< Judges 11 >
1 Jefta ará Gileadi jẹ́ akọni jagunjagun. Gileadi ni baba rẹ̀; ṣùgbọ́n ìyá rẹ̀ jẹ́ panṣágà.
А Јефтај од Галада беше храбар јунак, али син једне курве, с којом Галад роди Јефтаја.
2 Ìyàwó Gileadi sì bí àwọn ọmọkùnrin fún un, nígbà tí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí dàgbà, wọ́n rán Jefta jáde kúrò nílé, wọ́n wí pé, “Ìwọ kì yóò ní ogún kankan ní ìdílé wa, nítorí pé ìwọ jẹ́ ọmọ obìnrin mìíràn.”
Али Галаду и жена његова роди синове, па кад дорастоше синови те жене, отераше Јефтаја рекавши му: Нећеш имати наследство у дому оца нашег, јер си син друге жене.
3 Jefta sì sá kúrò lọ́dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, ó sì pàgọ́ sí ilẹ̀ Tobu, ó sì ń gbé níbẹ̀, níbẹ̀ ni àwọn ènìyàn kan ti ń tẹ òfin lójú parapọ̀ láti máa tẹ̀lé e kiri.
Зато побеже Јефтај од браће своје, и настани се у земљи Тову; и стекоше се к њему људи празнови, и иђаху с њим.
4 Ní àsìkò kan, nígbà tí àwọn ará Ammoni dìde ogun sí àwọn Israẹli,
А после неког времена завојштише синови Амонови на Израиља;
5 Ó sì ṣe nígbà tí àwọn Ammoni bá Israẹli jagun, àwọn àgbàgbà Gileadi tọ Jefta lọ láti pè é wá láti ilẹ̀ Tobu.
И кад завојштише синови Амонови на Израиља, отидоше старешине галадске да доведу Јефтаја из земље Това.
6 Wọ́n wí fún Jefta wí pé, “Wá kí o sì jẹ́ olórí ogun wa kí a lè kọjú ogun sí àwọn ará Ammoni.”
И рекоше Јефтају: Ходи и буди нам војвода, да војујемо са синовима Амоновим.
7 Jefta sì wí fún àwọn àgbàgbà Gileadi pé, “Ṣé kì í ṣe pé ẹ kórìíra mi tí ẹ sì lé mi kúrò ní ilé baba mi? Kí ló dé tí ẹ fi tọ̀ mí wá báyìí nígbà tí ẹ wà nínú wàhálà?”
А Јефтај рече старешинама галадским: Не мрзите ли ви на ме, и не истерасте ли ме из дома оца мог? Што сте дакле дошли к мени сада кад сте у невољи?
8 Àwọn àgbà Gileadi sì wí fún Jefta pé, “Nítorí rẹ̀ ni àwa fi yípadà sí ọ báyìí: tẹ̀lé wa, kí a lè dojú ìjà kọ àwọn ará Ammoni, ìwọ yóò sì jẹ olórí wa àti gbogbo àwa tí ń gbé ní Gileadi.”
А старешине галадске рекоше Јефтају: Зато смо сада дошли опет к теби да пођеш с нама и да војујеш са синовима Амоновим и да нам будеш поглавар свима који живимо у Галаду.
9 Jefta sì wí fún àwọn àgbàgbà Gileadi pé, “Bí ẹ̀yin bá mú mi padà láti bá àwọn ará Ammoni jà àti tí Olúwa bá fi wọ́n lé mi lọ́wọ́: ṣe èmi yóò jẹ́ olórí yín nítòótọ́?”
А Јефтај рече старешинама галадским: Кад хоћете да ме одведете натраг да војујем са синовима Амоновим, ако ми их да Господ, хоћу ли вам бити поглавар?
10 Àwọn àgbàgbà Gileadi sì wí fún Jefta pé, “Àwa fi Olúwa ṣe ẹlẹ́rìí: àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá wí.”
А старешине галадске рекоше Јефтају: Господ нека буде сведок међу нама, ако не учинимо како си казао.
11 Jefta sì tẹ̀lé àwọn àgbàgbà Gileadi lọ, àwọn ènìyàn náà sì fi ṣe olórí àti ọ̀gágun wọn. Jefta sì tún sọ gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ tí ó ti sọtẹ́lẹ̀ níwájú Olúwa ní Mispa.
