< Judges 13 >

1 Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Olúwa sì fi wọ́n lé àwọn ará Filistini lọ́wọ́ fún ogójì ọdún.
O rĩngĩ andũ a Isiraeli magĩĩka maũndũ mooru maitho-inĩ ma Jehova, na nĩ ũndũ wa ũguo Jehova akĩmaneana moko-inĩ ma Afilisti handũ ha mĩaka mĩrongo ĩna.
2 Ọkùnrin ará Sora kan wà, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Manoa láti ẹ̀yà Dani. Aya rẹ̀ yàgàn kò sì bímọ.
Mũndũ ũmwe warĩ wa Zora, wetagwo Manoa kuuma mũhĩrĩga wa Adani, aarĩ na mũtumia warĩ thaata watũũrĩte atarĩ na mwana.
3 Angẹli Olúwa fi ara han obìnrin náà, ó sì wí fún un pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ yàgàn, ìwọ kò sì tí ì bímọ, ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan.
Mũraika wa Jehova akĩmuumĩrĩra, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ũrĩ thaata na ndũrĩ mwana, no nĩũkũgĩa nda ũciare kahĩĩ.
4 Báyìí rí i dájúdájú pé ìwọ kò mu wáìnì tàbí ọtí líle kankan àti pé ìwọ kò jẹ ohun aláìmọ́ kankan,
Na rĩrĩ, wĩmenyerere ndũkananyue ndibei kana kĩndũ o gĩothe kĩgagatu, na ndũkanarĩe kĩndũ o gĩothe kĩrĩ thaahu,
5 nítorí ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan. Má ṣe fi abẹ kan orí rẹ̀, nítorí pé Nasiri, ẹni ìyàsọ́tọ̀ fún Ọlọ́run ni ọmọ náà yóò jẹ́ láti ọjọ́ ìbí rẹ̀. Òun ni yóò bẹ̀rẹ̀ ìdáǹdè àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní ọwọ́ àwọn ará Filistini.”
tondũ wee nĩũkũgĩa nda na ũciare kahĩĩ. Gũtirĩ kanyũi gakaahũthĩrwo mũtwe-inĩ wake, nĩ ũndũ kahĩĩ kau gagaatuĩka Mũnaziri wamũrĩirwo Ngai kuuma gũciarwo, na nĩakambĩrĩria kũhonokia Isiraeli kuuma moko-inĩ ma Afilisti.”
6 Nígbà náà ni obìnrin náà tọ ọkọ rẹ̀ lọ, o sì sọ fún un wí pé, “Ènìyàn Ọlọ́run kan tọ̀ mí wá. Ó jọ angẹli Ọlọ́run, ó ba ènìyàn lẹ́rù gidigidi. Èmi kò béèrè ibi tí ó ti wá, òun náà kò sì sọ orúkọ rẹ̀ fún mi.
Hĩndĩ ĩyo mũtumia ũcio agĩthiĩ kũrĩ mũthuuriwe, akĩmwĩra atĩrĩ, “Mũndũ wa Ngai nĩokire kũrĩ niĩ. Ekuonekaga ahaana ta mũraika wa Ngai wa gwĩtigĩrwo mũno. Ndinamũũria kũrĩa oimĩte, nake ndananjĩĩra rĩĩtwa rĩake.
7 Ṣùgbọ́n ó sọ fún mi wí pé, ‘Ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan, fún ìdí èyí, má ṣe mu wáìnì tàbí àwọn ọtí líle mìíràn bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ má ṣe jẹ ohunkóhun tí í ṣe aláìmọ́, nítorí pé Nasiri Ọlọ́run ni ọmọ náà yóò jẹ́ láti ọjọ́ ìbí rẹ̀ títí di ọjọ́ ikú rẹ̀.’”
No nĩanjĩĩrire atĩrĩ, ‘Nĩũkũgĩa nda na ũciare kahĩĩ. Nĩ ũndũ wa ũguo, ndũkanyue ndibei kana kĩndũ kĩgagatu, o na ndũkarĩe kĩndũ o gĩothe kĩrĩ thaahu, tondũ kahĩĩ kau gagaakorwo karĩ Mũnaziri wa Ngai kuuma gũciarwo nginya mũthenya wako wa gũkua.’”
8 Nígbà náà ni Manoa gbàdúrà sí Olúwa wí pé, “Háà Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ènìyàn Ọlọ́run tí ìwọ rán sí wa padà tọ̀ wá wá láti kọ́ wa bí àwa yóò ti ṣe tọ́ ọmọ tí àwa yóò bí náà.”
