< Judges 16 >

1 Ní ọjọ́ kan Samsoni lọ sí Gasa níbi tí ó ti rí obìnrin panṣágà kan. Ó wọlé tọ̀ ọ́ láti sun ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní òru ọjọ́ náà.
Potem je Samson odšel v Gazo in tam videl pocestnico in šel noter k njej.
2 Àwọn ará Gasa sì gbọ́ wí pé, “Samsoni wà níbí.” Wọ́n sì yí agbègbè náà ká, wọ́n ń ṣọ́ ọ ní gbogbo òru náà ní ẹnu-bodè ìlú náà. Wọn kò mira ní gbogbo òru náà pé ní “àfẹ̀mọ́júmọ́ àwa yóò pa á.”
To je bilo povedano prebivalcem Gaze, rekoč: »Samson je prišel sèm.« Obkolili so ga in vso noč prežali nanj v velikih vratih mesta in vso noč so mirovali, rekoč: »Zjutraj, ko je dan, ga bomo umorili.«
3 Ṣùgbọ́n Samsoni sùn níbẹ̀ di àárín ọ̀gànjọ́. Òun sì dìde ní ọ̀gànjọ́, ó fi ọwọ́ di àwọn ìlẹ̀kùn odi ìlú náà mú, pẹ̀lú òpó méjèèjì, ó sì fà wọ́n tu, pẹ̀lú ìdábùú àti ohun gbogbo tí ó wà lára rẹ̀. Ó gbé wọn lé èjìká rẹ̀ òun sì gbé wọn lọ sí orí òkè tí ó kọjú sí Hebroni.
Samson je ležal do polnoči, ob polnoči pa je vstal, vzel vrata velikih vrat mesta in dva podboja in z njimi odšel proč, zapah in vse in si jih naložil na svoje rame in jih odnesel gor na vrh hriba, ki je pred Hebrónom.
4 Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, ó sì ní ìfẹ́ obìnrin kan ní àfonífojì Soreki, orúkọ ẹni tí í ṣe Dẹlila.
Potem se je pripetilo, da je ljubil žensko v dolini Sorék, ki ji je bilo ime Dalíla.
5 Àwọn ìjòyè Filistini sì lọ bá obìnrin náà, wọ́n sọ fún un wí pé, “Bí ìwọ bá le tàn án kí òun sì fi àṣírí agbára rẹ̀ hàn ọ́, àti bí àwa ó ti lè borí rẹ̀, kí àwa sì dè é kí àwa sì ṣẹ́gun rẹ̀. Ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú wa yóò sì fún ọ ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà fàdákà.”
Filistejski knezi so prišli gor k njej in ji rekli: »Premami ga in poglej kje tiči njegova velika moč in s kakšnimi sredstvi bi lahko prevladali zoper njega, da bi ga lahko zvezali, da ga oslabimo, mi pa ti bomo dali, vsak izmed nas, tisoč sto koščkov srebra.«
6 Torí náà Dẹlila sọ fún Samsoni pé, “Sọ àṣírí agbára ńlá rẹ fún mi àti bí wọ́n ti le dè ọ́, àti bí wọ́n ṣe lè borí rẹ.”
Dalíla je rekla Samsonu: »Povej mi, prosim te, kje leži tvoja velika moč in s čim bi bil lahko zvezan, da se te oslabi.«
7 Samsoni dá a lóhùn wí pé, “Bí ẹnikẹ́ni bá fi okùn tútù méje tí ẹnìkan kò sá gbẹ dè mí, èmi yóò di aláìlágbára bí i gbogbo àwọn ọkùnrin yòókù.”
Samson ji je rekel: »Če me zvežejo s sedmimi zelenimi vrvmi, ki niso bile nikoli posušene, potem bom slaboten in bom kakor drug človek.«
8 Àwọn olóyè Filistini sì mú okùn tútù méje tí ẹnikẹ́ni kò sá gbẹ wá fún Dẹlila òun sì fi wọ́n dè é.
Potem so filistejski knezi gor k njej prinesli sedem zelenih vrvi, ki niso bile posušene in ona ga je z njimi zvezala.
9 Nígbà tí àwọn ènìyàn tí sá pamọ́ sínú yàrá, òun pè pé, “Samsoni àwọn Filistini ti dé láti mú ọ.” Ṣùgbọ́n òun já àwọn okùn náà bí òwú ti í já nígbà tí ó bá wà lẹ́bàá iná. Torí náà wọn kò mọ àṣírí agbára rẹ̀.
