< Judges 18 >

1 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ọmọ Israẹli kò ní ọba. Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ẹ̀yà Dani ń wá ilẹ̀ tiwọn, níbi tí wọn yóò máa gbé, nítorí pé títí di àkókò náà wọn kò ì tí ì pín ogún ilẹ̀ fún wọn ní ìní láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
Siihen aikaan ei ollut kuningasta Israelissa, ja silloin Danin sukukunta etsi itsellensä perintöä asuaksensa; sillä siihen päivään asti ei ollut yhtään perintöarpaa hänelle langennut Israelin sukukuntain seassa.
2 Nítorí náà àwọn ẹ̀yà Dani rán àwọn jagunjagun márùn-ún lọ láti Sora àti Eṣtaoli láti yọ́ ilẹ̀ náà wò àti láti rìn ín wò. Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣe ojú fún gbogbo àwọn ẹ̀yà wọn. Wọ́n wí fún wọn pé, “Ẹ lọ kí ẹ rin ilẹ̀ náà ká, kí ẹ sì wò ó fínní fínní.” Àwọn ọkùnrin náà wọ àwọn ìlú tí ó wà ní agbègbè òkè Efraimu, wọ́n sì dé ilé Mika, níbi tí wọ́n sùn ní òru náà.
Ja Danin lapset lähettivät sukukunnastansa ja ääristänsä viisi urhoollista sotamiestä Zorasta ja Estaolista, vakoomaan maata ja tutkistelemaan sitä, ja sanoivat heille: menkäät ja vaotkaat maata. Ja he tulivat Ephraimin vuorelle Miikan huoneesen ja yötyivät sinne.
3 Nígbà tí wọ́n súnmọ́ tòsí ilé e Mika, wọ́n dá ohùn ọ̀dọ́mọkùnrin Lefi náà mọ̀, torí náà wọ́n yípadà, wọ́n sì wọ inú ilé náà lọ wọ́n sì bi í pé, “Tá ni ó mú ọ wa sí ibi? Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín yìí? Èéṣe tí o fi wà ní ibí?”
Ja kuin he olivat Miikan perheen tykönä, tunsivat he sen nuoren miehen Leviläisen äänen; ja he menivät hänen tykönsä ja sanoivat hänelle: kuka sinun on tänne tuonut? mitäs täällä teet? ja mitä sinun on täällä?
4 Ó sọ ohun tí Mika ti ṣe fún un, ó fi kún un fún wọn pé, “Ó gbà mí sí iṣẹ́, èmi sì ni àlùfáà rẹ̀.”
Hän vastasi heitä: niin ja niin on Miika minulle tehnyt, ja hän on palkannut minun papiksensa.
5 Wọ́n wí fún un pé, “Jọ̀wọ́ béèrè ní ọwọ́ Ọlọ́run, kí àwa lè mọ̀ bí ìrìnàjò wa yóò yọrí sí rere.”
He sanoivat hänelle: kysy Jumalalta, että me saisimme tietää, onko tiemme, jota me vaellamme, meille onnellinen.
6 Àlùfáà náà dá wọn lóhùn pé, “Ẹ máa lọ ní àlàáfíà. Ìrìnàjò yín tí ẹ̀yin ń rìn bá ojúrere Olúwa pàdé.”
Pappi vastasi heitä: menkäät rauhassa: Herran edessä on teidän tienne, jota te vaellatte.
7 Àwọn ọkùnrin márààrún náà kúrò, wọ́n sì wá sí Laiṣi, níbi tí wọ́n ti rí i pé àwọn ènìyàn tí ń gbé ibẹ̀ ní ààbò, bí àwọn ará Sidoni, láìsí ìfòyà àti ní ìpamọ́. Ní ìgbà tí ilẹ̀ wọn kò ṣe aláìní ohunkóhun, wọ́n ní ọrọ̀ púpọ̀. Ibùgbé wọn tún jìnnà sí ti àwọn ará Sidoni, wọn kò fi ohunkóhun bá ẹnikẹ́ni dàpọ̀.
