< Judges 16 >

1 Ní ọjọ́ kan Samsoni lọ sí Gasa níbi tí ó ti rí obìnrin panṣágà kan. Ó wọlé tọ̀ ọ́ láti sun ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní òru ọjọ́ náà.
Elment Sámson Azzába; ott meglátott egy parázna asszonyt és bement hozzá.
2 Àwọn ará Gasa sì gbọ́ wí pé, “Samsoni wà níbí.” Wọ́n sì yí agbègbè náà ká, wọ́n ń ṣọ́ ọ ní gbogbo òru náà ní ẹnu-bodè ìlú náà. Wọn kò mira ní gbogbo òru náà pé ní “àfẹ̀mọ́júmọ́ àwa yóò pa á.”
Megmondták az Azzabelieknek: eljött ide Sámson; erre körülálltak és leselkedtek reá egész éjjel a város kapujában. Hallgatag voltak egész éjjel, mondván: a reggel fölvirradtáig megöljük.
3 Ṣùgbọ́n Samsoni sùn níbẹ̀ di àárín ọ̀gànjọ́. Òun sì dìde ní ọ̀gànjọ́, ó fi ọwọ́ di àwọn ìlẹ̀kùn odi ìlú náà mú, pẹ̀lú òpó méjèèjì, ó sì fà wọ́n tu, pẹ̀lú ìdábùú àti ohun gbogbo tí ó wà lára rẹ̀. Ó gbé wọn lé èjìká rẹ̀ òun sì gbé wọn lọ sí orí òkè tí ó kọjú sí Hebroni.
S feküdt Sámson éjfélig, fölkelt éjfélkor, megragadta a város kapujának ajtait meg a két félfát, kirántotta a retesszel együtt és vállaira tette; fölvitte a hegy tetejére, mely Chebrón előtt van.
4 Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, ó sì ní ìfẹ́ obìnrin kan ní àfonífojì Soreki, orúkọ ẹni tí í ṣe Dẹlila.
Történt ezután, megszeretett egy asszonyt Szórék völgyében, neve Delíla.
5 Àwọn ìjòyè Filistini sì lọ bá obìnrin náà, wọ́n sọ fún un wí pé, “Bí ìwọ bá le tàn án kí òun sì fi àṣírí agbára rẹ̀ hàn ọ́, àti bí àwa ó ti lè borí rẹ̀, kí àwa sì dè é kí àwa sì ṣẹ́gun rẹ̀. Ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú wa yóò sì fún ọ ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà fàdákà.”
Ahhoz fölmentek a filiszteusok fejedelmei és mondták neki: Beszéld őt rá és nézd, miáltal nagy az ereje és miképpen bírnánk vele és megkötözzük őt, hogy lealázzuk; mi pedig adunk neked ki-ki ezer meg száz ezüstöt.
6 Torí náà Dẹlila sọ fún Samsoni pé, “Sọ àṣírí agbára ńlá rẹ fún mi àti bí wọ́n ti le dè ọ́, àti bí wọ́n ṣe lè borí rẹ.”
Szólt Delíla Sámsonhoz: Mondd meg csak nekem, miáltal nagy az erőd és mivel kötözhetnek meg, hogy lealázzanak?
7 Samsoni dá a lóhùn wí pé, “Bí ẹnikẹ́ni bá fi okùn tútù méje tí ẹnìkan kò sá gbẹ dè mí, èmi yóò di aláìlágbára bí i gbogbo àwọn ọkùnrin yòókù.”
Szólt hozzá Sámson: Ha megkötöznek engem hét nyers ínnal, melyeket meg nem szárítottak, akkor elgyengülök és olyan leszek, mint akármely ember.
8 Àwọn olóyè Filistini sì mú okùn tútù méje tí ẹnikẹ́ni kò sá gbẹ wá fún Dẹlila òun sì fi wọ́n dè é.
És fölvittek neki a filiszteusok fejedelmei hét nedves inat, melyeket meg nem szárítottak; és megkötözte őt azokkal –
9 Nígbà tí àwọn ènìyàn tí sá pamọ́ sínú yàrá, òun pè pé, “Samsoni àwọn Filistini ti dé láti mú ọ.” Ṣùgbọ́n òun já àwọn okùn náà bí òwú ti í já nígbà tí ó bá wà lẹ́bàá iná. Torí náà wọn kò mọ àṣírí agbára rẹ̀.
a lestálló pedig várt nála a kamarában – és szólt hozzá: Filiszteusok ellened, Sámson! Ekkor szétszakította az inakat, mint szétszakad a csepűfonál, mikor tüzet szagol, s nem tudódott ki az ereje.
