< Judges 18 >

1 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ọmọ Israẹli kò ní ọba. Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ẹ̀yà Dani ń wá ilẹ̀ tiwọn, níbi tí wọn yóò máa gbé, nítorí pé títí di àkókò náà wọn kò ì tí ì pín ogún ilẹ̀ fún wọn ní ìní láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
I de samme Dage var ingen Konge i Israel, og i de samme Dage søgte Daniternes Stamme sig en Lod, hvor de kunde bo; thi der var indtil den Dag ikke tilfaldet dem nogen Arv iblandt Israels Stammer.
2 Nítorí náà àwọn ẹ̀yà Dani rán àwọn jagunjagun márùn-ún lọ láti Sora àti Eṣtaoli láti yọ́ ilẹ̀ náà wò àti láti rìn ín wò. Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣe ojú fún gbogbo àwọn ẹ̀yà wọn. Wọ́n wí fún wọn pé, “Ẹ lọ kí ẹ rin ilẹ̀ náà ká, kí ẹ sì wò ó fínní fínní.” Àwọn ọkùnrin náà wọ àwọn ìlú tí ó wà ní agbègbè òkè Efraimu, wọ́n sì dé ilé Mika, níbi tí wọ́n sùn ní òru náà.
Og Dans Børn udsendte af deres Slægt fem Mænd af deres hele Tal, stridbare Mænd fra Zora og fra Esthaol for at bespejde Landet og at udforske det, og de sagde til dem: Gaar hen, udforsker Landet; og de kom paa Efraims Bjerg, til Mikas Hus, og bleve der om Natten.
3 Nígbà tí wọ́n súnmọ́ tòsí ilé e Mika, wọ́n dá ohùn ọ̀dọ́mọkùnrin Lefi náà mọ̀, torí náà wọ́n yípadà, wọ́n sì wọ inú ilé náà lọ wọ́n sì bi í pé, “Tá ni ó mú ọ wa sí ibi? Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín yìí? Èéṣe tí o fi wà ní ibí?”
Disse vare ved Mikas Hus, og disse kendte den unge Karls, Levitens Bøst, og de toge derind og sagde til ham: Hvo har ført dig herhid? og hvad gør du paa dette Sted? og hvad har du her?
4 Ó sọ ohun tí Mika ti ṣe fún un, ó fi kún un fún wọn pé, “Ó gbà mí sí iṣẹ́, èmi sì ni àlùfáà rẹ̀.”
Og han sagde til dem: Paa den og den Maade har Mika gjort imod mig, og han har lejet mig, og jeg er bleven hans Præst.
5 Wọ́n wí fún un pé, “Jọ̀wọ́ béèrè ní ọwọ́ Ọlọ́run, kí àwa lè mọ̀ bí ìrìnàjò wa yóò yọrí sí rere.”
Og de sagde til ham: Kære, spørg Gud ad, at vi maa vide, om vor Vej, som vi vandre paa, skal blive lykkelig.
6 Àlùfáà náà dá wọn lóhùn pé, “Ẹ máa lọ ní àlàáfíà. Ìrìnàjò yín tí ẹ̀yin ń rìn bá ojúrere Olúwa pàdé.”
Og Præsten sagde til dem: Gaar med Fred! eders Vej, som I vandre paa, er for Herren.
7 Àwọn ọkùnrin márààrún náà kúrò, wọ́n sì wá sí Laiṣi, níbi tí wọ́n ti rí i pé àwọn ènìyàn tí ń gbé ibẹ̀ ní ààbò, bí àwọn ará Sidoni, láìsí ìfòyà àti ní ìpamọ́. Ní ìgbà tí ilẹ̀ wọn kò ṣe aláìní ohunkóhun, wọ́n ní ọrọ̀ púpọ̀. Ibùgbé wọn tún jìnnà sí ti àwọn ará Sidoni, wọn kò fi ohunkóhun bá ẹnikẹ́ni dàpọ̀.
