< Judges 16 >

1 Ní ọjọ́ kan Samsoni lọ sí Gasa níbi tí ó ti rí obìnrin panṣágà kan. Ó wọlé tọ̀ ọ́ láti sun ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní òru ọjọ́ náà.
Also Sampson yede in to Gazam, and he siy there a womman hoore, and he entride to hir.
2 Àwọn ará Gasa sì gbọ́ wí pé, “Samsoni wà níbí.” Wọ́n sì yí agbègbè náà ká, wọ́n ń ṣọ́ ọ ní gbogbo òru náà ní ẹnu-bodè ìlú náà. Wọn kò mira ní gbogbo òru náà pé ní “àfẹ̀mọ́júmọ́ àwa yóò pa á.”
And whanne Filisteis hadden seyn this, and it was pupplischid at hem, that Sampson entride in to the citee, thei cumpassiden hym, whanne keperis weren set in the yate of the citee; and thei abididen there al nyyt `with silence, that in the morewtid thei schulen kille Sampson goynge out.
3 Ṣùgbọ́n Samsoni sùn níbẹ̀ di àárín ọ̀gànjọ́. Òun sì dìde ní ọ̀gànjọ́, ó fi ọwọ́ di àwọn ìlẹ̀kùn odi ìlú náà mú, pẹ̀lú òpó méjèèjì, ó sì fà wọ́n tu, pẹ̀lú ìdábùú àti ohun gbogbo tí ó wà lára rẹ̀. Ó gbé wọn lé èjìká rẹ̀ òun sì gbé wọn lọ sí orí òkè tí ó kọjú sí Hebroni.
Forsothe Sampson slepte til to `the myddis of the nyyt; and `fro thennus he roos, and took bothe the closyngis, ethir leeues, of the yate, with hise postis and lok; and he bar tho leeues, put on the schuldris, to the cop of the hil that biholdith Ebron.
4 Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, ó sì ní ìfẹ́ obìnrin kan ní àfonífojì Soreki, orúkọ ẹni tí í ṣe Dẹlila.
After these thingis Sampson louyde a womman that dwellide in the valey of Soreth, and sche was clepid Dalida.
5 Àwọn ìjòyè Filistini sì lọ bá obìnrin náà, wọ́n sọ fún un wí pé, “Bí ìwọ bá le tàn án kí òun sì fi àṣírí agbára rẹ̀ hàn ọ́, àti bí àwa ó ti lè borí rẹ̀, kí àwa sì dè é kí àwa sì ṣẹ́gun rẹ̀. Ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú wa yóò sì fún ọ ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà fàdákà.”
And the princes of Filisteis camen to hir, and seiden, Disseyue thou hym, and lerne thou of hym, in what thing he hath so greet strengthe, and how we mowen ouercome hym, and turmente hym boundun; that if thou doist, we schulen yyue to thee ech man a thousynde and an hundrid platis of siluer.
6 Torí náà Dẹlila sọ fún Samsoni pé, “Sọ àṣírí agbára ńlá rẹ fún mi àti bí wọ́n ti le dè ọ́, àti bí wọ́n ṣe lè borí rẹ.”
Therfor Dalida spak to Sampson, Y biseche, seie thou to me, wher ynne is thi gretteste strengthe, and what is that thing, with which thou boundun maist not breke?
7 Samsoni dá a lóhùn wí pé, “Bí ẹnikẹ́ni bá fi okùn tútù méje tí ẹnìkan kò sá gbẹ dè mí, èmi yóò di aláìlágbára bí i gbogbo àwọn ọkùnrin yòókù.”
To whom Sampson answeride, If Y be boundun with seuene coordis of senewis not yit drye `and yit moiste, Y schal be feble as othere men.
8 Àwọn olóyè Filistini sì mú okùn tútù méje tí ẹnikẹ́ni kò sá gbẹ wá fún Dẹlila òun sì fi wọ́n dè é.
