< Judges 15 >

1 Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, ní àkókò ìkórè alikama, Samsoni mú ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan láti bẹ ìyàwó rẹ̀ wò. Ó ní, “Èmi yóò wọ yàrá ìyàwó mi lọ.” Ṣùgbọ́n baba rẹ̀ kò gbà á láààyè láti wọlé.
Otiia i muri iho, na ka haere a Hamahona, me tetahi kuao koati, i te wa o te kotinga witi, kia kite i tana wahine, a ka mea, Ka haere ahau ki taku wahine ki roto ki te whare moenga. Otiia kihai ia i tukua e te papa o te wahine kia haere ki roto.
2 Baba ìyàwó dá a lóhùn pé, “Ó dá mi lójú pé o kórìíra rẹ̀, torí náà mo ti fi fún ọ̀rẹ́ rẹ, ṣe bí àbúrò rẹ̀ obìnrin kò ha lẹ́wà jùlọ? Fẹ́ ẹ dípò rẹ̀.”
I mea hoki tona papa, i tino mea ahau e kino rawa ana koe ki a ia; na hoatu ana ia e ahau ma tou hoa; kahore ianei tona teina e pai atu i a ia? Tena kia riro tenei i a koe hei utu mo tera.
3 Samsoni dáhùn pé, “Ní àkókò yìí tí mo bá ṣe àwọn Filistini ní ibi èmi yóò jẹ́ aláìjẹ̀bi.”
Na ka mea a Hamahona ki a ratou, Engari i tenei, ka kore hara ahau ki nga Pirihitini, ina tukino ahau ki a ratou.
4 Samsoni sì jáde lọ, ó mú ọ̀ọ́dúnrún kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ ó so ìrù wọn mọ́ ara wọn ní méjì méjì. Ó mú ètùfù iná, ó so ó mọ́ àwọn ìrù tí ó so pọ̀.
Na haere ana a Hamahona, a hopukia ana e ia e toru rau nga pokiha; katahi ka tikina etahi rama e ia, a whakaangahia atu ana nga hiawero ki a raua whaka hiawero, a whakanohoia iho he rama ki waenganui o nga hiawero e rua.
5 Ó fi iná ran àwọn ètùfù tí ó so náà, ó sì jọ̀wọ́ wọn lọ́wọ́ lọ sínú àwọn oko ọkà àwọn Filistini. Ó jó àwọn pòpóòrò ọkà tí ó dúró àti àwọn tí a dì ní ìtí, ìtí, pẹ̀lú àwọn ọgbà àjàrà àti olifi.
Na ka tahuna e ia nga rama, a tukua atu ana ki te witi a nga Pirihitini, wera ake nga puranga witi, me nga mea ano e tu ana; nga mara waina, oriwa ano hoki.
6 Nígbà tí àwọn Filistini béèrè pé, “Ta ni ó ṣe èyí?” Wọ́n dá wọn lóhùn pé, “Samsoni ará Timna ni, nítorí a gba ìyàwó rẹ̀ fún ọ̀rẹ́ rẹ̀.” Nítorí náà àwọn Filistini lọ wọ́n sì sun obìnrin náà àti baba rẹ̀.
A ka ki nga Pirihitini, Na wai tenei mahi? na ka korerotia, Na Hamahona hunaonga a te Timini; mona i tango i tana wahine, a hoatu ana ki tona hoa. Katahi ka haere nga Pirihitini, a tahuna ake e ratou te wahine raua ko tona papa ki te ahi.
7 Samsoni sọ fún un pé, “Nítorí pé ẹ̀yin ṣe èyí, èmi ó gbẹ̀san lára yín, lẹ́yìn náà èmi yóò sì dẹ́kun.”
Na ka mea a Hamahona ki a ratou, Ahakoa kua meatia tenei e koutou, he pono ka rapu utu ano ahau i a koutou, a muri iho ka mutu taku.
8 Ó kọlù wọ́n pẹ̀lú ìbínú àti agbára ńlá, ó sì pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú wọn. Lẹ́yìn náà ni ó lọ, ó sì dúró nínú ihò àpáta kan nínú àpáta Etamu.
Na tukitukia ana ratou e ia, te papa, te huha, he nui te patunga, a haere ana, noho ana i te kapiti o te kamaka i Etama.
9 Àwọn ará Filistini sì dìde ogun sí Juda, wọ́n ti tan ara wọn ká sí agbègbè Lehi.
Katahi ka haere nga Pirihitini, noho ana i Hura, tohatoha noa atu i Rehi.
10 Àwọn ọkùnrin Juda sì béèrè pé, “Èéṣe tí ẹ fi wá gbóguntì wá?” Ìdáhùn wọn ni pé, “A wá láti mú Samsoni ní ìgbèkùn, kí a ṣe sí i bí òun ti ṣe sí wa.”
Na ka mea nga tangata o Hura, He aha koutou i haere mai ai ki a matou? Na ka mea ratou, He here i a Hamahona i haere mai ai matou, kia meatia ki a ia tana i mea ai ki a matou.
11 Nígbà náà ni ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkùnrin láti Juda sọ̀kalẹ̀ lọ sí ihò àpáta nínú àpáta Etamu, wọ́n sì sọ fún Samsoni pé, “Kò ti yé ọ pé àwọn Filistini ní ń ṣe alákòóso lórí wa? Kí ni o ṣe sí wa?” Òun sì dáhùn pé, “Ohun tí wọ́n ṣe sí mi ni èmi náà ṣe sí wọn.”
