< Judges 10 >

1 Lẹ́yìn ikú Abimeleki, ọkùnrin kan láti ẹ̀yà Isakari tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Tola ọmọ Pua, ọmọ Dodo, dìde láti gba Israẹli sílẹ̀. Ní Ṣamiri tí ó wà ní òkè Efraimu ni ó gbé.
Și după Abimelec s-a ridicat Tola, fiul lui Pua, fiul lui Dodo, un bărbat din Isahar, să apere pe Israel; și el locuia în Șamir, pe muntele Efraim.
2 Ó ṣe àkóso Israẹli ní ọdún mẹ́tàlélógún. Nígbà tí ó kú wọ́n sìn ín sí Ṣamiri.
Și a judecat pe Israel douăzeci și trei de ani și a murit și a fost îngropat în Șamir.
3 Jairi ti ẹ̀yà Gileadi ni ó dìde lẹ́yìn rẹ̀, ó ṣàkóso Israẹli ní ọdún méjìlélógún.
Și după el s-a ridicat Iair, un galaadit, și a judecat pe Israel douăzeci și doi de ani.
4 Àwọn ọgbọ̀n ọmọ tí ó n gun ọgbọ̀n kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Wọ́n ṣe àkóso ọgbọ̀n ìlú ní Gileadi, tí a pe orúkọ wọn ní Hafoti-Jairi títí di òní.
Și el a avut treizeci de fii care călăreau pe treizeci de mânji de măgăriță, și ei aveau treizeci de cetăți, care se numesc Havot-Iair, până în această zi, care sunt în țara Galaadului.
5 Nígbà tí Jairi kú wọ́n sin ín sí Kamoni.
Și Iair a murit și a fost îngropat în Camon.
6 Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú lójú Olúwa. Wọ́n sin Baali àti Aṣtoreti àti àwọn òrìṣà Aramu, òrìṣà Sidoni, òrìṣà Moabu, òrìṣà àwọn ará Ammoni àti òrìṣà àwọn ará Filistini. Nítorí àwọn ará Israẹli kọ Olúwa sílẹ̀ tí wọn kò sì sìn ín mọ́,
Și copiii lui Israel din nou au făcut ce este rău în ochii DOMNULUI și au servit Baalilor și Astarteelor și dumnezeilor Siriei și dumnezeilor Sidonului și dumnezeilor Moabului și dumnezeilor copiilor lui Amon și dumnezeilor filistenilor și au părăsit pe DOMNUL și nu i-au servit lui.
7 ó bínú sí wọn, ó fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn ará Filistini àti Ammoni láti jẹ ẹ́ ní ìyà.
Și mânia DOMNULUI s-a aprins împotriva lui Israel și i-a vândut în mâna filistenilor și în mâna copiilor lui Amon.
8 Ní ọdún náà, wọ́n tú wọn ká wọ́n sì pọ́n wọn lójú. Fún ọdún méjìdínlógún ni wọ́n fi ni gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà ní ìlà-oòrùn odò Jordani ní ilẹ̀ àwọn ará Amori lára (èyí nì ní Gileadi).
Și în acel an, ei i-au chinuit și au oprimat pe copiii lui Israel, optsprezece ani, pe toți copiii lui Israel care erau dincolo de Iordan, în țara amoriților, care este în Galaad.
9 Àwọn ará Ammoni sì la odò Jordani kọjá láti bá Juda, Benjamini àti àwọn ará ilé Efraimu jagun: Israẹli sì dojúkọ ìpọ́njú tó lágbára.
Mai mult, copiii lui Amon au trecut Iordanul să lupte și cu Iuda și împotriva lui Beniamin și împotriva casei lui Efraim, astfel că Israel era foarte strâmtorat.
10 Nígbà tí èyí ti ṣẹlẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí ọ, nítorí pé àwa ti kọ Ọlọ́run wa sílẹ̀, àwa sì ń sin Baali.”
Și copiii lui Israel au strigat către DOMNUL, spunând: Am păcătuit împotriva ta, pentru că am părăsit pe Dumnezeul nostru și de asemenea am servit Baalilor.
11 Olúwa sì dáhùn pé, “Ǹjẹ́ nígbà tí àwọn ará Ejibiti, Amori, Ammoni, Filistini,
Și DOMNUL a spus copiilor lui Israel: Nu v-am eliberat de egipteni și de amoriți și de copiii lui Amon și de filisteni?
12 àwọn ará Sidoni, Amaleki pẹ̀lú Maoni ni yín lára, tí ẹ sì ké pè mí fún ìrànlọ́wọ́, ǹjẹ́ èmi kò gbà yín sílẹ̀ kúrò ní ọwọ́ wọn?
Sidonienii de asemenea și amaleciții și maoniții v-au oprimat și ați strigat către mine iar eu v-am eliberat din mâna lor.
13 Síbẹ̀síbẹ̀ ẹ̀yin kọ̀ mí sílẹ̀ láti sin àwọn ọlọ́run mìíràn, torí ìdí èyí, èmi kì yóò sì tún gbà yín mọ́.
Totuși voi m-ați părăsit și ați servit altor dumnezei, de aceea nu vă voi mai elibera.
14 Ẹ lọ kí ẹ sì ké pe àwọn òrìṣà tí ẹ̀yin ti yàn fún ara yín. Jẹ́ kí wọn gbà yín sílẹ̀ ní àsìkò ìpọ́njú yín!”
Duceți-vă și strigați la dumnezeii pe care vi i-ați ales, să vă salveze ei în timpul necazului vostru.
15 Àwọn ọmọ Israẹli sì dá Olúwa lóhùn pé, “Àwa ti ṣẹ̀, ṣe ohun tí ó bá fẹ́ pẹ̀lú wa, ṣùgbọ́n, jọ̀wọ́ gbà wá sílẹ̀ náání àsìkò yìí.”
Și copiii lui Israel au spus DOMNULUI: Am păcătuit, fă-ne cum ți se pare bine, eliberează-ne numai în ziua aceasta, te rugăm.
16 Nígbà náà ni wọ́n kó gbogbo ọlọ́run àjèjì tí ó wà láàrín wọn kúrò wọ́n sì sin Olúwa nìkan, ọkàn rẹ̀ kò sì le gbàgbé ìrora Israẹli mọ́.
Și au îndepărtat dumnezeii străini din mijlocul lor și au servit DOMNULUI, și sufletul său s-a mâhnit de nefericirea lui Israel.
17 Nígbà tí àwọn ará Ammoni kógun jọ ní Gileadi láti bá Israẹli jà, àwọn ọmọ Israẹli gbárajọpọ̀, wọ́n sì tẹ̀dó ogun ní Mispa.
Atunci copiii lui Amon s-au adunat și și-au înălțat corturile în Galaad. Și copiii lui Israel s-au adunat și și-au înălțat corturile în Mițpa.
18 Àwọn ìjòyè: aṣíwájú àwọn ará Gileadi wí fún ará wọn pé, “Ẹnikẹ́ni tí yóò kọ́ ṣígun si àwọn ará Ammoni ni yóò jẹ́ orí fún gbogbo àwọn tí ń gbé ní Gileadi.”
Și poporul și prinții Galaadului, au spus unul către altul: Care bărbat este acesta care va începe să lupte împotriva copiilor lui Amon? El va fi capul tuturor locuitorilor Galaadului.

< Judges 10 >