Torej tam so v zasedi prežali možje, ki so z njo ostajali v sobi. Rekla mu je: »Filistejci nadte Samson.« Potrgal je vrvi, kakor se pretrga nit prediva, ko se dotakne ognja. Tako njegova moč ni bila poznana.
10 Dẹlila sì sọ fún Samsoni pé, ìwọ ti tàn mí; o sì purọ́ fún mi. Wá báyìí kí o sì sọ bí a ti ṣe le dè ọ́.
Dalíla je rekla Samsonu: »Glej, zasmehoval si me in mi govoril laži. Sedaj mi povej, prosim te, s čim bi bil lahko zvezan.«
11 Òun dáhùn pé, “Bí wọ́n bá lè fi okùn tuntun tí ẹnikẹ́ni kò tí ì lò rí dì mí dáradára, èmi yóò di aláìlágbára, èmi yóò sì dàbí àwọn ọkùnrin yòókù.”
Rekel ji je: »Če bi me trdno zvezali z novimi vrvmi, ki niso bile nikoli uporabljene, potem bi bil šibek in bi bil kakor drug človek.«
12 Dẹlila sì mú àwọn okùn tuntun, ó fi wọ́n dì í. Nígbà tí àwọn ọkùnrin Filistini ti fi ara pamọ́ sínú yàrá, òun kígbe sí i pé, “Samsoni àwọn Filistini dé láti mú ọ,” òun sì já okùn náà kúrò ní ọwọ́ rẹ̀ bí òwú.
Zato je Dalíla vzela nove vrvi, ga z njimi zvezala in mu rekla: »Filistejci nadte Samson.« In tam so bili prežavci v zasedi, ki so ostajali v sobi. In potrgal jih je iz svojih rok kakor nit.
13 Dẹlila sì tún sọ fún Samsoni pé, “Títí di ìsinsin yìí ìwọ sì ń tún tàn mí, o sì tún purọ́ fún mi. Sọ fún mi ọ̀nà tí wọ́n fi le dè ọ́.” Samsoni dá a lóhùn pé, “Bí ìwọ bá hun ìdí irun méjèèje tí ó wà ní orí mi pẹ̀lú okùn, tí ó sì le dáradára kí o sì fi ẹ̀mú mú un mọ́lẹ̀, èmi yóò di aláìlágbára bí àwọn ọkùnrin yòókù.” Nígbà tí òun ti sùn, Dẹlila hun àwọn ìdí irun méjèèje tí ó wà ní orí rẹ̀,
Dalíla je rekla Samsonu: »Doklej si me zasmehoval in mi govoril laži. Povej mi s čim naj bi bil zvezan.« Rekel ji je: »Če stkeš sedem pramenov moje glave s tkalčjim osnutkom.«
14 ó sì fi ìhunṣọ dè wọ́n. Ó sì tún pè é pé, “Samsoni àwọn Filistini dé láti mú ọ.” Òun sì jí ní ojú oorun, ó sì fa ìdè ìhunṣọ náà tu pẹ̀lú ohun gbogbo tí wọ́n fi kàn án mọ́lẹ̀.
In pritrdila ga je z iglo in mu rekla: »Filistejci nadte Samson.« Prebudil se je iz svojega spanja in odšel s tkalsko iglo in s tkalčjim osnutkom.
15 Dẹlila sì sọ fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi wí pé, ‘Èmi fẹ́ràn rẹ,’ nígbà tí ìwọ kò fi ọkàn tán mi. Èyí ni ìgbà kẹta tí ìwọ ti tàn mí jẹ, tí ìwọ kò sì sọ àṣírí ibi tí agbára ńlá rẹ gbé wà fún mi.”
Rekla mu je: »Kako lahko rečeš: ›Ljubim te, ‹ ko tvoje srce ni z menoj?« Že trikrat si me zasmehoval in mi nisi povedal, v čem leži tvoja velika moč.
16 Ó sì ṣe nígbà tí ó fi ọ̀rọ̀ rẹ̀ rọ̀ ọ́ ní ojoojúmọ́ pẹ̀lú ọ̀rọ̀ rẹ̀ títí dé bi pé ó sú dé òpin ẹ̀mí rẹ̀.
