrel felövezett hatszáz ember.
18 Nígbà tí àwọn ọkùnrin yìí wọ ilé e Mika lọ tí wọ́n sì kó ère fínfín náà, efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé mìíràn àti ère dídà náà, àlùfáà náà béèrè lọ́wọ́ wọn wí pé, “Kí ni ẹ̀yin ń ṣe?”
Amazok bementek Míkha házába, s elvették a faragott képet, az éfódot, a teráfimot és az öntött képet; ekkor szólt hozzájuk a pap: Mit cselekesztek?
19 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Dákẹ́! Ma sọ nǹkan kan, tẹ̀lé wa kí o sì di baba àti àlùfáà wa. Kò ha sàn fún ọ láti máa ṣe ìránṣẹ́ ẹ̀yà àti ìdílé kan tí ó wá láti Israẹli bí àlùfáà ju ilé ẹnìkan ṣoṣo lọ?”
Mondták neki: Hallgass, tedd kezedet szádra és jer velünk, hogy nekünk légy atyánk és papunk. Jobb-e papja lenned egy ember házának, vagy papja lenned egy törzsnek és nemzetségnek Izraélben?
20 Nígbà náà ni inú àlùfáà náà sì dùn, òun mú efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé mìíràn àti ère fínfín náà, ó sì bá àwọn ènìyàn náà lọ.
Ekkor fölvidult a papnak szíve, vette az éfódot, a teráfimot és a faragott képet és ment a nép közé.
21 Wọ́n kó àwọn ọmọdé wọn, àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní wọn síwájú, wọ́n yípadà wọ́n sì lọ.
Erre fordultak és elmentek; s maguk elé helyezték a gyermekeket, a jószágot és a podgyászt.
22 Nígbà tí wọ́n ti rìn jìnnà díẹ̀ sí ilé Mika, àwọn ọkùnrin tí ó wà ní agbègbè Mika kó ara wọn jọ, wọ́n sì lé àwọn ará Dani bá.
Alig távoztak Míkha házától és az emberek, kik a Míkha háza mellett levő házakban voltak, összegyűltek és utolérték Dán fiait.
23 Bí wọ́n ṣe ń pariwo tẹ̀lé wọn lẹ́yìn, àwọn ará Dani yípadà wọ́n sì bi Mika pé, “Kí ló ṣe ọ́ tí o fi pe àwọn ọkùnrin rẹ jáde láti jà?”
Kiáltottak Dán fiaira; odafordultak arczukkal és mondták Míkhának: Mi bajod, hogy összegyűltél?
24 Ó dáhùn pé, “Ẹ̀yin kó àwọn ère tí mo ṣe, àti àlùfáà mi lọ. Kí ni ó kù tí mo ní? Báwo ni ẹ̀yin ò ṣe béèrè pé, ‘Kí ló ṣe ọ́?’”
Mondta: Istenemet, melyet készítettem, elvittétek meg a papot és elmentetek; hát mim van még, hogy is mondhatjátok hát nekem: mi bajod?
25 Àwọn ọkùnrin Dani náà dáhùn pé, “Má ṣe bá wa jiyàn, tàbí àwọn oníbìínú fùfù ènìyàn lè kọlù yín, ìwọ àti àwọn ìdílé yóò sì sọ ẹ̀mí yín nù.”
És szóltak hozzá Dán fiai: Ne hallasd hangodat ellenünk, nehogy reátok támadjanak elkeseredett lelkű emberek és elveszítenéd lelkedet és házad lelkét.
26 Àwọn ọkùnrin Dani náà sì bá ọ̀nà wọn lọ. Nígbà tí Mika rí í pé wọ́n lágbára púpọ̀ fún òun, ó sì padà sí ilé rẹ̀.
Erre útjukra indultak Dán fiai; s midőn látta Míkha, hogy ők erősebbek nálánál, megfordult és visszatért házába.
27 Wọ́n sì kó àwọn ohun tí Mika ti ṣe àti àlùfáà rẹ̀, wọ́n sì kọjá lọ sí Laiṣi, ní ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tí ó ní ìbàlẹ̀ ọkàn tí wọ́n sì wà ní àlàáfíà. Wọ́n fi ojú idà kọlù wọ́n, wọ́n sì jó ìlú wọn run.
Ők pedig elvették azt, a mit Míkha készített volt, meg a papot, a ki az övé volt és mentek Lájis ellen, egy nyugodt és biztos nép ellen és megverték őket a kard élével; a várost meg elégették tűzben.
28 Kò sì sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀ nítorí pé ibi tí wọ́n ń gbé jìnà sí àwọn ará Sidoni, wọn kò sì ní àṣepọ̀ pẹ̀lú ẹnikẹ́ni. Ìlú náà wà ní inú àfonífojì lẹ́bàá a Beti-Rehobu. Àwọn ará Dani sì tún ìlú náà kọ́, wọ́n sì ń gbé inú rẹ̀.
S nem volt a ki megmentené, mert messze volt Czídóntól és dolguk nem volt senkivel; fekszik ugyanis a Bét-Rechóbhoz való völgyben. És fölépítették a várost és megtelepedtek benne.
29 Wọ́n sọ orúkọ ìlú náà ní Dani gẹ́gẹ́ bí orúkọ baba ńlá wọn Dani, ẹni tí wọ́n bí fún Israẹli: bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Laiṣi ni orúkọ ìlú náà tẹ́lẹ̀ rí.
És elnevezték a várost Dánnak, Dán atyjuk nevéről, a ki született Izraélnek; azonban Lájis volt a város neve azelőtt.
30 Àwọn ọmọ Dani sì gbé àwọn ère kalẹ̀ fún ara wọn níbẹ̀; Jonatani ọmọ Gerṣomu, ọmọ Mose, àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni àlùfáà fún àwọn ẹ̀yà Dani títí di àkókò tí a kó ilẹ̀ náà ní ìgbèkùn.
S fölállították maguknak Dán fiai a faragott képet; Jehónátán pedig, Gérsóm fia, Menasse fia, ő meg fiai papjai voltak Dán törzsének az ország számkivetése napjáig.
31 Wọ́n tẹ̀síwájú láti lo àwọn ère tí Mika ṣe, ní gbogbo àkókò tí ilé Ọlọ́run wà ní Ṣilo.
És tartották maguknak Míkha faragott képét, melyet készített volt, mind a napokon át, melyekben Isten háza Sílóban volt.

< Judges 18 >