< Judges 11 >

1 Jefta ará Gileadi jẹ́ akọni jagunjagun. Gileadi ni baba rẹ̀; ṣùgbọ́n ìyá rẹ̀ jẹ́ panṣágà.
A Jefte Gileadczyk był dzielnym wojownikiem, a był synem nierządnicy. Jeftego spłodził Gilead.
2 Ìyàwó Gileadi sì bí àwọn ọmọkùnrin fún un, nígbà tí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí dàgbà, wọ́n rán Jefta jáde kúrò nílé, wọ́n wí pé, “Ìwọ kì yóò ní ogún kankan ní ìdílé wa, nítorí pé ìwọ jẹ́ ọmọ obìnrin mìíràn.”
[Ale] również żona Gileada urodziła mu synów; gdy więc synowie tej żony dorośli, wygnali Jeftego, mówiąc mu: Nie będziesz brał dziedzictwa w domu naszego ojca, gdyż jesteś synem obcej kobiety.
3 Jefta sì sá kúrò lọ́dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, ó sì pàgọ́ sí ilẹ̀ Tobu, ó sì ń gbé níbẹ̀, níbẹ̀ ni àwọn ènìyàn kan ti ń tẹ òfin lójú parapọ̀ láti máa tẹ̀lé e kiri.
Jefte uciekł więc przed swoimi braćmi i zamieszkał w ziemi Tob. Przyłączyli się do niego ludzie próżni i wyruszali z nim.
4 Ní àsìkò kan, nígbà tí àwọn ará Ammoni dìde ogun sí àwọn Israẹli,
Po pewnym czasie synowie Ammona walczyli z Izraelem.
5 Ó sì ṣe nígbà tí àwọn Ammoni bá Israẹli jagun, àwọn àgbàgbà Gileadi tọ Jefta lọ láti pè é wá láti ilẹ̀ Tobu.
A gdy Ammonici zaczęli walczyć z Izraelem, starsi z Gileadu poszli sprowadzić Jeftego z ziemi Tob.
6 Wọ́n wí fún Jefta wí pé, “Wá kí o sì jẹ́ olórí ogun wa kí a lè kọjú ogun sí àwọn ará Ammoni.”
I powiedzieli mu: Chodź i bądź naszym dowódcą, a będziemy walczyć przeciwko synom Ammona.
7 Jefta sì wí fún àwọn àgbàgbà Gileadi pé, “Ṣé kì í ṣe pé ẹ kórìíra mi tí ẹ sì lé mi kúrò ní ilé baba mi? Kí ló dé tí ẹ fi tọ̀ mí wá báyìí nígbà tí ẹ wà nínú wàhálà?”
Lecz Jefte odpowiedział starszym Gileadu: Czy wy nie znienawidziliście mnie i nie wygnaliście mnie z domu mego ojca? Dlaczego przyszliście do mnie teraz, gdy [znajdujecie się] w ucisku?
8 Àwọn àgbà Gileadi sì wí fún Jefta pé, “Nítorí rẹ̀ ni àwa fi yípadà sí ọ báyìí: tẹ̀lé wa, kí a lè dojú ìjà kọ àwọn ará Ammoni, ìwọ yóò sì jẹ olórí wa àti gbogbo àwa tí ń gbé ní Gileadi.”
Wtedy starsi Gileadu powiedzieli do Jeftego: Dlatego teraz zwracamy się do ciebie, abyś poszedł z nami i walczył przeciwko synom Ammona, i był naszym wodzem nad wszystkimi mieszkańcami Gileadu.
9 Jefta sì wí fún àwọn àgbàgbà Gileadi pé, “Bí ẹ̀yin bá mú mi padà láti bá àwọn ará Ammoni jà àti tí Olúwa bá fi wọ́n lé mi lọ́wọ́: ṣe èmi yóò jẹ́ olórí yín nítòótọ́?”
I Jefte odpowiedział starszym z Gileadu: Jeśli sprowadzicie mnie, abym walczył przeciwko synom Ammona, a PAN mi ich wyda, czy będę waszym wodzem?
10 Àwọn àgbàgbà Gileadi sì wí fún Jefta pé, “Àwa fi Olúwa ṣe ẹlẹ́rìí: àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá wí.”
I starsi Gileadu odpowiedzieli Jeftemu: PAN będzie świadkiem między nami, jeśli nie postąpimy według twego słowa.
11 Jefta sì tẹ̀lé àwọn àgbàgbà Gileadi lọ, àwọn ènìyàn náà sì fi ṣe olórí àti ọ̀gágun wọn. Jefta sì tún sọ gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ tí ó ti sọtẹ́lẹ̀ níwájú Olúwa ní Mispa.
