< Judges 11 >

1 Jefta ará Gileadi jẹ́ akọni jagunjagun. Gileadi ni baba rẹ̀; ṣùgbọ́n ìyá rẹ̀ jẹ́ panṣágà.
Иефта, Галаадитул, ера ун ом витяз. Ел ера фиул уней курве. Галаад нэскусе пе Иефта.
2 Ìyàwó Gileadi sì bí àwọn ọmọkùnrin fún un, nígbà tí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí dàgbà, wọ́n rán Jefta jáde kúrò nílé, wọ́n wí pé, “Ìwọ kì yóò ní ogún kankan ní ìdílé wa, nítorí pé ìwọ jẹ́ ọmọ obìnrin mìíràn.”
Неваста луй Галаад й-а нэскут фий, каре, фэкынду-се марь, ау изгонит пе Иефта ши й-ау зис: „Ту ну вей авя моштенире ын каса татэлуй ностру, кэч ешть фиул уней алте фемей.”
3 Jefta sì sá kúrò lọ́dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, ó sì pàgọ́ sí ilẹ̀ Tobu, ó sì ń gbé níbẹ̀, níbẹ̀ ni àwọn ènìyàn kan ti ń tẹ òfin lójú parapọ̀ láti máa tẹ̀lé e kiri.
Ши Иефта а фуӂит де ла фраций луй ши а локуит ын цара Тоб. Ниште оамень фэрэ кэпэтый с-ау стрынс ла Иефта ши фэчяу плимбэрь ку ел.
4 Ní àsìkò kan, nígbà tí àwọn ará Ammoni dìde ogun sí àwọn Israẹli,
Дупэ кытва тимп, фиий луй Амон ау порнит ку рэзбой ымпотрива луй Исраел.
5 Ó sì ṣe nígbà tí àwọn Ammoni bá Israẹli jagun, àwọn àgbàgbà Gileadi tọ Jefta lọ láti pè é wá láti ilẹ̀ Tobu.
Ши пе кынд фиий луй Амон фэчяу рэзбой ку Исраел, бэтрыний Галаадулуй с-ау дус сэ кауте пе Иефта дин цара Тоб.
6 Wọ́n wí fún Jefta wí pé, “Wá kí o sì jẹ́ olórí ogun wa kí a lè kọjú ogun sí àwọn ará Ammoni.”
Ей ау зис луй Иефта: „Вино де фий кэпетения ноастрэ ши сэ батем пе фиий луй Амон.”
7 Jefta sì wí fún àwọn àgbàgbà Gileadi pé, “Ṣé kì í ṣe pé ẹ kórìíra mi tí ẹ sì lé mi kúrò ní ilé baba mi? Kí ló dé tí ẹ fi tọ̀ mí wá báyìí nígbà tí ẹ wà nínú wàhálà?”
Иефта а рэспунс бэтрынилор Галаадулуй: „Ну м-аць урыт вой ши ну м-аць изгонит вой дин каса татэлуй меу? Пентру че вениць ла мине акум, кынд сунтець ын стрымтораре?”
8 Àwọn àgbà Gileadi sì wí fún Jefta pé, “Nítorí rẹ̀ ni àwa fi yípadà sí ọ báyìí: tẹ̀lé wa, kí a lè dojú ìjà kọ àwọn ará Ammoni, ìwọ yóò sì jẹ olórí wa àti gbogbo àwa tí ń gbé ní Gileadi.”
Бэтрыний Галаадулуй ау зис луй Иефта: „Не ынтоарчем ла тине акум ка сэ мерӂь ку ной, сэ баць пе фиий луй Амон ши сэ фий кэпетения ноастрэ, кэпетения тутурор локуиторилор Галаадулуй.”
9 Jefta sì wí fún àwọn àgbàgbà Gileadi pé, “Bí ẹ̀yin bá mú mi padà láti bá àwọn ará Ammoni jà àti tí Olúwa bá fi wọ́n lé mi lọ́wọ́: ṣe èmi yóò jẹ́ olórí yín nítòótọ́?”
