< Judges 13 >

1 Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Olúwa sì fi wọ́n lé àwọn ará Filistini lọ́wọ́ fún ogójì ọdún.
Și copiii lui Israel au făcut din nou ce este rău în ochii DOMNULUI; și DOMNUL i-a dat în mâna filistenilor patruzeci de ani.
2 Ọkùnrin ará Sora kan wà, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Manoa láti ẹ̀yà Dani. Aya rẹ̀ yàgàn kò sì bímọ.
Și a fost un anumit bărbat din Țoreea, din familia daniților, al cărui nume era Manoah; și soția lui era stearpă și nu năștea.
3 Angẹli Olúwa fi ara han obìnrin náà, ó sì wí fún un pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ yàgàn, ìwọ kò sì tí ì bímọ, ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan.
Și îngerul DOMNULUI s-a arătat femeii și i-a spus: Iată acum, tu ești stearpă și nu naști, dar vei rămâne însărcinată și vei naște un fiu.
4 Báyìí rí i dájúdájú pé ìwọ kò mu wáìnì tàbí ọtí líle kankan àti pé ìwọ kò jẹ ohun aláìmọ́ kankan,
Și acum ia seama, te rog, și să nu bei vin, nici băutură tare și să nu mănânci vreun lucru necurat,
5 nítorí ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan. Má ṣe fi abẹ kan orí rẹ̀, nítorí pé Nasiri, ẹni ìyàsọ́tọ̀ fún Ọlọ́run ni ọmọ náà yóò jẹ́ láti ọjọ́ ìbí rẹ̀. Òun ni yóò bẹ̀rẹ̀ ìdáǹdè àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní ọwọ́ àwọn ará Filistini.”
Pentru că, iată, vei rămâne însărcinată și vei naște un fiu; și brici nu va trece pe capul lui, căci copilul va fi nazireu pentru Dumnezeu din pântece; și el va începe să elibereze pe Israel din mâna filistenilor.
6 Nígbà náà ni obìnrin náà tọ ọkọ rẹ̀ lọ, o sì sọ fún un wí pé, “Ènìyàn Ọlọ́run kan tọ̀ mí wá. Ó jọ angẹli Ọlọ́run, ó ba ènìyàn lẹ́rù gidigidi. Èmi kò béèrè ibi tí ó ti wá, òun náà kò sì sọ orúkọ rẹ̀ fún mi.
Atunci femeia a venit și a spus soțului ei, zicând: Un om al lui Dumnezeu a venit la mine și înfățișarea lui era ca înfățișarea unui înger al lui Dumnezeu, foarte înfricoșătoare; dar nu l-am întrebat de unde era, nici nu mi-a spus numele său;
7 Ṣùgbọ́n ó sọ fún mi wí pé, ‘Ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan, fún ìdí èyí, má ṣe mu wáìnì tàbí àwọn ọtí líle mìíràn bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ má ṣe jẹ ohunkóhun tí í ṣe aláìmọ́, nítorí pé Nasiri Ọlọ́run ni ọmọ náà yóò jẹ́ láti ọjọ́ ìbí rẹ̀ títí di ọjọ́ ikú rẹ̀.’”
Ci mi-a zis: Iată, vei rămâne însărcinată și vei naște un fiu; și acum să nu bei vin, nici băutură tare, nici să nu mănânci vreun lucru necurat, căci copilul va fi nazireu pentru Dumnezeu din pântece, până în ziua morții sale.
8 Nígbà náà ni Manoa gbàdúrà sí Olúwa wí pé, “Háà Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ènìyàn Ọlọ́run tí ìwọ rán sí wa padà tọ̀ wá wá láti kọ́ wa bí àwa yóò ti ṣe tọ́ ọmọ tí àwa yóò bí náà.”
Atunci Manoah a implorat pe DOMNUL și a spus: O, DOMNUL meu, să mai vină la noi omul lui Dumnezeu, pe care l-ai trimis și să ne învețe ce să facem cu copilul care se va naște.
9 Ọlọ́run fetí sí ohùn Manoa, angẹli Ọlọ́run náà tún padà tọ obìnrin náà wá nígbà tí ó wà ní oko ṣùgbọ́n ọkọ rẹ̀ Manoa kò sí ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
Și Dumnezeu a dat ascultare la vocea lui Manoah; și îngerul lui Dumnezeu a venit din nou la femeie pe când ședea ea în câmp; dar Manoah, soțul ei, nu era cu ea.
10 Nítorí náà ni obìnrin náà ṣe yára lọ sọ fún ọkọ rẹ̀ pé, “Ọkùnrin tí ó fi ara hàn mí ní ọjọ́sí ti tún padà wá.”
Și femeia s-a grăbit și a alergat și i-a arătat soțului ei, spunându-i: Iată, mi s-a arătat omul care a venit la mine în ziua aceea.
11 Manoa yára dìde, ó sì tẹ̀lé aya rẹ̀, nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ ọkùnrin náà ó ní, “Ǹjẹ́ ìwọ ni o bá obìnrin yìí sọ̀rọ̀?” Ọkùnrin náà dáhùn pé, “Èmi ni.”
Și Manoah s-a ridicat și a mers după soția sa și a venit la omul acela și i-a spus: Tu ești cel care a vorbit femeii? Iar el a spus: Eu sunt.
12 Manoa bi ọkùnrin náà pé, “Nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ bá ṣẹ kí ni yóò jẹ́ ìlànà fún ìgbé ayé àti iṣẹ́ ọmọ náà?”
Și Manoah a spus: Să se împlinească acum cuvintele tale. Cum să creștem copilul și cum să ne purtăm cu el?
