< Judges 13 >

1 Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Olúwa sì fi wọ́n lé àwọn ará Filistini lọ́wọ́ fún ogójì ọdún.
Tedy opět synové Izraelští činili to, což jest zlého před očima Hospodinovýma, i vydal je Hospodin v ruce Filistinských za čtyřidceti let.
2 Ọkùnrin ará Sora kan wà, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Manoa láti ẹ̀yà Dani. Aya rẹ̀ yàgàn kò sì bímọ.
Byl pak muž jeden z Zaraha, z čeledi Dan, jménem Manue, jehož manželka byla neplodná a nerodila.
3 Angẹli Olúwa fi ara han obìnrin náà, ó sì wí fún un pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ yàgàn, ìwọ kò sì tí ì bímọ, ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan.
I ukázal se anděl Hospodinův ženě té a řekl jí: Aj, nyní jsi neplodná, aniž jsi rodila; počneš pak a porodíš syna.
4 Báyìí rí i dájúdájú pé ìwọ kò mu wáìnì tàbí ọtí líle kankan àti pé ìwọ kò jẹ ohun aláìmọ́ kankan,
Protož nyní vystříhej se, abys vína nepila aneb nápoje opojného, a abys nejedla nic nečistého.
5 nítorí ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan. Má ṣe fi abẹ kan orí rẹ̀, nítorí pé Nasiri, ẹni ìyàsọ́tọ̀ fún Ọlọ́run ni ọmọ náà yóò jẹ́ láti ọjọ́ ìbí rẹ̀. Òun ni yóò bẹ̀rẹ̀ ìdáǹdè àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní ọwọ́ àwọn ará Filistini.”
Nebo aj, počneš a porodíš syna, a břitva ať nevchází na hlavu jeho, nebo bude to dítě od života Nazarejský Boží, a tenť počne vysvobozovati Izraele z ruky Filistinských.
6 Nígbà náà ni obìnrin náà tọ ọkọ rẹ̀ lọ, o sì sọ fún un wí pé, “Ènìyàn Ọlọ́run kan tọ̀ mí wá. Ó jọ angẹli Ọlọ́run, ó ba ènìyàn lẹ́rù gidigidi. Èmi kò béèrè ibi tí ó ti wá, òun náà kò sì sọ orúkọ rẹ̀ fún mi.
I přišla žena a pověděla to muži svému, řkuci: Muž Boží přišel ke mně, jehož oblíčej byl jako oblíčej anděla Božího, hrozný velmi, a neotázala jsem se jeho, odkud by byl, ani mi svého jména neoznámil.
7 Ṣùgbọ́n ó sọ fún mi wí pé, ‘Ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan, fún ìdí èyí, má ṣe mu wáìnì tàbí àwọn ọtí líle mìíràn bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ má ṣe jẹ ohunkóhun tí í ṣe aláìmọ́, nítorí pé Nasiri Ọlọ́run ni ọmọ náà yóò jẹ́ láti ọjọ́ ìbí rẹ̀ títí di ọjọ́ ikú rẹ̀.’”
Ale řekl mi: Aj, počneš a porodíš syna, protož nyní nepí vína aneb nápoje opojného, aniž jez co nečistého, nebo to dítě od života bude Nazarejský Boží až do dne smrti své.
8 Nígbà náà ni Manoa gbàdúrà sí Olúwa wí pé, “Háà Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ènìyàn Ọlọ́run tí ìwọ rán sí wa padà tọ̀ wá wá láti kọ́ wa bí àwa yóò ti ṣe tọ́ ọmọ tí àwa yóò bí náà.”
Tedy Manue modlil se Hospodinu a řekl: Vyslyš mne, můj Pane, prosím, nechť muž Boží, kteréhož jsi byl poslal, zase přijde k nám, a naučí nás, co máme dělati s dítětem, kteréž se má naroditi.
9 Ọlọ́run fetí sí ohùn Manoa, angẹli Ọlọ́run náà tún padà tọ obìnrin náà wá nígbà tí ó wà ní oko ṣùgbọ́n ọkọ rẹ̀ Manoa kò sí ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
I vyslyšel Bůh hlas Manue; nebo přišel anděl Boží opět k ženě té, když seděla na poli. Manue pak muž její nebyl s ní.
10 Nítorí náà ni obìnrin náà ṣe yára lọ sọ fún ọkọ rẹ̀ pé, “Ọkùnrin tí ó fi ara hàn mí ní ọjọ́sí ti tún padà wá.”
A protož s chvátáním běžela žena ta, a oznámila muži svému, řkuci jemu: Hle, ukázal se mi muž ten, kterýž byl ke mně prvé přišel.
11 Manoa yára dìde, ó sì tẹ̀lé aya rẹ̀, nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ ọkùnrin náà ó ní, “Ǹjẹ́ ìwọ ni o bá obìnrin yìí sọ̀rọ̀?” Ọkùnrin náà dáhùn pé, “Èmi ni.”
Vstav pak Manue, šel za manželkou svou, a přišed k muži tomu, řekl jemu: Ty-li jsi ten muž, kterýž jsi mluvil k manželce mé? Odpověděl: Jsem.
12 Manoa bi ọkùnrin náà pé, “Nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ bá ṣẹ kí ni yóò jẹ́ ìlànà fún ìgbé ayé àti iṣẹ́ ọmọ náà?”
I řekl Manue: Nechť se nyní stane slovo tvé, ale jaká péče o to dítě a správa při něm býti má?
