< Judges 13 >

1 Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Olúwa sì fi wọ́n lé àwọn ará Filistini lọ́wọ́ fún ogójì ọdún.
Mwet Israel elos sifilpa oru ma koluk ye mutun LEUM GOD, ke ma inge LEUM GOD El lela tuh mwet Philistia in leum faclos yac angngaul.
2 Ọkùnrin ará Sora kan wà, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Manoa láti ẹ̀yà Dani. Aya rẹ̀ yàgàn kò sì bímọ.
In pacl sac oasr sie mwet in siti Zorah su pangpang Manoah, sin sruf lal Dan, ac mutan kial ah el sie mutan talap.
3 Angẹli Olúwa fi ara han obìnrin náà, ó sì wí fún un pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ yàgàn, ìwọ kò sì tí ì bímọ, ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan.
Na lipufan lun LEUM GOD sikyang nu sin mutan sac ac fahk, “Soenna oasr tulik nutum mweyen kom talap, tusruktu ac tia paht kom ac pitutu, ac oswela sie wen.
4 Báyìí rí i dájúdájú pé ìwọ kò mu wáìnì tàbí ọtí líle kankan àti pé ìwọ kò jẹ ohun aláìmọ́ kankan,
Karinganang tuh kom in tia nim wain ku kutena mwe nim ku, ac nik kom kang kutena mongo ma oal.
5 nítorí ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan. Má ṣe fi abẹ kan orí rẹ̀, nítorí pé Nasiri, ẹni ìyàsọ́tọ̀ fún Ọlọ́run ni ọmọ náà yóò jẹ́ láti ọjọ́ ìbí rẹ̀. Òun ni yóò bẹ̀rẹ̀ ìdáǹdè àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní ọwọ́ àwọn ará Filistini.”
Na tukun wen se nutum an el isusla, kom in tia kal aunsifal, mweyen len se na ma el isusla ah fahla el fah sriyukla nu sin God oana sie mwet Nazirite. El pa ac molela mwet Israel liki inpoun mwet Philistia.”
6 Nígbà náà ni obìnrin náà tọ ọkọ rẹ̀ lọ, o sì sọ fún un wí pé, “Ènìyàn Ọlọ́run kan tọ̀ mí wá. Ó jọ angẹli Ọlọ́run, ó ba ènìyàn lẹ́rù gidigidi. Èmi kò béèrè ibi tí ó ti wá, òun náà kò sì sọ orúkọ rẹ̀ fún mi.
Na mutan sac som ac fahk nu sin mukul tumal, “Sie mwet lun God tuku nu yuruk. Arulana aksangeng lumahl, oana elan sie lipufan lun God. Nga tiana siyuk lah el tuku ya me, ac el tia pacna fahk inel nu sik.
7 Ṣùgbọ́n ó sọ fún mi wí pé, ‘Ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan, fún ìdí èyí, má ṣe mu wáìnì tàbí àwọn ọtí líle mìíràn bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ má ṣe jẹ ohunkóhun tí í ṣe aláìmọ́, nítorí pé Nasiri Ọlọ́run ni ọmọ náà yóò jẹ́ láti ọjọ́ ìbí rẹ̀ títí di ọjọ́ ikú rẹ̀.’”
Tusruktu el fahk nu sik lah nga ac fah pitutu ac oswela sie wen. Ac el fahk pac mu nga in tiana nim wain ku kutena mwe nim ku, ku kang kutena mongo oal, mweyen tulik sac ac fah sie mwet Nazirite nu sin God ke lusen moul lal nufon.”
8 Nígbà náà ni Manoa gbàdúrà sí Olúwa wí pé, “Háà Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ènìyàn Ọlọ́run tí ìwọ rán sí wa padà tọ̀ wá wá láti kọ́ wa bí àwa yóò ti ṣe tọ́ ọmọ tí àwa yóò bí náà.”
