< Judges 10 >

1 Lẹ́yìn ikú Abimeleki, ọkùnrin kan láti ẹ̀yà Isakari tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Tola ọmọ Pua, ọmọ Dodo, dìde láti gba Israẹli sílẹ̀. Ní Ṣamiri tí ó wà ní òkè Efraimu ni ó gbé.
E depois de Abimelech, se levantou, para livrar a Israel, Tola, filho de Puah, filho de Dodo, homem d'Issacar: e habitava em Samir, na montanha d'Ephraim.
2 Ó ṣe àkóso Israẹli ní ọdún mẹ́tàlélógún. Nígbà tí ó kú wọ́n sìn ín sí Ṣamiri.
E julgou a Israel vinte e tres annos: e morreu, e foi sepultado em Samir.
3 Jairi ti ẹ̀yà Gileadi ni ó dìde lẹ́yìn rẹ̀, ó ṣàkóso Israẹli ní ọdún méjìlélógún.
E depois d'elle se levantou Jair, gileadita, e julgou a Israel vinte e dois annos.
4 Àwọn ọgbọ̀n ọmọ tí ó n gun ọgbọ̀n kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Wọ́n ṣe àkóso ọgbọ̀n ìlú ní Gileadi, tí a pe orúkọ wọn ní Hafoti-Jairi títí di òní.
E tinha este trinta filhos, que cavalgavam sobre trinta jumentos; e tinham trinta cidades, a que chamaram Havoth-jair, até ao dia d'hoje; as quaes estão na terra de Gilead.
5 Nígbà tí Jairi kú wọ́n sin ín sí Kamoni.
E morreu Jair, e foi sepultado em Camon.
6 Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú lójú Olúwa. Wọ́n sin Baali àti Aṣtoreti àti àwọn òrìṣà Aramu, òrìṣà Sidoni, òrìṣà Moabu, òrìṣà àwọn ará Ammoni àti òrìṣà àwọn ará Filistini. Nítorí àwọn ará Israẹli kọ Olúwa sílẹ̀ tí wọn kò sì sìn ín mọ́,
Então tornaram os filhos de Israel a fazer o que parecia mal aos olhos do Senhor, e serviram aos baalins, e a Astaroth, e aos deuses da Syria, e aos deuses de Sidon, e aos deuses de Moab, e aos deuses dos filhos d'Ammon, e aos deuses dos philisteos: e deixaram ao Senhor, e não o serviram.
7 ó bínú sí wọn, ó fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn ará Filistini àti Ammoni láti jẹ ẹ́ ní ìyà.
E a ira do Senhor se accendeu contra Israel: e vendeu-os em mão dos philisteos, e em mão dos filhos d'Ammon.
8 Ní ọdún náà, wọ́n tú wọn ká wọ́n sì pọ́n wọn lójú. Fún ọdún méjìdínlógún ni wọ́n fi ni gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà ní ìlà-oòrùn odò Jordani ní ilẹ̀ àwọn ará Amori lára (èyí nì ní Gileadi).
E n'aquelle mesmo anno opprimiram e vexaram aos filhos de Israel: dezoito annos opprimiram a todos os filhos de Israel que estavam d'além do Jordão, na terra dos amorrheos, que está em Gilead.
9 Àwọn ará Ammoni sì la odò Jordani kọjá láti bá Juda, Benjamini àti àwọn ará ilé Efraimu jagun: Israẹli sì dojúkọ ìpọ́njú tó lágbára.
Até os filhos d'Ammon passaram o Jordão, para pelejar tambem contra Judah, e contra Benjamin, e contra a casa d'Ephraim: de maneira que Israel ficou mui angustiado.
10 Nígbà tí èyí ti ṣẹlẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí ọ, nítorí pé àwa ti kọ Ọlọ́run wa sílẹ̀, àwa sì ń sin Baali.”
Então os filhos d'Israel clamaram ao Senhor, dizendo: Contra ti havemos peccado, em que deixámos a nosso Deus, e em que servimos aos baalins.
11 Olúwa sì dáhùn pé, “Ǹjẹ́ nígbà tí àwọn ará Ejibiti, Amori, Ammoni, Filistini,
Porém o Senhor disse aos filhos de Israel: Porventura dos egypcios, e dos amorrheos, e dos filhos d'Ammon, e dos philisteos,
12 àwọn ará Sidoni, Amaleki pẹ̀lú Maoni ni yín lára, tí ẹ sì ké pè mí fún ìrànlọ́wọ́, ǹjẹ́ èmi kò gbà yín sílẹ̀ kúrò ní ọwọ́ wọn?
E dos sidonios, e dos amalekitas, e dos maonitas, que vos opprimiam, quando a mim chamastes, não vos livrei eu então da sua mão?
13 Síbẹ̀síbẹ̀ ẹ̀yin kọ̀ mí sílẹ̀ láti sin àwọn ọlọ́run mìíràn, torí ìdí èyí, èmi kì yóò sì tún gbà yín mọ́.
Comtudo vós me deixastes a mim, e servistes a outros deuses: pelo que não vos livrarei mais.
14 Ẹ lọ kí ẹ sì ké pe àwọn òrìṣà tí ẹ̀yin ti yàn fún ara yín. Jẹ́ kí wọn gbà yín sílẹ̀ ní àsìkò ìpọ́njú yín!”
Andae, e clamae aos deuses que escolhestes: que vos livrem elles no tempo do vosso aperto.
15 Àwọn ọmọ Israẹli sì dá Olúwa lóhùn pé, “Àwa ti ṣẹ̀, ṣe ohun tí ó bá fẹ́ pẹ̀lú wa, ṣùgbọ́n, jọ̀wọ́ gbà wá sílẹ̀ náání àsìkò yìí.”
Mas os filhos de Israel disseram ao Senhor: Peccámos, faze-nos conforme a tudo quanto te parecer bem aos teus olhos; tão sómente te rogamos que nos livres n'este dia.
16 Nígbà náà ni wọ́n kó gbogbo ọlọ́run àjèjì tí ó wà láàrín wọn kúrò wọ́n sì sin Olúwa nìkan, ọkàn rẹ̀ kò sì le gbàgbé ìrora Israẹli mọ́.
E tiraram os deuses alheios do meio de si, e serviram ao Senhor: então se angustiou a sua alma por causa do trabalho d'Israel.
17 Nígbà tí àwọn ará Ammoni kógun jọ ní Gileadi láti bá Israẹli jà, àwọn ọmọ Israẹli gbárajọpọ̀, wọ́n sì tẹ̀dó ogun ní Mispa.
E os filhos d'Ammon se convocaram, e se pozeram em campo em Gilead: e tambem os de Israel se congregaram, e se pozeram em campo em Mispah.
18 Àwọn ìjòyè: aṣíwájú àwọn ará Gileadi wí fún ará wọn pé, “Ẹnikẹ́ni tí yóò kọ́ ṣígun si àwọn ará Ammoni ni yóò jẹ́ orí fún gbogbo àwọn tí ń gbé ní Gileadi.”
Então o povo, os principes de Gilead disseram uns aos outros: Quem será o varão que começará a pelejar contra os filhos d'Ammon? elle será por Cabeça de todos os moradores de Gilead

< Judges 10 >