< Judges 13 >
1 Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Olúwa sì fi wọ́n lé àwọn ará Filistini lọ́wọ́ fún ogójì ọdún.
Un Israēla bērni darīja joprojām, kas Tam Kungam nepatika; tad Tas Kungs tos nodeva Fīlistu rokā četrdesmit gadus.
2 Ọkùnrin ará Sora kan wà, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Manoa láti ẹ̀yà Dani. Aya rẹ̀ yàgàn kò sì bímọ.
Un tur bija viens vīrs no Careas, no Dana cilts, un viņa vārds bija Manoūs, un viņa sieva bija neauglīga un nedzemdēja.
3 Angẹli Olúwa fi ara han obìnrin náà, ó sì wí fún un pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ yàgàn, ìwọ kò sì tí ì bímọ, ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan.
Un Tā Kunga eņģelis parādījās tai sievai un uz to sacīja: redzi, tu esi neauglīga un neesi dzemdējusi, bet tu tapsi grūta un dzemdēsi dēlu.
4 Báyìí rí i dájúdájú pé ìwọ kò mu wáìnì tàbí ọtí líle kankan àti pé ìwọ kò jẹ ohun aláìmọ́ kankan,
Tad nu sargies un nedzer vīna nedz stipra dzēriena un neēd nekā, kas nešķīsts.
5 nítorí ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan. Má ṣe fi abẹ kan orí rẹ̀, nítorí pé Nasiri, ẹni ìyàsọ́tọ̀ fún Ọlọ́run ni ọmọ náà yóò jẹ́ láti ọjọ́ ìbí rẹ̀. Òun ni yóò bẹ̀rẹ̀ ìdáǹdè àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní ọwọ́ àwọn ará Filistini.”
Jo redzi, tu tapsi grūta un dzemdēsi dēlu, kam uz galvu nebūs nākt nekādam dzenamam nazim, jo tas puisis būs Dievam svētīts (nazīrs) no mātes miesām, un viņš sāks Israēli izpestīt no Fīlistu rokas.
6 Nígbà náà ni obìnrin náà tọ ọkọ rẹ̀ lọ, o sì sọ fún un wí pé, “Ènìyàn Ọlọ́run kan tọ̀ mí wá. Ó jọ angẹli Ọlọ́run, ó ba ènìyàn lẹ́rù gidigidi. Èmi kò béèrè ibi tí ó ti wá, òun náà kò sì sọ orúkọ rẹ̀ fún mi.
Tad tā sieva nāca un runāja uz savu vīru un sacīja: viens Dieva vīrs pie manis atnāca; viņa ģīmis bija kā Dieva eņģeļa ģīmis, ļoti bijājams, un es viņu nevaicāju, no kurienes tas esot, un viņš man arī savu vārdu neteica.
7 Ṣùgbọ́n ó sọ fún mi wí pé, ‘Ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan, fún ìdí èyí, má ṣe mu wáìnì tàbí àwọn ọtí líle mìíràn bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ má ṣe jẹ ohunkóhun tí í ṣe aláìmọ́, nítorí pé Nasiri Ọlọ́run ni ọmọ náà yóò jẹ́ láti ọjọ́ ìbí rẹ̀ títí di ọjọ́ ikú rẹ̀.’”
Bet viņš uz mani sacīja: redzi, tu tapsi grūta un dzemdēsi dēlu, un nu nedzer vīna nedz stipra dzēriena, nedz ēd ko, kas nešķīsts, jo tas puisis būs Dievam svētīts no mātes miesām līdz pat savai nāves dienai.
8 Nígbà náà ni Manoa gbàdúrà sí Olúwa wí pé, “Háà Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ènìyàn Ọlọ́run tí ìwọ rán sí wa padà tọ̀ wá wá láti kọ́ wa bí àwa yóò ti ṣe tọ́ ọmọ tí àwa yóò bí náà.”
