< Judges 16 >

1 Ní ọjọ́ kan Samsoni lọ sí Gasa níbi tí ó ti rí obìnrin panṣágà kan. Ó wọlé tọ̀ ọ́ láti sun ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní òru ọjọ́ náà.
И иде Сампсон в Газу, и виде тамо жену блудницу и вниде к ней.
2 Àwọn ará Gasa sì gbọ́ wí pé, “Samsoni wà níbí.” Wọ́n sì yí agbègbè náà ká, wọ́n ń ṣọ́ ọ ní gbogbo òru náà ní ẹnu-bodè ìlú náà. Wọn kò mira ní gbogbo òru náà pé ní “àfẹ̀mọ́júmọ́ àwa yóò pa á.”
И поведаша Газяном, глаголюще: прииде Сампсон семо. И обыдоша и подседоша ему всю нощь у врат градных, и утаишася всю нощь, глаголюще: дондеже осветает утро, и убием его.
3 Ṣùgbọ́n Samsoni sùn níbẹ̀ di àárín ọ̀gànjọ́. Òun sì dìde ní ọ̀gànjọ́, ó fi ọwọ́ di àwọn ìlẹ̀kùn odi ìlú náà mú, pẹ̀lú òpó méjèèjì, ó sì fà wọ́n tu, pẹ̀lú ìdábùú àti ohun gbogbo tí ó wà lára rẹ̀. Ó gbé wọn lé èjìká rẹ̀ òun sì gbé wọn lọ sí orí òkè tí ó kọjú sí Hebroni.
И спа Сампсон до полунощи: и воста в полунощи, и восхити двери у врат града со обеими вереями, и подя оныя с заворою, и возложи я на рамена своя, и вознесе я на верх горы, яже пред лицем Хеврона, и положи их тамо.
4 Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, ó sì ní ìfẹ́ obìnrin kan ní àfonífojì Soreki, orúkọ ẹni tí í ṣe Dẹlila.
И бысть по сем, и возлюби жену от водотечи Сориховы: имя же ей Далида.
5 Àwọn ìjòyè Filistini sì lọ bá obìnrin náà, wọ́n sọ fún un wí pé, “Bí ìwọ bá le tàn án kí òun sì fi àṣírí agbára rẹ̀ hàn ọ́, àti bí àwa ó ti lè borí rẹ̀, kí àwa sì dè é kí àwa sì ṣẹ́gun rẹ̀. Ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú wa yóò sì fún ọ ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà fàdákà.”
И взыдоша к ней князи иноплеменничи и рекоша ей: прельсти его, и виждь, в чем есть крепость его великая, и чим преможем его, и свяжем его, яко смирити его: и мы тебе дадим кийждо тысящу и сто сребреников.
6 Torí náà Dẹlila sọ fún Samsoni pé, “Sọ àṣírí agbára ńlá rẹ fún mi àti bí wọ́n ti le dè ọ́, àti bí wọ́n ṣe lè borí rẹ.”
И рече Далида к Сампсону: повеждь ми ныне, в чем крепость твоя (тако) великая, и чим свяжешися и смиришися?
7 Samsoni dá a lóhùn wí pé, “Bí ẹnikẹ́ni bá fi okùn tútù méje tí ẹnìkan kò sá gbẹ dè mí, èmi yóò di aláìlágbára bí i gbogbo àwọn ọkùnrin yòókù.”
И рече ей Сампсон: аще свяжут мя седмию тятивами сырыми неистлевшими, и изнемогу, и буду яко един от человек.
8 Àwọn olóyè Filistini sì mú okùn tútù méje tí ẹnikẹ́ni kò sá gbẹ wá fún Dẹlila òun sì fi wọ́n dè é.
И принесоша ей князи от иноплеменник седмь тятив мокрых неистлевших, и связа его ими:
9 Nígbà tí àwọn ènìyàn tí sá pamọ́ sínú yàrá, òun pè pé, “Samsoni àwọn Filistini ti dé láti mú ọ.” Ṣùgbọ́n òun já àwọn okùn náà bí òwú ti í já nígbà tí ó bá wà lẹ́bàá iná. Torí náà wọn kò mọ àṣírí agbára rẹ̀.
