< Judges 18 >
1 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ọmọ Israẹli kò ní ọba. Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ẹ̀yà Dani ń wá ilẹ̀ tiwọn, níbi tí wọn yóò máa gbé, nítorí pé títí di àkókò náà wọn kò ì tí ì pín ogún ilẹ̀ fún wọn ní ìní láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
Na rĩrĩ, matukũ-inĩ macio Isiraeli gũtiarĩ na mũthamaki. Na matukũ-inĩ macio mũhĩrĩga wa Dani nĩwacaragia kũndũ kwao gwa gũtũũra, tondũ matiegwatĩire igai rĩao gatagatĩ-inĩ ka mĩhĩrĩga ya Isiraeli.
2 Nítorí náà àwọn ẹ̀yà Dani rán àwọn jagunjagun márùn-ún lọ láti Sora àti Eṣtaoli láti yọ́ ilẹ̀ náà wò àti láti rìn ín wò. Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣe ojú fún gbogbo àwọn ẹ̀yà wọn. Wọ́n wí fún wọn pé, “Ẹ lọ kí ẹ rin ilẹ̀ náà ká, kí ẹ sì wò ó fínní fínní.” Àwọn ọkùnrin náà wọ àwọn ìlú tí ó wà ní agbègbè òkè Efraimu, wọ́n sì dé ilé Mika, níbi tí wọ́n sùn ní òru náà.
Nĩ ũndũ ũcio andũ a Dani magĩthuura njamba cia ita ithano kuuma Zora na Eshitaoli ithiĩ igathigaane bũrũri ũcio na ituĩrie ũhoro. Andũ a mũhĩrĩga wa Dani makĩmeera atĩrĩ, “Thiĩi, mũgatuĩrie ũhoro wa bũrũri ũcio.” Andũ acio magĩtoonya bũrũri ũrĩa ũrĩ irĩma wa Efiraimu na magĩkinya mũciĩ wa Mika kũrĩa maararĩrĩire ũtukũ ũcio.
3 Nígbà tí wọ́n súnmọ́ tòsí ilé e Mika, wọ́n dá ohùn ọ̀dọ́mọkùnrin Lefi náà mọ̀, torí náà wọ́n yípadà, wọ́n sì wọ inú ilé náà lọ wọ́n sì bi í pé, “Tá ni ó mú ọ wa sí ibi? Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín yìí? Èéṣe tí o fi wà ní ibí?”
Na rĩrĩa maakuhĩrĩirie nyũmba ya Mika, magĩkũũrana mũgambo wa mwanake ũcio Mũlawii; nĩ ũndũ ũcio magĩtoonya kuo makĩmũũria atĩrĩ, “Nũũ wakũrehire gũkũ? Nĩ kĩĩ ũreka kũndũ gũkũ? Nĩ kĩĩ gĩtũmĩte ũkorwo ũrĩ gũkũ?”
4 Ó sọ ohun tí Mika ti ṣe fún un, ó fi kún un fún wọn pé, “Ó gbà mí sí iṣẹ́, èmi sì ni àlùfáà rẹ̀.”
Nake akĩmeera ũrĩa Mika aamwĩkĩire, akĩmeera atĩrĩ, “We nĩanyandĩkĩte na niĩ ndĩ mũthĩnjĩri-Ngai wake.”
5 Wọ́n wí fún un pé, “Jọ̀wọ́ béèrè ní ọwọ́ Ọlọ́run, kí àwa lè mọ̀ bí ìrìnàjò wa yóò yọrí sí rere.”
Nao magĩcooka makĩmwĩra atĩrĩ, “Twagũthaitha ũtũtuĩrĩrie ũhoro kũrĩ Ngai tũmenye kana rũgendo rwitũ nĩrũkũgaacĩra.”
6 Àlùfáà náà dá wọn lóhùn pé, “Ẹ máa lọ ní àlàáfíà. Ìrìnàjò yín tí ẹ̀yin ń rìn bá ojúrere Olúwa pàdé.”
Nake mũthĩnjĩri-Ngai ũcio akĩmacookeria atĩrĩ, “Thiĩi na thayũ. Rũgendo rwanyu nĩ rwĩtĩkĩrĩku nĩ Jehova.”
7 Àwọn ọkùnrin márààrún náà kúrò, wọ́n sì wá sí Laiṣi, níbi tí wọ́n ti rí i pé àwọn ènìyàn tí ń gbé ibẹ̀ ní ààbò, bí àwọn ará Sidoni, láìsí ìfòyà àti ní ìpamọ́. Ní ìgbà tí ilẹ̀ wọn kò ṣe aláìní ohunkóhun, wọ́n ní ọrọ̀ púpọ̀. Ibùgbé wọn tún jìnnà sí ti àwọn ará Sidoni, wọn kò fi ohunkóhun bá ẹnikẹ́ni dàpọ̀.