Ko ga je dnevno pritiskala s svojimi besedami in ga silila, tako da je bila njegova duša vznemirjena do smrti, se je pripetilo,
17 Òun sì sọ ohun gbogbo tí ó wà ní ọkàn rẹ̀ fún un. Ó ní, “Abẹ kò tí ì kan orí mi rí, nítorí pé Nasiri, ẹni ìyàsọ́tọ̀ fún Ọlọ́run ni mo jẹ́ láti ìgbà ìbí mi wá. Bí a bá fá irun orí mi, agbára mi yóò fi mí sílẹ̀, èmi yóò sì di aláìlágbára bí àwọn ọkùnrin yòókù.”
da ji je izpovedal vse svoje srce in ji rekel: »Britev ni prišla na mojo glavo, kajti bil sem nazirec Bogu od maternice svoje matere. Če bom obrit, potem bo moja moč odšla od mene in postanem slaboten in bom podoben kateremukoli drugemu človeku.«
18 Nígbà tí Dẹlila rí i pé ó ti sọ ohun gbogbo fún òun tan, Dẹlila ránṣẹ́ sí àwọn ìjòyè Filistini pé, “Ẹ wá lẹ́ẹ̀kan sí i, ó ti sọ ohun gbogbo fún mi.” Torí náà àwọn olóyè Filistini padà, wọ́n sì mú owó ìpinnu náà lọ́wọ́.
Ko je Dalíla videla, da ji je izpovedal vse svoje srce, je poslala in dala poklicati filistejske kneze, rekoč: »Pridite tokrat gor, kajti razodel mi je vse svoje srce.« Potem so gor k njej prišli gospodarji Filistejcev in v svoji roki prinesli denar.
19 Òun sì mú kí Samsoni sùn lórí itan rẹ̀, òun sì pe ọkùnrin kan láti fá àwọn ìdì irun orí rẹ̀ méjèèje, òun sì bẹ̀rẹ̀ sí ṣẹ́gun rẹ̀. Agbára rẹ̀ sì fi í sílẹ̀ lọ.
Pripravila ga je, da je zaspal na njenih kolenih in dala poklicati moža, da mu iz njegove glave odstriže sedem pramenov in ga začela poniževati in njegova moč je odšla od njega.
20 Òun pè é wí pé, “Samsoni àwọn Filistini dé láti mú ọ.” Òun jí ní ojú oorun rẹ̀, ó sì sọ pé, “Èmi yóò jáde lọ bí í ti àtẹ̀yìnwá, kí èmi sì gba ara mi, kí n di òmìnira.” Ṣùgbọ́n òun kò mọ̀ pé Olúwa ti fi òun sílẹ̀.
Rekla je: »Filistejci nadte Samson.« Prebudil se je iz svojega spanja in rekel: »Šel bom ven kakor ob drugih časih poprej in se stresel.« Ni pa vedel, da je Gospod odšel od njega.
21 Nígbà náà ni àwọn Filistini mú un, wọ́n yọ ojú rẹ̀ méjèèjì wọ́n sì mú un lọ sí Gasa. Wọ́n fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ idẹ dè é, wọ́n sì fi sí ibi iṣẹ́ ọlọ lílọ̀ nínú ilé túbú.
Toda Filistejci so ga prijeli in iztaknili njegove oči in ga privedli dol v Gazo in ga zvezali z bronastimi okovi in mlel je v jetnišnici.
22 Ṣùgbọ́n irun orí rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí í tún hù lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti fá a.
Vendar so potem, ko je bil ostrižen, lasje njegove glave začeli ponovno rasti.
23 Àwọn ìjòyè, àwọn ará Filistini sì péjọpọ̀ láti ṣe ìrúbọ ńlá sí Dagoni ọlọ́run wọn àti láti ṣe ayẹyẹ wọ́n wí pé, ọlọ́run wa ti fi Samsoni ọ̀tá wa lé wa lọ́wọ́.
Potem so se filistejski knezi zbrali skupaj, da svojemu bogu Dagónu darujejo veliko klavno daritev in da se veselijo, kajti rekli so: »Naš bog je v našo roko izročil našega sovražnika Samsona.«
24 Nígbà tí àwọn ènìyàn rí Samsoni wọ́n yin ọlọ́run wọn wí pé, “Ọlọ́run wa ti fi ọ̀tá wa lé wa lọ́wọ́. Àní ẹni tí ó ti run ilẹ̀ wa ẹni tí ó ti pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú wa.”