Тада отиде Јефтај са старешинама галадским, и народ га постави поглаварем и војводом над собом: и Јефтај изговори пред Господом у Миспи све речи које беше рекао.
12 Jefta sì rán àwọn oníṣẹ́ sí ọba àwọn ará Ammoni pé, “Kí ni ẹ̀sùn tí o ní sí wa láti fi kàn wá tí ìwọ fi dojú ìjà kọ ilẹ̀ wa?”
Потом посла Јефтај посланике к цару синова Амонових, и поручи: Шта имаш ти са мном, те си допао к мени да ратујеш по мојој земљи?
13 Ọba àwọn Ammoni dá àwọn oníṣẹ́ Jefta lóhùn pé, “Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli jáde ti Ejibiti wá. Wọ́n gba ilẹ̀ mi láti Arnoni dé Jabbok, àní dé Jordani, nítorí náà dá wọn padà lọ ní àlàáfíà àti ní pẹ̀lẹ́ kùtù.”
А цар синова Амонових рече посланицима Јефтајевим: Што је узео Израиљ моју земљу кад дође из Мисира, од Ариона до Јавока и до Јордана; сада дакле врати ми је с миром.
14 Jefta sì tún ránṣẹ́ padà sí ọba àwọn ará Ammoni
Али Јефтај посла опет посланике к цару синова Амонових.
15 ó sì wí fún un pé, “Báyìí ni Jefta wí: àwọn ọmọ Israẹli kò gba ilẹ̀ Moabu tàbí ilẹ̀ àwọn ará Ammoni.
И поручи му: Овако вели Јефтај: Није узео Израиљ земље моавске ни земље синова Амонових.
16 Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n jáde kúrò ní Ejibiti àwọn ọmọ Israẹli la aginjù kọjá lọ sí ọ̀nà Òkun Pupa wọ́n sì lọ sí Kadeṣi.
Него изашавши из Мисира пређе Израиљ преко пустиње до Црвеног Мора и дође до Кадиса.
17 Nígbà náà Israẹli rán àwọn oníṣẹ́ sí ọba Edomu pé, ‘Gbà fún wa láti gba ilẹ̀ rẹ̀ kọjá,’ ṣùgbọ́n ọba Edomu kò fetí sí wọn. Wọ́n tún ránṣẹ́ sí ọba Moabu bákan náà òun náà kọ̀. Nítorí náà Israẹli dúró sí Kadeṣi.
И посла Израиљ посланике к цару едомском и рече: Пусти да прођем кроз твоју земљу. Али не послуша цар едомски. Посла такође к цару моавском: , али ни он не хте. И тако стаја Израиљ у Кадису.
18 “Wọ́n rin aginjù kọjá, wọ́n pẹ́ àwọn ilẹ̀ Edomu àti ti Moabu sílẹ̀, nígbà tí wọ́n gba apá ìlà-oòrùn Moabu, wọ́n sì tẹ̀dó sí apá kejì Arnoni. Wọn kò wọ ilẹ̀ Moabu, nítorí pé ààlà rẹ̀ ni Arnoni wà.
Потом идући преко пустиње обиђе земљу едомску и земљу моавску, и дошавши с Истока земљи моавској стаде у логор с оне стране Ариона; али не пређоше преко међе моавске, јер Арион беше међа моавска.
19 “Nígbà náà ni Israẹli rán àwọn oníṣẹ́ sí Sihoni ọba àwọn ará Amori, ẹni tí ń ṣe àkóso ní Heṣboni, wọ́n sì wí fún un pé, ‘Jẹ́ kí a la ilẹ̀ rẹ kọjá lọ sí ibùgbé wa.’
Него посла Израиљ посланике к Сиону цару аморејском, цару есевонском, и рече му Израиљ; допусти нам да прођемо кроз твоју земљу до свог места.
20 Ṣùgbọ́n Sihoni kò gba Israẹli gbọ́ (kò fọkàn tán an) láti jẹ́ kí ó kọjá. Ó kó gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ jọ, ó sì tẹ̀dó sí Jahisa láti bá Israẹli jagun.
Али Сион не верова Израиљу да га пусти да пређе преко међе његове, него Сион скупи сав свој народ и стадоше у логор у Јаси, и поби се са Израиљем.
