< Judges 18 >

1 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ọmọ Israẹli kò ní ọba. Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ẹ̀yà Dani ń wá ilẹ̀ tiwọn, níbi tí wọn yóò máa gbé, nítorí pé títí di àkókò náà wọn kò ì tí ì pín ogún ilẹ̀ fún wọn ní ìní láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
Siihen aikaan ei ollut kuningasta Israelissa; ja siihen aikaan daanilaisten sukukunta etsi itsellensä perintöosaa asuttavaksensa, sillä siihen päivään asti se ei ollut saanut perintöosaa Israelin sukukuntien kesken.
2 Nítorí náà àwọn ẹ̀yà Dani rán àwọn jagunjagun márùn-ún lọ láti Sora àti Eṣtaoli láti yọ́ ilẹ̀ náà wò àti láti rìn ín wò. Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣe ojú fún gbogbo àwọn ẹ̀yà wọn. Wọ́n wí fún wọn pé, “Ẹ lọ kí ẹ rin ilẹ̀ náà ká, kí ẹ sì wò ó fínní fínní.” Àwọn ọkùnrin náà wọ àwọn ìlú tí ó wà ní agbègbè òkè Efraimu, wọ́n sì dé ilé Mika, níbi tí wọ́n sùn ní òru náà.
Ja daanilaiset lähettivät sukukuntansa keskuudesta viisi miestä, sotakuntoisia miehiä Sorasta ja Estaolista, vakoilemaan maata ja tutkimaan sitä; he sanoivat heille: "Menkää tutkimaan maata". Ja nämä tulivat Efraimin vuoristoon, Miikan talolle asti, ja yöpyivät sinne.
3 Nígbà tí wọ́n súnmọ́ tòsí ilé e Mika, wọ́n dá ohùn ọ̀dọ́mọkùnrin Lefi náà mọ̀, torí náà wọ́n yípadà, wọ́n sì wọ inú ilé náà lọ wọ́n sì bi í pé, “Tá ni ó mú ọ wa sí ibi? Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín yìí? Èéṣe tí o fi wà ní ibí?”
Ollessaan Miikan talon luona he tunsivat nuoren miehen hänen äänestään leeviläiseksi; niin he poikkesivat sinne ja kysyivät häneltä: "Kuka on tuonut sinut tänne? Mitä sinä täällä toimitat, ja mitä sinulla on täällä tekemistä?"
4 Ó sọ ohun tí Mika ti ṣe fún un, ó fi kún un fún wọn pé, “Ó gbà mí sí iṣẹ́, èmi sì ni àlùfáà rẹ̀.”
Hän vastasi heille: "Niin ja niin teki Miika minulle ja palkkasi minut papiksensa".
5 Wọ́n wí fún un pé, “Jọ̀wọ́ béèrè ní ọwọ́ Ọlọ́run, kí àwa lè mọ̀ bí ìrìnàjò wa yóò yọrí sí rere.”
Ja he sanoivat hänelle: "Kysy Jumalalta, että saisimme tietää, onnistuuko matka, jolla me olemme".
6 Àlùfáà náà dá wọn lóhùn pé, “Ẹ máa lọ ní àlàáfíà. Ìrìnàjò yín tí ẹ̀yin ń rìn bá ojúrere Olúwa pàdé.”
Pappi vastasi heille: "Menkää rauhassa. Matka, jolla olette, tapahtuu Herran edessä."
7 Àwọn ọkùnrin márààrún náà kúrò, wọ́n sì wá sí Laiṣi, níbi tí wọ́n ti rí i pé àwọn ènìyàn tí ń gbé ibẹ̀ ní ààbò, bí àwọn ará Sidoni, láìsí ìfòyà àti ní ìpamọ́. Ní ìgbà tí ilẹ̀ wọn kò ṣe aláìní ohunkóhun, wọ́n ní ọrọ̀ púpọ̀. Ibùgbé wọn tún jìnnà sí ti àwọn ará Sidoni, wọn kò fi ohunkóhun bá ẹnikẹ́ni dàpọ̀.
