< Judges 12 >

1 Àwọn ọkùnrin Efraimu pe àwọn ológun wọn jáde, wọ́n sì rékọjá sí ìhà àríwá, wọ́n sì bi Jefta pé, “Èéṣe tí o fi lọ bá àwọn ará Ammoni jagun láì ké sí wa láti bá ọ lọ? Àwa yóò sun ilé rẹ mọ́ ọ lórí.”
И собрашася мужие Ефремли и приидоша в Сефину, и реша Иеффаю: почто ходил еси ополчитися на сыны Аммони, и нас не позвал еси ити с тобою? Дом твой с тобою сожжем огнем.
2 Jefta dáhùn pé, “Èmi àti àwọn ènìyàn ní ìyọnu ńlá pẹ̀lú àwọn ará Ammoni, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo pè yín, ẹ̀yin kò gbà mí sílẹ̀ ní ọwọ́ wọn.
И рече к ним Иеффай: имех прю аз и людие мои, и сынове Аммони оскорбиша мене зело: и воззвах вас, и не избависте мене от руки их:
3 Nígbà tí mo rí i pé ẹ̀yin kò gbà mí, mo fi ẹ̀mí mi wéwu. Mó sì gòkè lọ láti bá àwọn ará Ammoni jà, Olúwa sì fún mi ní ìṣẹ́gun lórí wọn, èéṣe báyìí tí ẹ fi dìde wá lónìí láti bá mi jà?”
и видех, яко не бяше спасающаго, и положих душу мою в руку мою, и приидох к сыном Аммоним, и предаде я Господь в руку мою: и вскую приидосте ко мне днесь, ополчити ли ся на мя?
4 Nígbà náà ni Jefta kó gbogbo ọkùnrin Gileadi jọ, ó sì bá Efraimu jà. Àwọn ọkùnrin Gileadi sì kọlù Efraimu, nítorí wọ́n ti sọtẹ́lẹ̀ pé, “Ẹ̀yin ará Gileadi jẹ́ àsáwọ̀ àwọn ará Efraimu àti ti Manase.”
И собра Иеффай вся мужы Галаадски и ополчися на Ефрема: и избиша мужие Галаадстии Ефрема, понеже глаголаху: уцелевшии от Ефрема, вы Галаад среде Ефрема и среде Манассии.
5 Àwọn ará Gileadi gba à bá wọ odò Jordani tí wọ́n máa gbà lọ sí Efraimu, nígbàkígbà tí àwọn ará Efraimu bá wí pé, “Jẹ́ kí ń sálọ sí òkè,” lọ́hùn ún àwọn ará Gileadi yóò bi í pé, “Ṣé ará Efraimu ni ìwọ ń ṣe?” Tí ó bá wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́,”
И засяде Галаад проходы у Иордана Ефремовы. И бысть егда реша уцелевшии от Ефрема: прейдем: и рекоша им мужие Галаадстии: еда ли от Ефрема вы? И реша: несмы.
6 wọ́n ó wí fún un pé, “Ó dá à wí pé ‘Ṣibolẹti.’” Tí ó bá ní, “Sibolẹti,” torí pé kò ní mọ̀ ọ́n pé dáradára, wọ́n á mú un wọn, a sì pa á ni à bá wọ odò Jordani. Àwọn ará Efraimu tí wọn pa ní àkókò yìí jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjìlélógójì ọkùnrin.
И реша им: рцыте, клас. И не управиша рещи тако: и имаху их, и закалаху у преходов Иорданих: и падоша в то время от Ефрема четыредесять и две тысящы.
7 Jefta ṣe ìdájọ́ Israẹli ní ọdún mẹ́fà. Lẹ́yìn náà Jefta ará Gileadi kú, wọ́n sì sin ín sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú Gileadi.
И суди Иеффай Израилеви лет шесть: и умре Иеффай Галаадитин, и погребен бысть во граде своем в Галааде.
8 Lẹ́yìn Jefta, Ibsani ará Bẹtilẹhẹmu ṣe ìdájọ́ àwọn ọmọ Israẹli.
И суди по нем Израилеви Есевон от Вифлеема:
9 Ó ní ọgbọ̀n ọmọkùnrin àti ọgbọ̀n ọmọbìnrin fún àwọn tí kì í ṣe ẹ̀yà rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìyàwó, ó sì fẹ́ ọgbọ̀n àwọn ọmọbìnrin fún àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin lára àwọn tí kì í ṣe ẹ̀yà rẹ̀. Ibsani ṣe ìdájọ́ Israẹli fún ọdún méje.
и быша ему тридесять сыны и тридесять дщери, яже отдаде вон (мужем), и тридесять жен приведе сыном своим отвне: и суди Израилеви седмь лет:
10 Lẹ́yìn náà ni Ibsani kú, wọ́n sì sin ín sí Bẹtilẹhẹmu.
и умре Есевон, и погребен бысть в Вифлееме.
11 Lẹ́yìn rẹ̀, Eloni ti ẹ̀yà Sebuluni ṣe àkóso Israẹli fún ọdún mẹ́wàá.
И суди по нем Израилеви Елон Завулонянин десять лет:
12 Eloni sì kú, wọ́n sì sin ín sí Aijaloni ní ilẹ̀ Sebuluni.
и умре Елон Завулонянин, и погребен бысть во Елиме в земли Завулони.
13 Lẹ́yìn rẹ̀ ni Abdoni ọmọ Hileli tí Piratoni n ṣe àkóso Israẹli.
И суди по нем Израилеви Авдон сын Еллихов Фарафонитин:
14 Òun ní ogójì ọmọkùnrin àti ọgbọ̀n ọmọ ọmọ àwọn tí ó ń gun àádọ́rin kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Ó ṣe ìdájọ́ Israẹli ní ọdún mẹ́jọ.
и быша ему четыредесять сынове и тридесять внуцы, ездящии на седмидесяти ослех: и суди Израилеви осмь лет:
15 Abdoni ọmọ Hileli sì kú, wọ́n sin ín sí Piratoni ní ilé Efraimu ní ìlú òkè àwọn ará Amaleki.
и умре Авдон сын Еллихов Фарафонитин, и погребен бысть в Фарафоне, в земли Ефремли, в горе Амаликове.

< Judges 12 >