Иефта а рэспунс бэтрынилор Галаадулуй: „Дакэ мэ адучець ынапой ка сэ бат пе фиий луй Амон ши дакэ Домнул ый ва да ынаинтя мя, вой фи еу оаре кэпетения воастрэ?”
10 Àwọn àgbàgbà Gileadi sì wí fún Jefta pé, “Àwa fi Olúwa ṣe ẹlẹ́rìí: àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá wí.”
Бэтрыний Галаадулуй ау зис луй Иефта: „Домнул сэ не аудэ ши сэ жудече дакэ ну вом фаче че спуй.”
11 Jefta sì tẹ̀lé àwọn àgbàgbà Gileadi lọ, àwọn ènìyàn náà sì fi ṣe olórí àti ọ̀gágun wọn. Jefta sì tún sọ gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ tí ó ti sọtẹ́lẹ̀ níwájú Olúwa ní Mispa.
Ши Иефта а порнит ку бэтрыний Галаадулуй. Попорул л-а пус ын фрунтя луй ши л-а ашезат кэпетение, ши Иефта а спус дин ноу ынаинтя Домнулуй, ла Мицпа, тоате кувинтеле пе каре ле ростисе.
12 Jefta sì rán àwọn oníṣẹ́ sí ọba àwọn ará Ammoni pé, “Kí ni ẹ̀sùn tí o ní sí wa láti fi kàn wá tí ìwọ fi dojú ìjà kọ ilẹ̀ wa?”
Иефта а тримис соль ымпэратулуй фиилор луй Амон ка сэ-й спунэ: „Че ай ку мине де вий ымпотрива мя сэ фачь рэзбой ымпотрива цэрий меле?”
13 Ọba àwọn Ammoni dá àwọn oníṣẹ́ Jefta lóhùn pé, “Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli jáde ti Ejibiti wá. Wọ́n gba ilẹ̀ mi láti Arnoni dé Jabbok, àní dé Jordani, nítorí náà dá wọn padà lọ ní àlàáfíà àti ní pẹ̀lẹ́ kùtù.”
Ымпэратул фиилор луй Амон а рэспунс солилор луй Иефта: „Пентру кэ Исраел, кынд с-а суит дин Еӂипт, а пус мына пе цара мя, де ла Арнон пынэ ла Иабок ши Йордан. Дэ-мь-о ынапой акум де бунэвое.”
14 Jefta sì tún ránṣẹ́ padà sí ọba àwọn ará Ammoni
Иефта а тримис ярэшь соль ымпэратулуй фиилор луй Амон
15 ó sì wí fún un pé, “Báyìí ni Jefta wí: àwọn ọmọ Israẹli kò gba ilẹ̀ Moabu tàbí ilẹ̀ àwọn ará Ammoni.
ка сэ-й спунэ: „Аша ворбеште Иефта: ‘Исраел н-а пус мына пе цара Моабулуй, нич пе цара фиилор луй Амон.
16 Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n jáde kúrò ní Ejibiti àwọn ọmọ Israẹli la aginjù kọjá lọ sí ọ̀nà Òkun Pupa wọ́n sì lọ sí Kadeṣi.
Кэч, кынд с-а суит Исраел дин Еӂипт, а мерс ын пустиу пынэ ла Маря Рошие ши а ажунс ла Кадес.
17 Nígbà náà Israẹli rán àwọn oníṣẹ́ sí ọba Edomu pé, ‘Gbà fún wa láti gba ilẹ̀ rẹ̀ kọjá,’ ṣùgbọ́n ọba Edomu kò fetí sí wọn. Wọ́n tún ránṣẹ́ sí ọba Moabu bákan náà òun náà kọ̀. Nítorí náà Israẹli dúró sí Kadeṣi.
Атунч, Исраел а тримис соль ымпэратулуй Едомулуй ка сэ-й спунэ: «Ласэ-мэ сэ трек прин цара та.» Дар ымпэратул Едомулуй н-а воит. А тримис ши ла ымпэратул Моабулуй, ши нич ел н-а врут. Ши Исраел а рэмас ла Кадес.