Da gik de fem Mænd og kom til Lais; og de saa, at det Folk, som der var, boede tryggeligen, efter Zidoniernes Vis, roligt og trygt; og der var ingen, som lastede nogen Ting i Landet, eller som havde arvelig Magt; og de vare langt fra Zidonierne og havde intet at gøre med noget Menneske.
8 Nígbà tí wọ́n padà sí Sora àti Eṣtaoli, àwọn arákùnrin wọn bi wọ́n léèrè pé, “Báwo ni ibi tí ẹ lọ ti rí? Kí ni ìròyìn tí ẹ mú wá?”
Og de kom til deres Brødre i Zora og Esthaol, og deres Brødre sagde til dem: Hvad sige I?
9 Wọ́n dáhùn pé, “Ẹ dìde ẹ jẹ́ kí a lọ kọlù wọ́n! A wá rí i pé ilẹ̀ náà dára gidigidi. Ṣé ẹ̀yin ó sì jókòó láìsí nǹkan nípa rẹ̀? Ẹ má ṣe lọ́ra láti lọ síbẹ̀ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà.
Og de sagde: Staar op og lader os drage op imod dem; thi vi have set Landet; og se, det er saare godt; og I tie? værer ikke lade til at gaa hen til at komme til at tage Landet til Eje.
10 Nígbà tí ẹ̀yin bá dé ibẹ̀, ẹ yóò rí àwọn ènìyàn tí ọkàn wọn balẹ̀ àti ilẹ̀ tí ó tẹ́jú tí Ọlọ́run ti fi fún yín, ilẹ̀ tí kò ṣe aláìní nǹkan kan.”
Naar I komme, da skulle I komme til et trygt Folk, og Landet er vidt og bredt; thi Gud har givet det i eders Haand, et Sted, hvor der ikke er Mangel paa nogen Verdens Ting.
11 Nígbà náà ni ẹgbẹ̀ta ọkùnrin tí ó múra ogun láti ìran Dani, jáde lọ láti Sora àti Eṣtaoli ní mímú ra láti jagun.
Da rejste derfra af Daniternes Slægt, fra Zora og Esthaol, seks Hundrede Mænd omgjordede med Krigsvaaben.
12 Wọ́n sì jáde lọ, ní ojú ọ̀nà wọn, wọ́n tẹ̀dó ogun sí ẹ̀bá Kiriati-Jearimu ní Juda. Ìdí nìyí tí wọ́n fi ń gbé ìwọ̀-oòrùn Kiriati-Jearimu ni Mahane-Dani títí di òní yìí.
Og de droge op og lejrede sig i Kirjath-Jearim i Juda; derfor kaldte de det samme Sted Dans Lejr indtil denne Dag, se, den er bag Kirjath-Jearim.
13 Láti ibẹ̀ wọ́n kọjá lọ sí àwọn ìlú agbègbè òkè Efraimu, wọ́n sì dé ilé Mika.
Og de gik derfra over paa Efraims Bjerg, og de kom til Mikas Hus.
14 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin márùn-ún tí ó lọ yọ́ ilẹ̀ Laiṣi wò sọ fún àwọn arákùnrin wọn pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin mọ̀ pé ọ̀kan nínú àwọn ilé yìí ní ẹ̀wù efodu, àwọn yòókù ní òrìṣà, ère gbígbẹ́ àti ère dídà? Ẹ mọ ohun tí ó yẹ kí ẹ ṣe báyìí.”
Da talte de fem Mænd, som vare gangne til at bespejde Landet Lais, og sagde til deres Brødre: Vide I, at i disse Huse er en Livkjortel og Husguder og et udskaaret og støbt Billede? derfor skønner nu, hvad I skulle gøre.
