< Judges 18 >

1 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ọmọ Israẹli kò ní ọba. Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ẹ̀yà Dani ń wá ilẹ̀ tiwọn, níbi tí wọn yóò máa gbé, nítorí pé títí di àkókò náà wọn kò ì tí ì pín ogún ilẹ̀ fún wọn ní ìní láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
En ce temps-là, il n'y avait point de roi en Israël, et la tribu de Dan cherchait un héritage ou elle pût demeurer, parce que, jusqu'à ces jours-là, il ne lui était point échu d'héritage au milieu des tribus d'Israël.
2 Nítorí náà àwọn ẹ̀yà Dani rán àwọn jagunjagun márùn-ún lọ láti Sora àti Eṣtaoli láti yọ́ ilẹ̀ náà wò àti láti rìn ín wò. Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣe ojú fún gbogbo àwọn ẹ̀yà wọn. Wọ́n wí fún wọn pé, “Ẹ lọ kí ẹ rin ilẹ̀ náà ká, kí ẹ sì wò ó fínní fínní.” Àwọn ọkùnrin náà wọ àwọn ìlú tí ó wà ní agbègbè òkè Efraimu, wọ́n sì dé ilé Mika, níbi tí wọ́n sùn ní òru náà.
Les fils de Dan envoyèrent donc de Saraa et d'Esthaol cinq hommes vaillants de leurs familles, afin d'explorer la terre et de l'observer avec soin; et ils leur dirent: Allez, et observez avec soin la terre. Et les hommes allèrent dans les montagnes d'Ephraïm, jusqu'à la maison de Michas, et ils logèrent
3 Nígbà tí wọ́n súnmọ́ tòsí ilé e Mika, wọ́n dá ohùn ọ̀dọ́mọkùnrin Lefi náà mọ̀, torí náà wọ́n yípadà, wọ́n sì wọ inú ilé náà lọ wọ́n sì bi í pé, “Tá ni ó mú ọ wa sí ibi? Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín yìí? Èéṣe tí o fi wà ní ibí?”
En la maison de Michas; là, ayant entendu la voix du jeune lévite, ils allèrent à lui, et lui dirent: Qui t'a amené ici? Que fais-tu en ce lieu? Comment y es-tu traité?
4 Ó sọ ohun tí Mika ti ṣe fún un, ó fi kún un fún wọn pé, “Ó gbà mí sí iṣẹ́, èmi sì ni àlùfáà rẹ̀.”
Il leur répondit: Voici comment me traite Michas: il me salarie, et je suis chez lui le prêtre.
5 Wọ́n wí fún un pé, “Jọ̀wọ́ béèrè ní ọwọ́ Ọlọ́run, kí àwa lè mọ̀ bí ìrìnàjò wa yóò yọrí sí rere.”
Et ils lui dirent: Consulte donc Dieu, pour que nous sachions si le voyage que nous avons entrepris réussira.
6 Àlùfáà náà dá wọn lóhùn pé, “Ẹ máa lọ ní àlàáfíà. Ìrìnàjò yín tí ẹ̀yin ń rìn bá ojúrere Olúwa pàdé.”
Et le prêtre leur dit: Allez en paix, le voyage que vous faites est sous la protection du Seigneur.
7 Àwọn ọkùnrin márààrún náà kúrò, wọ́n sì wá sí Laiṣi, níbi tí wọ́n ti rí i pé àwọn ènìyàn tí ń gbé ibẹ̀ ní ààbò, bí àwọn ará Sidoni, láìsí ìfòyà àti ní ìpamọ́. Ní ìgbà tí ilẹ̀ wọn kò ṣe aláìní ohunkóhun, wọ́n ní ọrọ̀ púpọ̀. Ibùgbé wọn tún jìnnà sí ti àwọn ará Sidoni, wọn kò fi ohunkóhun bá ẹnikẹ́ni dàpọ̀.