Wtedy Jefte poszedł ze starszymi Gileadu i lud ustanowił go nad sobą dowódcą i wodzem. I Jefte powtórzył wszystkie te słowa przed PANEM w Mispie.
12 Jefta sì rán àwọn oníṣẹ́ sí ọba àwọn ará Ammoni pé, “Kí ni ẹ̀sùn tí o ní sí wa láti fi kàn wá tí ìwọ fi dojú ìjà kọ ilẹ̀ wa?”
Potem Jefte wyprawił posłańców do króla synów Ammona, mówiąc: Co zaszło między mną a tobą, że wyruszyłeś przeciwko mnie, aby walczyć w mojej ziemi?
13 Ọba àwọn Ammoni dá àwọn oníṣẹ́ Jefta lóhùn pé, “Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli jáde ti Ejibiti wá. Wọ́n gba ilẹ̀ mi láti Arnoni dé Jabbok, àní dé Jordani, nítorí náà dá wọn padà lọ ní àlàáfíà àti ní pẹ̀lẹ́ kùtù.”
Król synów Ammona odpowiedział posłańcom Jeftego: Ponieważ Izrael po wyjściu z Egiptu zajął moją ziemię od Arnonu aż do Jabbok i aż do Jordanu. Dlatego teraz zwróć mi ją pokojowo.
14 Jefta sì tún ránṣẹ́ padà sí ọba àwọn ará Ammoni
Jefte po raz drugi wyprawił posłańców do króla synów Ammona.
15 ó sì wí fún un pé, “Báyìí ni Jefta wí: àwọn ọmọ Israẹli kò gba ilẹ̀ Moabu tàbí ilẹ̀ àwọn ará Ammoni.
I powiedział mu: Tak mówi Jefte: Izrael nie zajął ziemi Moabu ani ziemi synów Ammona.
16 Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n jáde kúrò ní Ejibiti àwọn ọmọ Israẹli la aginjù kọjá lọ sí ọ̀nà Òkun Pupa wọ́n sì lọ sí Kadeṣi.
Lecz gdy Izrael wychodził z Egiptu przez pustynię aż do Morza Czerwonego i przyszedł do Kadesz;
17 Nígbà náà Israẹli rán àwọn oníṣẹ́ sí ọba Edomu pé, ‘Gbà fún wa láti gba ilẹ̀ rẹ̀ kọjá,’ ṣùgbọ́n ọba Edomu kò fetí sí wọn. Wọ́n tún ránṣẹ́ sí ọba Moabu bákan náà òun náà kọ̀. Nítorí náà Israẹli dúró sí Kadeṣi.
Wtedy Izrael wyprawił posłów do króla Edomu, [mówiąc]: Pozwól mi, proszę, przejść przez twoją ziemię. Lecz król Edomu nie pozwolił. Posłał także do króla Moabu, i [on] nie pozwolił. Izrael więc pozostał w Kadesz.
18 “Wọ́n rin aginjù kọjá, wọ́n pẹ́ àwọn ilẹ̀ Edomu àti ti Moabu sílẹ̀, nígbà tí wọ́n gba apá ìlà-oòrùn Moabu, wọ́n sì tẹ̀dó sí apá kejì Arnoni. Wọn kò wọ ilẹ̀ Moabu, nítorí pé ààlà rẹ̀ ni Arnoni wà.
A gdy szedł przez pustynię, obszedł ziemię Edomu i ziemię Moabu i przyszedł od wschodniej strony ziemi Moabu, i rozbił obóz za Arnonem, lecz nie wszedł w granice Moabu, bo Arnon [jest] granicą Moabu.
19 “Nígbà náà ni Israẹli rán àwọn oníṣẹ́ sí Sihoni ọba àwọn ará Amori, ẹni tí ń ṣe àkóso ní Heṣboni, wọ́n sì wí fún un pé, ‘Jẹ́ kí a la ilẹ̀ rẹ kọjá lọ sí ibùgbé wa.’
Dlatego Izrael wyprawił posłańców do Sichona, króla Amorytów, króla w Cheszbonie, i Izrael powiedział mu: Pozwól nam, proszę, przejść przez twoją ziemię aż do mego miejsca.
20 Ṣùgbọ́n Sihoni kò gba Israẹli gbọ́ (kò fọkàn tán an) láti jẹ́ kí ó kọjá. Ó kó gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ jọ, ó sì tẹ̀dó sí Jahisa láti bá Israẹli jagun.
Lecz Sichon nie dowierzał Izraelowi, że chce przejść przez jego granicę; przeciwnie, Sichon zebrał cały swój lud i rozbił obóz w Jahaza, i stoczył bitwę z Izraelem.