18 “Wọ́n rin aginjù kọjá, wọ́n pẹ́ àwọn ilẹ̀ Edomu àti ti Moabu sílẹ̀, nígbà tí wọ́n gba apá ìlà-oòrùn Moabu, wọ́n sì tẹ̀dó sí apá kejì Arnoni. Wọn kò wọ ilẹ̀ Moabu, nítorí pé ààlà rẹ̀ ni Arnoni wà.
Апой а мерс прин пустиу, а околит цара Едомулуй ши цара Моабулуй ши а венит ла рэсэритул цэрий Моабулуй; ау тэбэрыт динколо де Арнон, фэрэ сэ интре пе цинутул Моабулуй, кэч Арнонул ера хотарул Моабулуй.
19 “Nígbà náà ni Israẹli rán àwọn oníṣẹ́ sí Sihoni ọba àwọn ará Amori, ẹni tí ń ṣe àkóso ní Heṣboni, wọ́n sì wí fún un pé, ‘Jẹ́ kí a la ilẹ̀ rẹ kọjá lọ sí ibùgbé wa.’
Исраел а тримис соль луй Сихон, ымпэратул аморицилор, ымпэратул Хесбонулуй. Ши Исраел й-а зис: «Ласэ-мэ сэ трек прин цара та пынэ ла локул спре каре мерӂем.»
20 Ṣùgbọ́n Sihoni kò gba Israẹli gbọ́ (kò fọkàn tán an) láti jẹ́ kí ó kọjá. Ó kó gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ jọ, ó sì tẹ̀dó sí Jahisa láti bá Israẹli jagun.
Дар Сихон н-а авут ынкредере ын Исраел, ка сэ-л ласе сэ трякэ пе цинутул луй, шь-а стрынс тот попорул, а тэбэрыт ла Иахат ши а луптат ымпотрива луй Исраел.
21 “Olúwa Ọlọ́run Israẹli sì fi Sihoni àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ lé Israẹli lọ́wọ́, wọ́n sì ṣẹ́gun wọn. Israẹli sì gba gbogbo ilẹ̀ àwọn ará Amori tí wọ́n ń gbé ní agbègbè náà,
Домнул Думнезеул луй Исраел а дат пе Сихон ши пе тот попорул луй ын мыниле луй Исраел, каре й-а бэтут. Исраел а пус мына пе тоатэ цара аморицилор каре ерау ашезаць ын цара ачаста.
22 wọ́n gbà gbogbo agbègbè àwọn ará Amori, láti Arnoni tí ó fi dé Jabbok, àti láti aginjù dé Jordani.
Ау пус мына пе тот цинутул аморицилор, де ла Арнон пынэ ла Иабок ши де ла пустиу пынэ ла Йордан.
23 “Wàyí o, nígbà tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ti lé àwọn ará Amori kúrò níwájú àwọn ènìyàn rẹ̀; Israẹli, ẹ̀tọ́ wo ni ẹ ní láti gba ilẹ̀ náà?
Ши акум, кынд Домнул Думнезеул луй Исраел а изгонит пе амориць динаинтя попорулуй Сэу Исраел, ту сэ ле стэпынешть цара?
24 Ǹjẹ́ ìwọ kì yóò ha gba èyí tí Kemoṣi òrìṣà rẹ fi fún ọ? Bákan náà àwa yóò gba èyíkéyìí tí Olúwa Ọlọ́run wa fi fún wa.
Оаре че-ць дэ ын стэпынире думнезеул тэу, Кемош, ну вей стэпыни? Ши тот че не-а дат ын стэпынире Домнул Думнезеул ностру, ынаинтя ноастрэ, ной сэ ну стэпыним?
25 Ǹjẹ́ ìwọ ha sàn ju Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu lọ? Ǹjẹ́ òun ha ṣe gbólóhùn asọ̀ pẹ̀lú Israẹli bí? Tàbí òun dojú ìjà kọ wọ́n rí bí?
