< Judges 11 >
1 Jefta ará Gileadi jẹ́ akọni jagunjagun. Gileadi ni baba rẹ̀; ṣùgbọ́n ìyá rẹ̀ jẹ́ panṣágà.
Il y avait alors un vaillant guerrier, Jephté le Galaadite; c’était le fils d’une femme prostituée, et Ghilad était son père.
2 Ìyàwó Gileadi sì bí àwọn ọmọkùnrin fún un, nígbà tí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí dàgbà, wọ́n rán Jefta jáde kúrò nílé, wọ́n wí pé, “Ìwọ kì yóò ní ogún kankan ní ìdílé wa, nítorí pé ìwọ jẹ́ ọmọ obìnrin mìíràn.”
Mais la femme de Ghilad lui donna aussi des fils. Ceux-ci, devenus grands, expulsèrent Jephté en lui disant: "Tu n’as pas droit à l’héritage de notre père, car tu es le fils d’une femme étrangère."
3 Jefta sì sá kúrò lọ́dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, ó sì pàgọ́ sí ilẹ̀ Tobu, ó sì ń gbé níbẹ̀, níbẹ̀ ni àwọn ènìyàn kan ti ń tẹ òfin lójú parapọ̀ láti máa tẹ̀lé e kiri.
Jephté dut s’éloigner de ses frères et alla s’établir au pays de Tob. Là il devint le centre d’un ramas d’aventuriers, qui firent avec lui des incursions.
4 Ní àsìkò kan, nígbà tí àwọn ará Ammoni dìde ogun sí àwọn Israẹli,
Ce fut quelque temps après, qu’eut lieu la guerre des Ammonites contre Israël.
5 Ó sì ṣe nígbà tí àwọn Ammoni bá Israẹli jagun, àwọn àgbàgbà Gileadi tọ Jefta lọ láti pè é wá láti ilẹ̀ Tobu.
Les Ammonites ayant attaqué Israël, les anciens de Galaad allèrent chercher Jephté au pays de Tob.
6 Wọ́n wí fún Jefta wí pé, “Wá kí o sì jẹ́ olórí ogun wa kí a lè kọjú ogun sí àwọn ará Ammoni.”
Ils dirent à Jephté: "Viens, sois notre chef, que nous puissions combattre les enfants d’Ammon."
7 Jefta sì wí fún àwọn àgbàgbà Gileadi pé, “Ṣé kì í ṣe pé ẹ kórìíra mi tí ẹ sì lé mi kúrò ní ilé baba mi? Kí ló dé tí ẹ fi tọ̀ mí wá báyìí nígbà tí ẹ wà nínú wàhálà?”
Jephté répondit aux anciens de Galaad: "Est-ce que vous n’êtes pas mes ennemis, qui m’avez chassé de la maison de mon père? Pourquoi donc venez-vous à moi, maintenant que vous êtes dans la détresse?"
8 Àwọn àgbà Gileadi sì wí fún Jefta pé, “Nítorí rẹ̀ ni àwa fi yípadà sí ọ báyìí: tẹ̀lé wa, kí a lè dojú ìjà kọ àwọn ará Ammoni, ìwọ yóò sì jẹ olórí wa àti gbogbo àwa tí ń gbé ní Gileadi.”
"Oui vraiment, dirent les anciens de Galaad à Jephté, maintenant nous revenons à toi, afin que tu marches avec nous, que tu combattes les enfants d’Ammon, et que tu deviennes notre chef à tous, habitants du Galaad."
9 Jefta sì wí fún àwọn àgbàgbà Gileadi pé, “Bí ẹ̀yin bá mú mi padà láti bá àwọn ará Ammoni jà àti tí Olúwa bá fi wọ́n lé mi lọ́wọ́: ṣe èmi yóò jẹ́ olórí yín nítòótọ́?”
Alors Jephté dit aux anciens de Galaad: "Si vous me déterminez à revenir pour guerroyer avec les Ammonites et que l’Eternel me les livre, je veux rester votre chef."
10 Àwọn àgbàgbà Gileadi sì wí fún Jefta pé, “Àwa fi Olúwa ṣe ẹlẹ́rìí: àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá wí.”
Et les anciens de Galaad lui répondirent: "Par l’Eternel qui nous entend les uns et les autres, nous jurons de faire comme tu l’as dit!"
11 Jefta sì tẹ̀lé àwọn àgbàgbà Gileadi lọ, àwọn ènìyàn náà sì fi ṣe olórí àti ọ̀gágun wọn. Jefta sì tún sọ gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ tí ó ti sọtẹ́lẹ̀ níwájú Olúwa ní Mispa.
