< Judges 15 >

1 Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, ní àkókò ìkórè alikama, Samsoni mú ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan láti bẹ ìyàwó rẹ̀ wò. Ó ní, “Èmi yóò wọ yàrá ìyàwó mi lọ.” Ṣùgbọ́n baba rẹ̀ kò gbà á láààyè láti wọlé.
Дупэ кытва тимп, пе время сечератулуй грыулуй, Самсон с-а дус сэ-шь вадэ неваста ши й-а дус ун ед. Ел а зис: „Вряу сэ интру ла невастэ-мя ын одая ей.”
2 Baba ìyàwó dá a lóhùn pé, “Ó dá mi lójú pé o kórìíra rẹ̀, torí náà mo ti fi fún ọ̀rẹ́ rẹ, ṣe bí àbúrò rẹ̀ obìnrin kò ha lẹ́wà jùlọ? Fẹ́ ẹ dípò rẹ̀.”
Дар татэл невестей ну й-а ынгэдуит сэ интре. „Ам крезут кэ о урэшть”, а зис ел, „ши ам дат-о товарэшулуй тэу. Ну есте сорэ-са чя тынэрэ май фрумоасэ ка еа? Я-о дар ын локул ей.”
3 Samsoni dáhùn pé, “Ní àkókò yìí tí mo bá ṣe àwọn Filistini ní ibi èmi yóò jẹ́ aláìjẹ̀bi.”
Самсон ле-а зис: „Де дата ачаста ну вой фи виноват фацэ де филистень дакэ ле вой фаче рэу.”
4 Samsoni sì jáde lọ, ó mú ọ̀ọ́dúnrún kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ ó so ìrù wọn mọ́ ara wọn ní méjì méjì. Ó mú ètùfù iná, ó so ó mọ́ àwọn ìrù tí ó so pọ̀.
Самсон а плекат. А принс трей суте де вулпь ши а луат ниште фэклий, апой а легат вулпиле коадэ де коадэ ши а пус кыте о фэклие ынтре челе доуэ козь, ла мижлок.
5 Ó fi iná ran àwọn ètùfù tí ó so náà, ó sì jọ̀wọ́ wọn lọ́wọ́ lọ sínú àwọn oko ọkà àwọn Filistini. Ó jó àwọn pòpóòrò ọkà tí ó dúró àti àwọn tí a dì ní ìtí, ìtí, pẹ̀lú àwọn ọgbà àjàrà àti olifi.
А апринс фэклииле, а дат друмул вулпилор ын грынеле филистенилор ши а апринс астфел атыт стогуриле де снопь, кыт ши грыул каре ера ын пичоаре, ба ынкэ ши грэдиниле де мэслинь.
6 Nígbà tí àwọn Filistini béèrè pé, “Ta ni ó ṣe èyí?” Wọ́n dá wọn lóhùn pé, “Samsoni ará Timna ni, nítorí a gba ìyàwó rẹ̀ fún ọ̀rẹ́ rẹ̀.” Nítorí náà àwọn Filistini lọ wọ́n sì sun obìnrin náà àti baba rẹ̀.
Филистений ау зис: „Чине а фэкут лукрул ачеста?” Ли с-а рэспунс: „Самсон, ӂинереле Тимнеанулуй, пентру кэ ачеста й-а луат неваста ши а дат-о товарэшулуй луй.” Ши филистений с-ау суит ши ау арс-о пе еа ши пе татэл ей.
7 Samsoni sọ fún un pé, “Nítorí pé ẹ̀yin ṣe èyí, èmi ó gbẹ̀san lára yín, lẹ́yìn náà èmi yóò sì dẹ́kun.”
Самсон ле-а зис: „Аша фачець? Ну вой ынчета декыт дупэ че мэ вой рэзбуна пе вой.”
8 Ó kọlù wọ́n pẹ̀lú ìbínú àti agbára ńlá, ó sì pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú wọn. Lẹ́yìn náà ni ó lọ, ó sì dúró nínú ihò àpáta kan nínú àpáta Etamu.
Й-а бэтут аспру, пе спате ши пе пынтече; апой с-а коборыт ши а локуит ын крэпэтура стынчий Етам.
9 Àwọn ará Filistini sì dìde ogun sí Juda, wọ́n ti tan ara wọn ká sí agbègbè Lehi.
Атунч, филистений ау порнит, ау тэбэрыт ын Иуда ши с-ау ынтинс пынэ ла Лехи.
10 Àwọn ọkùnrin Juda sì béèrè pé, “Èéṣe tí ẹ fi wá gbóguntì wá?” Ìdáhùn wọn ni pé, “A wá láti mú Samsoni ní ìgbèkùn, kí a ṣe sí i bí òun ti ṣe sí wa.”
Бэрбаций дин Иуда ау зис: „Пентру че в-аць суит ымпотрива ноастрэ?” Ей ау рэспунс: „Не-ам суит сэ легэм пе Самсон, ка сэ-й фачем аша кум не-а фэкут ел ноуэ.”
11 Nígbà náà ni ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkùnrin láti Juda sọ̀kalẹ̀ lọ sí ihò àpáta nínú àpáta Etamu, wọ́n sì sọ fún Samsoni pé, “Kò ti yé ọ pé àwọn Filistini ní ń ṣe alákòóso lórí wa? Kí ni o ṣe sí wa?” Òun sì dáhùn pé, “Ohun tí wọ́n ṣe sí mi ni èmi náà ṣe sí wọn.”