21 “Olúwa Ọlọ́run Israẹli sì fi Sihoni àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ lé Israẹli lọ́wọ́, wọ́n sì ṣẹ́gun wọn. Israẹli sì gba gbogbo ilẹ̀ àwọn ará Amori tí wọ́n ń gbé ní agbègbè náà,
PAN, Bóg Izraela, wydał zaś Sichona i cały jego lud w ręce Izraela, który ich pobił. Izrael wziął więc w posiadanie całą ziemię Amorytów, którzy w niej mieszkali.
22 wọ́n gbà gbogbo agbègbè àwọn ará Amori, láti Arnoni tí ó fi dé Jabbok, àti láti aginjù dé Jordani.
Tak wziął w posiadanie wszystkie granice Amorytów: od Arnon aż do Jabbok i od pustyni aż do Jordanu.
23 “Wàyí o, nígbà tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ti lé àwọn ará Amori kúrò níwájú àwọn ènìyàn rẹ̀; Israẹli, ẹ̀tọ́ wo ni ẹ ní láti gba ilẹ̀ náà?
Teraz więc PAN, Bóg Izraela, wypędził Amorytów przed swym ludem Izraelem, a ty chcesz ją posiąść?
24 Ǹjẹ́ ìwọ kì yóò ha gba èyí tí Kemoṣi òrìṣà rẹ fi fún ọ? Bákan náà àwa yóò gba èyíkéyìí tí Olúwa Ọlọ́run wa fi fún wa.
Czyż nie weźmiesz w posiadanie tego, co daje ci posiąść Kemosz, twój bóg? Tak i my posiądziemy ziemię tego, kogo PAN, nasz Bóg, wygnał przed nami.
25 Ǹjẹ́ ìwọ ha sàn ju Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu lọ? Ǹjẹ́ òun ha ṣe gbólóhùn asọ̀ pẹ̀lú Israẹli bí? Tàbí òun dojú ìjà kọ wọ́n rí bí?
A teraz – czy jesteś lepszy od Balaka, syna Sippora, króla Moabu? Czy on się kiedyś spierał z Izraelem? Czy kiedyś z nim walczył?
26 Fún ọ̀ọ́dúnrún ọdún ni Israẹli fi ṣe àtìpó ní Heṣboni, Aroeri àti àwọn ìgbèríko àti àwọn ìlú tí ó yí Arnoni ká. Èéṣe tí ìwọ kò fi gbà wọ́n padà ní àsìkò náà?
Oto przez trzysta lat Izrael mieszkał w Cheszbonie i w przyległych do niego wioskach, także w Aroerze i w przyległych do niego wioskach oraz we wszystkich miastach, które są przy granicy Arnonu. Dlaczego nie próbowaliście ich odzyskać przez ten czas?
27 Èmi kọ́ ni ó ṣẹ̀ ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ ni ó ṣẹ̀ mí nípa kíkógun tọ̀ mí wá. Jẹ́ kí Olúwa olùdájọ́, ṣe ìdájọ́ lónìí láàrín àwọn ọmọ Israẹli àti àwọn ará Ammoni.”
Nie ja zawiniłem tobie, ale ty wyrządzasz mi zło, że walczysz ze mną. Niech PAN, który jest Sędzią, rozsądzi dziś między synami Izraela a synami Ammona.
28 Ṣùgbọ́n ọba àwọn Ammoni kò fetí sí iṣẹ́ tí Jefta rán sí i.
Lecz król synów Ammona nie posłuchał słów Jeftego, które mu przekazał.
29 Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Jefta òun sì la Gileadi àti Manase kọjá. Ó la Mispa àti Gileadi kọjá láti ibẹ̀, ó tẹ̀síwájú láti bá àwọn ará Ammoni jà.
Wtedy Duch PANA zstąpił na Jeftego, który przeszedł przez Gilead i Manassesa, przeszedł też przez Mispę w Gileadzie, a z Mispy w Gileadzie ciągnął przeciw synom Ammona.
30 Jefta sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa pé, “Bí ìwọ bá fi àwọn ará Ammoni lé mi lọ́wọ́,
Tam Jefte złożył PANU ślub, mówiąc: Jeśli naprawdę wydasz synów Ammona w moje ręce;
31 yóò sì ṣe, ohunkóhun tí ó bá jáde láti ẹnu-ọ̀nà ilé mi láti wá pàdé mi, nígbà tí èmi bá ń padà bọ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ammoni ní àlàáfíà, yóò jẹ́ ti Olúwa, èmi yóò sì fi rú ẹbọ bí ọrẹ ẹbọ sísun.”
Wtedy to, co wyjdzie z drzwi mego domu naprzeciw mnie, gdy wrócę w pokoju od synów Ammona, będzie należało do PANA albo ofiaruję to na całopalenie.