Ensuite, les cinq hommes partirent; ils arrivèrent à Laïs, et ils virent un peuple qui y demeurait sans inquiétude, tranquille comme le pays des Sidoniens; il était en paix sans que personne vint l'effrayer ou le troubler en quoi que ce fût. Il n'y avait pas là de maître pour extorquer ses richesses; il était d'ailleurs éloigné des Sidoniens, et sans rapport avec les autres hommes.
8 Nígbà tí wọ́n padà sí Sora àti Eṣtaoli, àwọn arákùnrin wọn bi wọ́n léèrè pé, “Báwo ni ibi tí ẹ lọ ti rí? Kí ni ìròyìn tí ẹ mú wá?”
Et les cinq hommes revinrent auprès de leurs frères en Saraa et en Esthaol, et ils dirent à leurs frères: Pourquoi restez-vous ici?
9 Wọ́n dáhùn pé, “Ẹ dìde ẹ jẹ́ kí a lọ kọlù wọ́n! A wá rí i pé ilẹ̀ náà dára gidigidi. Ṣé ẹ̀yin ó sì jókòó láìsí nǹkan nípa rẹ̀? Ẹ má ṣe lọ́ra láti lọ síbẹ̀ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà.
Ils ajoutèrent: Levez-vous, et marchons contre eux; lorsque nous sommes allés explorer le territoire jusqu'à Laisa, nous avons vu un peuple habitant en sécurité, à la façon des Sidoniens, paisible dans sa confiance, ne pouvant appeler personne car ils sont loin de Sidon, et sans relations avec la Syrie.
10 Nígbà tí ẹ̀yin bá dé ibẹ̀, ẹ yóò rí àwọn ènìyàn tí ọkàn wọn balẹ̀ àti ilẹ̀ tí ó tẹ́jú tí Ọlọ́run ti fi fún yín, ilẹ̀ tí kò ṣe aláìní nǹkan kan.”
Aussitôt que vous serez arrivés, vous entrerez chez un peuple qui demeure sans inquiétude en une vaste terre que le Seigneur a livrée à nos mains, où rien ne manque de ce que produit la terre.
11 Nígbà náà ni ẹgbẹ̀ta ọkùnrin tí ó múra ogun láti ìran Dani, jáde lọ láti Sora àti Eṣtaoli ní mímú ra láti jagun.
Alors, six cents hommes bien armés, tous des familles de Dan, partirent de Saraa et d'Esthaol.
12 Wọ́n sì jáde lọ, ní ojú ọ̀nà wọn, wọ́n tẹ̀dó ogun sí ẹ̀bá Kiriati-Jearimu ní Juda. Ìdí nìyí tí wọ́n fi ń gbé ìwọ̀-oòrùn Kiriati-Jearimu ni Mahane-Dani títí di òní yìí.
Ils montèrent et ils campèrent sur le territoire de Gariathiarim en Juda. A cause de cela, ce lieu s'appelle encore de nos jours le camp de Dan; il est derrière Gariathiarim.
13 Láti ibẹ̀ wọ́n kọjá lọ sí àwọn ìlú agbègbè òkè Efraimu, wọ́n sì dé ilé Mika.
Ils traversèrent ensuite les montagnes d'Ephraïm, et arrivèrent auprès de la maison de Michas.
14 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin márùn-ún tí ó lọ yọ́ ilẹ̀ Laiṣi wò sọ fún àwọn arákùnrin wọn pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin mọ̀ pé ọ̀kan nínú àwọn ilé yìí ní ẹ̀wù efodu, àwọn yòókù ní òrìṣà, ère gbígbẹ́ àti ère dídà? Ẹ mọ ohun tí ó yẹ kí ẹ ṣe báyìí.”
Et les cinq hommes qui avaient été envoyés à la découverte en Lais, s'expliquèrent; ils dirent à leurs frères: Sachez qu'il y a en cette maison un éphod, et des théraphim, et une sculpture et un ouvrage en fonte; voyez maintenant ce que vous ferez.