Tad Manoūs pielūdza To Kungu un sacīja: Ak Kungs, lai jel tas Dieva vīrs, ko Tu esi sūtījis, atkal pie mums atnāk un mums māca, ko lai ar to bērnu darām, kas piedzims.
9 Ọlọ́run fetí sí ohùn Manoa, angẹli Ọlọ́run náà tún padà tọ obìnrin náà wá nígbà tí ó wà ní oko ṣùgbọ́n ọkọ rẹ̀ Manoa kò sí ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
Un Dievs paklausīja Manoūs balsi, un tas Dieva eņģelis nāca atkal pie tās sievas; un viņa sēdēja tīrumā, bet Manoūs, viņas vīrs, nebija pie viņas.
10 Nítorí náà ni obìnrin náà ṣe yára lọ sọ fún ọkọ rẹ̀ pé, “Ọkùnrin tí ó fi ara hàn mí ní ọjọ́sí ti tún padà wá.”
Tad tā sieva steidzās un skrēja un to pasacīja savam vīram, un uz to sacīja: redzi, tas vīrs man parādījies, kas tai dienā pie manis nāca.
11 Manoa yára dìde, ó sì tẹ̀lé aya rẹ̀, nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ ọkùnrin náà ó ní, “Ǹjẹ́ ìwọ ni o bá obìnrin yìí sọ̀rọ̀?” Ọkùnrin náà dáhùn pé, “Èmi ni.”
Tad Manoūs cēlās un gāja savai sievai pakaļ un nāca pie tā vīra un uz to sacīja: vai tu esi tas vīrs, kas uz to sievu runājis? Un tas sacīja: es tas esmu.
12 Manoa bi ọkùnrin náà pé, “Nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ bá ṣẹ kí ni yóò jẹ́ ìlànà fún ìgbé ayé àti iṣẹ́ ọmọ náà?”
Tad Manoūs sacīja: kad nu tas notiks, ko tu sacījis, kāds tikums tad būs tam zēnam un kāds būs viņa darbs?
13 Angẹli Olúwa náà dáhùn wí pé, “Aya rẹ gbọdọ̀ ṣe gbogbo ohun tí mo ti sọ fún un
Un Tā Kunga eņģelis sacīja uz Manoū: no visa, ko es uz to sievu esmu runājis, viņai būs sargāties.
14 kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí ó bá ti inú èso àjàrà jáde wá, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ mu wáìnì tàbí àwọn ọtí líle mìíràn tàbí jẹ ohunkóhun tí ó bá jẹ́ aláìmọ́. Ó ní láti ṣe ohun gbogbo tí mo ti pàṣẹ fún un.”
Viņai nebūs ēst nekā, kas no vīna koka izaug, un viņai nebūs dzert ne vīna, ne stipra dzēriena, nedz ēst, kas nešķīsts, visu, ko es viņai esmu pavēlējis, viņai būs turēt.
15 Manoa sọ fún angẹli Olúwa náà pé, “Jọ̀wọ́ dára dúró títí àwa yóò fi pèsè ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan fún ọ.”
Tad Manoūs sacīja uz Tā Kunga eņģeli: lūdzams, pakavējies un mēs sataisīsim priekš tevis kazlēnu.
16 Angẹli Olúwa náà dá Manoa lóhùn pé, “Bí ẹ̀yin tilẹ̀ dá mi dúró, èmi kì yóò jẹ ọ̀kankan nínú oúnjẹ tí ẹ̀yin yóò pèsè. Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá fẹ́ ẹ pèsè ọrẹ ẹbọ sísun, kí ẹ sì fi rú ẹbọ sí Olúwa.” (Manoa kò mọ̀ pé angẹli Olúwa ní i ṣe.)
Tad Tā Kunga eņģelis sacīja uz Manoū; jebšu tu mani uzkavētu, tomēr es no tavas maizes neēdīšu, bet ja tu gribi dedzināmo upuri pienest, to tu Tam Kungam vari upurēt. Jo Manoūs nezināja, viņu esam Tā Kunga eņģeli.