Nĩ ũndũ ũcio andũ acio atano makiuma kuo na magĩkinya Laishi, kũrĩa maakorire atĩ andũ maatũũraga na thayũ matarĩ na ũgwati, o ta andũ a Sidoni, mategwĩkũũa na mategwĩtigĩra. Na tondũ bũrũri wao ndwarĩ kĩndũ waagaga, maarĩ atongu. Ningĩ maatũũraga kũraya na andũ a Sidoni, na matiatarainie na mũndũ o na ũrĩkũ.
8 Nígbà tí wọ́n padà sí Sora àti Eṣtaoli, àwọn arákùnrin wọn bi wọ́n léèrè pé, “Báwo ni ibi tí ẹ lọ ti rí? Kí ni ìròyìn tí ẹ mú wá?”
Na rĩrĩa maacookire Zora na Eshitaoli, ariũ a ithe makĩmooria atĩrĩ, “Mũronire atĩa?”
9 Wọ́n dáhùn pé, “Ẹ dìde ẹ jẹ́ kí a lọ kọlù wọ́n! A wá rí i pé ilẹ̀ náà dára gidigidi. Ṣé ẹ̀yin ó sì jókòó láìsí nǹkan nípa rẹ̀? Ẹ má ṣe lọ́ra láti lọ síbẹ̀ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà.
Magĩcookia atĩrĩ, “Ũkĩrai tũthiĩ tũkamatharĩkĩre! Nĩtuonete atĩ bũrũri ũcio nĩ mwega mũno. Anga gũtirĩ ũndũ mũgwĩka? Mũtigatithie gũthiĩ mũkaũtunyane.
10 Nígbà tí ẹ̀yin bá dé ibẹ̀, ẹ yóò rí àwọn ènìyàn tí ọkàn wọn balẹ̀ àti ilẹ̀ tí ó tẹ́jú tí Ọlọ́run ti fi fún yín, ilẹ̀ tí kò ṣe aláìní nǹkan kan.”
Mwakinya kuo, nĩmũgũkorerera andũ mategwĩkũũa ũgwati o na ũrĩkũ. Bũrũri ũcio nĩ mũnene ũrĩa Ngai aneanĩte moko-inĩ manyu, bũrũri ũtagaga kĩndũ o na kĩrĩkũ.”
11 Nígbà náà ni ẹgbẹ̀ta ọkùnrin tí ó múra ogun láti ìran Dani, jáde lọ láti Sora àti Eṣtaoli ní mímú ra láti jagun.
Hĩndĩ ĩyo andũ magana matandatũ a kuuma mũhĩrĩga wa Dani, meeohete indo cia mbaara, makiumagara kuuma Zora na Eshitaoli.
12 Wọ́n sì jáde lọ, ní ojú ọ̀nà wọn, wọ́n tẹ̀dó ogun sí ẹ̀bá Kiriati-Jearimu ní Juda. Ìdí nìyí tí wọ́n fi ń gbé ìwọ̀-oòrùn Kiriati-Jearimu ni Mahane-Dani títí di òní yìí.
Marĩ njĩra-inĩ, makĩamba hema ciao gũkuhĩ na Kiriathu-Jearimu kũu Juda. Nĩkĩo gĩtũmaga handũ hau he mwena wa ithũĩro rĩa Kiriathu-Jearimu heetwo Mahane-Dani nginya ũmũthĩ.
13 Láti ibẹ̀ wọ́n kọjá lọ sí àwọn ìlú agbègbè òkè Efraimu, wọ́n sì dé ilé Mika.
Kuuma kũu magĩthiĩ na mbere nginya bũrũri ũrĩa ũrĩ irĩma wa Efiraimu na magĩkinya mũciĩ wa Mika.
14 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin márùn-ún tí ó lọ yọ́ ilẹ̀ Laiṣi wò sọ fún àwọn arákùnrin wọn pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin mọ̀ pé ọ̀kan nínú àwọn ilé yìí ní ẹ̀wù efodu, àwọn yòókù ní òrìṣà, ère gbígbẹ́ àti ère dídà? Ẹ mọ ohun tí ó yẹ kí ẹ ṣe báyìí.”
Ningĩ andũ acio atano arĩa maathigaanĩte bũrũri ũcio wa Laishi makĩĩra ariũ a ithe atĩrĩ, “Inyuĩ nĩmũũĩ atĩ nyũmba ĩmwe ya ici ĩrĩ na ebodi, na ngai ingĩ cia nyũmba, na mũhianano mũicũhie, na mũhianano wa gũtwekio? Rĩu nĩmwamenya ũrĩa mũgwĩka.”