Niin ne viisi miestä jatkoivat matkaansa ja tulivat Laikseen; ja he näkivät, että sikäläinen kansa asui huoleti siidonilaisten tavoin, rauhassa ja huoletonna; eikä kukaan tehnyt vahinkoa siinä maassa rikkauksia anastamalla. Myöskin olivat he kaukana siidonilaisista eivätkä olleet tekemisissä muitten ihmisten kanssa.
8 Nígbà tí wọ́n padà sí Sora àti Eṣtaoli, àwọn arákùnrin wọn bi wọ́n léèrè pé, “Báwo ni ibi tí ẹ lọ ti rí? Kí ni ìròyìn tí ẹ mú wá?”
Ja he tulivat veljiensä luo Soraan ja Estaoliin, ja heidän veljensä kysyivät heiltä: "Mitä kuuluu?"
9 Wọ́n dáhùn pé, “Ẹ dìde ẹ jẹ́ kí a lọ kọlù wọ́n! A wá rí i pé ilẹ̀ náà dára gidigidi. Ṣé ẹ̀yin ó sì jókòó láìsí nǹkan nípa rẹ̀? Ẹ má ṣe lọ́ra láti lọ síbẹ̀ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà.
He sanoivat: "Nouskaa, lähtekäämme heitä vastaan. Sillä me olemme katselleet maata, ja katso, se on hyvin hyvä. Ja tekö jäisitte toimettomiksi! Älkää viivytelkö, lähtekää liikkeelle, menkää sinne ja ottakaa omaksenne se maa.
10 Nígbà tí ẹ̀yin bá dé ibẹ̀, ẹ yóò rí àwọn ènìyàn tí ọkàn wọn balẹ̀ àti ilẹ̀ tí ó tẹ́jú tí Ọlọ́run ti fi fún yín, ilẹ̀ tí kò ṣe aláìní nǹkan kan.”
Kun tulette sinne, tulette huoletonna elävän kansan luo, ja maa on tilava joka suuntaan. Niin, Jumala antaa sen teidän käsiinne, paikan, jossa ei ole puutetta mistään, mitä maan päällä on."
11 Nígbà náà ni ẹgbẹ̀ta ọkùnrin tí ó múra ogun láti ìran Dani, jáde lọ láti Sora àti Eṣtaoli ní mímú ra láti jagun.
Niin lähti sieltä liikkeelle, daanilaisten sukukunnasta, Sorasta ja Estaolista, kuusisataa sota-aseilla varustettua miestä.
12 Wọ́n sì jáde lọ, ní ojú ọ̀nà wọn, wọ́n tẹ̀dó ogun sí ẹ̀bá Kiriati-Jearimu ní Juda. Ìdí nìyí tí wọ́n fi ń gbé ìwọ̀-oòrùn Kiriati-Jearimu ni Mahane-Dani títí di òní yìí.
He nousivat Juudan Kirjat-Jearimiin ja leiriytyivät sinne. Sentähden kutsutaan sitä paikkaa vielä tänäkin päivänä "Daanin leiriksi"; se on Kirjat-Jearimin takana.
13 Láti ibẹ̀ wọ́n kọjá lọ sí àwọn ìlú agbègbè òkè Efraimu, wọ́n sì dé ilé Mika.
Sieltä he kulkivat Efraimin vuoristoon ja tulivat Miikan talolle asti.
14 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin márùn-ún tí ó lọ yọ́ ilẹ̀ Laiṣi wò sọ fún àwọn arákùnrin wọn pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin mọ̀ pé ọ̀kan nínú àwọn ilé yìí ní ẹ̀wù efodu, àwọn yòókù ní òrìṣà, ère gbígbẹ́ àti ère dídà? Ẹ mọ ohun tí ó yẹ kí ẹ ṣe báyìí.”
Niin ne viisi miestä, jotka olivat käyneet vakoilemassa Laiksen maata, rupesivat puhumaan ja sanoivat veljillensä: "Tiedättekö, että noissa huoneissa on kasukka ja kotijumalia sekä veistetty ja valettu jumalankuva? Miettikää siis, mitä teidän on tehtävä."
