< Judges 16 >

1 Ní ọjọ́ kan Samsoni lọ sí Gasa níbi tí ó ti rí obìnrin panṣágà kan. Ó wọlé tọ̀ ọ́ láti sun ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní òru ọjọ́ náà.
Potem Samson poszedł do Gazy i gdy zobaczył tam nierządnicę, obcował z nią.
2 Àwọn ará Gasa sì gbọ́ wí pé, “Samsoni wà níbí.” Wọ́n sì yí agbègbè náà ká, wọ́n ń ṣọ́ ọ ní gbogbo òru náà ní ẹnu-bodè ìlú náà. Wọn kò mira ní gbogbo òru náà pé ní “àfẹ̀mọ́júmọ́ àwa yóò pa á.”
I powiadomiono mieszkańców Gazy: Przybył tu Samson. Otoczyli go więc i czyhali na niego przez całą noc w bramie miasta. Zachowywali się cicho przez całą noc, mówiąc: Gdy zacznie świtać, zabijemy go.
3 Ṣùgbọ́n Samsoni sùn níbẹ̀ di àárín ọ̀gànjọ́. Òun sì dìde ní ọ̀gànjọ́, ó fi ọwọ́ di àwọn ìlẹ̀kùn odi ìlú náà mú, pẹ̀lú òpó méjèèjì, ó sì fà wọ́n tu, pẹ̀lú ìdábùú àti ohun gbogbo tí ó wà lára rẹ̀. Ó gbé wọn lé èjìká rẹ̀ òun sì gbé wọn lọ sí orí òkè tí ó kọjú sí Hebroni.
Ale Samson spał do północy, a o północy wstał, chwycił wrota bramy miejskiej z dwoma słupami i wyrwał je z zasuwą, potem włożył na swoje ramiona i zaniósł je na szczyt góry, która była naprzeciw Hebronu.
4 Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, ó sì ní ìfẹ́ obìnrin kan ní àfonífojì Soreki, orúkọ ẹni tí í ṣe Dẹlila.
Potem w dolinie Sorek zakochał się w kobiecie, która miała na imię Dalila.
5 Àwọn ìjòyè Filistini sì lọ bá obìnrin náà, wọ́n sọ fún un wí pé, “Bí ìwọ bá le tàn án kí òun sì fi àṣírí agbára rẹ̀ hàn ọ́, àti bí àwa ó ti lè borí rẹ̀, kí àwa sì dè é kí àwa sì ṣẹ́gun rẹ̀. Ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú wa yóò sì fún ọ ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà fàdákà.”
I przyszli do niej książęta Filistynów i powiedzieli jej: Oszukaj go i dowiedz się, w czym [tkwi] jego wielka siła i jak moglibyśmy go pokonać, by go związać i gnębić, a każdy z nas da ci tysiąc sto srebrników.
6 Torí náà Dẹlila sọ fún Samsoni pé, “Sọ àṣírí agbára ńlá rẹ fún mi àti bí wọ́n ti le dè ọ́, àti bí wọ́n ṣe lè borí rẹ.”
Powiedziała więc Dalila do Samsona: Powiedz mi, proszę, w czym tkwi twoja wielka siła i czym można by cię związać, by cię gnębić?
7 Samsoni dá a lóhùn wí pé, “Bí ẹnikẹ́ni bá fi okùn tútù méje tí ẹnìkan kò sá gbẹ dè mí, èmi yóò di aláìlágbára bí i gbogbo àwọn ọkùnrin yòókù.”
Samson jej odpowiedział: Gdyby mnie związano siedmioma świeżymi witkami, które jeszcze nie wyschły, wtedy osłabnę i będę jak każdy inny człowiek.
8 Àwọn olóyè Filistini sì mú okùn tútù méje tí ẹnikẹ́ni kò sá gbẹ wá fún Dẹlila òun sì fi wọ́n dè é.
I książęta Filistynów przynieśli jej siedem świeżych witek, które jeszcze nie wyschły, i związała go nimi.
9 Nígbà tí àwọn ènìyàn tí sá pamọ́ sínú yàrá, òun pè pé, “Samsoni àwọn Filistini ti dé láti mú ọ.” Ṣùgbọ́n òun já àwọn okùn náà bí òwú ti í já nígbà tí ó bá wà lẹ́bàá iná. Torí náà wọn kò mọ àṣírí agbára rẹ̀.