32 Jefta sì jáde lọ láti bá àwọn ará Ammoni jagun, Olúwa sì fi wọ́n lé e lọ́wọ́.
Wyruszył więc Jefte przeciwko synom Ammona, by walczyć z nimi, a PAN wydał ich w jego ręce.
33 Òun sì ṣẹ́gun wọn, ó sì pa wọ́n ní à pa tán láti Aroeri títí dé agbègbè Minniti, ó jẹ́ ogún ìlú, títí dé Abeli-Keramimu. Báyìí ni Israẹli ti ṣẹ́gun àwọn ará Ammoni.
I zadał im wielką klęskę od Aroeru aż do wejścia do Menit – w dwudziestu miastach – i aż do równiny winnic. Tak synowie Ammona zostali poniżeni przed synami Izraela.
34 Nígbà tí Jefta padà sí ilé rẹ̀ ní Mispa, wò ó, ọmọ rẹ̀ obìnrin ń jáde bọ̀ wá pàdé rẹ̀ pẹ̀lú timbrili àti ijó. Òun ni ọmọ kan ṣoṣo tí ó ní: kò ní ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin mìíràn yàtọ̀ sí òun nìkan.
A gdy Jefte wracał do Mispy, do swego domu, oto jego córka wyszła mu naprzeciw, z bębnami i muzyką. A była ona jedynaczką, [bo] nie miał żadnego syna ani innej córki.
35 Ní ìgbà tí ó rí i ó fa aṣọ rẹ̀ ya ní ìbànújẹ́, ó sì ké wí pé, “Háà! Ọ̀dọ́mọbìnrin mi, ìwọ fún mi ní ìbànújẹ́ ọkàn ìwọ sì rẹ̀ mí sílẹ̀ gidigidi, nítorí pé èmi ti ya ẹnu mi sí Olúwa ní ẹ̀jẹ́, èmi kò sì le sẹ́ ẹ̀jẹ́ mi.”
I gdy ją zobaczył, rozdarł swoje szaty i powiedział: Ach, moja córko, bardzo mnie zasmuciłaś! I jesteś z tych, którzy mnie zasmucają, bo złożyłem ślub PANU i nie mogę tego cofnąć.
36 Ọmọ náà sì dáhùn pé, “Baba mi bí ìwọ bá ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa, ṣe sí mi gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ, ní báyìí tí Olúwa ti gba ẹ̀san fún ọ lára àwọn ọ̀tá rẹ, àwọn ará Ammoni.
Ona mu odpowiedziała: Ojcze mój, jeśli złożyłeś ślub PANU, uczyń ze mną tak, jak wypowiedziały twoje usta; PAN bowiem dał ci pomstę na twoich wrogach, na synach Ammona.
37 Ṣùgbọ́n yọ̀ǹda ìbéèrè kan yìí fún mi, gbà mí láààyè oṣù méjì láti rìn ká orí àwọn òkè, kí n sọkún pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ mi torí mo jẹ́ wúńdíá tí n kò sì ní lè ṣe ìgbéyàwó.”
Powiedziała też do swego ojca: Tylko uczyń dla mnie to jedno: wypuść mnie na dwa miesiące, bym mogła pójść i chodzić po górach, i opłakiwać moje dziewictwo, ja i moje towarzyszki.
38 Jefta dá lóhùn pé, “Ìwọ lè lọ.” Ó sì gbà á láààyè láti lọ fún oṣù méjì. Òun àti àwọn ọmọbìnrin yòókù lọ sí orí àwọn òkè, wọ́n sọkún nítorí pé kì yóò lè ṣe ìgbéyàwó.
A [on] powiedział: Idź. I wypuścił ją na dwa miesiące. Poszła więc wraz ze swoimi towarzyszkami i opłakiwała swoje dziewictwo w górach.
39 Lẹ́yìn oṣù méjì náà, ó padà tọ baba rẹ̀ wá òun sì ṣe sí i bí ẹ̀jẹ́ tí ó ti jẹ́. Ọmọ náà sì jẹ́ wúńdíá tí kò mọ ọkùnrin rí. Èyí sì bẹ̀rẹ̀ àṣà kan ní Israẹli
A gdy minęły dwa miesiące, wróciła do swego ojca i wypełnił on na niej swój ślub, który złożył, a ona nie obcowała z mężczyzną. I weszło to w zwyczaj w Izraelu;
40 wí pé ní ọjọ́ mẹ́rin láàrín ọdún àwọn obìnrin Israẹli a máa lọ láti ṣọ̀fọ̀ àti ṣe ìrántí ọmọbìnrin Jefta ti Gileadi.
[Że] każdego roku schodziły się córki Izraela, aby przez cztery dni w roku rozmawiać z córką Jeftego Gileadczyka.

< Judges 11 >