15 Wọ́n sì yà sí ibẹ̀, wọ́n sì wọ ilé ọ̀dọ́mọkùnrin Lefi náà, sí ilé Mika, wọ́n sì béèrè àlàáfíà rẹ̀.
Niin he poikkesivat sinne ja tulivat sen nuoren leeviläisen miehen asunnolle, Miikan taloon, ja tervehtivät häntä.
16 Àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin ará Dani náà tí ó hámọ́ra ogun, dúró ní àbáwọlé ẹnu odi.
Ja ne kuusisataa sota-aseilla varustettua daanilaista asettuivat portin oven eteen.
17 Àwọn ọkùnrin márùn-ún tí wọ́n lọ yọ́ ilẹ̀ náà wò wọlé lọ wọ́n sì kó ère gbígbẹ́ náà, efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé àti ère dídà náà nígbà tí àlùfáà náà àti àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin tí ó hámọ́ra ogun dúró ní à bá wọ ẹnu odi náà.
Ja ne viisi miestä, jotka olivat käyneet vakoilemassa maata, nousivat taloon, menivät sisään ja ottivat veistetyn jumalankuvan ja kasukan ja kotijumalat ja valetun jumalankuvan, mutta pappi ja ne kuusisataa sota-aseilla varustettua miestä seisoivat portin oven edessä.
18 Nígbà tí àwọn ọkùnrin yìí wọ ilé e Mika lọ tí wọ́n sì kó ère fínfín náà, efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé mìíràn àti ère dídà náà, àlùfáà náà béèrè lọ́wọ́ wọn wí pé, “Kí ni ẹ̀yin ń ṣe?”
Kun he menivät Miikan taloon ja ottivat veistetyn jumalankuvan ja kasukan ja kotijumalat ja valetun jumalankuvan, niin pappi kysyi heiltä: "Mitä te teette?"
19 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Dákẹ́! Ma sọ nǹkan kan, tẹ̀lé wa kí o sì di baba àti àlùfáà wa. Kò ha sàn fún ọ láti máa ṣe ìránṣẹ́ ẹ̀yà àti ìdílé kan tí ó wá láti Israẹli bí àlùfáà ju ilé ẹnìkan ṣoṣo lọ?”
He vastasivat hänelle: "Vaikene, pidä suusi kiinni ja lähde meidän kanssamme ja tule meidän isäksemme ja papiksemme. Onko parempi ollaksesi pappina yhden miehen talossa kuin Israelin heimon ja sukukunnan pappina?"
20 Nígbà náà ni inú àlùfáà náà sì dùn, òun mú efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé mìíràn àti ère fínfín náà, ó sì bá àwọn ènìyàn náà lọ.
Silloin pappi tuli hyville mielin, ja hän otti kasukan ja kotijumalat ja veistetyn jumalankuvan ja meni väen keskeen.
21 Wọ́n kó àwọn ọmọdé wọn, àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní wọn síwájú, wọ́n yípadà wọ́n sì lọ.
Sitten he kääntyivät jatkamaan matkaansa ja panivat vaimot ja lapset sekä karjan ja kuormaston kulkemaan edellänsä.
22 Nígbà tí wọ́n ti rìn jìnnà díẹ̀ sí ilé Mika, àwọn ọkùnrin tí ó wà ní agbègbè Mika kó ara wọn jọ, wọ́n sì lé àwọn ará Dani bá.
He olivat ehtineet vähän matkaa Miikan talosta, kun Miikan talon lähitalojen miehet kutsuttiin koolle, ja he pääsivät daanilaisten kintereille.
23 Bí wọ́n ṣe ń pariwo tẹ̀lé wọn lẹ́yìn, àwọn ará Dani yípadà wọ́n sì bi Mika pé, “Kí ló ṣe ọ́ tí o fi pe àwọn ọkùnrin rẹ jáde láti jà?”
Ja he huusivat daanilaisille; nämä kääntyivät ja kysyivät Miikalta: "Mikä sinun on, kun väkesi on noin kutsuttu koolle?"
24 Ó dáhùn pé, “Ẹ̀yin kó àwọn ère tí mo ṣe, àti àlùfáà mi lọ. Kí ni ó kù tí mo ní? Báwo ni ẹ̀yin ò ṣe béèrè pé, ‘Kí ló ṣe ọ́?’”