Tymczasem czyhający na niego siedzieli u niej w komorze. Wtedy powiedziała mu: Filistyni nad tobą, Samsonie! Lecz [on] zerwał witki, jakby ktoś zerwał zgrzebną nić, gdy dotknie jej ogień. Nie poznano więc, [w czym tkwiła] jego siła.
10 Dẹlila sì sọ fún Samsoni pé, ìwọ ti tàn mí; o sì purọ́ fún mi. Wá báyìí kí o sì sọ bí a ti ṣe le dè ọ́.
Potem Dalila powiedziała do Samsona: Oszukałeś mnie i skłamałeś mi. Teraz powiedz mi, proszę, czym można by cię związać?
11 Òun dáhùn pé, “Bí wọ́n bá lè fi okùn tuntun tí ẹnikẹ́ni kò tí ì lò rí dì mí dáradára, èmi yóò di aláìlágbára, èmi yóò sì dàbí àwọn ọkùnrin yòókù.”
A on jej odpowiedział: Gdyby mnie związano nowymi powrozami, których [jeszcze] nie używano, wtedy osłabnę i będę jak każdy inny człowiek.
12 Dẹlila sì mú àwọn okùn tuntun, ó fi wọ́n dì í. Nígbà tí àwọn ọkùnrin Filistini ti fi ara pamọ́ sínú yàrá, òun kígbe sí i pé, “Samsoni àwọn Filistini dé láti mú ọ,” òun sì já okùn náà kúrò ní ọwọ́ rẹ̀ bí òwú.
Dalila wzięła więc nowe powrozy i związała go nimi, i powiedziała do niego: Filistyni nad tobą, Samsonie! A czyhający na niego siedzieli w komorze, lecz [on] porwał je ze swych ramion jak nici.
13 Dẹlila sì tún sọ fún Samsoni pé, “Títí di ìsinsin yìí ìwọ sì ń tún tàn mí, o sì tún purọ́ fún mi. Sọ fún mi ọ̀nà tí wọ́n fi le dè ọ́.” Samsoni dá a lóhùn pé, “Bí ìwọ bá hun ìdí irun méjèèje tí ó wà ní orí mi pẹ̀lú okùn, tí ó sì le dáradára kí o sì fi ẹ̀mú mú un mọ́lẹ̀, èmi yóò di aláìlágbára bí àwọn ọkùnrin yòókù.” Nígbà tí òun ti sùn, Dẹlila hun àwọn ìdí irun méjèèje tí ó wà ní orí rẹ̀,
Wtedy Dalila powiedziała do Samsona: Aż dotąd szydziłeś ze mnie i okłamywałeś mnie. Powiedz mi, czym można by cię związać? I powiedział jej: Jeśli spleciesz siedem pasm z mojej głowy w osnowę przędzy.
14 ó sì fi ìhunṣọ dè wọ́n. Ó sì tún pè é pé, “Samsoni àwọn Filistini dé láti mú ọ.” Òun sì jí ní ojú oorun, ó sì fa ìdè ìhunṣọ náà tu pẹ̀lú ohun gbogbo tí wọ́n fi kàn án mọ́lẹ̀.
Ona wtedy przybiła [je] kołkiem i powiedziała do niego: Filistyni nad tobą, Samsonie! Lecz [on] obudził się ze snu i wyrwał kołek z osnową i z wałkiem.
15 Dẹlila sì sọ fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi wí pé, ‘Èmi fẹ́ràn rẹ,’ nígbà tí ìwọ kò fi ọkàn tán mi. Èyí ni ìgbà kẹta tí ìwọ ti tàn mí jẹ, tí ìwọ kò sì sọ àṣírí ibi tí agbára ńlá rẹ gbé wà fún mi.”
Znowu powiedziała do niego: Jak możesz mówić: Kocham cię, skoro twoje serce nie jest ze mną. Już trzykrotnie mnie oszukałeś i nie powiedziałeś mi, w czym tkwi twoja wielka siła.
16 Ó sì ṣe nígbà tí ó fi ọ̀rọ̀ rẹ̀ rọ̀ ọ́ ní ojoojúmọ́ pẹ̀lú ọ̀rọ̀ rẹ̀ títí dé bi pé ó sú dé òpin ẹ̀mí rẹ̀.