Niin menivät ne viisi miestä matkaansa ja tulivat Laikseen, ja näkivät kansan, joka siellä oli, asuvan surutoinna Zidonilaisten tavan jälkeen, levollisesti ja surutoinna: ja ei yksikään ollut, joka heitä vaivasi sillä maalla, eikä myös heillä ollut yhtäkään isäntää; ja olivat kaukana Zidonilaisista, ja ei heillä ollut mitäkään yhdenkään ihmisen kanssa tekemistä.
8 Nígbà tí wọ́n padà sí Sora àti Eṣtaoli, àwọn arákùnrin wọn bi wọ́n léèrè pé, “Báwo ni ibi tí ẹ lọ ti rí? Kí ni ìròyìn tí ẹ mú wá?”
Ja he tulivat veljeinsä tykö Zoraan ja Estaoliin. Ja heidän veljensä sanoivat heille: kuinka teidän asianne on?
9 Wọ́n dáhùn pé, “Ẹ dìde ẹ jẹ́ kí a lọ kọlù wọ́n! A wá rí i pé ilẹ̀ náà dára gidigidi. Ṣé ẹ̀yin ó sì jókòó láìsí nǹkan nípa rẹ̀? Ẹ má ṣe lọ́ra láti lọ síbẹ̀ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà.
He sanoivat: nouskaat, käykäämme ylös heidän tykönsä; sillä me olemme katselleet maan, ja katso, se on sangen hyvä: sentähden rientäkäät, älkäät olko hitaat menemään ja omistamaan maata.
10 Nígbà tí ẹ̀yin bá dé ibẹ̀, ẹ yóò rí àwọn ènìyàn tí ọkàn wọn balẹ̀ àti ilẹ̀ tí ó tẹ́jú tí Ọlọ́run ti fi fún yín, ilẹ̀ tí kò ṣe aláìní nǹkan kan.”
Kuin te tulette, niin te löydätte suruttoman kansan, ja maa on itsestänsä lavia: sillä Jumala on antanut sen teidän käsiinne, sen paikan, jossa ei mitään puutu, mitä maan päällä on.
11 Nígbà náà ni ẹgbẹ̀ta ọkùnrin tí ó múra ogun láti ìran Dani, jáde lọ láti Sora àti Eṣtaoli ní mímú ra láti jagun.
Niin meni Danin sukukunnasta, Zorasta ja Estaolista, kuusisataa miestä hyvin varustettuina sota-aseilla,
12 Wọ́n sì jáde lọ, ní ojú ọ̀nà wọn, wọ́n tẹ̀dó ogun sí ẹ̀bá Kiriati-Jearimu ní Juda. Ìdí nìyí tí wọ́n fi ń gbé ìwọ̀-oòrùn Kiriati-Jearimu ni Mahane-Dani títí di òní yìí.
Ja menivät sinne ylös, ja sioittivat itsensä Juudan KirjatJearimiin: siitä kutsutaan se paikka Danin leiriksi tähän päivään asti; katso, se on KirjatJearimin takana.
13 Láti ibẹ̀ wọ́n kọjá lọ sí àwọn ìlú agbègbè òkè Efraimu, wọ́n sì dé ilé Mika.
Ja sieltä menivät he Ephraimin vuorelle ja tulivat Miikan huoneen tykö.
14 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin márùn-ún tí ó lọ yọ́ ilẹ̀ Laiṣi wò sọ fún àwọn arákùnrin wọn pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin mọ̀ pé ọ̀kan nínú àwọn ilé yìí ní ẹ̀wù efodu, àwọn yòókù ní òrìṣà, ère gbígbẹ́ àti ère dídà? Ẹ mọ ohun tí ó yẹ kí ẹ ṣe báyìí.”
Niin puhuivat ne viisi miestä, jotka läksivät Laikseen maata vakoomaan, ja sanoivat veljillensä: ettekö te tiedä, että näissä huoneissa on päällisvaate, pyhyys, kuvat ja epäjumalat? Nyt ajatelkaat, mitä te teette.