21 “Olúwa Ọlọ́run Israẹli sì fi Sihoni àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ lé Israẹli lọ́wọ́, wọ́n sì ṣẹ́gun wọn. Israẹli sì gba gbogbo ilẹ̀ àwọn ará Amori tí wọ́n ń gbé ní agbègbè náà,
А Господ Бог Израиљев предаде Сиона и сав народ његов у руке синовима Израиљевим, те их побише; и зароби Израиљ сву земљу Амореја, који живљаху у оној земљи.
22 wọ́n gbà gbogbo agbègbè àwọn ará Amori, láti Arnoni tí ó fi dé Jabbok, àti láti aginjù dé Jordani.
Задобише сву земљу аморејску од Ариона до Јавока, и од пустиње до Јордана.
23 “Wàyí o, nígbà tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ti lé àwọn ará Amori kúrò níwájú àwọn ènìyàn rẹ̀; Israẹli, ẹ̀tọ́ wo ni ẹ ní láti gba ilẹ̀ náà?
Тако је дакле Господ Бог Израиљев отерао Амореје испред народа свог Израиља, па ти ли хоћеш да је земља њихова твоја?
24 Ǹjẹ́ ìwọ kì yóò ha gba èyí tí Kemoṣi òrìṣà rẹ fi fún ọ? Bákan náà àwa yóò gba èyíkéyìí tí Olúwa Ọlọ́run wa fi fún wa.
Није ли твоје оно што ти да да је твоје Хемос бог твој? Тако кога год Господ Бог наш отера испред нас, оног је земља наша.
25 Ǹjẹ́ ìwọ ha sàn ju Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu lọ? Ǹjẹ́ òun ha ṣe gbólóhùn asọ̀ pẹ̀lú Israẹli bí? Tàbí òun dojú ìjà kọ wọ́n rí bí?
Или си ти по чем бољи од Валака сина Сефоровог цара моавског? Је ли се он кад свађао с Израиљем? Је ли кад војевао с нама?
26 Fún ọ̀ọ́dúnrún ọdún ni Israẹli fi ṣe àtìpó ní Heṣboni, Aroeri àti àwọn ìgbèríko àti àwọn ìlú tí ó yí Arnoni ká. Èéṣe tí ìwọ kò fi gbà wọ́n padà ní àsìkò náà?
Израиљ живи у Есевону и у селима његовим и у Ароиру и селима његовим и по свим градовима дуж Арнона три стотине година; зашто не отесте за толико времена.
27 Èmi kọ́ ni ó ṣẹ̀ ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ ni ó ṣẹ̀ mí nípa kíkógun tọ̀ mí wá. Jẹ́ kí Olúwa olùdájọ́, ṣe ìdájọ́ lónìí láàrín àwọn ọmọ Israẹli àti àwọn ará Ammoni.”
И тако нисам ја теби скривио, него ти мени чиниш зло ратујући на ме. Господ судија нек суди данас између синова Израиљевих и синова Амонових.
28 Ṣùgbọ́n ọba àwọn Ammoni kò fetí sí iṣẹ́ tí Jefta rán sí i.
Али цар синова Амонових не послуша речи које му поручи Јефтај.
29 Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Jefta òun sì la Gileadi àti Manase kọjá. Ó la Mispa àti Gileadi kọjá láti ibẹ̀, ó tẹ̀síwájú láti bá àwọn ará Ammoni jà.
И сиђе на Јефтаја дух Господњи, те прође кроз Галад и кроз Манасију, прође и Миспу галадску, и од Миспе галадске дође о синова Амонових.
30 Jefta sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa pé, “Bí ìwọ bá fi àwọn ará Ammoni lé mi lọ́wọ́,
И заветова Јефтај завет Господу и рече: Ако ми даш синове Амонове у руке,
31 yóò sì ṣe, ohunkóhun tí ó bá jáde láti ẹnu-ọ̀nà ilé mi láti wá pàdé mi, nígbà tí èmi bá ń padà bọ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ammoni ní àlàáfíà, yóò jẹ́ ti Olúwa, èmi yóò sì fi rú ẹbọ bí ọrẹ ẹbọ sísun.”
Шта год изиђе на врата из куће моје на сусрет мени, кад се вратим здрав од синова Амонових, биће Господње, и принећу на жртву паљеницу.