10 Dẹlila sì sọ fún Samsoni pé, ìwọ ti tàn mí; o sì purọ́ fún mi. Wá báyìí kí o sì sọ bí a ti ṣe le dè ọ́.
És szólt Delíla Sámsonhoz: Íme, ámítottál engem és hazugságokat beszéltél nekem; most mondd meg csak nekem, mivel kötözhetnek meg téged?
11 Òun dáhùn pé, “Bí wọ́n bá lè fi okùn tuntun tí ẹnikẹ́ni kò tí ì lò rí dì mí dáradára, èmi yóò di aláìlágbára, èmi yóò sì dàbí àwọn ọkùnrin yòókù.”
Szólt hozzá: Ha jól megkötöznek új kötelekkel, melyekkel nem végeztek munkát, akkor elgyengülök és olyan leszek, mint akármely ember.
12 Dẹlila sì mú àwọn okùn tuntun, ó fi wọ́n dì í. Nígbà tí àwọn ọkùnrin Filistini ti fi ara pamọ́ sínú yàrá, òun kígbe sí i pé, “Samsoni àwọn Filistini dé láti mú ọ,” òun sì já okùn náà kúrò ní ọwọ́ rẹ̀ bí òwú.
S vett Delíla új köteleket, megkötözte őt azokkal és szólt hozzá: Filiszteusok ellened, Sámson! A lestálló pedig várta a kamarában – és leszakította karjáról, mint madzagot.
13 Dẹlila sì tún sọ fún Samsoni pé, “Títí di ìsinsin yìí ìwọ sì ń tún tàn mí, o sì tún purọ́ fún mi. Sọ fún mi ọ̀nà tí wọ́n fi le dè ọ́.” Samsoni dá a lóhùn pé, “Bí ìwọ bá hun ìdí irun méjèèje tí ó wà ní orí mi pẹ̀lú okùn, tí ó sì le dáradára kí o sì fi ẹ̀mú mú un mọ́lẹ̀, èmi yóò di aláìlágbára bí àwọn ọkùnrin yòókù.” Nígbà tí òun ti sùn, Dẹlila hun àwọn ìdí irun méjèèje tí ó wà ní orí rẹ̀,
És szólt Delíla Sámsonhoz: Mindeddig ámítottál engem és hazugságokat beszéltél nekem; mondd meg nekem, mivel kötözhetnek meg téged? Szólt hozzá: Ha összeszövöd hajamnak hét fonatját a szövedékkel.
14 ó sì fi ìhunṣọ dè wọ́n. Ó sì tún pè é pé, “Samsoni àwọn Filistini dé láti mú ọ.” Òun sì jí ní ojú oorun, ó sì fa ìdè ìhunṣọ náà tu pẹ̀lú ohun gbogbo tí wọ́n fi kàn án mọ́lẹ̀.
S beleütötte a szöget és szólt hozzá: Filiszteusok ellened, Sámson! Erre fölébredt álmából és kirántotta a szövőszöget meg a szövedéket.
15 Dẹlila sì sọ fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi wí pé, ‘Èmi fẹ́ràn rẹ,’ nígbà tí ìwọ kò fi ọkàn tán mi. Èyí ni ìgbà kẹta tí ìwọ ti tàn mí jẹ, tí ìwọ kò sì sọ àṣírí ibi tí agbára ńlá rẹ gbé wà fún mi.”
S mondta neki: Hogyan mondhatod: szeretlek, holott szíved nincsen velem? Immár háromszor ámítottál engem és nem mondtad meg nekem, miáltal nagy az erőd.
16 Ó sì ṣe nígbà tí ó fi ọ̀rọ̀ rẹ̀ rọ̀ ọ́ ní ojoojúmọ́ pẹ̀lú ọ̀rọ̀ rẹ̀ títí dé bi pé ó sú dé òpin ẹ̀mí rẹ̀.
És volt, midőn faggatta őt szavaival minden nap és szorította, halálig csüggedt el a lelke.