15 Wọ́n sì yà sí ibẹ̀, wọ́n sì wọ ilé ọ̀dọ́mọkùnrin Lefi náà, sí ilé Mika, wọ́n sì béèrè àlàáfíà rẹ̀.
Nĩ ũndũ ũcio magĩtoonya nyũmba ya mwanake ũcio Mũlawii o kũu mũciĩ kwa Mika na makĩmũgeithia.
16 Àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin ará Dani náà tí ó hámọ́ra ogun, dúró ní àbáwọlé ẹnu odi.
Nao andũ acio a Dani magana matandatũ meeohete indo cia mbaara makĩrũgama hau kĩhingo-inĩ.
17 Àwọn ọkùnrin márùn-ún tí wọ́n lọ yọ́ ilẹ̀ náà wò wọlé lọ wọ́n sì kó ère gbígbẹ́ náà, efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé àti ère dídà náà nígbà tí àlùfáà náà àti àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin tí ó hámọ́ra ogun dúró ní à bá wọ ẹnu odi náà.
Andũ acio atano arĩa maathigaanĩte bũrũri ũcio magĩtoonya thĩinĩ, makĩoya mũhianano ũrĩa mũicũhie, na ebodi, na ngai icio ingĩ cia nyũmba na mũhianano wa gũtwekio, nake mũthĩnjĩri-Ngai o na andũ acio magana matandatũ meeohete indo cia mbaara maarũgamĩte hau kĩhingo-inĩ.
18 Nígbà tí àwọn ọkùnrin yìí wọ ilé e Mika lọ tí wọ́n sì kó ère fínfín náà, efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé mìíràn àti ère dídà náà, àlùfáà náà béèrè lọ́wọ́ wọn wí pé, “Kí ni ẹ̀yin ń ṣe?”
Rĩrĩa andũ acio maatoonyire nyũmba ya Mika na makĩoya mũhianano wa gwacũhio, na ebodi, na ngai icio ingĩ cia nyũmba, na mũhianano wa gũtwekio-rĩ, mũthĩnjĩri-ngai ũcio akĩmooria atĩrĩ, “Nĩ atĩa mũreka?”
19 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Dákẹ́! Ma sọ nǹkan kan, tẹ̀lé wa kí o sì di baba àti àlùfáà wa. Kò ha sàn fún ọ láti máa ṣe ìránṣẹ́ ẹ̀yà àti ìdílé kan tí ó wá láti Israẹli bí àlùfáà ju ilé ẹnìkan ṣoṣo lọ?”
Nao makĩmũcookeria atĩrĩ, “Kira ki! Ndũkoige ũndũ. Ũka ũtwarane na ithuĩ, ũtuĩke ithe witũ na mũthĩnjĩri-Ngai witũ. Githĩ ti wega ũgĩtungatĩra rũrĩrĩ na mũhĩrĩga thĩinĩ wa Isiraeli ũrĩ mũthĩnjĩri-Ngai, handũ ha gũtungatĩra nyũmba ya mũndũ ũmwe?”
20 Nígbà náà ni inú àlùfáà náà sì dùn, òun mú efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé mìíràn àti ère fínfín náà, ó sì bá àwọn ènìyàn náà lọ.
Nake mũthĩnjĩri-Ngai ũcio agĩkena. Akĩoya ebodi, na ngai iria ingĩ cia nyũmba, na mũhianano ũrĩa mũicũhie, nake agĩthiĩ na andũ acio.
21 Wọ́n kó àwọn ọmọdé wọn, àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní wọn síwájú, wọ́n yípadà wọ́n sì lọ.
Nao makĩhũndũka magĩthiĩ matongoretio nĩ ciana ciao iria nini na mahiũ mao, na indo ciao.
22 Nígbà tí wọ́n ti rìn jìnnà díẹ̀ sí ilé Mika, àwọn ọkùnrin tí ó wà ní agbègbè Mika kó ara wọn jọ, wọ́n sì lé àwọn ará Dani bá.
Rĩrĩa maakorirwo mathiĩte handũ haraaya kuuma nyũmba ya Mika-rĩ, andũ arĩa maatũũraga hakuhĩ na Mika makĩũngana hamwe na magĩkinyĩra andũ acio a Dani.
23 Bí wọ́n ṣe ń pariwo tẹ̀lé wọn lẹ́yìn, àwọn ará Dani yípadà wọ́n sì bi Mika pé, “Kí ló ṣe ọ́ tí o fi pe àwọn ọkùnrin rẹ jáde láti jà?”
O andũ acio makĩmoigagĩrĩria-rĩ, andũ a Dani makĩĩhũgũra makĩũria Mika atĩrĩ, “Kaĩ wona atĩa tondũ weta andũ aku othe marũe?”
24 Ó dáhùn pé, “Ẹ̀yin kó àwọn ère tí mo ṣe, àti àlùfáà mi lọ. Kí ni ó kù tí mo ní? Báwo ni ẹ̀yin ò ṣe béèrè pé, ‘Kí ló ṣe ọ́?’”
