< Judges 10 >

1 Lẹ́yìn ikú Abimeleki, ọkùnrin kan láti ẹ̀yà Isakari tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Tola ọmọ Pua, ọmọ Dodo, dìde láti gba Israẹli sílẹ̀. Ní Ṣamiri tí ó wà ní òkè Efraimu ni ó gbé.
Za Abimélehom je vstal Tolá, sin Puvája, sinú Dodója, mož iz Isahárja, da brani Izrael. Prebival je v Šamíru, na gori Efrájim.
2 Ó ṣe àkóso Israẹli ní ọdún mẹ́tàlélógún. Nígbà tí ó kú wọ́n sìn ín sí Ṣamiri.
Izraelu je sodil triindvajset let in umrl ter bil pokopan v Šamíru.
3 Jairi ti ẹ̀yà Gileadi ni ó dìde lẹ́yìn rẹ̀, ó ṣàkóso Israẹli ní ọdún méjìlélógún.
Za njim je vstal Gileádec Jaír in Izraelu sodil dvaindvajset let.
4 Àwọn ọgbọ̀n ọmọ tí ó n gun ọgbọ̀n kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Wọ́n ṣe àkóso ọgbọ̀n ìlú ní Gileadi, tí a pe orúkọ wọn ní Hafoti-Jairi títí di òní.
Imel je trideset sinov, ki so jahali na tridesetih osličjih žrebetih in imeli so trideset mest, ki se imenujejo Havot Jaír do tega dne, ki so v deželi Gileád.
5 Nígbà tí Jairi kú wọ́n sin ín sí Kamoni.
Jaír je umrl in bil pokopan v Kamónu.
6 Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú lójú Olúwa. Wọ́n sin Baali àti Aṣtoreti àti àwọn òrìṣà Aramu, òrìṣà Sidoni, òrìṣà Moabu, òrìṣà àwọn ará Ammoni àti òrìṣà àwọn ará Filistini. Nítorí àwọn ará Israẹli kọ Olúwa sílẹ̀ tí wọn kò sì sìn ín mọ́,
Izraelovi otroci pa so v Gospodovih očeh ponovno počeli zlo in služili Báalom, Astarti, bogovom Sirije, bogovom Sidóna, bogovom Moába, bogovom Amónovih otrok in bogovom Filistejcev in zapustili so Gospoda in mu niso služili.
7 ó bínú sí wọn, ó fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn ará Filistini àti Ammoni láti jẹ ẹ́ ní ìyà.
Gospodova jeza je bila vroča zoper Izrael in prodal jih je v roke Filistejcev in v roke Amónovih otrok.
8 Ní ọdún náà, wọ́n tú wọn ká wọ́n sì pọ́n wọn lójú. Fún ọdún méjìdínlógún ni wọ́n fi ni gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà ní ìlà-oòrùn odò Jordani ní ilẹ̀ àwọn ará Amori lára (èyí nì ní Gileadi).
Tisto leto so tlačili in zatirali Izraelove otroke; osemnajst let, vse Izraelove otroke, ki so bili na drugi strani Jordana, v deželi Amoréjcev, ki je v Gileádu.
9 Àwọn ará Ammoni sì la odò Jordani kọjá láti bá Juda, Benjamini àti àwọn ará ilé Efraimu jagun: Israẹli sì dojúkọ ìpọ́njú tó lágbára.
Poleg tega so Amónovi otroci prečkali Jordan, da se borijo tudi zoper Juda, zoper Benjamina in zoper Efrájimovo hišo, tako, da je bil Izrael silno stiskan.
10 Nígbà tí èyí ti ṣẹlẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí ọ, nítorí pé àwa ti kọ Ọlọ́run wa sílẹ̀, àwa sì ń sin Baali.”
Izraelovi otroci so vpili h Gospodu, rekoč: »Grešili smo zoper tebe, zato ker smo zapustili svojega Boga in služili tudi Báalom.«
11 Olúwa sì dáhùn pé, “Ǹjẹ́ nígbà tí àwọn ará Ejibiti, Amori, Ammoni, Filistini,
Gospod je Izraelovim otrokom rekel: » Mar vas nisem osvobodil pred Egipčani in pred Amoréjci, pred Amónovimi otroki in pred Filistejci?
12 àwọn ará Sidoni, Amaleki pẹ̀lú Maoni ni yín lára, tí ẹ sì ké pè mí fún ìrànlọ́wọ́, ǹjẹ́ èmi kò gbà yín sílẹ̀ kúrò ní ọwọ́ wọn?
Tudi Sidónci, Amalečani in Maonci so vas zatirali in klicali ste k meni in osvobodil sem vas iz njihove roke.
13 Síbẹ̀síbẹ̀ ẹ̀yin kọ̀ mí sílẹ̀ láti sin àwọn ọlọ́run mìíràn, torí ìdí èyí, èmi kì yóò sì tún gbà yín mọ́.
Vendar ste me zapustili in služili drugim bogovom, zato vas ne bom več osvobajal.
14 Ẹ lọ kí ẹ sì ké pe àwọn òrìṣà tí ẹ̀yin ti yàn fún ara yín. Jẹ́ kí wọn gbà yín sílẹ̀ ní àsìkò ìpọ́njú yín!”
Pojdite in jokajte k bogovom, ki ste jih izbrali. Naj vas oni osvobodijo v času vaše stiske.«
15 Àwọn ọmọ Israẹli sì dá Olúwa lóhùn pé, “Àwa ti ṣẹ̀, ṣe ohun tí ó bá fẹ́ pẹ̀lú wa, ṣùgbọ́n, jọ̀wọ́ gbà wá sílẹ̀ náání àsìkò yìí.”
Izraelovi otroci so rekli Gospodu: »Grešili smo. Stôri nam, karkoli se ti zdi dobro. Prosimo te, samo osvobodi nas ta dan.«
16 Nígbà náà ni wọ́n kó gbogbo ọlọ́run àjèjì tí ó wà láàrín wọn kúrò wọ́n sì sin Olúwa nìkan, ọkàn rẹ̀ kò sì le gbàgbé ìrora Israẹli mọ́.
Izmed sebe so odstranili tuje bogove in služili Gospodu. Njegova duša je bila užaloščena zaradi Izraelove bede.
17 Nígbà tí àwọn ará Ammoni kógun jọ ní Gileadi láti bá Israẹli jà, àwọn ọmọ Israẹli gbárajọpọ̀, wọ́n sì tẹ̀dó ogun ní Mispa.
Potem so bili Amónovi otroci zbrani skupaj in se utaborili v Gileádu. Izraelovi otroci pa so se zbrali skupaj in se utaborili v Micpi.
18 Àwọn ìjòyè: aṣíwájú àwọn ará Gileadi wí fún ará wọn pé, “Ẹnikẹ́ni tí yóò kọ́ ṣígun si àwọn ará Ammoni ni yóò jẹ́ orí fún gbogbo àwọn tí ń gbé ní Gileadi.”
Ljudstvo in gileádski princi so drug drugemu rekli: »Kateri mož je ta, ki se bo začel boriti zoper Amónove otroke? Ta bo poglavar nad vsemi prebivalci Gileáda.«

< Judges 10 >