17 Òun sì sọ ohun gbogbo tí ó wà ní ọkàn rẹ̀ fún un. Ó ní, “Abẹ kò tí ì kan orí mi rí, nítorí pé Nasiri, ẹni ìyàsọ́tọ̀ fún Ọlọ́run ni mo jẹ́ láti ìgbà ìbí mi wá. Bí a bá fá irun orí mi, agbára mi yóò fi mí sílẹ̀, èmi yóò sì di aláìlágbára bí àwọn ọkùnrin yòókù.”
Ekkor föltárta neki egész szívét és szólt hozzá: Borotva nem jutott fejemre, mert Isten názírja vagyok anyám méhétől fogva; ha lenyírnak, akkor távozik tőlem az erőm, elgyengülök és olyan leszek, mint akármely ember.
18 Nígbà tí Dẹlila rí i pé ó ti sọ ohun gbogbo fún òun tan, Dẹlila ránṣẹ́ sí àwọn ìjòyè Filistini pé, “Ẹ wá lẹ́ẹ̀kan sí i, ó ti sọ ohun gbogbo fún mi.” Torí náà àwọn olóyè Filistini padà, wọ́n sì mú owó ìpinnu náà lọ́wọ́.
Látta Delíla, hogy föltárta neki egész szívét, akkor küldött és hivatta a filiszteusok fejedelmeit, mondván: Ez egyszer jöjjetek fel, mert föltárta nekem egész szívét. – És felmentek hozzá a filiszteusok fejedelmei és fölvitték a pénzt kezükben. –
19 Òun sì mú kí Samsoni sùn lórí itan rẹ̀, òun sì pe ọkùnrin kan láti fá àwọn ìdì irun orí rẹ̀ méjèèje, òun sì bẹ̀rẹ̀ sí ṣẹ́gun rẹ̀. Agbára rẹ̀ sì fi í sílẹ̀ lọ.
És elaltatta őt térdein, hívott egy embert és lenyírta hajának hét fonatfát; így kezdte őt lealázni, és eltávozott tőle az ereje.
20 Òun pè é wí pé, “Samsoni àwọn Filistini dé láti mú ọ.” Òun jí ní ojú oorun rẹ̀, ó sì sọ pé, “Èmi yóò jáde lọ bí í ti àtẹ̀yìnwá, kí èmi sì gba ara mi, kí n di òmìnira.” Ṣùgbọ́n òun kò mọ̀ pé Olúwa ti fi òun sílẹ̀.
És mondta: filiszteusok ellened, Sámson! Erre fölébredt álmából és mondta: Kijutok, mint egyszer-másszor, és lerázom magamról. De ő nem tudta, hogy az Örökkévaló eltávozott tőle.
21 Nígbà náà ni àwọn Filistini mú un, wọ́n yọ ojú rẹ̀ méjèèjì wọ́n sì mú un lọ sí Gasa. Wọ́n fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ idẹ dè é, wọ́n sì fi sí ibi iṣẹ́ ọlọ lílọ̀ nínú ilé túbú.
Ekkor megfogták őt a filiszteusok és kiszúrták szemeit; levitték Azzába és megkötözték bilincsekkel, és őrlenie kellett neki a foglyok házában.
22 Ṣùgbọ́n irun orí rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí í tún hù lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti fá a.
S kezdett megnőni fejének haja, miután lenyíratott.
23 Àwọn ìjòyè, àwọn ará Filistini sì péjọpọ̀ láti ṣe ìrúbọ ńlá sí Dagoni ọlọ́run wọn àti láti ṣe ayẹyẹ wọ́n wí pé, ọlọ́run wa ti fi Samsoni ọ̀tá wa lé wa lọ́wọ́.
A filiszteusok fejedelmei pedig összegyűltek, hogy tartanak nagy áldozatot Dágón istenüknek, meg örömünnepre; és mondták: Kezünkbe adta istenünk Sámsont, a mi ellenségünket.
24 Nígbà tí àwọn ènìyàn rí Samsoni wọ́n yin ọlọ́run wọn wí pé, “Ọlọ́run wa ti fi ọ̀tá wa lé wa lọ́wọ́. Àní ẹni tí ó ti run ilẹ̀ wa ẹni tí ó ti pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú wa.”