Akĩmacookeria atĩrĩ, “Muoire ngai iria ndethondekeire, o na mũthĩnjĩri-ngai wakwa, na mwathiĩ. Nĩ kĩĩ kĩngĩ ngĩrĩ nakĩo? Mwakĩhota atĩa kũũria atĩrĩ, ‘Kaĩ wona atĩa?’”
25 Àwọn ọkùnrin Dani náà dáhùn pé, “Má ṣe bá wa jiyàn, tàbí àwọn oníbìínú fùfù ènìyàn lè kọlù yín, ìwọ àti àwọn ìdílé yóò sì sọ ẹ̀mí yín nù.”
Andũ acio a Dani magĩcookia atĩrĩ, “Tiga gũkararania na ithuĩ, kana ũtharĩkĩrwo nĩ andũ amwe arĩa me marakara, nawe hamwe na nyũmba yaku mũũrwo nĩ mĩoyo yanyu.”
26 Àwọn ọkùnrin Dani náà sì bá ọ̀nà wọn lọ. Nígbà tí Mika rí í pé wọ́n lágbára púpọ̀ fún òun, ó sì padà sí ilé rẹ̀.
Nĩ ũndũ ũcio andũ acio a Dani magĩĩthiĩra, nake Mika, ona atĩ maarĩ na hinya mũnene mũno kũmũkĩra, akĩhũndũka agĩcooka mũciĩ.
27 Wọ́n sì kó àwọn ohun tí Mika ti ṣe àti àlùfáà rẹ̀, wọ́n sì kọjá lọ sí Laiṣi, ní ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tí ó ní ìbàlẹ̀ ọkàn tí wọ́n sì wà ní àlàáfíà. Wọ́n fi ojú idà kọlù wọ́n, wọ́n sì jó ìlú wọn run.
Ningĩ makĩoya kĩrĩa Mika aathondekete, na mũthĩnjĩri-Ngai wake, magĩthiĩ nginya Laishi, magĩũkĩrĩra andũ maarĩ na thayũ na matekũũaga ũndũ. Makĩmatharĩkĩra na rũhiũ rwa njora na magĩcina itũũra rĩao inene.
28 Kò sì sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀ nítorí pé ibi tí wọ́n ń gbé jìnà sí àwọn ará Sidoni, wọn kò sì ní àṣepọ̀ pẹ̀lú ẹnikẹ́ni. Ìlú náà wà ní inú àfonífojì lẹ́bàá a Beti-Rehobu. Àwọn ará Dani sì tún ìlú náà kọ́, wọ́n sì ń gbé inú rẹ̀.
Gũtiarĩ na mũndũ wa kũmahonokia tondũ maatũũraga kũraihu na Sidoni na matiatarainie na mũndũ o na ũrĩkũ. Itũũra rĩu inene rĩarĩ gĩtuamba-inĩ kĩrĩa kĩarĩ hakuhĩ na Bethi-Rehobu. Andũ acio a Dani magĩaka itũũra rĩu inene rĩngĩ na magĩthaamĩra kuo.
29 Wọ́n sọ orúkọ ìlú náà ní Dani gẹ́gẹ́ bí orúkọ baba ńlá wọn Dani, ẹni tí wọ́n bí fún Israẹli: bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Laiṣi ni orúkọ ìlú náà tẹ́lẹ̀ rí.
Makĩrĩĩta Dani o ta ithe wao Dani ũrĩa waciarĩtwo nĩ Isiraeli o na gũtuĩka itũũra rĩu inene rĩetagwo Laishi mbere ĩyo.
30 Àwọn ọmọ Dani sì gbé àwọn ère kalẹ̀ fún ara wọn níbẹ̀; Jonatani ọmọ Gerṣomu, ọmọ Mose, àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni àlùfáà fún àwọn ẹ̀yà Dani títí di àkókò tí a kó ilẹ̀ náà ní ìgbèkùn.
Andũ a Dani makĩĩhaandĩra mĩhianano kũu, nake Jonathani mũrũ wa Gerishomu, mũrũ wa Musa, na ariũ ake magĩtuĩka athĩnjĩri-Ngai mũhĩrĩga-inĩ wa Dani nginya hĩndĩ ĩrĩa andũ acio maatahirwo makĩrutwo bũrũri ũcio.
31 Wọ́n tẹ̀síwájú láti lo àwọn ère tí Mika ṣe, ní gbogbo àkókò tí ilé Ọlọ́run wà ní Ṣilo.
Magĩthiĩ na mbere kũhũthĩra mĩhianano ĩrĩa Mika aathondekete, ihinda rĩrĩa rĩothe nyũmba ya Ngai yarĩ Shilo.