And the princis of Filisteis brouyten `to hir seuene coordis, as he hadde seide; with whiche sche boond him,
9 Nígbà tí àwọn ènìyàn tí sá pamọ́ sínú yàrá, òun pè pé, “Samsoni àwọn Filistini ti dé láti mú ọ.” Ṣùgbọ́n òun já àwọn okùn náà bí òwú ti í já nígbà tí ó bá wà lẹ́bàá iná. Torí náà wọn kò mọ àṣírí agbára rẹ̀.
while buyschementis weren hid at hir, and abididen in a closet the ende of the thing. And sche criede to hym, Sampson, Filisteis ben on thee! Which brak the boondis, as if a man brekith a threed of herdis, writhun with spotle, whanne it hath take the odour of fier; and it was not knowun wher ynne his strengthe was.
10 Dẹlila sì sọ fún Samsoni pé, ìwọ ti tàn mí; o sì purọ́ fún mi. Wá báyìí kí o sì sọ bí a ti ṣe le dè ọ́.
And Dalida seide to hym, Lo! thou hast scorned me, and thou hast spok fals; nameli now schewe thou to me, with what thing thou schuldist be boundun.
11 Òun dáhùn pé, “Bí wọ́n bá lè fi okùn tuntun tí ẹnikẹ́ni kò tí ì lò rí dì mí dáradára, èmi yóò di aláìlágbára, èmi yóò sì dàbí àwọn ọkùnrin yòókù.”
To whom he answeride, If Y be boundun with newe coordis, that weren not yit in werk, I schal be feble, and lijk othere men.
12 Dẹlila sì mú àwọn okùn tuntun, ó fi wọ́n dì í. Nígbà tí àwọn ọkùnrin Filistini ti fi ara pamọ́ sínú yàrá, òun kígbe sí i pé, “Samsoni àwọn Filistini dé láti mú ọ,” òun sì já okùn náà kúrò ní ọwọ́ rẹ̀ bí òwú.
With whiche Dalida boond him eft, and criede, Sampson, Filistees ben on thee! the while buyschementis weren maad redi in closet. Which brak `so the boondis as thredis of webbis.
13 Dẹlila sì tún sọ fún Samsoni pé, “Títí di ìsinsin yìí ìwọ sì ń tún tàn mí, o sì tún purọ́ fún mi. Sọ fún mi ọ̀nà tí wọ́n fi le dè ọ́.” Samsoni dá a lóhùn pé, “Bí ìwọ bá hun ìdí irun méjèèje tí ó wà ní orí mi pẹ̀lú okùn, tí ó sì le dáradára kí o sì fi ẹ̀mú mú un mọ́lẹ̀, èmi yóò di aláìlágbára bí àwọn ọkùnrin yòókù.” Nígbà tí òun ti sùn, Dẹlila hun àwọn ìdí irun méjèèje tí ó wà ní orí rẹ̀,
And Dalida seide eft to hym, Hou long schalt thou disseyue me, and schalt speke fals? Schew thou to me, with what thing thou schalt be boundun. To whom Sampson answeryde, he seide, If thou plattist seuene heeris of myn heed with a strong boond, and fastnest to the erthe a naile boundun a boute with these, Y schal be feble.
14 ó sì fi ìhunṣọ dè wọ́n. Ó sì tún pè é pé, “Samsoni àwọn Filistini dé láti mú ọ.” Òun sì jí ní ojú oorun, ó sì fa ìdè ìhunṣọ náà tu pẹ̀lú ohun gbogbo tí wọ́n fi kàn án mọ́lẹ̀.
And whanne Dalida hadde do this, sche seide to hym, Sampson, Filisteis ben on thee! And he roos fro sleep, and drow out the nail, with the heeris and strong boond.
15 Dẹlila sì sọ fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi wí pé, ‘Èmi fẹ́ràn rẹ,’ nígbà tí ìwọ kò fi ọkàn tán mi. Èyí ni ìgbà kẹta tí ìwọ ti tàn mí jẹ, tí ìwọ kò sì sọ àṣírí ibi tí agbára ńlá rẹ gbé wà fún mi.”
And Dalida seide to hym, Hou seist thou, that thou louest me, sithen thi soule is not with me? Bi thre tymes thou liedist to me, and noldist seie to me, wher ynne is thi moost strengthe.
16 Ó sì ṣe nígbà tí ó fi ọ̀rọ̀ rẹ̀ rọ̀ ọ́ ní ojoojúmọ́ pẹ̀lú ọ̀rọ̀ rẹ̀ títí dé bi pé ó sú dé òpin ẹ̀mí rẹ̀.