Hän vastasi: "Te olette ottaneet minun jumalani, jotka minä olen teettänyt, ja papin, ja menette matkoihinne. Mitä on minulla enää jäljellä? Ja kuinka te vielä kysytte minulta: 'Mikä sinun on'?"
25 Àwọn ọkùnrin Dani náà dáhùn pé, “Má ṣe bá wa jiyàn, tàbí àwọn oníbìínú fùfù ènìyàn lè kọlù yín, ìwọ àti àwọn ìdílé yóò sì sọ ẹ̀mí yín nù.”
Mutta daanilaiset sanoivat hänelle: "Herkeä huutamasta meille, muuten miehet ärtyvät ja käyvät kimppuunne, ja te menetätte henkenne, sekä sinä että sinun perheesi".
26 Àwọn ọkùnrin Dani náà sì bá ọ̀nà wọn lọ. Nígbà tí Mika rí í pé wọ́n lágbára púpọ̀ fún òun, ó sì padà sí ilé rẹ̀.
Niin daanilaiset jatkoivat matkaansa, ja kun Miika näki, että he olivat häntä voimakkaammat, kääntyi hän ja palasi kotiinsa.
27 Wọ́n sì kó àwọn ohun tí Mika ti ṣe àti àlùfáà rẹ̀, wọ́n sì kọjá lọ sí Laiṣi, ní ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tí ó ní ìbàlẹ̀ ọkàn tí wọ́n sì wà ní àlàáfíà. Wọ́n fi ojú idà kọlù wọ́n, wọ́n sì jó ìlú wọn run.
Otettuaan siis sen, minkä Miika oli teettänyt, sekä hänen pappinsa, hyökkäsivät he Laiksen rauhassa ja huoletonna elävän kansan kimppuun ja surmasivat heidät miekan terällä ja polttivat kaupungin tulella.
28 Kò sì sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀ nítorí pé ibi tí wọ́n ń gbé jìnà sí àwọn ará Sidoni, wọn kò sì ní àṣepọ̀ pẹ̀lú ẹnikẹ́ni. Ìlú náà wà ní inú àfonífojì lẹ́bàá a Beti-Rehobu. Àwọn ará Dani sì tún ìlú náà kọ́, wọ́n sì ń gbé inú rẹ̀.
Eikä kukaan tullut avuksi, sillä se oli kaukana Siidonista eivätkä he olleet tekemisissä muitten ihmisten kanssa; se oli Beet-Rehobin tasangolla. Daanilaiset rakensivat kaupungin uudestaan ja asettuivat siihen.
29 Wọ́n sọ orúkọ ìlú náà ní Dani gẹ́gẹ́ bí orúkọ baba ńlá wọn Dani, ẹni tí wọ́n bí fún Israẹli: bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Laiṣi ni orúkọ ìlú náà tẹ́lẹ̀ rí.
Ja he antoivat kaupungille nimen Daan, isänsä Daanin nimen mukaan, hänen, joka oli Israelille syntynyt; mutta ennen oli kaupungin nimi ollut Lais.
30 Àwọn ọmọ Dani sì gbé àwọn ère kalẹ̀ fún ara wọn níbẹ̀; Jonatani ọmọ Gerṣomu, ọmọ Mose, àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni àlùfáà fún àwọn ẹ̀yà Dani títí di àkókò tí a kó ilẹ̀ náà ní ìgbèkùn.
Sitten daanilaiset pystyttivät itsellensä sen veistetyn jumalankuvan; ja Joonatan, Manassen pojan Geersomin poika, ja hänen poikansa olivat daanilaisten sukukunnan pappeina, kunnes maan väestö vietiin pakkosiirtolaisuuteen.
31 Wọ́n tẹ̀síwájú láti lo àwọn ère tí Mika ṣe, ní gbogbo àkókò tí ilé Ọlọ́run wà ní Ṣilo.
He pystyttivät itsellensä sen veistetyn jumalankuvan, jonka Miika oli teettänyt, ja se oli siinä koko ajan, minkä Jumalan huone oli Siilossa.

< Judges 18 >