и подсада ему седяше в храмине. И рече ему: иноплеменницы на тя, Сампсоне. И расторже тятивы, аки бы кто расторгнул соскание изгребий, егда коснется ему огнь: и не уведася крепость его.
10 Dẹlila sì sọ fún Samsoni pé, ìwọ ti tàn mí; o sì purọ́ fún mi. Wá báyìí kí o sì sọ bí a ti ṣe le dè ọ́.
И рече Далида к Сампсону: се, прельстил еси мя, глаголя ко мне лжу: ныне убо повеждь ми, чим свяжешися?
11 Òun dáhùn pé, “Bí wọ́n bá lè fi okùn tuntun tí ẹnikẹ́ni kò tí ì lò rí dì mí dáradára, èmi yóò di aláìlágbára, èmi yóò sì dàbí àwọn ọkùnrin yòókù.”
И рече к ней: аще вяжуще свяжут мя ужы новыми, имиже не делано, и изнемогу, и буду яко един от человек.
12 Dẹlila sì mú àwọn okùn tuntun, ó fi wọ́n dì í. Nígbà tí àwọn ọkùnrin Filistini ti fi ara pamọ́ sínú yàrá, òun kígbe sí i pé, “Samsoni àwọn Filistini dé láti mú ọ,” òun sì já okùn náà kúrò ní ọwọ́ rẹ̀ bí òwú.
И взя Далида ужы новы и связа его ими, и рече ему: иноплеменницы на тя, Сампсоне. Подсада же седяше в храмине. И расторже я от руку своею аки нить.
13 Dẹlila sì tún sọ fún Samsoni pé, “Títí di ìsinsin yìí ìwọ sì ń tún tàn mí, o sì tún purọ́ fún mi. Sọ fún mi ọ̀nà tí wọ́n fi le dè ọ́.” Samsoni dá a lóhùn pé, “Bí ìwọ bá hun ìdí irun méjèèje tí ó wà ní orí mi pẹ̀lú okùn, tí ó sì le dáradára kí o sì fi ẹ̀mú mú un mọ́lẹ̀, èmi yóò di aláìlágbára bí àwọn ọkùnrin yòókù.” Nígbà tí òun ti sùn, Dẹlila hun àwọn ìdí irun méjèèje tí ó wà ní orí rẹ̀,
И рече Далида к Сампсону: даже до ныне прельщал мя еси и глаголал ко мне лжу: повеждь ми убо, чим свяжешися? И рече ей: аще сплетеши седмь плениц влас главы моея спрядением и вбиеши колом в стену, и буду немощен яко един от человек.
14 ó sì fi ìhunṣọ dè wọ́n. Ó sì tún pè é pé, “Samsoni àwọn Filistini dé láti mú ọ.” Òun sì jí ní ojú oorun, ó sì fa ìdè ìhunṣọ náà tu pẹ̀lú ohun gbogbo tí wọ́n fi kàn án mọ́lẹ̀.
И успи Далида его на коленех своих, и бысть внегда уснути ему, взя Далида седмь плениц влас главы его и сплете спрядением и вонзе колом в стену, и рече: иноплеменницы на тя, Сампсоне. И возбну от сна своего и исторже кол сплетением из стены, и не уведася крепость его.
15 Dẹlila sì sọ fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi wí pé, ‘Èmi fẹ́ràn rẹ,’ nígbà tí ìwọ kò fi ọkàn tán mi. Èyí ni ìgbà kẹta tí ìwọ ti tàn mí jẹ, tí ìwọ kò sì sọ àṣírí ibi tí agbára ńlá rẹ gbé wà fún mi.”
И рече к нему Далида: како глаголеши, возлюбих тя, и сердце твое несть со мною? Се, третие прельстил еси мя, и не поведал еси мне, в чем крепость твоя великая.
16 Ó sì ṣe nígbà tí ó fi ọ̀rọ̀ rẹ̀ rọ̀ ọ́ ní ojoojúmọ́ pẹ̀lú ọ̀rọ̀ rẹ̀ títí dé bi pé ó sú dé òpin ẹ̀mí rẹ̀.