13 Angẹli Olúwa náà dáhùn wí pé, “Aya rẹ gbọdọ̀ ṣe gbogbo ohun tí mo ti sọ fún un
Și îngerul DOMNULUI i-a spus lui Manoah: Femeia să ia seama la tot ce i-am spus.
14 kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí ó bá ti inú èso àjàrà jáde wá, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ mu wáìnì tàbí àwọn ọtí líle mìíràn tàbí jẹ ohunkóhun tí ó bá jẹ́ aláìmọ́. Ó ní láti ṣe ohun gbogbo tí mo ti pàṣẹ fún un.”
Să nu mănânce nimic din ce iese din viță, nici să nu bea vin sau băutură tare, nici să nu mănânce vreun lucru necurat, să păzească tot ce i-am poruncit.
15 Manoa sọ fún angẹli Olúwa náà pé, “Jọ̀wọ́ dára dúró títí àwa yóò fi pèsè ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan fún ọ.”
Și Manoah a spus îngerului DOMNULUI: Te rog, lasă-ne să te reținem, până când îți vom fi pregătit un ied dintre capre.
16 Angẹli Olúwa náà dá Manoa lóhùn pé, “Bí ẹ̀yin tilẹ̀ dá mi dúró, èmi kì yóò jẹ ọ̀kankan nínú oúnjẹ tí ẹ̀yin yóò pèsè. Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá fẹ́ ẹ pèsè ọrẹ ẹbọ sísun, kí ẹ sì fi rú ẹbọ sí Olúwa.” (Manoa kò mọ̀ pé angẹli Olúwa ní i ṣe.)
Și îngerul DOMNULUI i-a spus lui Manoah: Chiar de m-ai reține, nu voi mânca din pâinea ta; și dacă vrei să aduci o ofrandă arsă, adu-o DOMNULUI. Pentru că Manoah nu știa că era un înger al DOMNULUI.
17 Manoa sì béèrè lọ́wọ́ angẹli Olúwa náà pé, “Kí ni orúkọ rẹ, kí àwa bá à lè fi ọlá fún ọ nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ bá ṣẹ?”
Și Manoah a spus îngerului DOMNULUI: Care este numele tău, ca să te onorăm când se vor împlini spusele tale?
18 Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa náà dáhùn pé, “Èéṣe tí ìwọ ń béèrè orúkọ mi? Ìyanu ni, ó kọjá ìmọ̀.”
Și îngerul DOMNULUI i-a spus: De ce întrebi de numele meu, văzând că este o taină?
19 Lẹ́yìn náà ni Manoa mú ọ̀dọ́ ewúrẹ́, pẹ̀lú ẹbọ ọkà, ó sì fi rú ẹbọ lórí àpáta kan sí Olúwa. Nígbà tí Manoa àti ìyàwó dúró tí wọn ń wò Olúwa ṣe ohun ìyanu kan.
Astfel Manoah a luat un ied împreună cu un dar de mâncare și le-a oferit DOMNULUI pe o stâncă; și îngerul a făcut ceva minunat; și Manoah și soția lui se uitau.
20 Bí ẹ̀là ahọ́n iná ti là jáde láti ibi pẹpẹ ìrúbọ náà sí ọ̀run, angẹli Olúwa gòkè re ọ̀run láàrín ahọ́n iná náà. Nígbà tí wọ́n rí ìṣẹ̀lẹ̀ yìí, Manoa àti aya rẹ̀ wólẹ̀ wọ́n sì dojúbolẹ̀.
Și s-a întâmplat, pe când se înălța flacăra de pe altar spre cer, că îngerul DOMNULUI s-a înălțat în flacăra altarului. Și Manoah și soția lui s-au uitat și au căzut cu fețele la pământ.
21 Nígbà tí angẹli Olúwa náà kò tún fi ara rẹ̀ han Manoa àti aya rẹ̀ mọ́, Manoa wá mọ̀ pé angẹli Olúwa ni.
Dar îngerul DOMNULUI nu s-a mai arătat lui Manoah și soției sale. Atunci Manoah a cunoscut că acela era un înger al DOMNULUI.
22 Manoa sọ fún aya rẹ̀ pé, “Dájúdájú àwa yóò kú nítorí àwa ti fi ojú rí Ọlọ́run.”
Și Manoah a spus soției sale: Vom muri negreșit, pentru că am văzut pe Dumnezeu.
23 Ṣùgbọ́n ìyàwó rẹ̀ dáhùn pé, “Bí Olúwa bá ní èrò àti pa wá kò bá tí gba ẹbọ sísun àti ọrẹ ọkà wa, tàbí fi gbogbo nǹkan wọ̀nyí hàn wá tó sọ nǹkan ìyanu yìí fún wa.”
Dar soția lui i-a spus: Dacă DOMNULUI i-ar fi făcut plăcere să ne omoare, nu ar fi primit o ofrandă arsă și un dar de mâncare din mâinile noastre, nici nu ne-ar fi arătat toate acestea, nici nu ne-ar fi spus acum lucruri ca acestea.
24 Obìnrin náà sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Samsoni. Ọmọ náà dàgbà Olúwa sì bùkún un.
Și femeia a născut un fiu și i-a pus numele Samson, și copilul a crescut și DOMNUL l-a binecuvântat.
25 Ẹ̀mí Olúwa sì bẹ̀rẹ̀ sí ru sókè nígbà tí ó wà ní Mahane-Dani ní agbede-méjì Sora àti Eṣtaoli.
Și Duhul DOMNULUI a început să îl miște în tabăra lui Dan, între Țoreea și Eștaol.

< Judges 13 >