15 Wọ́n sì yà sí ibẹ̀, wọ́n sì wọ ilé ọ̀dọ́mọkùnrin Lefi náà, sí ilé Mika, wọ́n sì béèrè àlàáfíà rẹ̀.
Ja he poikkesivat sinne ja tulivat nuoren miehen Leviläisen huoneesen, joka oli Miikan huoneessa, ja tervehtivät häntä ystävällisesti.
16 Àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin ará Dani náà tí ó hámọ́ra ogun, dúró ní àbáwọlé ẹnu odi.
Mutta ne kuusisataa sota-aseilla varustettua miestä, jotka olivat Danin lapsista, seisoivat portilla.
17 Àwọn ọkùnrin márùn-ún tí wọ́n lọ yọ́ ilẹ̀ náà wò wọlé lọ wọ́n sì kó ère gbígbẹ́ náà, efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé àti ère dídà náà nígbà tí àlùfáà náà àti àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin tí ó hámọ́ra ogun dúró ní à bá wọ ẹnu odi náà.
Ja ne viisi miestä, jotka olivat menneet vakoomaan maata, menivät ylös ja tulivat sinne sisälle, ja ottivat kuvan, päällisvaatteen, pyhyyden ja epäjumalan. Ja pappi seisoi portilla kuudensadan sota-aseilla varustettuin miesten tykönä.
18 Nígbà tí àwọn ọkùnrin yìí wọ ilé e Mika lọ tí wọ́n sì kó ère fínfín náà, efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé mìíràn àti ère dídà náà, àlùfáà náà béèrè lọ́wọ́ wọn wí pé, “Kí ni ẹ̀yin ń ṣe?”
Kuin ne olivat tulleet Miikan huoneesen ja ottivat kuvan, päällisvaatteen, pyhyyden ja epäjumalat, sanoi pappi heille: mitä te teette?
19 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Dákẹ́! Ma sọ nǹkan kan, tẹ̀lé wa kí o sì di baba àti àlùfáà wa. Kò ha sàn fún ọ láti máa ṣe ìránṣẹ́ ẹ̀yà àti ìdílé kan tí ó wá láti Israẹli bí àlùfáà ju ilé ẹnìkan ṣoṣo lọ?”
He vastasivat häntä: ole vaiti ja pidä suus kiinni, ja tule meidän kanssamme, ja ole meidän isämme ja pappimme: onko se parempi, ettäs olet pappi yhden miehen huoneessa, kuin koko sukukunnassa Israelissa?
20 Nígbà náà ni inú àlùfáà náà sì dùn, òun mú efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé mìíràn àti ère fínfín náà, ó sì bá àwọn ènìyàn náà lọ.
Ja papin mieli oli hyvä, ja otti sekä päällisvaatteen, pyhyyden ja kuvan, ja meni kansan keskelle.
21 Wọ́n kó àwọn ọmọdé wọn, àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní wọn síwájú, wọ́n yípadà wọ́n sì lọ.
Ja kuin he käänsivät itsensä ja menivät matkaansa, asettivat he pienet lapset ja karjan ja kaikkein kalliimmat tavaransa, menemään edellänsä.
22 Nígbà tí wọ́n ti rìn jìnnà díẹ̀ sí ilé Mika, àwọn ọkùnrin tí ó wà ní agbègbè Mika kó ara wọn jọ, wọ́n sì lé àwọn ará Dani bá.
Kuin he olivat taamma joutuneet Miikan huoneesta, kokoontuivat ne miehet, jotka niissä huoneissa olivat, jotka olivat Miikan huoneen tykönä, ja ajoivat Danin lapsia takaa,
23 Bí wọ́n ṣe ń pariwo tẹ̀lé wọn lẹ́yìn, àwọn ará Dani yípadà wọ́n sì bi Mika pé, “Kí ló ṣe ọ́ tí o fi pe àwọn ọkùnrin rẹ jáde láti jà?”
Ja huusivat Danin lapsille; ja he käänsivät kasvonsa ja sanoivat Miikalle: mikä sinun on, ettäs niin huudat?
24 Ó dáhùn pé, “Ẹ̀yin kó àwọn ère tí mo ṣe, àti àlùfáà mi lọ. Kí ni ó kù tí mo ní? Báwo ni ẹ̀yin ò ṣe béèrè pé, ‘Kí ló ṣe ọ́?’”