И бысть егда стужи ему словесы своими по вся дни, и убеди его, и изнеможе даже до умертвия.
17 Òun sì sọ ohun gbogbo tí ó wà ní ọkàn rẹ̀ fún un. Ó ní, “Abẹ kò tí ì kan orí mi rí, nítorí pé Nasiri, ẹni ìyàsọ́tọ̀ fún Ọlọ́run ni mo jẹ́ láti ìgbà ìbí mi wá. Bí a bá fá irun orí mi, agbára mi yóò fi mí sílẹ̀, èmi yóò sì di aláìlágbára bí àwọn ọkùnrin yòókù.”
И поведа ей все сердце свое, и рече к ней: железо не взыде на главу мою, яко назорей есмь аз Господу от утробы матере моея: аще убо обриюся, отступит от мене крепость моя, и изнемогу, и буду якоже вси человецы.
18 Nígbà tí Dẹlila rí i pé ó ti sọ ohun gbogbo fún òun tan, Dẹlila ránṣẹ́ sí àwọn ìjòyè Filistini pé, “Ẹ wá lẹ́ẹ̀kan sí i, ó ti sọ ohun gbogbo fún mi.” Torí náà àwọn olóyè Filistini padà, wọ́n sì mú owó ìpinnu náà lọ́wọ́.
И виде Далида, яко поведа ей все сердце свое, посла и призва князи иноплеменничи, глаголющи: взыдите еще единою, яко поведа ми все сердце свое. И взыдоша к ней вси князи иноплеменничи, и принесоша сребро в руках своих.
19 Òun sì mú kí Samsoni sùn lórí itan rẹ̀, òun sì pe ọkùnrin kan láti fá àwọn ìdì irun orí rẹ̀ méjèèje, òun sì bẹ̀rẹ̀ sí ṣẹ́gun rẹ̀. Agbára rẹ̀ sì fi í sílẹ̀ lọ.
И успи Далида Сампсона на коленех своих: и призва стригача, и остриже седмь плениц влас главы его: и нача смирятися, и отступи крепость его от него.
20 Òun pè é wí pé, “Samsoni àwọn Filistini dé láti mú ọ.” Òun jí ní ojú oorun rẹ̀, ó sì sọ pé, “Èmi yóò jáde lọ bí í ti àtẹ̀yìnwá, kí èmi sì gba ara mi, kí n di òmìnira.” Ṣùgbọ́n òun kò mọ̀ pé Olúwa ti fi òun sílẹ̀.
И рече Далида: иноплеменницы на тя, Сампсоне. И возбудися от сна своего и рече: изыду якоже и прежде, и отрясуся. И не разуме, яко Господь отступи от него.
21 Nígbà náà ni àwọn Filistini mú un, wọ́n yọ ojú rẹ̀ méjèèjì wọ́n sì mú un lọ sí Gasa. Wọ́n fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ idẹ dè é, wọ́n sì fi sí ibi iṣẹ́ ọlọ lílọ̀ nínú ilé túbú.
И яша его иноплеменницы, и избодоша ему очи, и введоша его в Газу, и оковаша его путы медяны: и бяше меля в храмине темничней.
22 Ṣùgbọ́n irun orí rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí í tún hù lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti fá a.
И начаша власы главы его расти по острижении.
23 Àwọn ìjòyè, àwọn ará Filistini sì péjọpọ̀ láti ṣe ìrúbọ ńlá sí Dagoni ọlọ́run wọn àti láti ṣe ayẹyẹ wọ́n wí pé, ọlọ́run wa ti fi Samsoni ọ̀tá wa lé wa lọ́wọ́.
И князи иноплеменничи собрашася пожрети жертву велику Дагону богу своему и возвеселитися, и рекоша: предаде бог наш в руки нашя Сампсона врага нашего.
24 Nígbà tí àwọn ènìyàn rí Samsoni wọ́n yin ọlọ́run wọn wí pé, “Ọlọ́run wa ti fi ọ̀tá wa lé wa lọ́wọ́. Àní ẹni tí ó ti run ilẹ̀ wa ẹni tí ó ti pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú wa.”
