< Judges 13 >

1 Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Olúwa sì fi wọ́n lé àwọn ará Filistini lọ́wọ́ fún ogójì ọdún.
Les enfants d'Israël firent encore ce qui est mal aux yeux de l'Éternel, et l'Éternel les livra entre les mains des Philistins pendant quarante ans.
2 Ọkùnrin ará Sora kan wà, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Manoa láti ẹ̀yà Dani. Aya rẹ̀ yàgàn kò sì bímọ.
Il y avait un homme de Tsorea, de la famille des Danites, dont le nom était Manoach; sa femme était stérile et sans enfants.
3 Angẹli Olúwa fi ara han obìnrin náà, ó sì wí fún un pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ yàgàn, ìwọ kò sì tí ì bímọ, ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan.
L'ange de Yahvé apparut à la femme et lui dit: « Voici, tu es stérile et sans enfants; mais tu concevras et tu enfanteras un fils.
4 Báyìí rí i dájúdájú pé ìwọ kò mu wáìnì tàbí ọtí líle kankan àti pé ìwọ kò jẹ ohun aláìmọ́ kankan,
Maintenant, prends garde, ne bois pas de vin ni de boisson forte, et ne mange pas de choses impures;
5 nítorí ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan. Má ṣe fi abẹ kan orí rẹ̀, nítorí pé Nasiri, ẹni ìyàsọ́tọ̀ fún Ọlọ́run ni ọmọ náà yóò jẹ́ láti ọjọ́ ìbí rẹ̀. Òun ni yóò bẹ̀rẹ̀ ìdáǹdè àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní ọwọ́ àwọn ará Filistini.”
car voici, tu concevras et tu enfanteras un fils. Aucun rasoir ne viendra sur sa tête, car l'enfant sera naziréen à Dieu dès le ventre de sa mère. C'est lui qui commencera à sauver Israël de la main des Philistins. »
6 Nígbà náà ni obìnrin náà tọ ọkọ rẹ̀ lọ, o sì sọ fún un wí pé, “Ènìyàn Ọlọ́run kan tọ̀ mí wá. Ó jọ angẹli Ọlọ́run, ó ba ènìyàn lẹ́rù gidigidi. Èmi kò béèrè ibi tí ó ti wá, òun náà kò sì sọ orúkọ rẹ̀ fún mi.
Alors la femme vint le dire à son mari, en disant: « Un homme de Dieu est venu à moi, et son visage était comme celui de l'ange de Dieu, très impressionnant. Je ne lui ai pas demandé d'où il venait, et il ne m'a pas dit son nom;
7 Ṣùgbọ́n ó sọ fún mi wí pé, ‘Ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan, fún ìdí èyí, má ṣe mu wáìnì tàbí àwọn ọtí líle mìíràn bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ má ṣe jẹ ohunkóhun tí í ṣe aláìmọ́, nítorí pé Nasiri Ọlọ́run ni ọmọ náà yóò jẹ́ láti ọjọ́ ìbí rẹ̀ títí di ọjọ́ ikú rẹ̀.’”
mais il m'a dit: 'Voici que tu vas concevoir et enfanter un fils; et maintenant ne bois ni vin ni boisson forte. Ne mange pas de choses impures, car l'enfant sera naziréen pour Dieu depuis le ventre de sa mère jusqu'au jour de sa mort.'"
8 Nígbà náà ni Manoa gbàdúrà sí Olúwa wí pé, “Háà Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ènìyàn Ọlọ́run tí ìwọ rán sí wa padà tọ̀ wá wá láti kọ́ wa bí àwa yóò ti ṣe tọ́ ọmọ tí àwa yóò bí náà.”
Alors Manoah pria Yahvé et dit: « Oh, Seigneur, fais que l'homme de Dieu que tu as envoyé revienne vers nous, et qu'il nous apprenne ce que nous devons faire à l'enfant qui va naître. »
9 Ọlọ́run fetí sí ohùn Manoa, angẹli Ọlọ́run náà tún padà tọ obìnrin náà wá nígbà tí ó wà ní oko ṣùgbọ́n ọkọ rẹ̀ Manoa kò sí ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
Dieu écouta la voix de Manoah, et l'ange de Dieu revint vers la femme comme elle était assise dans les champs; mais Manoah, son mari, n'était pas avec elle.
10 Nítorí náà ni obìnrin náà ṣe yára lọ sọ fún ọkọ rẹ̀ pé, “Ọkùnrin tí ó fi ara hàn mí ní ọjọ́sí ti tún padà wá.”
La femme se hâta et courut le dire à son mari, en lui disant: « Voici que l'homme qui m'était apparu ce jour-là m'est apparu. »
11 Manoa yára dìde, ó sì tẹ̀lé aya rẹ̀, nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ ọkùnrin náà ó ní, “Ǹjẹ́ ìwọ ni o bá obìnrin yìí sọ̀rọ̀?” Ọkùnrin náà dáhùn pé, “Èmi ni.”
Manoah se leva et suivit sa femme; il vint vers l'homme et lui dit: « Es-tu l'homme qui a parlé à ma femme? » Il a dit: « Je le suis. »
12 Manoa bi ọkùnrin náà pé, “Nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ bá ṣẹ kí ni yóò jẹ́ ìlànà fún ìgbé ayé àti iṣẹ́ ọmọ náà?”