Jephté partit alors avec les anciens de Galaad, et le peuple le nomma son chef et son capitaine, et Jephté répéta toutes ses paroles devant l’Eternel, à Miçpa.
12 Jefta sì rán àwọn oníṣẹ́ sí ọba àwọn ará Ammoni pé, “Kí ni ẹ̀sùn tí o ní sí wa láti fi kàn wá tí ìwọ fi dojú ìjà kọ ilẹ̀ wa?”
Puis Jephté envoya une députation au roi des Ammonites, pour lui dire: "Qu’ai-je à démêler avec toi, que tu sois venu porter la guerre dans mon pays?"
13 Ọba àwọn Ammoni dá àwọn oníṣẹ́ Jefta lóhùn pé, “Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli jáde ti Ejibiti wá. Wọ́n gba ilẹ̀ mi láti Arnoni dé Jabbok, àní dé Jordani, nítorí náà dá wọn padà lọ ní àlàáfíà àti ní pẹ̀lẹ́ kùtù.”
Le roi des Ammonites répondit aux envoyés de Jephté: "C’Est qu’Israël, étant sorti d’Egypte, s’empara de mon pays, depuis l’Arnon jusqu’au Jaboc et jusqu’au Jourdain. Et maintenant, rends-le moi à l’amiable."
14 Jefta sì tún ránṣẹ́ padà sí ọba àwọn ará Ammoni
Jephté envoya une nouvelle députation au roi des Ammonites,
15 ó sì wí fún un pé, “Báyìí ni Jefta wí: àwọn ọmọ Israẹli kò gba ilẹ̀ Moabu tàbí ilẹ̀ àwọn ará Ammoni.
et lui fit dire: "Ainsi parla Jephté: Israël ne s’est emparé ni du territoire de Moab, ni de celui des enfants d’Ammon.
16 Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n jáde kúrò ní Ejibiti àwọn ọmọ Israẹli la aginjù kọjá lọ sí ọ̀nà Òkun Pupa wọ́n sì lọ sí Kadeṣi.
En effet, après être sorti d’Egypte, Israël s’avança dans le désert jusqu’à la mer des Joncs, puis il arriva à Kadêch.
17 Nígbà náà Israẹli rán àwọn oníṣẹ́ sí ọba Edomu pé, ‘Gbà fún wa láti gba ilẹ̀ rẹ̀ kọjá,’ ṣùgbọ́n ọba Edomu kò fetí sí wọn. Wọ́n tún ránṣẹ́ sí ọba Moabu bákan náà òun náà kọ̀. Nítorí náà Israẹli dúró sí Kadeṣi.
Et Israël envoya des émissaires au roi d’Edom pour lui dire: "Je voudrais passer par ton pays." Mais le roi d’Edom n’y consentit point. On envoya pareil message au roi de Moab, qui refusa également, et Israël resta à Kadêch.
18 “Wọ́n rin aginjù kọjá, wọ́n pẹ́ àwọn ilẹ̀ Edomu àti ti Moabu sílẹ̀, nígbà tí wọ́n gba apá ìlà-oòrùn Moabu, wọ́n sì tẹ̀dó sí apá kejì Arnoni. Wọn kò wọ ilẹ̀ Moabu, nítorí pé ààlà rẹ̀ ni Arnoni wà.
Alors, prenant par le désert, il tourna les pays d’Edom et de Moab, arriva jusqu’au pays de Moab du côté de l’Orient, et ils campèrent au bord de l’Arnon; mais ils ne franchirent point la limite de Moab, car c’est l’Arnon qui forme cette limite.
19 “Nígbà náà ni Israẹli rán àwọn oníṣẹ́ sí Sihoni ọba àwọn ará Amori, ẹni tí ń ṣe àkóso ní Heṣboni, wọ́n sì wí fún un pé, ‘Jẹ́ kí a la ilẹ̀ rẹ kọjá lọ sí ibùgbé wa.’
Et Israël envoya des députés à Sihôn, roi des Amorréens, qui régnait à Hesbon, et il lui fit dire: "Laisse-nous traverser ton pays pour gagner notre destination."
20 Ṣùgbọ́n Sihoni kò gba Israẹli gbọ́ (kò fọkàn tán an) láti jẹ́ kí ó kọjá. Ó kó gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ jọ, ó sì tẹ̀dó sí Jahisa láti bá Israẹli jagun.
Mais Sihôn n’eut pas assez de confiance en Israël pour le laisser franchir sa frontière: il rassembla donc tout son peuple, ils prirent position à Yahça et attaquèrent Israël.