13 Angẹli Olúwa náà dáhùn wí pé, “Aya rẹ gbọdọ̀ ṣe gbogbo ohun tí mo ti sọ fún un
Odpověděl anděl Hospodinův Manue: Ode všeho toho, o čemž jsem oznámil ženě, ať se ona vystříhá.
14 kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí ó bá ti inú èso àjàrà jáde wá, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ mu wáìnì tàbí àwọn ọtí líle mìíràn tàbí jẹ ohunkóhun tí ó bá jẹ́ aláìmọ́. Ó ní láti ṣe ohun gbogbo tí mo ti pàṣẹ fún un.”
Ničeho, což pochází z vinného kmene, ať neužívá, to jest, vína aneb nápoje opojného ať nepije, a nic nečistého ať nejí; cožkoli jsem jí přikázal, ať ostříhá.
15 Manoa sọ fún angẹli Olúwa náà pé, “Jọ̀wọ́ dára dúró títí àwa yóò fi pèsè ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan fún ọ.”
Tedy řekl Manue andělu Hospodinovu: Medle, nechť tě pozdržíme, a připravímeť kozlíka.
16 Angẹli Olúwa náà dá Manoa lóhùn pé, “Bí ẹ̀yin tilẹ̀ dá mi dúró, èmi kì yóò jẹ ọ̀kankan nínú oúnjẹ tí ẹ̀yin yóò pèsè. Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá fẹ́ ẹ pèsè ọrẹ ẹbọ sísun, kí ẹ sì fi rú ẹbọ sí Olúwa.” (Manoa kò mọ̀ pé angẹli Olúwa ní i ṣe.)
I odpověděl anděl Hospodinův Manue: Bys mne i pozdržel, nebuduť jísti pokrmu tvého, ale jestliže připravíš obět zápalnou, Hospodinu ji obětuj. Nebo nevěděl Manue, že byl anděl Hospodinův.
17 Manoa sì béèrè lọ́wọ́ angẹli Olúwa náà pé, “Kí ni orúkọ rẹ, kí àwa bá à lè fi ọlá fún ọ nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ bá ṣẹ?”
Řekl opět Manue andělu Hospodinovu: Jaké jest jméno tvé, abychom, když se naplní řeč tvá, poctili tebe?
18 Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa náà dáhùn pé, “Èéṣe tí ìwọ ń béèrè orúkọ mi? Ìyanu ni, ó kọjá ìmọ̀.”
Jemuž odpověděl anděl Hospodinův: Proč se ptáš na jméno mé, kteréž jest divné?
19 Lẹ́yìn náà ni Manoa mú ọ̀dọ́ ewúrẹ́, pẹ̀lú ẹbọ ọkà, ó sì fi rú ẹbọ lórí àpáta kan sí Olúwa. Nígbà tí Manoa àti ìyàwó dúró tí wọn ń wò Olúwa ṣe ohun ìyanu kan.
Vzav tedy Manue kozlíka a obět suchou, obětoval to na skále Hospodinu, a on divnou věc učinil, an na to hledí Manue a manželka jeho.
20 Bí ẹ̀là ahọ́n iná ti là jáde láti ibi pẹpẹ ìrúbọ náà sí ọ̀run, angẹli Olúwa gòkè re ọ̀run láàrín ahọ́n iná náà. Nígbà tí wọ́n rí ìṣẹ̀lẹ̀ yìí, Manoa àti aya rẹ̀ wólẹ̀ wọ́n sì dojúbolẹ̀.
Nebo když vstupoval plamen s oltáře k nebi, vznesl se anděl Hospodinův v plameni s oltáře, Manue pak a manželka jeho vidouce to, padli na tvář svou na zemi.
21 Nígbà tí angẹli Olúwa náà kò tún fi ara rẹ̀ han Manoa àti aya rẹ̀ mọ́, Manoa wá mọ̀ pé angẹli Olúwa ni.
A již se více neukázal anděl Hospodinův Manue ani manželce jeho. Tedy porozuměl Manue, že byl anděl Hospodinův.
22 Manoa sọ fún aya rẹ̀ pé, “Dájúdájú àwa yóò kú nítorí àwa ti fi ojú rí Ọlọ́run.”
I řekl Manue manželce své: Jistě my zemřeme, nebo jsme Boha viděli.
23 Ṣùgbọ́n ìyàwó rẹ̀ dáhùn pé, “Bí Olúwa bá ní èrò àti pa wá kò bá tí gba ẹbọ sísun àti ọrẹ ọkà wa, tàbí fi gbogbo nǹkan wọ̀nyí hàn wá tó sọ nǹkan ìyanu yìí fún wa.”
Jemuž odpověděla manželka jeho: Kdyby nás chtěl Hospodin usmrtiti, nebyl by přijal z rukou našich oběti zápalné a suché, aniž by nám byl ukázal čeho toho, aniž by na tento čas byl nám ohlásil věcí takových.
24 Obìnrin náà sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Samsoni. Ọmọ náà dàgbà Olúwa sì bùkún un.
A tak žena ta porodila syna a nazvala jméno jeho Samson. I rostlo dítě, a žehnal jemu Hospodin.
25 Ẹ̀mí Olúwa sì bẹ̀rẹ̀ sí ru sókè nígbà tí ó wà ní Mahane-Dani ní agbede-méjì Sora àti Eṣtaoli.
I počal ho Duch Hospodinův ponoukati v Mahane Dan, mezi Zaraha a Estaol.

< Judges 13 >