15 Wọ́n sì yà sí ibẹ̀, wọ́n sì wọ ilé ọ̀dọ́mọkùnrin Lefi náà, sí ilé Mika, wọ́n sì béèrè àlàáfíà rẹ̀.
Og de toge derind og kom til den unge Karls, Levitens Hus, i Mikas Hus, og de hilsede ham.
16 Àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin ará Dani náà tí ó hámọ́ra ogun, dúró ní àbáwọlé ẹnu odi.
Men de seks Hundrede Mænd, som vare omgjordede med deres Krigsvaaben, og som vare af Dans Børn, stode for Indgangen til Porten.
17 Àwọn ọkùnrin márùn-ún tí wọ́n lọ yọ́ ilẹ̀ náà wò wọlé lọ wọ́n sì kó ère gbígbẹ́ náà, efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé àti ère dídà náà nígbà tí àlùfáà náà àti àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin tí ó hámọ́ra ogun dúró ní à bá wọ ẹnu odi náà.
Og de fem Mænd, som vare udgangne til at bespejde Landet, gik op, de kom derhen, de toge det udskaarne Billede og Livkjortlen og Husguderne og det støbte Billede; og Præsten stod for Indgangen til Porten og de seks Hundrede Mænd, som vare omgjordede med Krigsvaaben.
18 Nígbà tí àwọn ọkùnrin yìí wọ ilé e Mika lọ tí wọ́n sì kó ère fínfín náà, efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé mìíràn àti ère dídà náà, àlùfáà náà béèrè lọ́wọ́ wọn wí pé, “Kí ni ẹ̀yin ń ṣe?”
Og der disse vare komne i Mikas Hus og havde taget det udskaarne Billede, Livkjortlen og Husguderne og det støbte Billede, da sagde Præsten til dem: Hvad gøre I?
19 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Dákẹ́! Ma sọ nǹkan kan, tẹ̀lé wa kí o sì di baba àti àlùfáà wa. Kò ha sàn fún ọ láti máa ṣe ìránṣẹ́ ẹ̀yà àti ìdílé kan tí ó wá láti Israẹli bí àlùfáà ju ilé ẹnìkan ṣoṣo lọ?”
Og de svarede ham: Ti, læg din Haand paa din Mund og gak med os, og vær vor Fader og Præst; er det bedre, at du er Præst for een Mands Hus, eller at du er Præst for en Stamme og for en Slægt i Israel?
20 Nígbà náà ni inú àlùfáà náà sì dùn, òun mú efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé mìíràn àti ère fínfín náà, ó sì bá àwọn ènìyàn náà lọ.
Og Præstens Hjerte blev vel til Mode, og han tog Livkjortlen og Husguderne og det udskaarne Billede, og han kom midt iblandt Folket.
21 Wọ́n kó àwọn ọmọdé wọn, àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní wọn síwájú, wọ́n yípadà wọ́n sì lọ.
Og de vendte sig og gik bort; og de satte de smaa Børn og Kvæget, og hvad de havde at føre, foran.
22 Nígbà tí wọ́n ti rìn jìnnà díẹ̀ sí ilé Mika, àwọn ọkùnrin tí ó wà ní agbègbè Mika kó ara wọn jọ, wọ́n sì lé àwọn ará Dani bá.
Der de vare langt fra Mikas Hus, da bleve de Mænd, som vare i Husene ved Mikas Hus, sammenkaldte, og de indhentede Dans Børn.
23 Bí wọ́n ṣe ń pariwo tẹ̀lé wọn lẹ́yìn, àwọn ará Dani yípadà wọ́n sì bi Mika pé, “Kí ló ṣe ọ́ tí o fi pe àwọn ọkùnrin rẹ jáde láti jà?”
Og de raabte til Dans Børn, og de vendte sig om, og de sagde til Mika: Hvad fattes dig, at du og de andre ere sammenkaldte?