Hän vastasi: te olette ottaneet minun jumalani, jotka minä tehnyt olen, ja papin, ja menneet matkaanne: ja mitä minulla nyt enää on? Ja te sanotte vielä sitte minulle: mikä sinun on?
25 Àwọn ọkùnrin Dani náà dáhùn pé, “Má ṣe bá wa jiyàn, tàbí àwọn oníbìínú fùfù ènìyàn lè kọlù yín, ìwọ àti àwọn ìdílé yóò sì sọ ẹ̀mí yín nù.”
Mutta Danin lapset sanoivat hänelle: älä anna ääntäs kuulua meidän tykönämme, ettei vihaiset miehet lankeaisi teidän päällenne, ja sinä hukutat sielus ja huonees sielut.
26 Àwọn ọkùnrin Dani náà sì bá ọ̀nà wọn lọ. Nígbà tí Mika rí í pé wọ́n lágbára púpọ̀ fún òun, ó sì padà sí ilé rẹ̀.
Niin Danin lapset menivät matkaansa. Ja kuin Miika näki heidät häntä väkevämmäksi, käänsi hän itsensä ja palasi huoneesensa.
27 Wọ́n sì kó àwọn ohun tí Mika ti ṣe àti àlùfáà rẹ̀, wọ́n sì kọjá lọ sí Laiṣi, ní ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tí ó ní ìbàlẹ̀ ọkàn tí wọ́n sì wà ní àlàáfíà. Wọ́n fi ojú idà kọlù wọ́n, wọ́n sì jó ìlú wọn run.
Mutta he ottivat sen mitä Miika tehnyt oli ja papin, joka hänellä oli, ja tulivat Laikseen, levollisen ja suruttoman kansan päälle, ja löivät heitä miekan terällä, ja polttivat kaupungin.
28 Kò sì sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀ nítorí pé ibi tí wọ́n ń gbé jìnà sí àwọn ará Sidoni, wọn kò sì ní àṣepọ̀ pẹ̀lú ẹnikẹ́ni. Ìlú náà wà ní inú àfonífojì lẹ́bàá a Beti-Rehobu. Àwọn ará Dani sì tún ìlú náà kọ́, wọ́n sì ń gbé inú rẹ̀.
Ja ei yksikään ollut, joka heitä autti, sillä he olivat kaukana Zidonista, ja ei ollut heillä kenenkään kanssa tekemistä: ja he olivat siinä laaksossa, joka on BetRehobin tykönä; niin rakensivat he kaupungin, ja asuivat siinä;
29 Wọ́n sọ orúkọ ìlú náà ní Dani gẹ́gẹ́ bí orúkọ baba ńlá wọn Dani, ẹni tí wọ́n bí fún Israẹli: bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Laiṣi ni orúkọ ìlú náà tẹ́lẹ̀ rí.
Ja kutsuivat kaupungin nimen Dan, isänsä Danin nimeltä, joka Israelista oli syntynyt, vaikka se kaupunki ennen muinen kutsuttiin Lais.
30 Àwọn ọmọ Dani sì gbé àwọn ère kalẹ̀ fún ara wọn níbẹ̀; Jonatani ọmọ Gerṣomu, ọmọ Mose, àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni àlùfáà fún àwọn ẹ̀yà Dani títí di àkókò tí a kó ilẹ̀ náà ní ìgbèkùn.
Ja Danin lapset panivat heillensä sen kuvan ylös, ja Jonatan Gersomin poika, Manassen pojan, ja hänen poikansa olivat papit Danilaisten sukukunnassa, siihenasti että he vietiin vankina maalta pois,
31 Wọ́n tẹ̀síwájú láti lo àwọn ère tí Mika ṣe, ní gbogbo àkókò tí ilé Ọlọ́run wà ní Ṣilo.
Ja he panivat keskellensä Miikan kuvan, jonka hän tehnyt oli, niinkauvan kuin Jumalan huone oli Silossa.

< Judges 18 >