< Judges 17 >

1 Nígbà náà ni ọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Mika láti agbègbè òkè Efraimu
Byl pak muž nějaký s hory Efraim, jehož jméno bylo Mícha.
2 sọ fún ìyá rẹ̀ pé, “Ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà ṣékélì fàdákà èyí tí wọ́n jí mọ́ ọ lọ́wọ́, àti nípa èyí tí mo gbọ́ tí ìwọ ń ṣẹ́ èpè. Kíyèsi fàdákà náà wà ní ọ̀dọ̀ mi, èmi ni mo kó o.” Nígbà náà ni ìyá rẹ̀ dáhùn pé, “Kí Olúwa bùkún ọ ọmọ mi!”
Kterýž řekl matce své: Ten tisíc a sto stříbrných, kteříž vzati byli tobě, pro něž jsi zlořečila a mluvilas přede mnou, hle, stříbro to u mne jest, já jsem je vzal. I řekla matka jeho: Požehnaný jsi, synu můj, od Hospodina.
3 Nígbà tí ó da ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà ṣékélì fàdákà náà padà fún ìyá rẹ̀, ìyá rẹ̀ dáhùn pé, “Èmi ti fi òtítọ́ inú ya sílífà náà sọ́tọ̀ sí Olúwa fún ọmọ mi láti fi dá ère dídá àti ère gbígbẹ́. Èmi yóò dá a padà fún ọ.”
Navrátil tedy ten tisíc a sto stříbrných matce své. I řekla matka jeho: Jižť jsem zajisté posvětila stříbro to Hospodinu z ruky své, a tobě synu svému, aby udělán byl obraz rytý a slitý. Protož nyní dám je tobě.
4 Nítorí náà òun dá sílífà náà padà fún ìyá rẹ̀, ìyá rẹ̀ sì mú igba ṣékélì fàdákà, ó sì fún alágbẹ̀dẹ fàdákà ẹni tí ó fi wọ́n rọ ère fínfín àti ère dídà. Wọ́n sì kó wọn sí ilé Mika.
On pak navrátil to stříbro matce své, z něhož vzala matka jeho dvě stě stříbrných, a dala zlatníku. I udělal z nich obraz rytý a slitý, kterýž byl v domě Míchově.
5 Ọkùnrin náà, Mika sì ní ojúbọ kan. Òun sì ra ẹ̀wù efodu kan, ó sì ṣe àwọn ère kan, ó sì fi ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin ṣe àlùfáà rẹ̀.
Měl pak ten Mícha chrám bohů, i udělal efod a terafim, a naplnil ruce jednoho z synů svých, aby mu byl knězem.
6 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ọmọ Israẹli kò ní ọba; olúkúlùkù ṣe bí ó ti rò pé ó tọ́ ní ojú ara rẹ́.
Toho času nebylo krále v Izraeli; jeden každý, což se mu za dobré vidělo, to činil.
7 Ọ̀dọ́mọkùnrin kan sì ti Bẹtilẹhẹmu ti Juda wá, tí í ṣe ìdílé Juda, ẹni tí í ṣe ẹ̀yà Lefi, òun sì ṣe àtìpó níbẹ̀,
Byl pak mládenec z Betléma Judova, totiž z čeledi Judovy, kterýž, jsa Levíta, byl tam pohostinu.
8 ọkùnrin náà sì ti ìlú Bẹtilẹhẹmu ti Juda lọ, láti ṣe àtìpó ní ibikíbi tí ó bá rí. Ní ojú ọ̀nà àjò rẹ̀, ó dé ilẹ̀ Mika nínú àwọn ilẹ̀ òkè Efraimu.
Odšel tedy člověk ten z města Betléma Judova, aby byl pohostinu, kdež by se mu koli nahodilo. I přišel na horu Efraim, až k domu Míchovu, jda cestou svou.
9 Mika bi í pé, “Níbo ni ó ti ń bọ̀?” Ó dáhùn pé, “Ọmọ Lefi ni mí láti Bẹtilẹhẹmu Juda, mo sì ń wá ibi tí èmi yóò máa gbé.”
Jemuž řekl Mícha: Odkud jdeš? Odpověděl mu: Já jsem Levíta, z Betléma Judova beru se, abych byl pohostinu, kdež by mi se koli nahodilo.
10 Mika sì sọ fún un wí pé, “Dúró lọ́dọ̀ mi kí ìwọ sì jẹ́ baba mi àti àlùfáà fún mi, èmi ó sì máa fún ọ ní ṣékélì mẹ́wàá fàdákà ní ọdọọdún, pẹ̀lú aṣọ àti oúnjẹ rẹ̀.”
I řekl jemu Mícha: Zůstaň u mne, a buď mi za otce a za kněze, a buduť dávati deset stříbrných na každý rok, a dvoje roucho i stravu tvou. I šel Levíta.
11 Ọmọ Lefi náà sì gbà láti máa bá a gbé, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì dàbí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
Líbilo se pak Levítovi zůstati u muže toho, a byl u něho mládenec ten, jako jeden z synů jeho.
12 Nígbà náà ni Mika ya ará Lefi náà sí mímọ́, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì di àlùfáà rẹ̀, ó sì ń gbé ilé rẹ̀.
I posvětil Mícha rukou Levíty, a byl mu mládenec ten za kněze; i bydlil v domě jeho.
13 Mika sì wí pé, “Báyìí, èmi mọ̀ pé Olúwa yóò ṣe mi ní oore nítorí pé mo ní ọmọ Lefi ní àlùfáà mi.”
Řekl pak Mícha: Nyníť vím, že mi dobře učiní Hospodin, proto že mám toho Levítu za kněze.

< Judges 17 >