24 Ó dáhùn pé, “Ẹ̀yin kó àwọn ère tí mo ṣe, àti àlùfáà mi lọ. Kí ni ó kù tí mo ní? Báwo ni ẹ̀yin ò ṣe béèrè pé, ‘Kí ló ṣe ọ́?’”
Og han sagde: I have taget mine Guder, som jeg havde gjort, og Præsten, og I gaa bort; og hvad har jeg ydermere? hvi sige I da til mig: Hvad fattes dig?
25 Àwọn ọkùnrin Dani náà dáhùn pé, “Má ṣe bá wa jiyàn, tàbí àwọn oníbìínú fùfù ènìyàn lè kọlù yín, ìwọ àti àwọn ìdílé yóò sì sọ ẹ̀mí yín nù.”
Da sagde Dans Børn til ham: Lad din Røst ikke høres hos os, at de Mænd, som ere bitre i Sindet, ikke skulle anfalde eder, og du forspilde dit Liv og dit Folks Liv.
26 Àwọn ọkùnrin Dani náà sì bá ọ̀nà wọn lọ. Nígbà tí Mika rí í pé wọ́n lágbára púpọ̀ fún òun, ó sì padà sí ilé rẹ̀.
Saa gik Dans Børn deres Vej; og Mika saa, at de vare stærkere end han, og han vendte sig og kom tilbage til sit Hus.
27 Wọ́n sì kó àwọn ohun tí Mika ti ṣe àti àlùfáà rẹ̀, wọ́n sì kọjá lọ sí Laiṣi, ní ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tí ó ní ìbàlẹ̀ ọkàn tí wọ́n sì wà ní àlàáfíà. Wọ́n fi ojú idà kọlù wọ́n, wọ́n sì jó ìlú wọn run.
Men de toge det, som Mika havde gjort, og Præsten, som han havde haft, og kom over Lais, over et roligt og trygt Folk, og sloge dem med skarpe Sværd; og de opbrændte Staden med Ild.
28 Kò sì sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀ nítorí pé ibi tí wọ́n ń gbé jìnà sí àwọn ará Sidoni, wọn kò sì ní àṣepọ̀ pẹ̀lú ẹnikẹ́ni. Ìlú náà wà ní inú àfonífojì lẹ́bàá a Beti-Rehobu. Àwọn ará Dani sì tún ìlú náà kọ́, wọ́n sì ń gbé inú rẹ̀.
Og der var ingen, som friede den, thi den var langt fra Zidon, og de havde intet at gøre med noget Menneske; og den laa i Dalen, som er ved Beth-Rekob; saa byggede de Staden og boede derudi.
29 Wọ́n sọ orúkọ ìlú náà ní Dani gẹ́gẹ́ bí orúkọ baba ńlá wọn Dani, ẹni tí wọ́n bí fún Israẹli: bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Laiṣi ni orúkọ ìlú náà tẹ́lẹ̀ rí.
Og de kaldte Stadens Navn Dan, efter deres Fader Dans Navn, denne var en Søn af Israel; dog fra Begyndelsen var Stadens Navn Lais.
30 Àwọn ọmọ Dani sì gbé àwọn ère kalẹ̀ fún ara wọn níbẹ̀; Jonatani ọmọ Gerṣomu, ọmọ Mose, àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni àlùfáà fún àwọn ẹ̀yà Dani títí di àkókò tí a kó ilẹ̀ náà ní ìgbèkùn.
Og Dans Børn oprejste sig det udskaarne Billede; og Jonathan, en Søn af Gerson, Manasse Søn, var med sine Børn Præster for Daniternes Stamme, indtil den Dag, de flyttedes ud af Landet.
31 Wọ́n tẹ̀síwájú láti lo àwọn ère tí Mika ṣe, ní gbogbo àkókò tí ilé Ọlọ́run wà ní Ṣilo.
Saa satte de iblandt sig Mikas udskaarne Billede, som han havde gjort, alle de Dage, Guds Hus var i Silo.

< Judges 18 >