A gdy mu się tak naprzykrzała słowami każdego dnia i naciskała na niego tak, że jego dusza zmęczyła się na śmierć;
17 Òun sì sọ ohun gbogbo tí ó wà ní ọkàn rẹ̀ fún un. Ó ní, “Abẹ kò tí ì kan orí mi rí, nítorí pé Nasiri, ẹni ìyàsọ́tọ̀ fún Ọlọ́run ni mo jẹ́ láti ìgbà ìbí mi wá. Bí a bá fá irun orí mi, agbára mi yóò fi mí sílẹ̀, èmi yóò sì di aláìlágbára bí àwọn ọkùnrin yòókù.”
Wtedy otworzył przed nią całe swoje serce i powiedział jej: Brzytwa nigdy nie dotknęła mojej głowy, bo jestem nazirejczykiem dla Boga [już] z łona mojej matki. Jeśli zostanę ogolony, odejdzie ode mnie moja siła, osłabnę i będę jak każdy inny człowiek.
18 Nígbà tí Dẹlila rí i pé ó ti sọ ohun gbogbo fún òun tan, Dẹlila ránṣẹ́ sí àwọn ìjòyè Filistini pé, “Ẹ wá lẹ́ẹ̀kan sí i, ó ti sọ ohun gbogbo fún mi.” Torí náà àwọn olóyè Filistini padà, wọ́n sì mú owó ìpinnu náà lọ́wọ́.
A gdy Dalila spostrzegła, że otworzył przed nią całe swoje serce, wezwała książąt Filistynów, mówiąc: Przyjdźcie raz [jeszcze], gdyż otworzył przede mną całe swoje serce. Przyszli więc do niej książęta Filistynów, niosąc srebro w rękach.
19 Òun sì mú kí Samsoni sùn lórí itan rẹ̀, òun sì pe ọkùnrin kan láti fá àwọn ìdì irun orí rẹ̀ méjèèje, òun sì bẹ̀rẹ̀ sí ṣẹ́gun rẹ̀. Agbára rẹ̀ sì fi í sílẹ̀ lọ.
Wtedy uśpiła go na swoich kolanach, przywołała [pewnego] człowieka i kazała zgolić siedem pasm jego głowy; potem zaczęła go gnębić, a jego siła odeszła od niego.
20 Òun pè é wí pé, “Samsoni àwọn Filistini dé láti mú ọ.” Òun jí ní ojú oorun rẹ̀, ó sì sọ pé, “Èmi yóò jáde lọ bí í ti àtẹ̀yìnwá, kí èmi sì gba ara mi, kí n di òmìnira.” Ṣùgbọ́n òun kò mọ̀ pé Olúwa ti fi òun sílẹ̀.
I powiedziała: Filistyni nad tobą, Samsonie! A gdy się obudził ze snu, powiedział: Wyjdę jak poprzednio i otrząsnę się. Lecz nie wiedział, że PAN odstąpił od niego.
21 Nígbà náà ni àwọn Filistini mú un, wọ́n yọ ojú rẹ̀ méjèèjì wọ́n sì mú un lọ sí Gasa. Wọ́n fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ idẹ dè é, wọ́n sì fi sí ibi iṣẹ́ ọlọ lílọ̀ nínú ilé túbú.
Wtedy Filistyni pojmali go, wyłupili mu oczy i zaprowadzili do Gazy, a tam związali go dwoma spiżowymi łańcuchami i musiał mleć w domu więźniów.
22 Ṣùgbọ́n irun orí rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí í tún hù lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti fá a.
Potem włosy na jego głowie zaczęły odrastać po ogoleniu.
23 Àwọn ìjòyè, àwọn ará Filistini sì péjọpọ̀ láti ṣe ìrúbọ ńlá sí Dagoni ọlọ́run wọn àti láti ṣe ayẹyẹ wọ́n wí pé, ọlọ́run wa ti fi Samsoni ọ̀tá wa lé wa lọ́wọ́.
A książęta Filistynów zebrali się, aby złożyć swemu bogu Dagonowi wielką ofiarę i radować się. Mówili bowiem: Nasz bóg wydał w nasze ręce Samsona, naszego wroga.
24 Nígbà tí àwọn ènìyàn rí Samsoni wọ́n yin ọlọ́run wọn wí pé, “Ọlọ́run wa ti fi ọ̀tá wa lé wa lọ́wọ́. Àní ẹni tí ó ti run ilẹ̀ wa ẹni tí ó ti pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú wa.”