Hĩndĩ ĩyo Manoa akĩhooya Jehova: “Mwathani nĩndagũthaitha, reke mũndũ ũcio wa Ngai ũgũtũmĩte kũrĩ ithuĩ oke rĩngĩ nĩguo atũrute ũrĩa tũkũrera kahĩĩ karĩa gagaaciarwo.”
9 Ọlọ́run fetí sí ohùn Manoa, angẹli Ọlọ́run náà tún padà tọ obìnrin náà wá nígbà tí ó wà ní oko ṣùgbọ́n ọkọ rẹ̀ Manoa kò sí ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
Ngai akĩigua Manoa, na mũraika wa Ngai agĩũka rĩngĩ kũrĩ mũtumia rĩrĩa aarĩ mũgũnda-inĩ; no mũthuuriwe Manoa ndaarĩ hamwe nake.
10 Nítorí náà ni obìnrin náà ṣe yára lọ sọ fún ọkọ rẹ̀ pé, “Ọkùnrin tí ó fi ara hàn mí ní ọjọ́sí ti tún padà wá.”
Nake mũtumia akĩhiũha gũthiĩ kwĩra mũthuuriwe, “Mũndũ ũrĩa wanyumĩrĩire mũthenya ũrĩa ũngĩ-rĩ, arĩ haha!”
11 Manoa yára dìde, ó sì tẹ̀lé aya rẹ̀, nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ ọkùnrin náà ó ní, “Ǹjẹ́ ìwọ ni o bá obìnrin yìí sọ̀rọ̀?” Ọkùnrin náà dáhùn pé, “Èmi ni.”
Manoa agĩũkĩra, akĩrũmĩrĩra mũtumia wake. Rĩrĩa aakinyire harĩ mũndũ ũcio-rĩ, akĩmũũria atĩrĩ, “We nĩwe waririe na mũtumia wakwa?” Nake akiuga atĩrĩ, “Ĩĩ, nĩ niĩ.”
12 Manoa bi ọkùnrin náà pé, “Nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ bá ṣẹ kí ni yóò jẹ́ ìlànà fún ìgbé ayé àti iṣẹ́ ọmọ náà?”
Nĩ ũndũ ũcio Manoa akĩmũũria atĩrĩ, “Hĩndĩ ĩrĩa ciugo ciaku ikaahinga-rĩ, watho wa mũtũũrĩre wa kahĩĩ gaka na wĩra wako ũgaakorwo ũrĩ ũrĩkũ?”
13 Angẹli Olúwa náà dáhùn wí pé, “Aya rẹ gbọdọ̀ ṣe gbogbo ohun tí mo ti sọ fún un
Mũraika wa Jehova agĩcookia atĩrĩ, “Mũtumia waku no nginya eeke ũrĩa wothe ndĩmwĩrĩte.
14 kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí ó bá ti inú èso àjàrà jáde wá, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ mu wáìnì tàbí àwọn ọtí líle mìíràn tàbí jẹ ohunkóhun tí ó bá jẹ́ aláìmọ́. Ó ní láti ṣe ohun gbogbo tí mo ti pàṣẹ fún un.”
Ndakarĩe kĩndũ o gĩothe kiumĩte mũthabibũ-inĩ, kana anyue ndibei o yothe, kana kĩndũ kĩngĩ gĩa kũnyua kĩgagatu kana arĩe kĩndũ o gĩothe kĩrĩ thaahu. No nginya eeke maũndũ mothe marĩa niĩ ndĩmwathĩte.”
15 Manoa sọ fún angẹli Olúwa náà pé, “Jọ̀wọ́ dára dúró títí àwa yóò fi pèsè ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan fún ọ.”
Manoa akĩĩra mũraika wa Jehova atĩrĩ, “No twende ũikare nginya tũgũthĩnjĩre koori.”
16 Angẹli Olúwa náà dá Manoa lóhùn pé, “Bí ẹ̀yin tilẹ̀ dá mi dúró, èmi kì yóò jẹ ọ̀kankan nínú oúnjẹ tí ẹ̀yin yóò pèsè. Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá fẹ́ ẹ pèsè ọrẹ ẹbọ sísun, kí ẹ sì fi rú ẹbọ sí Olúwa.” (Manoa kò mọ̀ pé angẹli Olúwa ní i ṣe.)
Mũraika wa Jehova agĩcookia atĩrĩ, “O na wangiria thiĩ, ndikũrĩa irio ciaku. No wahaarĩria igongona rĩa njino-rĩ, rĩu rĩrutĩre Jehova.” (Manoa ndaigana gũkũũrana atĩ ũcio aarĩ mũraika wa Jehova.)