And whanne sche was diseseful to hym, and cleuyde to hym contynueli bi many daies, and yaf not space to reste, his lijf failide, and was maad wery `til to deeth.
17 Òun sì sọ ohun gbogbo tí ó wà ní ọkàn rẹ̀ fún un. Ó ní, “Abẹ kò tí ì kan orí mi rí, nítorí pé Nasiri, ẹni ìyàsọ́tọ̀ fún Ọlọ́run ni mo jẹ́ láti ìgbà ìbí mi wá. Bí a bá fá irun orí mi, agbára mi yóò fi mí sílẹ̀, èmi yóò sì di aláìlágbára bí àwọn ọkùnrin yòókù.”
Thanne he openyde the treuthe of the thing, and seide to hir, Yrun stiede neuere on myn heed, for Y am a Nazarei, that is, halewid to the Lord, fro `the wombe of my modir; if myn heed be schauun, my strengthe schal go awei fro me, and Y schal faile, and Y schal be as othere men.
18 Nígbà tí Dẹlila rí i pé ó ti sọ ohun gbogbo fún òun tan, Dẹlila ránṣẹ́ sí àwọn ìjòyè Filistini pé, “Ẹ wá lẹ́ẹ̀kan sí i, ó ti sọ ohun gbogbo fún mi.” Torí náà àwọn olóyè Filistini padà, wọ́n sì mú owó ìpinnu náà lọ́wọ́.
And sche siy that he knowlechide to hir al his wille, `ether herte; and sche sente to the princes of Filisteis, and comaundide, Stie ye yit onys, for now he openyde his herte to me. Whiche stieden, with the money takun which thei bihiyten.
19 Òun sì mú kí Samsoni sùn lórí itan rẹ̀, òun sì pe ọkùnrin kan láti fá àwọn ìdì irun orí rẹ̀ méjèèje, òun sì bẹ̀rẹ̀ sí ṣẹ́gun rẹ̀. Agbára rẹ̀ sì fi í sílẹ̀ lọ.
And sche made hym slepe on hir knees, and `bowe the heed in hir bosum; and sche clepide a barbour, and schauede seuene heeris of hym; and sche bigan to caste hym awei, and to put fro hir; for anoon the strengthe yede awei fro him.
20 Òun pè é wí pé, “Samsoni àwọn Filistini dé láti mú ọ.” Òun jí ní ojú oorun rẹ̀, ó sì sọ pé, “Èmi yóò jáde lọ bí í ti àtẹ̀yìnwá, kí èmi sì gba ara mi, kí n di òmìnira.” Ṣùgbọ́n òun kò mọ̀ pé Olúwa ti fi òun sílẹ̀.
And sche seide, Sampson, Filisteis ben on thee! And he roos fro sleep, and seide to his soule, Y schal go out, as and Y dide bifore, and Y schal schake me fro boondis; and he wiste not, that the Lord hadde goon awei fro hym.
21 Nígbà náà ni àwọn Filistini mú un, wọ́n yọ ojú rẹ̀ méjèèjì wọ́n sì mú un lọ sí Gasa. Wọ́n fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ idẹ dè é, wọ́n sì fi sí ibi iṣẹ́ ọlọ lílọ̀ nínú ilé túbú.
And whanne Filisteis hadden take hym, anoon thei diden out hise iyen, and ledden hym boundun with chaynes to Gaza, and `maden hym closid in prisoun to grynde.
22 Ṣùgbọ́n irun orí rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí í tún hù lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti fá a.
And now hise heeris bigunnen to growe ayen;
23 Àwọn ìjòyè, àwọn ará Filistini sì péjọpọ̀ láti ṣe ìrúbọ ńlá sí Dagoni ọlọ́run wọn àti láti ṣe ayẹyẹ wọ́n wí pé, ọlọ́run wa ti fi Samsoni ọ̀tá wa lé wa lọ́wọ́.
and the princes of Filisteis camen togidere to offre grete sacrifices to Dagon, her god, and `to ete, seiynge, Oure god hath bitake oure enemy Sampson in to oure hondis.
24 Nígbà tí àwọn ènìyàn rí Samsoni wọ́n yin ọlọ́run wọn wí pé, “Ọlọ́run wa ti fi ọ̀tá wa lé wa lọ́wọ́. Àní ẹni tí ó ti run ilẹ̀ wa ẹni tí ó ti pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú wa.”