17 Manoa sì béèrè lọ́wọ́ angẹli Olúwa náà pé, “Kí ni orúkọ rẹ, kí àwa bá à lè fi ọlá fún ọ nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ bá ṣẹ?”
Un Manoūs sacīja uz Tā Kunga eņģeli: kā tavs vārds? Ka tevi varam godāt, kad notiks pēc tava vārda.
18 Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa náà dáhùn pé, “Èéṣe tí ìwọ ń béèrè orúkọ mi? Ìyanu ni, ó kọjá ìmọ̀.”
Tad Tā Kunga eņģelis uz viņu sacīja: kāpēc tu tā vaicā pēc Mana Vārda, kas taču ir brīnišķīgs?
19 Lẹ́yìn náà ni Manoa mú ọ̀dọ́ ewúrẹ́, pẹ̀lú ẹbọ ọkà, ó sì fi rú ẹbọ lórí àpáta kan sí Olúwa. Nígbà tí Manoa àti ìyàwó dúró tí wọn ń wò Olúwa ṣe ohun ìyanu kan.
Tad Manoūs ņēma kazlēnu un to ēdamo upuri, un to upurēja Tam Kungam uz tās klints; un viņš darīja brīnumu un Manoūs un viņa sieva skatījās.
20 Bí ẹ̀là ahọ́n iná ti là jáde láti ibi pẹpẹ ìrúbọ náà sí ọ̀run, angẹli Olúwa gòkè re ọ̀run láàrín ahọ́n iná náà. Nígbà tí wọ́n rí ìṣẹ̀lẹ̀ yìí, Manoa àti aya rẹ̀ wólẹ̀ wọ́n sì dojúbolẹ̀.
Jo kad liesma no altāra virsas šāvās pret debesi, tad Tā Kunga eņģelis uzkāpa altāra liesmā. Un Manoūs un viņa sieva to redzēja un metās pie zemes uz saviem vaigiem.
21 Nígbà tí angẹli Olúwa náà kò tún fi ara rẹ̀ han Manoa àti aya rẹ̀ mọ́, Manoa wá mọ̀ pé angẹli Olúwa ni.
Un Tā Kunga eņģelis neparādījās vairs ne Manoūm, nedz viņa sievai. Tad Manoūs atzina, ka tas bija Tā Kunga eņģelis.
22 Manoa sọ fún aya rẹ̀ pé, “Dájúdájú àwa yóò kú nítorí àwa ti fi ojú rí Ọlọ́run.”
Un Manoūs sacīja uz savu sievu: mēs tiešām mirsim, jo mēs esam Dievu redzējuši.
23 Ṣùgbọ́n ìyàwó rẹ̀ dáhùn pé, “Bí Olúwa bá ní èrò àti pa wá kò bá tí gba ẹbọ sísun àti ọrẹ ọkà wa, tàbí fi gbogbo nǹkan wọ̀nyí hàn wá tó sọ nǹkan ìyanu yìí fún wa.”
Bet viņa sieva uz viņu sacīja: kad Tas Kungs mūs gribētu nokaut, tad Viņš to dedzināmo upuri un ēdamo upuri nebūtu pieņēmis no mūsu rokām; Viņš arī visas šīs lietas mums nebūtu parādījis, nedz mums to licis dzirdēt šai laikā.
24 Obìnrin náà sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Samsoni. Ọmọ náà dàgbà Olúwa sì bùkún un.
Un tā sieva dzemdēja dēlu un nosauca viņa vārdu Simsons, un tas zēns uzauga, un Tas Kungs to svētīja.
25 Ẹ̀mí Olúwa sì bẹ̀rẹ̀ sí ru sókè nígbà tí ó wà ní Mahane-Dani ní agbede-méjì Sora àti Eṣtaoli.
Un Tā Kunga Gars viņu sāka skubināt Dana lēģerī starp Careu un Estaoli.