17 Manoa sì béèrè lọ́wọ́ angẹli Olúwa náà pé, “Kí ni orúkọ rẹ, kí àwa bá à lè fi ọlá fún ọ nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ bá ṣẹ?”
Nake Manoa agĩtuĩria ũhoro kuuma kũrĩ mũraika wa Jehova akĩmũũria atĩrĩ, “Wee wĩtagwo atĩa, nĩguo tũgaagũtĩĩa hĩndĩ ĩrĩa kiugo gĩaku gĩgaatuĩka kĩa ma?”
18 Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa náà dáhùn pé, “Èéṣe tí ìwọ ń béèrè orúkọ mi? Ìyanu ni, ó kọjá ìmọ̀.”
Nake agĩcookia atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ gĩgũtũma ũnjũũrie rĩĩtwa rĩakwa? Ndũngĩhota kũrĩmenya, nĩ rĩa magegania.”
19 Lẹ́yìn náà ni Manoa mú ọ̀dọ́ ewúrẹ́, pẹ̀lú ẹbọ ọkà, ó sì fi rú ẹbọ lórí àpáta kan sí Olúwa. Nígbà tí Manoa àti ìyàwó dúró tí wọn ń wò Olúwa ṣe ohun ìyanu kan.
Hĩndĩ ĩyo Manoa akĩoya koori hamwe na mũtu wa igongona, agĩcirutĩra Jehova igũrũ rĩa ihiga. Nake Jehova agĩĩka ũndũ wa magegania o Manoa na mũtumia wake meroreire:
20 Bí ẹ̀là ahọ́n iná ti là jáde láti ibi pẹpẹ ìrúbọ náà sí ọ̀run, angẹli Olúwa gòkè re ọ̀run láàrín ahọ́n iná náà. Nígbà tí wọ́n rí ìṣẹ̀lẹ̀ yìí, Manoa àti aya rẹ̀ wólẹ̀ wọ́n sì dojúbolẹ̀.
O rũrĩrĩmbĩ rũkĩrĩrĩmbũkaga kuuma kĩgongona-inĩ rũrorete igũrũ-rĩ, mũraika wa Jehova akĩambatĩra rũrĩrĩmbĩ-inĩ rũu. Nake Manoa na mũtumia wake mona ũguo, makĩĩgũithia magĩturumithia mothiũ mao thĩ.
21 Nígbà tí angẹli Olúwa náà kò tún fi ara rẹ̀ han Manoa àti aya rẹ̀ mọ́, Manoa wá mọ̀ pé angẹli Olúwa ni.
Rĩrĩa mũraika ũcio wa Jehova aagire gũcooka kwĩyonithania kũrĩ Manoa na mũtumia wake, Manoa akĩmenya atĩ ũcio aarĩ mũraika wa Jehova.
22 Manoa sọ fún aya rẹ̀ pé, “Dájúdájú àwa yóò kú nítorí àwa ti fi ojú rí Ọlọ́run.”
Akĩĩra mũtumia wake atĩrĩ, “Ithuĩ rĩu no tũgũkua, tondũ nĩtuonete Ngai!”
23 Ṣùgbọ́n ìyàwó rẹ̀ dáhùn pé, “Bí Olúwa bá ní èrò àti pa wá kò bá tí gba ẹbọ sísun àti ọrẹ ọkà wa, tàbí fi gbogbo nǹkan wọ̀nyí hàn wá tó sọ nǹkan ìyanu yìí fún wa.”
No mũtumia wake akĩmũcookeria atĩrĩ, “Korwo Jehova nĩegũtuĩte gũtũũraga-rĩ, ndangĩtĩkĩrire igongona rĩa njino na igongona rĩa mũtu kuuma moko-inĩ maitũ, o na kana atuonie maũndũ maya mothe kana gũtwĩra ũguo aatwĩra rĩu.”
24 Obìnrin náà sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Samsoni. Ọmọ náà dàgbà Olúwa sì bùkún un.
Mũtumia ũcio agĩciara kahĩĩ na agĩgatua Samusoni. Gagĩkũra, nake Jehova agĩkarathima,
25 Ẹ̀mí Olúwa sì bẹ̀rẹ̀ sí ru sókè nígbà tí ó wà ní Mahane-Dani ní agbede-méjì Sora àti Eṣtaoli.
nake Roho wa Jehova akĩambĩrĩria gũkaarahũra o hĩndĩ ĩyo kaarĩ kũu Mahane-Dani, gatagatĩ ga Zora na Eshitaoli.

< Judges 13 >