21 “Olúwa Ọlọ́run Israẹli sì fi Sihoni àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ lé Israẹli lọ́wọ́, wọ́n sì ṣẹ́gun wọn. Israẹli sì gba gbogbo ilẹ̀ àwọn ará Amori tí wọ́n ń gbé ní agbègbè náà,
L’Eternel, Dieu d’Israël, livra Sihôn et toute son armée au pouvoir d’Israël, qui les défit et qui prit possession de tout le pays des Amorréens, habitants de cette contrée.
22 wọ́n gbà gbogbo agbègbè àwọn ará Amori, láti Arnoni tí ó fi dé Jabbok, àti láti aginjù dé Jordani.
Ils possédèrent ainsi tout le territoire amorréen, depuis l’Arnon jusqu’au Jaboc, et depuis le désert jusqu’au Jourdain.
23 “Wàyí o, nígbà tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ti lé àwọn ará Amori kúrò níwájú àwọn ènìyàn rẹ̀; Israẹli, ẹ̀tọ́ wo ni ẹ ní láti gba ilẹ̀ náà?
Ainsi l’Eternel, Dieu d’Israël, a évincé l’Amorréen pour son peuple Israël, et tu voudrais déposséder celui-ci!
24 Ǹjẹ́ ìwọ kì yóò ha gba èyí tí Kemoṣi òrìṣà rẹ fi fún ọ? Bákan náà àwa yóò gba èyíkéyìí tí Olúwa Ọlọ́run wa fi fún wa.
N’Est-ce pas, ce que ton Dieu Camos te fait conquérir devient ta possession? Eh bien! tout ce que l’Eternel, notre Dieu, nous a fait conquérir, restera la nôtre.
25 Ǹjẹ́ ìwọ ha sàn ju Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu lọ? Ǹjẹ́ òun ha ṣe gbólóhùn asọ̀ pẹ̀lú Israẹli bí? Tàbí òun dojú ìjà kọ wọ́n rí bí?
Au surplus, es-tu mieux fondé en droit que Balak, fils de Cippor, le roi de Moab? Osa-t-il contester avec Israël? osa-t-il lui faire la guerre?
26 Fún ọ̀ọ́dúnrún ọdún ni Israẹli fi ṣe àtìpó ní Heṣboni, Aroeri àti àwọn ìgbèríko àti àwọn ìlú tí ó yí Arnoni ká. Èéṣe tí ìwọ kò fi gbà wọ́n padà ní àsìkò náà?
Israël est établi, depuis trois cents ans, dans Hesbon et sa banlieue, dans Aror et sa banlieue, dans toutes les villes qui bordent l’Arnon: pourquoi donc, durant toute cette période, ne les avez-vous point reprises?
27 Èmi kọ́ ni ó ṣẹ̀ ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ ni ó ṣẹ̀ mí nípa kíkógun tọ̀ mí wá. Jẹ́ kí Olúwa olùdájọ́, ṣe ìdájọ́ lónìí láàrín àwọn ọmọ Israẹli àti àwọn ará Ammoni.”
Pour moi, je ne t’ai point lésé, et tu agis mal à mon égard en me faisant la guerre. Que l’Eternel, le vrai Juge, prononce maintenant entre les enfants d’Israël et les enfants d’Ammon!"
28 Ṣùgbọ́n ọba àwọn Ammoni kò fetí sí iṣẹ́ tí Jefta rán sí i.
Mais le roi des Ammonites ne tint pas compte des paroles que Jephté lui avait fait adresser.
29 Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Jefta òun sì la Gileadi àti Manase kọjá. Ó la Mispa àti Gileadi kọjá láti ibẹ̀, ó tẹ̀síwájú láti bá àwọn ará Ammoni jà.
Alors, animé de l’esprit de l’Eternel, Jephté traversa le Galaad et Manassé, atteignit Miçpé-Ghilad, et de là s’avança jusqu’aux Ammonites.
30 Jefta sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa pé, “Bí ìwọ bá fi àwọn ará Ammoni lé mi lọ́wọ́,
Et Jephté fit un vœu à l’Eternel en disant: "Si tu livres en mon pouvoir les enfants d’Ammon,
31 yóò sì ṣe, ohunkóhun tí ó bá jáde láti ẹnu-ọ̀nà ilé mi láti wá pàdé mi, nígbà tí èmi bá ń padà bọ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ammoni ní àlàáfíà, yóò jẹ́ ti Olúwa, èmi yóò sì fi rú ẹbọ bí ọrẹ ẹbọ sísun.”
la première créature qui sortira de ma maison au-devant de moi, quand je reviendrai vainqueur des enfants d’Ammon, sera vouée à l’Eternel, et je l’offrirai en holocauste."