Ko ga je ljudstvo zagledalo, so hvalili svojega boga, kajti rekli so: »Naš bog je v naše roke izročil našega sovražnika in uničevalca naše dežele, ki je umoril številne izmed nas.«
25 Nígbà tí inú wọn dùn gidigidi tí wọ́n ń yọ ayọ̀ ńlá, wọ́n pariwo pé, ẹ mú Samsoni wá kí ó wá dá wa lára yá. Wọ́n sì pe Samsoni jáde láti ọgbà ẹ̀wọ̀n náà, òun sì ń ṣeré fún wọn. Nígbà tí wọ́n mú un dúró láàrín àwọn òpó.
Pripetilo pa se je, ko so bila njihova srca vesela, da so rekli: »Pokličite Samsona, da nam bo lahko naredil zabavo.« Iz jetnišnice so dali poklicati Samsona in naredil jim je zabavo. Postavili so ga med stebre.
26 Samsoni sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí ó di ọwọ́ rẹ̀ mú pé, “Ẹ fi mí si ibi tí ọwọ́ mi yóò ti le tó àwọn òpó tí ó gbé tẹmpili dúró mú, kí èmi lè fẹ̀yìn tì wọ́n.”
Samson pa je rekel dečku, ki ga je držal za roko: »Dopusti mi, da lahko čutim stebre, na katerih stoji hiša, da se lahko naslonim nanje.«
27 Ní àsìkò náà, tẹmpili yìí kún fún àwọn ọkùnrin àti obìnrin; gbogbo àwọn ìjòyè Filistini wà níbẹ̀, ní òkè ilé náà, níbi tí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àwọn ọkùnrin àti obìnrin tí ń wòran Samsoni bí òun ti ń ṣeré.
Torej hiša je bila polna mož in žena in vsi filistejski knezi so bili tam in tam je bilo na strehi okoli tri tisoč mož in žena, ki so gledali, medtem ko jih je Samson zabaval.
28 Nígbà náà ni Samsoni ké pe Olúwa wí pé, “Olúwa Olódùmarè, rántí mi. Háà Ọlọ́run jọ̀wọ́ fi agbára fún mi lẹ́ẹ̀kan yìí sí i, kí èmi lè gbẹ̀san lára àwọn Filistini nítorí àwọn ojú mi méjèèjì.”
Samson pa je zaklical h Gospodu in rekel: »Oh Gospod Bog, spomni se me, prosim te in okrepi me, prosim te, samo [še] tokrat, oh Bog, da se bom lahko takoj maščeval Filistejcem za svoji dve očesi.«
29 Samsoni sì na ọwọ́ mú àwọn òpó méjèèjì tí ó wà láàrín gbùngbùn, orí àwọn tí tẹmpili náà dúró lé, ó fi ọwọ́ ọ̀tún mú ọ̀kan àti ọwọ́ òsì mú èkejì, ó fi ara tì wọ́n,
Samson se je oklenil dveh srednjih nosilnih stebrov, na katerih, je slonela hiša, na enega s svojo desnico in na drugega s svojo levico.
30 Samsoni sì wí pé, “Jẹ́ kí èmi kú pẹ̀lú àwọn Filistini!” Òun sì fi agbára ńlá tì wọ́n, bẹ́ẹ̀ ni ilé náà wó lu àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn tí ó wà nínú rẹ̀. Báyìí ni ó pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ nígbà ikú rẹ̀ ju ìgbà ayé rẹ̀ lọ.
Samson je rekel: »Naj umrem s Filistejci.« Z vso svojo močjo se je sklonil in hiša je padla na kneze in na vse ljudstvo, ki je bilo v njej. Tako je bilo mrtvih, ki jih je usmrtil ob svoji smrti, več kakor tistih, ki jih je usmrtil v svojem življenju.
31 Nígbà náà ni àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀ ní àpapọ̀ gòkè lọ wọ́n sì gbé e, wọ́n gbé e padà wá, wọ́n sì sin ín sí agbede-méjì Sora àti Eṣtaoli, sínú ibojì Manoa baba rẹ̀. Òun ti ṣe àkóso Israẹli ní ogún ọdún.
Potem so njegovi bratje in vsa hiša njegovega očeta prišli dol, ga vzeli in ga prinesli gor ter ga pokopali med Coro in Eštaólom, na grobišču njegovega očeta Manóaha. Izraelu je sodil dvajset let.

< Judges 16 >