Na Manoah el pre nu sin LEUM GOD ac fahk, “O LEUM GOD, nunak munas, lela tuh mwet lun God se su kom supwama meet ah in sifil foloko nu yorosr ac fahk nu sesr lah mea kut ac oru nu sin tulik se inge ke el ac isusla uh.”
9 Ọlọ́run fetí sí ohùn Manoa, angẹli Ọlọ́run náà tún padà tọ obìnrin náà wá nígbà tí ó wà ní oko ṣùgbọ́n ọkọ rẹ̀ Manoa kò sí ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
God El oru oana ma Manoah el siyuk ah. Lipufan lun God sifilpa foloko nu yurin mutan sac ke el muta in ima ah, tusruktu mukul tumal el wangin in pacl sac.
10 Nítorí náà ni obìnrin náà ṣe yára lọ sọ fún ọkọ rẹ̀ pé, “Ọkùnrin tí ó fi ara hàn mí ní ọjọ́sí ti tún padà wá.”
Na mutan sac sulaklak som ac fahk nu sin mukul tumal, “Liye, mwet se ma tuh tuku nu yuruk ah el sifilpa sikyak nu sik!”
11 Manoa yára dìde, ó sì tẹ̀lé aya rẹ̀, nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ ọkùnrin náà ó ní, “Ǹjẹ́ ìwọ ni o bá obìnrin yìí sọ̀rọ̀?” Ọkùnrin náà dáhùn pé, “Èmi ni.”
Manoah el tuyak ac fahsr tukun mutan kial ah, ac ke el sun mwet sac, el siyuk sel, “Ku kom pa mwet se ma sramsram nu sin mutan kiuk ah?” Na lipufan sac fahk, “Aok.”
12 Manoa bi ọkùnrin náà pé, “Nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ bá ṣẹ kí ni yóò jẹ́ ìlànà fún ìgbé ayé àti iṣẹ́ ọmọ náà?”
Na Manoah el fahk, “Na inge, ke pacl se ma kas lom inge akpwayeyeyuk, mea tulik se inge ac oru? Moul fuka el ac moulkin?”
13 Angẹli Olúwa náà dáhùn wí pé, “Aya rẹ gbọdọ̀ ṣe gbogbo ohun tí mo ti sọ fún un
Na lipufan lun LEUM GOD el fahk, “Mutan kiom an el enenu in liyaung ma nukewa nga fahk nu sel ah.
14 kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí ó bá ti inú èso àjàrà jáde wá, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ mu wáìnì tàbí àwọn ọtí líle mìíràn tàbí jẹ ohunkóhun tí ó bá jẹ́ aláìmọ́. Ó ní láti ṣe ohun gbogbo tí mo ti pàṣẹ fún un.”
El tia enenu in kang kutena ma su tuku ke fokin grape, ku nim kutena wain, ku mwe nim ku, ku kang kutena mongo oal. El enenu in oru ma nukewa ma nga sapkin nu sel ah.”
15 Manoa sọ fún angẹli Olúwa náà pé, “Jọ̀wọ́ dára dúró títí àwa yóò fi pèsè ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan fún ọ.”
Manoah el fahk nu sin lipufan lun LEUM GOD, “Nunak munas, nimet kom sa som. Soano kut in akmolyela soko nani fusr kom in mongo.”
16 Angẹli Olúwa náà dá Manoa lóhùn pé, “Bí ẹ̀yin tilẹ̀ dá mi dúró, èmi kì yóò jẹ ọ̀kankan nínú oúnjẹ tí ẹ̀yin yóò pèsè. Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá fẹ́ ẹ pèsè ọrẹ ẹbọ sísun, kí ẹ sì fi rú ẹbọ sí Olúwa.” (Manoa kò mọ̀ pé angẹli Olúwa ní i ṣe.)
Na lipufan lun LEUM GOD el fahk nu sel Manoah, “Kom finne ikolyuwi, nga ac tia kang mongo kom oru an. Tusruktu kom fin lungse oru, kom kisakin nu sin LEUM GOD.”