Katahi ka haere etahi tangata o Hura, e toru nga mano, ki te kapiti o te kohatu i Etama, ka mea ki a Hamahona, Kahore ianei koe e mohio he rangatira no tatou nga Pirihitini? he mahi aha tenei nau ki a matou? Na ka mea ia ki a ratou, Rite tonu ki ta ratou i mea mai ai ki ahau, taku i mea ai ki a ratou.
12 Wọ́n wí pé, “Àwa wá láti dè ọ́, kí a sì fi ọ́ lé àwọn Filistini lọ́wọ́.” Samsoni wí pé, “Ẹ búra fún mi pé, ẹ̀yin kì yóò fúnra yín pa mí.”
Na ka mea ratou ki a ia, He here i a koe i haere mai ai matou, kia hoatu koe ki te ringa o nga Pirihitini. Na ka mea a Hamahona ki a ratou, Oati mai ki ahau e kore koutou na e rere ki runga ki ahau.
13 “Àwa gbà,” ni ìdáhùn wọn. “Àwa yóò kàn dè ọ́, àwa yóò sì fi ọ́ lé wọn lọ́wọ́, àwa kì yóò pa ọ́.” Wọ́n sì dé pẹ̀lú okùn tuntun méjì, wọ́n sì mú u jáde wá láti ihò àpáta náà.
Na ka korero ratou ki a ia, ka mea, Kahore; erangi me ata here koe e matou, a ka hoatu koe ki to ratou ringa: ko te whakamate ia, e kore matou e whakamate i a koe. Na ka herea ia e ratou ki nga taura hou e rua, a kawea atu ana i te kamaka.
14 Bí ó ti súnmọ́ Lehi, àwọn Filistini ń pariwo bí wọ́n ṣe ń tò bọ̀. Ẹ̀mí Olúwa bà lé e pẹ̀lú agbára. Àwọn okùn ọwọ́ rẹ̀ dàbí òwú tí ó jóná, ìdè ọwọ́ rẹ̀ já kúrò ní ọwọ́ rẹ̀.
I tona taenga ki Rehi, na ka hamama nga Pirihitini i te tutakitanga ki a ia. Ko te tino putanga o te wairua o Ihowa ki runga ki a ia: na rite tonu nga taura i ona ringa ki te muka kua wera i te ahi; harotu noa iho nga here o ona ringa.
15 Nígbà tí ó rí egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tuntun kan, ó mú un, ó sì fi pa ẹgbẹ̀rún ọkùnrin.
Na kia pono ia ki tetahi kauae kaihe, he mea hou, a totoro atu ana tona ringa, tangohia ake ana; na kotahi mano tangata i patua e ia ki taua mea.
16 Samsoni sì wí pé, “Pẹ̀lú egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan, mo sọ wọ́n di òkìtì kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Pẹ̀lú egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan, mo ti pa ẹgbẹ̀rún ọkùnrin.”
Na ka mea a Hamahona, Na te kauae kaihe, puranga atu, puranga atu; na te kauae kaihe, patua iho e ahau kotahi mano tangata.
17 Nígbà tí ó dákẹ́ ọ̀rọ̀ í sọ, ó ju egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ náà nù, wọ́n sì pe ibẹ̀ ní Ramati-Lehi (ìtumọ̀ rẹ̀ jẹ́ egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ pa).
A, i te mutunga o tana korero, na maka atu ana e ia te kauae i tona ringa, a huaina iho te ingoa o tena wahi, Ko Ramatarehi.
18 Nítorí tí òǹgbẹ gbẹ ẹ́ gidigidi, ó ké pe Olúwa, wí pé, “Ìwọ ti fún ìránṣẹ́ ní ìṣẹ́gun tí ó tóbi yìí. Ṣé èmi yóò ha kú pẹ̀lú òǹgbẹ, kí èmi sì ṣubú sí ọwọ́ àwọn aláìkọlà ènìyàn?”
Na nui rawa tona matewai, a ka karanga ia ki a Ihowa, ka mea, Nau i homai tenei whakaoranga nui ki te ringa o tau pononga, a ka mate nei ahau i te matewai, ka hinga hoki i te ringa o te hunga kokotikore?
19 Nígbà náà ni Ọlọ́run la kòtò ìsun omi tí ó wà ní Lehi, omi sì tú jáde láti inú rẹ̀. Nígbà tí Samsoni mú mi tan, agbára rẹ̀ sì padà, ọkàn sì sọjí, fún ìdí èyí wọ́n pe ìsun omi náà ni. Ẹni Hakkore (orísun ẹni tí ó pe Ọlọ́run) èyí tí ó sì wà ní Lehi di òní.
Na ka wahia e te Atua he poka i Rehi, a ka puta mai he wai i reira. Katahi ka inu ia, a hoki ana tona wairua, na kua ora ia. Na reira i huaina ai to reira ingoa, Ko Enehakore: kei Rehi na ano a tae noa ki tenei ra.
20 Samsoni ṣe ìdájọ́ Israẹli fún ogún ọdún ní àkókò àwọn ará Filistini.
Na e rua tekau nga tau i whakarite ai ia mo Iharaira i nga ra o nga Pirihitini.

< Judges 15 >