32 Jefta sì jáde lọ láti bá àwọn ará Ammoni jagun, Olúwa sì fi wọ́n lé e lọ́wọ́.
Jephté marcha alors sur les Ammonites pour les combattre, et l’Eternel les livra en sa main.
33 Òun sì ṣẹ́gun wọn, ó sì pa wọ́n ní à pa tán láti Aroeri títí dé agbègbè Minniti, ó jẹ́ ogún ìlú, títí dé Abeli-Keramimu. Báyìí ni Israẹli ti ṣẹ́gun àwọn ará Ammoni.
Il les battit depuis Aroêr jusque vers Minnit (vingt villes), et jusqu’à Abel-Keramim; défaite considérable, qui abaissa les Ammonites devant les enfants d’Israël.
34 Nígbà tí Jefta padà sí ilé rẹ̀ ní Mispa, wò ó, ọmọ rẹ̀ obìnrin ń jáde bọ̀ wá pàdé rẹ̀ pẹ̀lú timbrili àti ijó. Òun ni ọmọ kan ṣoṣo tí ó ní: kò ní ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin mìíràn yàtọ̀ sí òun nìkan.
Comme Jephté rentrait dans sa maison à Miçpa, voici venir sa fille à sa rencontre, avec des tambourins et des chœurs de danse. C’Était son unique enfant; hors d’elle il n’avait ni fils ni fille.
35 Ní ìgbà tí ó rí i ó fa aṣọ rẹ̀ ya ní ìbànújẹ́, ó sì ké wí pé, “Háà! Ọ̀dọ́mọbìnrin mi, ìwọ fún mi ní ìbànújẹ́ ọkàn ìwọ sì rẹ̀ mí sílẹ̀ gidigidi, nítorí pé èmi ti ya ẹnu mi sí Olúwa ní ẹ̀jẹ́, èmi kò sì le sẹ́ ẹ̀jẹ́ mi.”
Quand il la vit, il déchira ses vêtements et s’écria: "Hélas! ma fille, tu m’accables! c’est toi qui fais mon malheur! Mais je me suis engagé devant l’Eternel, je ne puis m’en dédire."
36 Ọmọ náà sì dáhùn pé, “Baba mi bí ìwọ bá ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa, ṣe sí mi gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ, ní báyìí tí Olúwa ti gba ẹ̀san fún ọ lára àwọn ọ̀tá rẹ, àwọn ará Ammoni.
Elle lui répondit: "Mort père, tu t’es engagé devant Dieu, fais-moi ce qu’a promis ta bouche, maintenant que l’Eternel t’a vengé de tes ennemis, les Ammonites.
37 Ṣùgbọ́n yọ̀ǹda ìbéèrè kan yìí fún mi, gbà mí láààyè oṣù méjì láti rìn ká orí àwọn òkè, kí n sọkún pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ mi torí mo jẹ́ wúńdíá tí n kò sì ní lè ṣe ìgbéyàwó.”
Seulement, ajouta-t-elle, qu’on m’accorde cette faveur, de me laisser deux mois de répit, afin que j’aille, retirée sur les montagnes, pleurer avec mes amies sur ma virginité."
38 Jefta dá lóhùn pé, “Ìwọ lè lọ.” Ó sì gbà á láààyè láti lọ fún oṣù méjì. Òun àti àwọn ọmọbìnrin yòókù lọ sí orí àwọn òkè, wọ́n sọkún nítorí pé kì yóò lè ṣe ìgbéyàwó.
"Va", dit-il. Et il la laissa libre pour deux mois; et elle s’en alla avec ses compagnes sur les monts, où elle pleura sa virginité.
39 Lẹ́yìn oṣù méjì náà, ó padà tọ baba rẹ̀ wá òun sì ṣe sí i bí ẹ̀jẹ́ tí ó ti jẹ́. Ọmọ náà sì jẹ́ wúńdíá tí kò mọ ọkùnrin rí. Èyí sì bẹ̀rẹ̀ àṣà kan ní Israẹli
Au bout de deux mois, elle revint chez son père, qui accomplit à son égard le vœu qu’il avait prononcé. Elle n’avait jamais connu d’homme. Et cela devint une coutume en Israël:
40 wí pé ní ọjọ́ mẹ́rin láàrín ọdún àwọn obìnrin Israẹli a máa lọ láti ṣọ̀fọ̀ àti ṣe ìrántí ọmọbìnrin Jefta ti Gileadi.
d’année en année, quatre jours de suite, les filles israélites se réunissaient pour pleurer la mémoire de la fille de Jephté le Galaadite.