Meglátta őt a nép, és dicsérték istenüket, mert mondták: Kezünkbe adta istenünk ellenségünket, országunk pusztítóját s a ki megsokasította elesettjeinket!
25 Nígbà tí inú wọn dùn gidigidi tí wọ́n ń yọ ayọ̀ ńlá, wọ́n pariwo pé, ẹ mú Samsoni wá kí ó wá dá wa lára yá. Wọ́n sì pe Samsoni jáde láti ọgbà ẹ̀wọ̀n náà, òun sì ń ṣeré fún wọn. Nígbà tí wọ́n mú un dúró láàrín àwọn òpó.
És volt, midőn jó kedvük lett, azt mondták: Hívjátok Sámsont, hogy játszadozzon nekünk. És hívták Sámsont a foglyok házából és játszadozott előttük, és állították őt az oszlopok közé.
26 Samsoni sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí ó di ọwọ́ rẹ̀ mú pé, “Ẹ fi mí si ibi tí ọwọ́ mi yóò ti le tó àwọn òpó tí ó gbé tẹmpili dúró mú, kí èmi lè fẹ̀yìn tì wọ́n.”
Ekkor szólt Sámson a fiúhoz, ki őt kezénél fogta: Hagyj engem, hadd tapogatom meg az oszlopokat, melyeken áll a ház, majd támaszkodom rájuk.
27 Ní àsìkò náà, tẹmpili yìí kún fún àwọn ọkùnrin àti obìnrin; gbogbo àwọn ìjòyè Filistini wà níbẹ̀, ní òkè ilé náà, níbi tí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àwọn ọkùnrin àti obìnrin tí ń wòran Samsoni bí òun ti ń ṣeré.
A ház pedig tele volt férfiakkal és asszonyokkal, és ott voltak mind a filiszteusok fejedelmei; a tetőn pedig mintegy háromezer férfi és asszony, a kik nézték Sámson játékát.
28 Nígbà náà ni Samsoni ké pe Olúwa wí pé, “Olúwa Olódùmarè, rántí mi. Háà Ọlọ́run jọ̀wọ́ fi agbára fún mi lẹ́ẹ̀kan yìí sí i, kí èmi lè gbẹ̀san lára àwọn Filistini nítorí àwọn ojú mi méjèèjì.”
Ekkor kiáltott Sámson az Örökkévalóhoz és mondta: Uram, Örökkévaló, emlékezzél, kérlek, meg rólam és erősíts meg csak ez egyszer, oh Isten, hadd álljak bosszút egy bosszúval két szememért a filiszteusokon.
29 Samsoni sì na ọwọ́ mú àwọn òpó méjèèjì tí ó wà láàrín gbùngbùn, orí àwọn tí tẹmpili náà dúró lé, ó fi ọwọ́ ọ̀tún mú ọ̀kan àti ọwọ́ òsì mú èkejì, ó fi ara tì wọ́n,
Erre átfogta Sámson a középső hét oszlopot, melyeken állt a ház, és rájuk támaszkodott: az egyiket jobbjával, a másikat baljával.
30 Samsoni sì wí pé, “Jẹ́ kí èmi kú pẹ̀lú àwọn Filistini!” Òun sì fi agbára ńlá tì wọ́n, bẹ́ẹ̀ ni ilé náà wó lu àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn tí ó wà nínú rẹ̀. Báyìí ni ó pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ nígbà ikú rẹ̀ ju ìgbà ayé rẹ̀ lọ.
És mondta Sámson: Haljon meg lelkem a filiszteusokkal együtt! Neki hajolt erővel és ledőlt a ház a fejedelmekre és az egész népre, mely benne volt; és számosabbak voltak a halottak, kiket megölt halálában, mint a kiket megölt életében.
31 Nígbà náà ni àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀ ní àpapọ̀ gòkè lọ wọ́n sì gbé e, wọ́n gbé e padà wá, wọ́n sì sin ín sí agbede-méjì Sora àti Eṣtaoli, sínú ibojì Manoa baba rẹ̀. Òun ti ṣe àkóso Israẹli ní ogún ọdún.
És lementek testvérei és atyjának egész háza, fölvették őt, fölmentek és eltemették őt Czorea és Estáól között, atyjának Mánóachnak sírjában. Ő pedig bírája volt Izraélnek húsz évig.

< Judges 16 >