Атунч, трей мий де бэрбаць дин Иуда с-ау коборыт ла крэпэтура стынчий Етам ши ау зис луй Самсон: „Ну штий кэ филистений стэпынеск песте ной? Че не-ай фэкут деч?” Ел ле-а рэспунс: „Ле-ам фэкут аша кум мь-ау фэкут ши ей мие.”
12 Wọ́n wí pé, “Àwa wá láti dè ọ́, kí a sì fi ọ́ lé àwọn Filistini lọ́wọ́.” Samsoni wí pé, “Ẹ búra fún mi pé, ẹ̀yin kì yóò fúnra yín pa mí.”
Ей й-ау зис: „Ной не-ам коборыт сэ те легэм, ка сэ те дэм ын мыниле филистенилор.” Самсон ле-а зис: „Жураци-мь кэ ну мэ вець оморы.”
13 “Àwa gbà,” ni ìdáhùn wọn. “Àwa yóò kàn dè ọ́, àwa yóò sì fi ọ́ lé wọn lọ́wọ́, àwa kì yóò pa ọ́.” Wọ́n sì dé pẹ̀lú okùn tuntun méjì, wọ́n sì mú u jáde wá láti ihò àpáta náà.
Ей й-ау рэспунс: „Ну, врем нумай сэ те легэм ши сэ те дэм ын мыниле лор, дар ну те вом оморы.” Ши л-ау легат ку доуэ фуний ной ши л-ау скос дин стынкэ.
14 Bí ó ti súnmọ́ Lehi, àwọn Filistini ń pariwo bí wọ́n ṣe ń tò bọ̀. Ẹ̀mí Olúwa bà lé e pẹ̀lú agbára. Àwọn okùn ọwọ́ rẹ̀ dàbí òwú tí ó jóná, ìdè ọwọ́ rẹ̀ já kúrò ní ọwọ́ rẹ̀.
Кынд а ажунс ла Лехи, филистений ау ынчепут сэ стриӂе де букурие ынаинтя луй. Атунч, Духул Домнулуй а венит песте ел. Фунииле пе каре ле авя ла браце с-ау фэкут ка ниште фире де ин арс ын фок ши легэтуриле й-ау кэзут де пе мынь.
15 Nígbà tí ó rí egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tuntun kan, ó mú un, ó sì fi pa ẹgbẹ̀rún ọkùnrin.
Ел а гэсит о фалкэ де мэгар неускатэ ынкэ, а ынтинс мына ши а луат-о ши а учис ку еа о мие де оамень.
16 Samsoni sì wí pé, “Pẹ̀lú egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan, mo sọ wọ́n di òkìtì kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Pẹ̀lú egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan, mo ti pa ẹgbẹ̀rún ọkùnrin.”
Ши Самсон а зис: „Ку о фалкэ де мэгар, о грэмадэ, доуэ грэмезь; Ку о фалкэ де мэгар, ам учис о мие де оамень.”
17 Nígbà tí ó dákẹ́ ọ̀rọ̀ í sọ, ó ju egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ náà nù, wọ́n sì pe ibẹ̀ ní Ramati-Lehi (ìtumọ̀ rẹ̀ jẹ́ egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ pa).
Дупэ че а испрэвит де ворбит, а арункат фалка дин мынэ. Ши локул ачела с-а нумит Рамат-Лехи.
18 Nítorí tí òǹgbẹ gbẹ ẹ́ gidigidi, ó ké pe Olúwa, wí pé, “Ìwọ ti fún ìránṣẹ́ ní ìṣẹ́gun tí ó tóbi yìí. Ṣé èmi yóò ha kú pẹ̀lú òǹgbẹ, kí èmi sì ṣubú sí ọwọ́ àwọn aláìkọlà ènìyàn?”
Фиинду-й фоарте сете, а стригат кэтре Домнул ши а зис: „Ту ай ынгэдуит, прин мына робулуй Тэу, ачастэ маре избэвире ши акум сэ мор де сете ши сэ кад ын мыниле челор нетэяць ымпрежур?”
19 Nígbà náà ni Ọlọ́run la kòtò ìsun omi tí ó wà ní Lehi, omi sì tú jáde láti inú rẹ̀. Nígbà tí Samsoni mú mi tan, agbára rẹ̀ sì padà, ọkàn sì sọjí, fún ìdí èyí wọ́n pe ìsun omi náà ni. Ẹni Hakkore (orísun ẹni tí ó pe Ọlọ́run) èyí tí ó sì wà ní Lehi di òní.
Думнезеу а деспикат крэпэтура стынчий дин Лехи ши а ешит апэ дин еа. Самсон а бэут, духул и с-а ынтремат ши с-а ынвиорат. Де ачея с-а нумит изворул ачела Ен-Хакоре; ел есте ши астэзь ла Лехи.
20 Samsoni ṣe ìdájọ́ Israẹli fún ogún ọdún ní àkókò àwọn ará Filistini.
Самсон а фост доуэзечь де ань жудекэтор ын Исраел пе время филистенилор.

< Judges 15 >