15 Wọ́n sì yà sí ibẹ̀, wọ́n sì wọ ilé ọ̀dọ́mọkùnrin Lefi náà, sí ilé Mika, wọ́n sì béèrè àlàáfíà rẹ̀.
Les cinq hommes y allèrent, et entrèrent dans la maison où était le jeune lévite, chez Michas, et ils questionnèrent le lévite pacifiquement.
16 Àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin ará Dani náà tí ó hámọ́ra ogun, dúró ní àbáwọlé ẹnu odi.
Cependant, les six cents hommes en armes se tenaient près de la porte de la maison, ceux d'entre les fils de Dan
17 Àwọn ọkùnrin márùn-ún tí wọ́n lọ yọ́ ilẹ̀ náà wò wọlé lọ wọ́n sì kó ère gbígbẹ́ náà, efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé àti ère dídà náà nígbà tí àlùfáà náà àti àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin tí ó hámọ́ra ogun dúró ní à bá wọ ẹnu odi náà.
Et les cinq hommes, qu'on avait envoyés d'abord à la découverte, étant entrés là se saisirent de l'éphod, des théraphim, et de la sculpture et l'ouvrage en fonte; et le prêtre se tenait devant la porte avec les six cents hommes en armes.
18 Nígbà tí àwọn ọkùnrin yìí wọ ilé e Mika lọ tí wọ́n sì kó ère fínfín náà, efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé mìíràn àti ère dídà náà, àlùfáà náà béèrè lọ́wọ́ wọn wí pé, “Kí ni ẹ̀yin ń ṣe?”
Et ceux-ci entrèrent dans la maison de Michas et prirent l'éphod, les théraphim, la sculpture et l'ouvrage en fonte, et le prêtre leur dit: Que faites-vous?
19 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Dákẹ́! Ma sọ nǹkan kan, tẹ̀lé wa kí o sì di baba àti àlùfáà wa. Kò ha sàn fún ọ láti máa ṣe ìránṣẹ́ ẹ̀yà àti ìdílé kan tí ó wá láti Israẹli bí àlùfáà ju ilé ẹnìkan ṣoṣo lọ?”
Et ils lui dirent: Garde le silence, mets ta main sur ta bouche; viens avec nous, sois pour nous un père et un prêtre; ne vaut-il pas mieux pour toi être le prêtre d'une tribu et de la maison d'une famille d'Israël, que le prêtre de la maison d'un seul homme?
20 Nígbà náà ni inú àlùfáà náà sì dùn, òun mú efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé mìíràn àti ère fínfín náà, ó sì bá àwọn ènìyàn náà lọ.
Le cœur du prêtre se réjouit; il prit l'éphod, et les théraphim, et la sculpture et l'ouvrage en fonte, et il se rendit au milieu de la troupe en armes.
21 Wọ́n kó àwọn ọmọdé wọn, àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní wọn síwájú, wọ́n yípadà wọ́n sì lọ.
Tous ensemble se remirent en marche; ils s'éloignèrent ayant placé en avant les enfants, le bétail et les bagages.
22 Nígbà tí wọ́n ti rìn jìnnà díẹ̀ sí ilé Mika, àwọn ọkùnrin tí ó wà ní agbègbè Mika kó ara wọn jọ, wọ́n sì lé àwọn ará Dani bá.
Ils étaient déjà a une certaine distance de la maison de Michas, quand Michas et les hommes des maisons voisines de la maison de Michas, jetant de grands cris, atteignirent les fils de Dan.
23 Bí wọ́n ṣe ń pariwo tẹ̀lé wọn lẹ́yìn, àwọn ará Dani yípadà wọ́n sì bi Mika pé, “Kí ló ṣe ọ́ tí o fi pe àwọn ọkùnrin rẹ jáde láti jà?”
Les fils de Dan firent volte-face, et ils dirent à Michas: Qu'as-tu? Pourquoi jettes-tu ces cris?
