< Judges 12 >

1 Àwọn ọkùnrin Efraimu pe àwọn ológun wọn jáde, wọ́n sì rékọjá sí ìhà àríwá, wọ́n sì bi Jefta pé, “Èéṣe tí o fi lọ bá àwọn ará Ammoni jagun láì ké sí wa láti bá ọ lọ? Àwa yóò sun ilé rẹ mọ́ ọ lórí.”
Os homens de Efraim foram reunidos e passaram para o norte; e disseram a Jefté: “Por que você passou para lutar contra as crianças de Ammon, e não nos chamou para irmos com você? Vamos queimar sua casa ao seu redor com fogo”!
2 Jefta dáhùn pé, “Èmi àti àwọn ènìyàn ní ìyọnu ńlá pẹ̀lú àwọn ará Ammoni, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo pè yín, ẹ̀yin kò gbà mí sílẹ̀ ní ọwọ́ wọn.
Jefthah disse a eles: “Eu e meu povo estávamos em grande contenda com os filhos de Ammon; e quando os chamei, vocês não me salvaram da mão deles.
3 Nígbà tí mo rí i pé ẹ̀yin kò gbà mí, mo fi ẹ̀mí mi wéwu. Mó sì gòkè lọ láti bá àwọn ará Ammoni jà, Olúwa sì fún mi ní ìṣẹ́gun lórí wọn, èéṣe báyìí tí ẹ fi dìde wá lónìí láti bá mi jà?”
Quando vi que você não me salvou, coloquei minha vida na mão e passei contra as crianças de Ammon, e Yahweh as entregou em minhas mãos. Por que então vocês vieram até mim hoje, para lutar contra mim”?
4 Nígbà náà ni Jefta kó gbogbo ọkùnrin Gileadi jọ, ó sì bá Efraimu jà. Àwọn ọkùnrin Gileadi sì kọlù Efraimu, nítorí wọ́n ti sọtẹ́lẹ̀ pé, “Ẹ̀yin ará Gileadi jẹ́ àsáwọ̀ àwọn ará Efraimu àti ti Manase.”
Então Jephthah reuniu todos os homens de Gilead, e lutou com Efraim. Os homens de Gilead atingiram Efraim, porque disseram: “Vocês são fugitivos de Efraim, seus gileaditas, no meio de Efraim, e no meio de Manasseh”.
5 Àwọn ará Gileadi gba à bá wọ odò Jordani tí wọ́n máa gbà lọ sí Efraimu, nígbàkígbà tí àwọn ará Efraimu bá wí pé, “Jẹ́ kí ń sálọ sí òkè,” lọ́hùn ún àwọn ará Gileadi yóò bi í pé, “Ṣé ará Efraimu ni ìwọ ń ṣe?” Tí ó bá wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́,”
Os gileaditas tomaram os vaus do Jordão contra os efraimitas. Sempre que um fugitivo de Efraim dizia: “Deixe-me ir”, os homens de Gilead lhe diziam: “Você é um efraimita? Se ele disse, “Não;”
6 wọ́n ó wí fún un pé, “Ó dá à wí pé ‘Ṣibolẹti.’” Tí ó bá ní, “Sibolẹti,” torí pé kò ní mọ̀ ọ́n pé dáradára, wọ́n á mú un wọn, a sì pa á ni à bá wọ odò Jordani. Àwọn ará Efraimu tí wọn pa ní àkókò yìí jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjìlélógójì ọkùnrin.
então eles lhe disseram, “Agora diga 'Shibboleth;'” e ele disse “Sibboleth”; pois ele não conseguiu pronunciá-lo corretamente, então eles o apreenderam e o mataram nos vaus do Jordão. Naquele momento, quarenta e dois mil de Efraim caíram.
7 Jefta ṣe ìdájọ́ Israẹli ní ọdún mẹ́fà. Lẹ́yìn náà Jefta ará Gileadi kú, wọ́n sì sin ín sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú Gileadi.
Jephthah julgou Israel por seis anos. Depois Jefté, o Gileadita, morreu e foi enterrado nas cidades de Gilead.
8 Lẹ́yìn Jefta, Ibsani ará Bẹtilẹhẹmu ṣe ìdájọ́ àwọn ọmọ Israẹli.
Depois dele, Ibzan de Belém julgou Israel.
9 Ó ní ọgbọ̀n ọmọkùnrin àti ọgbọ̀n ọmọbìnrin fún àwọn tí kì í ṣe ẹ̀yà rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìyàwó, ó sì fẹ́ ọgbọ̀n àwọn ọmọbìnrin fún àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin lára àwọn tí kì í ṣe ẹ̀yà rẹ̀. Ibsani ṣe ìdájọ́ Israẹli fún ọdún méje.
Ele teve trinta filhos. Ele enviou suas trinta filhas de fora de seu clã e trouxe trinta filhas de fora de seu clã para seus filhos. Ele julgou Israel por sete anos.
10 Lẹ́yìn náà ni Ibsani kú, wọ́n sì sin ín sí Bẹtilẹhẹmu.
Ibzan morreu, e foi enterrado em Belém.
11 Lẹ́yìn rẹ̀, Eloni ti ẹ̀yà Sebuluni ṣe àkóso Israẹli fún ọdún mẹ́wàá.
Depois dele, Elon, o zebulunita, julgou Israel; e ele julgou Israel dez anos.
12 Eloni sì kú, wọ́n sì sin ín sí Aijaloni ní ilẹ̀ Sebuluni.
Elon o zebulunita morreu, e foi enterrado em Aijalon, na terra de Zebulun.
13 Lẹ́yìn rẹ̀ ni Abdoni ọmọ Hileli tí Piratoni n ṣe àkóso Israẹli.
Depois dele, Abdon, filho de Hillel, o Piratonita, julgou Israel.
14 Òun ní ogójì ọmọkùnrin àti ọgbọ̀n ọmọ ọmọ àwọn tí ó ń gun àádọ́rin kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Ó ṣe ìdájọ́ Israẹli ní ọdún mẹ́jọ.
Ele tinha quarenta filhos e trinta filhos de filhos que montavam em setenta jumentos de burros. Ele julgou Israel por oito anos.
15 Abdoni ọmọ Hileli sì kú, wọ́n sin ín sí Piratoni ní ilé Efraimu ní ìlú òkè àwọn ará Amaleki.
Abdon, filho de Hillel, o piratonita, morreu e foi enterrado em Pirathon, na terra de Efraim, na região montanhosa dos amalequitas.

< Judges 12 >