32 Jefta sì jáde lọ láti bá àwọn ará Ammoni jagun, Olúwa sì fi wọ́n lé e lọ́wọ́.
И тако дође Јефтај до синова Амонових да се бије с њима; и Господ му их даде у руке.
33 Òun sì ṣẹ́gun wọn, ó sì pa wọ́n ní à pa tán láti Aroeri títí dé agbègbè Minniti, ó jẹ́ ogún ìlú, títí dé Abeli-Keramimu. Báyìí ni Israẹli ti ṣẹ́gun àwọn ará Ammoni.
И поби их од Ароира па до Минита у двадесет градова и до равнице виноградске у боју врло великом; и синови Амонови бише покорени пред синовима Израиљевим.
34 Nígbà tí Jefta padà sí ilé rẹ̀ ní Mispa, wò ó, ọmọ rẹ̀ obìnrin ń jáde bọ̀ wá pàdé rẹ̀ pẹ̀lú timbrili àti ijó. Òun ni ọmọ kan ṣoṣo tí ó ní: kò ní ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin mìíràn yàtọ̀ sí òun nìkan.
А кад се враћаше Јефтај кући својој у Миспу, гле, кћи његова изиђе му на сусрет с бубњевима и свиралама; она му беше јединица, и осим ње не имаше ни сина ни кћери.
35 Ní ìgbà tí ó rí i ó fa aṣọ rẹ̀ ya ní ìbànújẹ́, ó sì ké wí pé, “Háà! Ọ̀dọ́mọbìnrin mi, ìwọ fún mi ní ìbànújẹ́ ọkàn ìwọ sì rẹ̀ mí sílẹ̀ gidigidi, nítorí pé èmi ti ya ẹnu mi sí Olúwa ní ẹ̀jẹ́, èmi kò sì le sẹ́ ẹ̀jẹ́ mi.”
Па кад је угледа, раздре хаљине своје и рече: Ах кћери моја! Веле ли ме обори! Ти си од оних што ме цвеле; јер сам отворио уста своја ка Господу и не могу порећи.
36 Ọmọ náà sì dáhùn pé, “Baba mi bí ìwọ bá ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa, ṣe sí mi gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ, ní báyìí tí Olúwa ti gba ẹ̀san fún ọ lára àwọn ọ̀tá rẹ, àwọn ará Ammoni.
А она му рече: Оче мој, кад си отворио уста своја ка Господу, учини ми, како је изашло из уста твојих, кад те је Господ осветио од непријатеља твојих, синова Амонових.
37 Ṣùgbọ́n yọ̀ǹda ìbéèrè kan yìí fún mi, gbà mí láààyè oṣù méjì láti rìn ká orí àwọn òkè, kí n sọkún pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ mi torí mo jẹ́ wúńdíá tí n kò sì ní lè ṣe ìgbéyàwó.”
Још рече оцу свом: Учини ми ово: остави ме до два месеца да отидем да се попнем на горе да оплачем своје девојаштво с другама својим.
38 Jefta dá lóhùn pé, “Ìwọ lè lọ.” Ó sì gbà á láààyè láti lọ fún oṣù méjì. Òun àti àwọn ọmọbìnrin yòókù lọ sí orí àwọn òkè, wọ́n sọkún nítorí pé kì yóò lè ṣe ìgbéyàwó.
А он јој рече: Иди. И пусти је на два месеца, и она отиде с другама својим и оплакива девојаштво своје по горама.
39 Lẹ́yìn oṣù méjì náà, ó padà tọ baba rẹ̀ wá òun sì ṣe sí i bí ẹ̀jẹ́ tí ó ti jẹ́. Ọmọ náà sì jẹ́ wúńdíá tí kò mọ ọkùnrin rí. Èyí sì bẹ̀rẹ̀ àṣà kan ní Israẹli
А кад прођоше два месеца, врати се к оцу свом; и он сврши на њој завет свој који беше заветовао. А она не позна човека. И поста обичај у Израиљу
40 wí pé ní ọjọ́ mẹ́rin láàrín ọdún àwọn obìnrin Israẹli a máa lọ láti ṣọ̀fọ̀ àti ṣe ìrántí ọmọbìnrin Jefta ti Gileadi.
Да од године до године иду кћери Израиљеве да плачу за кћерју Јефтаја од Галада, четири дана у години.