Manoah dit: « Que tes paroles se réalisent maintenant. Quel sera le mode de vie et la mission de l'enfant? »
13 Angẹli Olúwa náà dáhùn wí pé, “Aya rẹ gbọdọ̀ ṣe gbogbo ohun tí mo ti sọ fún un
L'ange de Yahvé dit à Manoah: « Qu'elle prenne garde à tout ce que j'ai dit à la femme.
14 kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí ó bá ti inú èso àjàrà jáde wá, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ mu wáìnì tàbí àwọn ọtí líle mìíràn tàbí jẹ ohunkóhun tí ó bá jẹ́ aláìmọ́. Ó ní láti ṣe ohun gbogbo tí mo ti pàṣẹ fún un.”
Qu'elle ne mange pas de ce qui vient de la vigne, qu'elle ne boive pas de vin ni de boisson forte, et qu'elle ne mange aucune chose impure. Qu'elle observe tout ce que je lui ai ordonné. »
15 Manoa sọ fún angẹli Olúwa náà pé, “Jọ̀wọ́ dára dúró títí àwa yóò fi pèsè ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan fún ọ.”
Manoah dit à l'ange de l'Yahvé: « Reste avec nous, je te prie, afin que nous préparions un chevreau pour toi. »
16 Angẹli Olúwa náà dá Manoa lóhùn pé, “Bí ẹ̀yin tilẹ̀ dá mi dúró, èmi kì yóò jẹ ọ̀kankan nínú oúnjẹ tí ẹ̀yin yóò pèsè. Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá fẹ́ ẹ pèsè ọrẹ ẹbọ sísun, kí ẹ sì fi rú ẹbọ sí Olúwa.” (Manoa kò mọ̀ pé angẹli Olúwa ní i ṣe.)
L'ange de Yahvé dit à Manoah: « Si tu me retiens, je ne mangerai pas ton pain. Si tu veux préparer un holocauste, tu dois l'offrir à Yahvé. » Car Manoah ne savait pas que c'était l'ange de Yahvé.
17 Manoa sì béèrè lọ́wọ́ angẹli Olúwa náà pé, “Kí ni orúkọ rẹ, kí àwa bá à lè fi ọlá fún ọ nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ bá ṣẹ?”
Manoah dit à l'ange de Yahvé: « Quel est ton nom, afin que, lorsque tes paroles se réaliseront, nous puissions t'honorer? »
18 Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa náà dáhùn pé, “Èéṣe tí ìwọ ń béèrè orúkọ mi? Ìyanu ni, ó kọjá ìmọ̀.”
L'ange de Yahvé lui dit: « Pourquoi demandes-tu mon nom, puisqu'il est incompréhensible? »
19 Lẹ́yìn náà ni Manoa mú ọ̀dọ́ ewúrẹ́, pẹ̀lú ẹbọ ọkà, ó sì fi rú ẹbọ lórí àpáta kan sí Olúwa. Nígbà tí Manoa àti ìyàwó dúró tí wọn ń wò Olúwa ṣe ohun ìyanu kan.
Manoah prit le chevreau avec l'offrande et l'offrit sur le rocher à Yahvé. Et l'ange fit une chose étonnante, sous le regard de Manoah et de sa femme.
20 Bí ẹ̀là ahọ́n iná ti là jáde láti ibi pẹpẹ ìrúbọ náà sí ọ̀run, angẹli Olúwa gòkè re ọ̀run láàrín ahọ́n iná náà. Nígbà tí wọ́n rí ìṣẹ̀lẹ̀ yìí, Manoa àti aya rẹ̀ wólẹ̀ wọ́n sì dojúbolẹ̀.
Car lorsque la flamme de l'autel s'éleva vers le ciel, l'ange de Yahvé monta dans la flamme de l'autel. Manoah et sa femme regardaient, et ils tombèrent la face contre terre.
21 Nígbà tí angẹli Olúwa náà kò tún fi ara rẹ̀ han Manoa àti aya rẹ̀ mọ́, Manoa wá mọ̀ pé angẹli Olúwa ni.
Mais l'ange de Yahvé n'apparut plus ni à Manoah ni à sa femme. Alors Manoah sut que c'était l'ange de Yahvé.
22 Manoa sọ fún aya rẹ̀ pé, “Dájúdájú àwa yóò kú nítorí àwa ti fi ojú rí Ọlọ́run.”
Manoah dit à sa femme: « Nous allons mourir, car nous avons vu Dieu. »
23 Ṣùgbọ́n ìyàwó rẹ̀ dáhùn pé, “Bí Olúwa bá ní èrò àti pa wá kò bá tí gba ẹbọ sísun àti ọrẹ ọkà wa, tàbí fi gbogbo nǹkan wọ̀nyí hàn wá tó sọ nǹkan ìyanu yìí fún wa.”
Mais sa femme lui dit: « Si Yahvé voulait nous tuer, il n'aurait pas reçu de notre part un holocauste et une offrande de repas, et il ne nous aurait pas montré toutes ces choses, et il ne nous aurait pas dit de telles choses en ce moment. »
24 Obìnrin náà sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Samsoni. Ọmọ náà dàgbà Olúwa sì bùkún un.
La femme enfanta un fils et le nomma Samson. L'enfant grandit, et Yahvé le bénit.
25 Ẹ̀mí Olúwa sì bẹ̀rẹ̀ sí ru sókè nígbà tí ó wà ní Mahane-Dani ní agbede-méjì Sora àti Eṣtaoli.
L'Esprit de Yahvé commença à le toucher à Mahaneh Dan, entre Zorah et Eshtaol.

< Judges 13 >