Ешть ту май бун декыт Балак, фиул луй Ципор, ымпэратул Моабулуй? С-а чертат ел ку Исраел сау а фэкут ел рэзбой ымпотрива луй?
26 Fún ọ̀ọ́dúnrún ọdún ni Israẹli fi ṣe àtìpó ní Heṣboni, Aroeri àti àwọn ìgbèríko àti àwọn ìlú tí ó yí Arnoni ká. Èéṣe tí ìwọ kò fi gbà wọ́n padà ní àsìkò náà?
Ятэ кэ сунт трей суте де ань де кынд локуеште Исраел ла Хесбон ши ын сателе дин журул луй, ла Ароер ши ын сателе дин журул луй ши ын тоате четэциле каре сунт пе малул Арнонулуй. Пентру че ну и ле-аць луат ын тот тимпул ачеста?
27 Èmi kọ́ ni ó ṣẹ̀ ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ ni ó ṣẹ̀ mí nípa kíkógun tọ̀ mí wá. Jẹ́ kí Olúwa olùdájọ́, ṣe ìdájọ́ lónìí láàrín àwọn ọmọ Israẹli àti àwọn ará Ammoni.”
Еу ну те-ам супэрат делок, ши рэу те-ай пуртат ку мине, фэкынду-мь рэзбой. Домнул сэ жудече лукрул ачеста. Ел сэ фие астэзь жудекэтор ынтре фиий луй Исраел ши фиий луй Амон.’”
28 Ṣùgbọ́n ọba àwọn Ammoni kò fetí sí iṣẹ́ tí Jefta rán sí i.
Ымпэратул фиилор луй Амон н-а аскултат кувинтеле пе каре а тримис Иефта сэ и ле спунэ.
29 Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Jefta òun sì la Gileadi àti Manase kọjá. Ó la Mispa àti Gileadi kọjá láti ibẹ̀, ó tẹ̀síwájú láti bá àwọn ará Ammoni jà.
Духул Домнулуй а венит песте Иефта. Иефта а стрэбэтут Галаадул ши Манасе; а трекут ла Мицпе, ын Галаад, ши дин Мицпе, дин Галаад, а порнит ымпотрива фиилор луй Амон.
30 Jefta sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa pé, “Bí ìwọ bá fi àwọn ará Ammoni lé mi lọ́wọ́,
Иефта а фэкут о журуинцэ Домнулуй ши а зис: „Дакэ вей да ын мыниле меле пе фиий луй Амон,
31 yóò sì ṣe, ohunkóhun tí ó bá jáde láti ẹnu-ọ̀nà ilé mi láti wá pàdé mi, nígbà tí èmi bá ń padà bọ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ammoni ní àlàáfíà, yóò jẹ́ ti Olúwa, èmi yóò sì fi rú ẹbọ bí ọrẹ ẹbọ sísun.”
орьчине ва еши пе порциле касей меле ынаинтя мя, ла ынтоарчеря мя феричитэ де ла фиий луй Амон, ва фи ынкинат Домнулуй ши-л вой адуче ка ардере-де-тот.”
32 Jefta sì jáde lọ láti bá àwọn ará Ammoni jagun, Olúwa sì fi wọ́n lé e lọ́wọ́.
Иефта а порнит ымпотрива фиилор луй Амон ши Домнул й-а дат ын мыниле луй.
33 Òun sì ṣẹ́gun wọn, ó sì pa wọ́n ní à pa tán láti Aroeri títí dé agbègbè Minniti, ó jẹ́ ogún ìlú, títí dé Abeli-Keramimu. Báyìí ni Israẹli ti ṣẹ́gun àwọn ará Ammoni.
Ле-а причинуит о фоарте маре ынфрынӂере, де ла Ароер пынэ спре Минит, лок каре куприндя доуэзечь де четэць, ши пынэ ла Абел-Керамим. Ши фиий луй Амон ау фост смериць ынаинтя копиилор луй Исраел.