And the puple seynge also this thing preiside her god, and seide the same thingis, Our god hath bitake oure aduersarie in to oure hondis, which dide awey oure lond, and killide ful many men.
25 Nígbà tí inú wọn dùn gidigidi tí wọ́n ń yọ ayọ̀ ńlá, wọ́n pariwo pé, ẹ mú Samsoni wá kí ó wá dá wa lára yá. Wọ́n sì pe Samsoni jáde láti ọgbà ẹ̀wọ̀n náà, òun sì ń ṣeré fún wọn. Nígbà tí wọ́n mú un dúró láàrín àwọn òpó.
And thei weren glad bi feestis, for thei hadden ete thanne; and thei comaundiden, that Sampson schulde be clepid, and schulde pleie bifor hem; which was led out of prisoun, and pleiede bifor hem; and thei maden hym stonde bitwixe twei pileris.
26 Samsoni sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí ó di ọwọ́ rẹ̀ mú pé, “Ẹ fi mí si ibi tí ọwọ́ mi yóò ti le tó àwọn òpó tí ó gbé tẹmpili dúró mú, kí èmi lè fẹ̀yìn tì wọ́n.”
And he seide to the `child gouernynge hise steppis, Suffre thou me, that Y touche the pilers on whiche al the hows stondith, that Y be bowid on tho, and reste a litil.
27 Ní àsìkò náà, tẹmpili yìí kún fún àwọn ọkùnrin àti obìnrin; gbogbo àwọn ìjòyè Filistini wà níbẹ̀, ní òkè ilé náà, níbi tí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àwọn ọkùnrin àti obìnrin tí ń wòran Samsoni bí òun ti ń ṣeré.
Sotheli the hows was ful of men and of wymmen, and the princes of the Filisteis weren there, and aboute thre thousynde of `euer either kynde, biholdynge fro the roof and the soler Sampson pleynge.
28 Nígbà náà ni Samsoni ké pe Olúwa wí pé, “Olúwa Olódùmarè, rántí mi. Háà Ọlọ́run jọ̀wọ́ fi agbára fún mi lẹ́ẹ̀kan yìí sí i, kí èmi lè gbẹ̀san lára àwọn Filistini nítorí àwọn ojú mi méjèèjì.”
And whanne the Lord `was inwardli clepid, he seide, My Lord God, haue mynde on me, and, my God, yelde thou now to me the formere strengthe, that Y venge me of myn enemyes, and that Y resseyue o veniaunce for the los of tweyne iyen.
29 Samsoni sì na ọwọ́ mú àwọn òpó méjèèjì tí ó wà láàrín gbùngbùn, orí àwọn tí tẹmpili náà dúró lé, ó fi ọwọ́ ọ̀tún mú ọ̀kan àti ọwọ́ òsì mú èkejì, ó fi ara tì wọ́n,
And he took bothe pilers, on whiche the hows stood, and he helde the oon of tho in the riythond, and the tother in the left hond; and seide,
30 Samsoni sì wí pé, “Jẹ́ kí èmi kú pẹ̀lú àwọn Filistini!” Òun sì fi agbára ńlá tì wọ́n, bẹ́ẹ̀ ni ilé náà wó lu àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn tí ó wà nínú rẹ̀. Báyìí ni ó pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ nígbà ikú rẹ̀ ju ìgbà ayé rẹ̀ lọ.
My lijf die with Filesteis! And whanne the pileris weren schakun togidere strongli, the hows felde on alle the princes, and on the tother multitude, that was there; and he diynge killide many moo, than he quyk hadde slayn bifore.
31 Nígbà náà ni àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀ ní àpapọ̀ gòkè lọ wọ́n sì gbé e, wọ́n gbé e padà wá, wọ́n sì sin ín sí agbede-méjì Sora àti Eṣtaoli, sínú ibojì Manoa baba rẹ̀. Òun ti ṣe àkóso Israẹli ní ogún ọdún.
Forsothe hise britheren and al the kinrede camen doun, and token his bodi, and birieden bitwixe Saraa and Escahol, in the sepulcre of his fadir Manue; and he demyde Israel twenti yeer.

< Judges 16 >