< Judges 17 >

1 Nígbà náà ni ọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Mika láti agbègbè òkè Efraimu
Il y avait dans la montagne d’Ephraïm un homme nommé Micah.
2 sọ fún ìyá rẹ̀ pé, “Ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà ṣékélì fàdákà èyí tí wọ́n jí mọ́ ọ lọ́wọ́, àti nípa èyí tí mo gbọ́ tí ìwọ ń ṣẹ́ èpè. Kíyèsi fàdákà náà wà ní ọ̀dọ̀ mi, èmi ni mo kó o.” Nígbà náà ni ìyá rẹ̀ dáhùn pé, “Kí Olúwa bùkún ọ ọmọ mi!”
Il dit un jour à sa mère: "Les onze cents pièces d’argent qu’on t’a dérobées, vol dont tu as maudit l’auteur, et cela en ma présence, sache que cet argent est en ma possession; c’est moi qui l’ai pris." La mère répondit: "Que mon fils soit béni du Seigneur!"
3 Nígbà tí ó da ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà ṣékélì fàdákà náà padà fún ìyá rẹ̀, ìyá rẹ̀ dáhùn pé, “Èmi ti fi òtítọ́ inú ya sílífà náà sọ́tọ̀ sí Olúwa fún ọmọ mi láti fi dá ère dídá àti ère gbígbẹ́. Èmi yóò dá a padà fún ọ.”
Il rendit les onze cents pièces d’argent à sa mère, qui lui dit: "J’Avais destiné cet argent à l’Eternel, voulant le remettre à mon fils pour qu’on en fît une image taillée avec métal; je te prie donc de le reprendre."
4 Nítorí náà òun dá sílífà náà padà fún ìyá rẹ̀, ìyá rẹ̀ sì mú igba ṣékélì fàdákà, ó sì fún alágbẹ̀dẹ fàdákà ẹni tí ó fi wọ́n rọ ère fínfín àti ère dídà. Wọ́n sì kó wọn sí ilé Mika.
Mais il restitua l’argent à sa mère. Celle-ci prit deux cents pièces d’argent et les donna à l’orfèvre, qui en fit une image garnie de métal, laquelle fut placée dans la maison de Micah.
5 Ọkùnrin náà, Mika sì ní ojúbọ kan. Òun sì ra ẹ̀wù efodu kan, ó sì ṣe àwọn ère kan, ó sì fi ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin ṣe àlùfáà rẹ̀.
Cet homme, Micah, possédant une maison de Dieu, fit aussi fabriquer un éphod et des pénates; puis il consacra l’un de ses fils et l’employa comme prêtre.
6 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ọmọ Israẹli kò ní ọba; olúkúlùkù ṣe bí ó ti rò pé ó tọ́ ní ojú ara rẹ́.
En ce temps-là, il n’y avait point de roi en Israël, et chacun agissait à sa guise.
7 Ọ̀dọ́mọkùnrin kan sì ti Bẹtilẹhẹmu ti Juda wá, tí í ṣe ìdílé Juda, ẹni tí í ṣe ẹ̀yà Lefi, òun sì ṣe àtìpó níbẹ̀,
Il y avait alors un jeune homme de Bethléem-en-Juda, de la famille de Juda; il était lévite et séjournait là.
8 ọkùnrin náà sì ti ìlú Bẹtilẹhẹmu ti Juda lọ, láti ṣe àtìpó ní ibikíbi tí ó bá rí. Ní ojú ọ̀nà àjò rẹ̀, ó dé ilẹ̀ Mika nínú àwọn ilẹ̀ òkè Efraimu.
Cet homme quitta sa ville, Bethléem-en-Juda, pour s’établir là où il trouverait à vivre; dans le cours de son voyage, il arriva à la montagne d’Ephraïm, près de la maison de Micah.
9 Mika bi í pé, “Níbo ni ó ti ń bọ̀?” Ó dáhùn pé, “Ọmọ Lefi ni mí láti Bẹtilẹhẹmu Juda, mo sì ń wá ibi tí èmi yóò máa gbé.”
Micah lui demanda: "D’Où viens-tu?" Il répondit: "Je suis lévite, de Bethléem-en-Juda, et je voyage pour m’établir où je pourrai."
10 Mika sì sọ fún un wí pé, “Dúró lọ́dọ̀ mi kí ìwọ sì jẹ́ baba mi àti àlùfáà fún mi, èmi ó sì máa fún ọ ní ṣékélì mẹ́wàá fàdákà ní ọdọọdún, pẹ̀lú aṣọ àti oúnjẹ rẹ̀.”
"Eh bien! lui dit Micah, demeure avec moi, sers-moi de père et de prêtre, et je te donnerai dix pièces d’argent par an, l’habillement complet et la nourriture." Et le lévite y alla.
11 Ọmọ Lefi náà sì gbà láti máa bá a gbé, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì dàbí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
Il consentit donc à demeurer chez cet homme, qui traita le jeune lévite comme un de ses enfants.
12 Nígbà náà ni Mika ya ará Lefi náà sí mímọ́, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì di àlùfáà rẹ̀, ó sì ń gbé ilé rẹ̀.
Micah installa le lévite, de sorte que ce jeune homme lui servît de prêtre; et il resta dans la maison de Micah.
13 Mika sì wí pé, “Báyìí, èmi mọ̀ pé Olúwa yóò ṣe mi ní oore nítorí pé mo ní ọmọ Lefi ní àlùfáà mi.”
Alors Micah dit: "Je suis assuré maintenant que l’Eternel me fera du bien, puisque j’ai pu avoir un lévite pour prêtre."

< Judges 17 >