34 Nígbà tí Jefta padà sí ilé rẹ̀ ní Mispa, wò ó, ọmọ rẹ̀ obìnrin ń jáde bọ̀ wá pàdé rẹ̀ pẹ̀lú timbrili àti ijó. Òun ni ọmọ kan ṣoṣo tí ó ní: kò ní ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin mìíràn yàtọ̀ sí òun nìkan.
Иефта с-а ынторс акасэ ла Мицпа. Ши ятэ кэ фийкэ-са й-а ешит ынаинте ку тимпане ши жокурь. Еа ера сингурул луй копил; н-авя фий ши нич алтэ фатэ.
35 Ní ìgbà tí ó rí i ó fa aṣọ rẹ̀ ya ní ìbànújẹ́, ó sì ké wí pé, “Háà! Ọ̀dọ́mọbìnrin mi, ìwọ fún mi ní ìbànújẹ́ ọkàn ìwọ sì rẹ̀ mí sílẹ̀ gidigidi, nítorí pé èmi ti ya ẹnu mi sí Olúwa ní ẹ̀jẹ́, èmi kò sì le sẹ́ ẹ̀jẹ́ mi.”
Кум а вэзут-о, ел шь-а рупт хайнеле ши а зис: „Ах, фата мя, адынк мэ ловешть ши мэ тулбурь! Ам фэкут о журуинцэ Домнулуй ши н-о пот ынтоарче.”
36 Ọmọ náà sì dáhùn pé, “Baba mi bí ìwọ bá ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa, ṣe sí mi gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ, ní báyìí tí Olúwa ti gba ẹ̀san fún ọ lára àwọn ọ̀tá rẹ, àwọn ará Ammoni.
Еа й-а зис: „Татэ, ай фэкут о журуинцэ Домнулуй, фэ-мь потривит ку чея че ць-а ешит дин гурэ, акум, кынд Домнул те-а рэзбунат пе врэжмаший тэй, пе фиий луй Амон.”
37 Ṣùgbọ́n yọ̀ǹda ìbéèrè kan yìí fún mi, gbà mí láààyè oṣù méjì láti rìn ká orí àwọn òkè, kí n sọkún pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ mi torí mo jẹ́ wúńdíá tí n kò sì ní lè ṣe ìgbéyàwó.”
Ши еа а зис татэлуй сэу: „Атыт ынгэдуе-мь: ласэ-мэ слободэ доуэ лунь, ка сэ мэ дук сэ мэ кобор ын мунць ши сэ-мь плынг фечория ку товарэшеле меле.”
38 Jefta dá lóhùn pé, “Ìwọ lè lọ.” Ó sì gbà á láààyè láti lọ fún oṣù méjì. Òun àti àwọn ọmọbìnrin yòókù lọ sí orí àwọn òkè, wọ́n sọkún nítorí pé kì yóò lè ṣe ìgbéyàwó.
Ел а рэспунс: „Ду-те!” Ши а лэсат-о слободэ доуэ лунь. Еа с-а дус ку товарэшеле ей ши шь-а плынс фечория пе мунць.
39 Lẹ́yìn oṣù méjì náà, ó padà tọ baba rẹ̀ wá òun sì ṣe sí i bí ẹ̀jẹ́ tí ó ti jẹ́. Ọmọ náà sì jẹ́ wúńdíá tí kò mọ ọkùnrin rí. Èyí sì bẹ̀rẹ̀ àṣà kan ní Israẹli
Дупэ челе доуэ лунь, с-а ынторс ла татэл ей ши ел а ымплинит ку еа журуинца пе каре о фэкусе. Еа ну куноскусе ымпреунаря ку бэрбат. Де атунч с-а фэкут ын Исраел обичеюл
40 wí pé ní ọjọ́ mẹ́rin láàrín ọdún àwọn obìnrin Israẹli a máa lọ láti ṣọ̀fọ̀ àti ṣe ìrántí ọmọbìnrin Jefta ti Gileadi.
кэ, ын тоць аний, фетеле луй Исраел се дук сэ прэзнуяскэ пе фийка луй Иефта, Галаадитул, патру зиле пе ан.

< Judges 11 >