И видеша его людие, и похвалиша бога своего, яко реша: предаде бог наш в руки нашя врага нашего, опустошившаго землю нашу, и иже умножи язвенных наших.
25 Nígbà tí inú wọn dùn gidigidi tí wọ́n ń yọ ayọ̀ ńlá, wọ́n pariwo pé, ẹ mú Samsoni wá kí ó wá dá wa lára yá. Wọ́n sì pe Samsoni jáde láti ọgbà ẹ̀wọ̀n náà, òun sì ń ṣeré fún wọn. Nígbà tí wọ́n mú un dúró láàrín àwọn òpó.
И бысть егда возблажа сердце их, и рекоша: призовите Сампсона из дому темничнаго, и да играет пред нами. И призваша Сампсона из дому темничнаго, и играша пред ними: и заушаху его, и поставиша его между столпы.
26 Samsoni sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí ó di ọwọ́ rẹ̀ mú pé, “Ẹ fi mí si ibi tí ọwọ́ mi yóò ti le tó àwọn òpó tí ó gbé tẹmpili dúró mú, kí èmi lè fẹ̀yìn tì wọ́n.”
И рече Сампсон ко юноши держащему его за руку: остави мене, да осяжу столпы, на нихже дом сей утвержден есть, и опруся на них. Юноша же сотвори тако.
27 Ní àsìkò náà, tẹmpili yìí kún fún àwọn ọkùnrin àti obìnrin; gbogbo àwọn ìjòyè Filistini wà níbẹ̀, ní òkè ilé náà, níbi tí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àwọn ọkùnrin àti obìnrin tí ń wòran Samsoni bí òun ti ń ṣeré.
Дом же бяше полн мужей и жен, и тамо вси князи иноплеменничи: на крове же том до трех тысящ мужей и жен, зряще ругаемаго Сампсона.
28 Nígbà náà ni Samsoni ké pe Olúwa wí pé, “Olúwa Olódùmarè, rántí mi. Háà Ọlọ́run jọ̀wọ́ fi agbára fún mi lẹ́ẹ̀kan yìí sí i, kí èmi lè gbẹ̀san lára àwọn Filistini nítorí àwọn ojú mi méjèèjì.”
И воззва Сампсон ко Господу и рече: Адонаи Господи, Господи Сил, помяни мя ныне, и укрепи мя еще единою, Боже, да воздам мщение едино за два ока моя Филистимом.
29 Samsoni sì na ọwọ́ mú àwọn òpó méjèèjì tí ó wà láàrín gbùngbùn, orí àwọn tí tẹmpili náà dúró lé, ó fi ọwọ́ ọ̀tún mú ọ̀kan àti ọwọ́ òsì mú èkejì, ó fi ara tì wọ́n,
И объя Сампсон оба столпа средния, на нихже храмина бяше утверждена, и опреся на них, держя един рукою десною, а другий левою.
30 Samsoni sì wí pé, “Jẹ́ kí èmi kú pẹ̀lú àwọn Filistini!” Òun sì fi agbára ńlá tì wọ́n, bẹ́ẹ̀ ni ilé náà wó lu àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn tí ó wà nínú rẹ̀. Báyìí ni ó pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ nígbà ikú rẹ̀ ju ìgbà ayé rẹ̀ lọ.
И рече Сампсон: да умрет душа моя со иноплеменники. И преклонися крепостию, и паде храмина на князи и на вся люди иже в ней: и бысть мертвых, ихже умертви Сампсон при смерти своей, множае неже ихже умертви в животе своем.
31 Nígbà náà ni àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀ ní àpapọ̀ gòkè lọ wọ́n sì gbé e, wọ́n gbé e padà wá, wọ́n sì sin ín sí agbede-méjì Sora àti Eṣtaoli, sínú ibojì Manoa baba rẹ̀. Òun ti ṣe àkóso Israẹli ní ogún ọdún.
И снидоша братия его и весь дом отца его, и взяша его: и взыдоша, и погребоша его между Сараи и между Есфаолом во гробе Маноя отца его. И сей суди Израилю лет двадесять. (и воста по Сампсоне Емегар сын Енань, и уби от иноплеменников шесть сот мужей кроме скота, и спасе и он Израиля.)

< Judges 16 >