24 Ó dáhùn pé, “Ẹ̀yin kó àwọn ère tí mo ṣe, àti àlùfáà mi lọ. Kí ni ó kù tí mo ní? Báwo ni ẹ̀yin ò ṣe béèrè pé, ‘Kí ló ṣe ọ́?’”
Et Michas répondit: Vous avez pris la sculpture que j'avais faite; vous emmenez le prêtre, et que me reste-t-il? Comment pouvez-vous me dire: Pourquoi jettes-tu ces cris?
25 Àwọn ọkùnrin Dani náà dáhùn pé, “Má ṣe bá wa jiyàn, tàbí àwọn oníbìínú fùfù ènìyàn lè kọlù yín, ìwọ àti àwọn ìdílé yóò sì sọ ẹ̀mí yín nù.”
Et les fils de Dan lui dirent: Que ta voix n'arrive plus jusqu'à nous, de peur que des hommes irrités, courant sur vous, ne prennent ta vie et la vie de toute ta famille.
26 Àwọn ọkùnrin Dani náà sì bá ọ̀nà wọn lọ. Nígbà tí Mika rí í pé wọ́n lágbára púpọ̀ fún òun, ó sì padà sí ilé rẹ̀.
Puis, les fils de Dan se remirent en marche; Michas, voyant qu'ils étaient les plus forts, s'en retourna chez lui.
27 Wọ́n sì kó àwọn ohun tí Mika ti ṣe àti àlùfáà rẹ̀, wọ́n sì kọjá lọ sí Laiṣi, ní ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tí ó ní ìbàlẹ̀ ọkàn tí wọ́n sì wà ní àlàáfíà. Wọ́n fi ojú idà kọlù wọ́n, wọ́n sì jó ìlú wọn run.
Et les fils de Dan emportèrent ce qu'avait fabriqué Michas; ils emmenèrent le prêtre qui demeurait avec lui, et ils arrivèrent à Laïs chez un peuple paisible, plein de sécurité; ils le passèrent au fil de l'épée, et ils livrèrent la ville aux flammes.
28 Kò sì sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀ nítorí pé ibi tí wọ́n ń gbé jìnà sí àwọn ará Sidoni, wọn kò sì ní àṣepọ̀ pẹ̀lú ẹnikẹ́ni. Ìlú náà wà ní inú àfonífojì lẹ́bàá a Beti-Rehobu. Àwọn ará Dani sì tún ìlú náà kọ́, wọ́n sì ń gbé inú rẹ̀.
Il n'y avait là personne pour défendre ce peuple; car il était loin de Sidon, sans rapport avec les autres hommes, et il vivait dans la vallée de la maison de Rhaab; les fils de Dan rebâtirent la ville, où ils demeurèrent.
29 Wọ́n sọ orúkọ ìlú náà ní Dani gẹ́gẹ́ bí orúkọ baba ńlá wọn Dani, ẹni tí wọ́n bí fún Israẹli: bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Laiṣi ni orúkọ ìlú náà tẹ́lẹ̀ rí.
Et ils appelèrent la ville: Dan, du nom de leur père, fils d'Israël, car, auparavant, elle se nommait Ulamaïs.
30 Àwọn ọmọ Dani sì gbé àwọn ère kalẹ̀ fún ara wọn níbẹ̀; Jonatani ọmọ Gerṣomu, ọmọ Mose, àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni àlùfáà fún àwọn ẹ̀yà Dani títí di àkókò tí a kó ilẹ̀ náà ní ìgbèkùn.
Les fils de Dan y dressèrent la statue. Et Jonathan, fils de Gerson, fils de Manassé, lui et ses fils furent prêtres de la tribu de Dan, jusqu'au jour de sa captivité.
31 Wọ́n tẹ̀síwájú láti lo àwọn ère tí Mika ṣe, ní gbogbo àkókò tí ilé Ọlọ́run wà ní Ṣilo.
Et ils se servirent pour eux de la statue que Michas avait faite, tout le temps que la maison de Dieu fut à Silo. En ces jours-là, il n'y avait point de roi en Israël.

< Judges 18 >