Kiedy ludzie widzieli go, chwalili swego boga, bo mówili: Nasz bóg wydał w nasze ręce naszego wroga, tego, który pustoszył naszą ziemię i który wielu z naszych pozabijał.
25 Nígbà tí inú wọn dùn gidigidi tí wọ́n ń yọ ayọ̀ ńlá, wọ́n pariwo pé, ẹ mú Samsoni wá kí ó wá dá wa lára yá. Wọ́n sì pe Samsoni jáde láti ọgbà ẹ̀wọ̀n náà, òun sì ń ṣeré fún wọn. Nígbà tí wọ́n mú un dúró láàrín àwọn òpó.
A gdy ich serca się rozweseliły, powiedzieli: Zawołajcie Samsona, aby nas zabawiał. Przywołano więc Samsona z domu więźniów, aby ich zabawiał. I postawili go między dwiema kolumnami.
26 Samsoni sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí ó di ọwọ́ rẹ̀ mú pé, “Ẹ fi mí si ibi tí ọwọ́ mi yóò ti le tó àwọn òpó tí ó gbé tẹmpili dúró mú, kí èmi lè fẹ̀yìn tì wọ́n.”
Wtedy Samson powiedział do chłopca, który go trzymał za rękę: Poprowadź mnie, abym mógł dotknąć kolumn, na których stoi dom, abym się o nie oparł.
27 Ní àsìkò náà, tẹmpili yìí kún fún àwọn ọkùnrin àti obìnrin; gbogbo àwọn ìjòyè Filistini wà níbẹ̀, ní òkè ilé náà, níbi tí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àwọn ọkùnrin àti obìnrin tí ń wòran Samsoni bí òun ti ń ṣeré.
A dom był pełen mężczyzn i kobiet, [byli] tam wszyscy książęta Filistynów, na dachu zaś [było] około trzech tysięcy mężczyzn i kobiet, którzy się przyglądali, gdy Samson [ich] zabawiał.
28 Nígbà náà ni Samsoni ké pe Olúwa wí pé, “Olúwa Olódùmarè, rántí mi. Háà Ọlọ́run jọ̀wọ́ fi agbára fún mi lẹ́ẹ̀kan yìí sí i, kí èmi lè gbẹ̀san lára àwọn Filistini nítorí àwọn ojú mi méjèèjì.”
Wówczas Samson wezwał PANA i powiedział: Panie BOŻE, wspomnij na mnie, proszę, i wzmocnij mnie tylko ten jeden raz, Boże, abym mógł się zemścić już na Filistynach za dwoje moich oczu.
29 Samsoni sì na ọwọ́ mú àwọn òpó méjèèjì tí ó wà láàrín gbùngbùn, orí àwọn tí tẹmpili náà dúró lé, ó fi ọwọ́ ọ̀tún mú ọ̀kan àti ọwọ́ òsì mú èkejì, ó fi ara tì wọ́n,
Ujął więc Samson obie środkowe kolumny, na których stał dom i o które się wsparł, jedną swoją prawą ręką, a drugą swoją lewą ręką.
30 Samsoni sì wí pé, “Jẹ́ kí èmi kú pẹ̀lú àwọn Filistini!” Òun sì fi agbára ńlá tì wọ́n, bẹ́ẹ̀ ni ilé náà wó lu àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn tí ó wà nínú rẹ̀. Báyìí ni ó pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ nígbà ikú rẹ̀ ju ìgbà ayé rẹ̀ lọ.
Potem Samson powiedział: Niech umrę z Filistynami. A gdy się o nie mocno oparł, dom upadł na książąt i na cały lud, który w nim był. A martwych, których zabił przy swojej śmierci, było więcej niż tych, których zabił za swego życia.
31 Nígbà náà ni àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀ ní àpapọ̀ gòkè lọ wọ́n sì gbé e, wọ́n gbé e padà wá, wọ́n sì sin ín sí agbede-méjì Sora àti Eṣtaoli, sínú ibojì Manoa baba rẹ̀. Òun ti ṣe àkóso Israẹli ní ogún ọdún.
I przyszli jego bracia i cały dom jego ojca, wzięli go, wrócili i pogrzebali go między Sorea a Esztaol, w grobie Manoacha, jego ojca. A sądził on Izraela przez dwadzieścia lat.

< Judges 16 >