< Judges 17 >

1 Nígbà náà ni ọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Mika láti agbègbè òkè Efraimu
Ephraim mae nuiah kaom kami maeto oh; anih ih ahmin loe Mikah.
2 sọ fún ìyá rẹ̀ pé, “Ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà ṣékélì fàdákà èyí tí wọ́n jí mọ́ ọ lọ́wọ́, àti nípa èyí tí mo gbọ́ tí ìwọ ń ṣẹ́ èpè. Kíyèsi fàdákà náà wà ní ọ̀dọ̀ mi, èmi ni mo kó o.” Nígbà náà ni ìyá rẹ̀ dáhùn pé, “Kí Olúwa bùkún ọ ọmọ mi!”
Anih mah nangmah ih amno khaeah, Na tangoeng thuih ih phoisa, nang khae hoi ka lak ih phoisa shekel sang hatlaito loe, kai khaeah oh, kai mah ni ka lak, tiah a naa. To naah amno mah, Ka capa, Angraeng mah tahamhoihaih na paek nasoe, tiah a naa.
3 Nígbà tí ó da ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà ṣékélì fàdákà náà padà fún ìyá rẹ̀, ìyá rẹ̀ dáhùn pé, “Èmi ti fi òtítọ́ inú ya sílífà náà sọ́tọ̀ sí Olúwa fún ọmọ mi láti fi dá ère dídá àti ère gbígbẹ́. Èmi yóò dá a padà fún ọ.”
Mikah mah amno hanah phoisa shekel sang hatlaito paek let naah, amno mah anih khaeah, Ka capa paek hanah, hae phoisa hae Angraeng khaeah ka tathlang boeh; to phoisa hoiah daengh ih krang hoi atui pakaw ih krang to sak hanah kang paek let han, tiah a naa.
4 Nítorí náà òun dá sílífà náà padà fún ìyá rẹ̀, ìyá rẹ̀ sì mú igba ṣékélì fàdákà, ó sì fún alágbẹ̀dẹ fàdákà ẹni tí ó fi wọ́n rọ ère fínfín àti ère dídà. Wọ́n sì kó wọn sí ilé Mika.
Toe Mikah mah to phoisa to amno hanah paek let; amno mah phoisa shekel cumvai hnetto lak moe, sum daengh kop kami khaeah paek; anih mah phoisa hoiah daengh ih krang hoi atui pakaw ih krang to a sak pae; to krangnawk loe Mikah im ah oh.
5 Ọkùnrin náà, Mika sì ní ojúbọ kan. Òun sì ra ẹ̀wù efodu kan, ó sì ṣe àwọn ère kan, ó sì fi ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin ṣe àlùfáà rẹ̀.
Mikah loe sithawnawk bokhaih im to tawnh; anih mah kahni maeto hoi teraphim krang to sak moe, a capa maeto angmah ih qaima ah a suek.
6 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ọmọ Israẹli kò ní ọba; olúkúlùkù ṣe bí ó ti rò pé ó tọ́ ní ojú ara rẹ́.
To nathuem ah Israel kaminawk loe siangpahrang tawn o ai; toe kami boih mah angmacae mikhnuk ah hoih, tiah poek o ih baktih toengah hmuen to a sak o.
7 Ọ̀dọ́mọkùnrin kan sì ti Bẹtilẹhẹmu ti Juda wá, tí í ṣe ìdílé Juda, ẹni tí í ṣe ẹ̀yà Lefi, òun sì ṣe àtìpó níbẹ̀,
Judah prae Bethlehem vangpui ah kaom, Judah acaeng hoi nawnto kaom Levi thendoeng maeto loe to ah caeh.
8 ọkùnrin náà sì ti ìlú Bẹtilẹhẹmu ti Juda lọ, láti ṣe àtìpó ní ibikíbi tí ó bá rí. Ní ojú ọ̀nà àjò rẹ̀, ó dé ilẹ̀ Mika nínú àwọn ilẹ̀ òkè Efraimu.
To thendoeng loe a ohhaih ahmuen pakrong hanah, Judah prae Bethlehem vangpui to tacawt taak: anih kholong caeh naah Ephraim mae ah kaom Mikah im to phak.
9 Mika bi í pé, “Níbo ni ó ti ń bọ̀?” Ó dáhùn pé, “Ọmọ Lefi ni mí láti Bẹtilẹhẹmu Juda, mo sì ń wá ibi tí èmi yóò máa gbé.”
Mikah mah anih khaeah, Nang loe naa ih kami maw? tiah a naa. Anih mah Mikah khaeah, Kai loe Judah prae Bethlehem vangpui ih Levi kami maeto ah ka oh, ohhaih hmuen to ka pakrong, tiah a naa.
10 Mika sì sọ fún un wí pé, “Dúró lọ́dọ̀ mi kí ìwọ sì jẹ́ baba mi àti àlùfáà fún mi, èmi ó sì máa fún ọ ní ṣékélì mẹ́wàá fàdákà ní ọdọọdún, pẹ̀lú aṣọ àti oúnjẹ rẹ̀.”
To naah Mikah mah anih khaeah, Kai khaeah omh loe, kam pa hoi kai ih qaima ah om ah; saningto naah phoisa shekel hato, khukbuen hoi caaknaeknawk kang paek han, tiah a naa. To pongah Levi loe athung ah akunh.
11 Ọmọ Lefi náà sì gbà láti máa bá a gbé, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì dàbí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
Levi loe anih hoi nawnto oh hanah palungdue; anih mah to thendoeng to a capa maeto baktiah poek.
12 Nígbà náà ni Mika ya ará Lefi náà sí mímọ́, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì di àlùfáà rẹ̀, ó sì ń gbé ilé rẹ̀.
Mikah mah Levi to tathlang moe, thendoeng to angmah im ah qaima ah ohsak.
13 Mika sì wí pé, “Báyìí, èmi mọ̀ pé Olúwa yóò ṣe mi ní oore nítorí pé mo ní ọmọ Lefi ní àlùfáà mi.”
Mikah mah Levi loe vaihi kai ih qaima ah oh boeh pongah, Angraeng mah ka nuiah kahoih hmuen na sah pae tih boeh, tiah ka panoek, tiah thuih.

< Judges 17 >