17 Manoa sì béèrè lọ́wọ́ angẹli Olúwa náà pé, “Kí ni orúkọ rẹ, kí àwa bá à lè fi ọlá fún ọ nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ bá ṣẹ?”
Na Manoah el fahk, “Su inem an, tuh kut fah ku in akfulatye kom ke pacl se kas lom inge ac akpwayeyuk.”
18 Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa náà dáhùn pé, “Èéṣe tí ìwọ ń béèrè orúkọ mi? Ìyanu ni, ó kọjá ìmọ̀.”
Na lipufan sac el siyuk, “Efu ku kom ke etu inek? Inek sie ine lukma.”
19 Lẹ́yìn náà ni Manoa mú ọ̀dọ́ ewúrẹ́, pẹ̀lú ẹbọ ọkà, ó sì fi rú ẹbọ lórí àpáta kan sí Olúwa. Nígbà tí Manoa àti ìyàwó dúró tí wọn ń wò Olúwa ṣe ohun ìyanu kan.
Na Manoah el eis soko nani fusr ac kutu wheat, ac el kisakin ma inge fin sie eot nu sin LEUM GOD su oru ma usrnguk.
20 Bí ẹ̀là ahọ́n iná ti là jáde láti ibi pẹpẹ ìrúbọ náà sí ọ̀run, angẹli Olúwa gòkè re ọ̀run láàrín ahọ́n iná náà. Nígbà tí wọ́n rí ìṣẹ̀lẹ̀ yìí, Manoa àti aya rẹ̀ wólẹ̀ wọ́n sì dojúbolẹ̀.
Ke pacl se e sac firiryak liki loang sac, na lipufan lun LEUM GOD el weak firir sac nu inkusrao. Ke Manoah ac mutan kial ah ngetang liye ma inge, eltal putati ac faksufi nu infohk uh.
21 Nígbà tí angẹli Olúwa náà kò tún fi ara rẹ̀ han Manoa àti aya rẹ̀ mọ́, Manoa wá mọ̀ pé angẹli Olúwa ni.
Lipufan lun LEUM GOD el tia sifil sikyak nu sel Manoah ac mutan kial ah, na Manoah el tufah akilenak lah lipufan lun LEUM GOD pa mwet sac.
22 Manoa sọ fún aya rẹ̀ pé, “Dájúdájú àwa yóò kú nítorí àwa ti fi ojú rí Ọlọ́run.”
Manoah el fahk nu sin mutan kial ah, “Pwayena lah kut ac misa, mweyen kut liyalak God!”
23 Ṣùgbọ́n ìyàwó rẹ̀ dáhùn pé, “Bí Olúwa bá ní èrò àti pa wá kò bá tí gba ẹbọ sísun àti ọrẹ ọkà wa, tàbí fi gbogbo nǹkan wọ̀nyí hàn wá tó sọ nǹkan ìyanu yìí fún wa.”
Na mutan kial ah topuk ac fahk, “LEUM GOD El funu lungse unikuti, El lukun tia insewowo ke mwe kisa kut orala, ac El lukun tia pac akkalemye ma inge nu sesr, ku fahkak kas ouinge nu sesr ke pacl se inge.”
24 Obìnrin náà sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Samsoni. Ọmọ náà dàgbà Olúwa sì bùkún un.
Na mutan sac oswela wen se, ac sang inel Samson. Ac tulik sac el kapak, ac LEUM GOD El akinsewowoyal.
25 Ẹ̀mí Olúwa sì bẹ̀rẹ̀ sí ru sókè nígbà tí ó wà ní Mahane-Dani ní agbede-méjì Sora àti Eṣtaoli.
Ac ku lun LEUM GOD mutawauk in akkeyal ke el muta ke iwen aktuktuk lun mwet Dan in masrlon acn Zorah ac acn Eshtaol.

< Judges 13 >