< Judges 10 >

1 Lẹ́yìn ikú Abimeleki, ọkùnrin kan láti ẹ̀yà Isakari tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Tola ọmọ Pua, ọmọ Dodo, dìde láti gba Israẹli sílẹ̀. Ní Ṣamiri tí ó wà ní òkè Efraimu ni ó gbé.
Po Abimeleku powstał, aby bronić Izraela, Tola, syn Puy, syna Doda, mężczyzna z [pokolenia] Issachara. Mieszkał on w Szamir, na górze Efraim.
2 Ó ṣe àkóso Israẹli ní ọdún mẹ́tàlélógún. Nígbà tí ó kú wọ́n sìn ín sí Ṣamiri.
Sądził on Izraela przez dwadzieścia trzy lata, po czym umarł i został pogrzebany w Szamir.
3 Jairi ti ẹ̀yà Gileadi ni ó dìde lẹ́yìn rẹ̀, ó ṣàkóso Israẹli ní ọdún méjìlélógún.
A po nim powstał Jair Gileadczyk, który sądził Izraela przez dwadzieścia dwa lata.
4 Àwọn ọgbọ̀n ọmọ tí ó n gun ọgbọ̀n kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Wọ́n ṣe àkóso ọgbọ̀n ìlú ní Gileadi, tí a pe orúkọ wọn ní Hafoti-Jairi títí di òní.
Miał on trzydziestu synów, którzy jeździli na trzydziestu oślętach, a mieli trzydzieści miast zwanych do dziś Chawot-Jair, a [są one] w ziemi Gilead.
5 Nígbà tí Jairi kú wọ́n sin ín sí Kamoni.
Umarł Jair i został pogrzebany w Kamon.
6 Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú lójú Olúwa. Wọ́n sin Baali àti Aṣtoreti àti àwọn òrìṣà Aramu, òrìṣà Sidoni, òrìṣà Moabu, òrìṣà àwọn ará Ammoni àti òrìṣà àwọn ará Filistini. Nítorí àwọn ará Israẹli kọ Olúwa sílẹ̀ tí wọn kò sì sìn ín mọ́,
A synowie Izraela znowu czynili to, co złe w oczach PANA, służąc Baalom i Asztartom, bogom Syrii, bogom Sydonu, bogom Moabu, bogom synów Ammona i bogom filistyńskim, a opuścili PANA i nie służyli mu.
7 ó bínú sí wọn, ó fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn ará Filistini àti Ammoni láti jẹ ẹ́ ní ìyà.
Dlatego gniew PANA zapłonął przeciw Izraelowi i wydał ich w ręce Filistynów oraz w ręce synów Ammona.
8 Ní ọdún náà, wọ́n tú wọn ká wọ́n sì pọ́n wọn lójú. Fún ọdún méjìdínlógún ni wọ́n fi ni gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà ní ìlà-oòrùn odò Jordani ní ilẹ̀ àwọn ará Amori lára (èyí nì ní Gileadi).
Oni trapili i uciskali synów Izraela od tego roku przez osiemnaście lat – wszystkich synów Izraela, którzy byli za Jordanem w ziemi Amorytów, która jest w Gileadzie.
9 Àwọn ará Ammoni sì la odò Jordani kọjá láti bá Juda, Benjamini àti àwọn ará ilé Efraimu jagun: Israẹli sì dojúkọ ìpọ́njú tó lágbára.
Synowie Ammona przeprawili się też za Jordan, aby walczyć z Judą i Beniaminem, a także z domem Efraima, i Izrael był bardzo uciskany.
10 Nígbà tí èyí ti ṣẹlẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí ọ, nítorí pé àwa ti kọ Ọlọ́run wa sílẹ̀, àwa sì ń sin Baali.”
Wtedy synowie Izraela wołali do PANA: Zgrzeszyliśmy przeciw tobie, bo opuściliśmy naszego Boga, a służyliśmy Baalom.
11 Olúwa sì dáhùn pé, “Ǹjẹ́ nígbà tí àwọn ará Ejibiti, Amori, Ammoni, Filistini,
I PAN powiedział do synów Izraela: Czy [nie wybawiłem] was od Egipcjan, od Amorytów, od synów Ammona i od Filistynów?
12 àwọn ará Sidoni, Amaleki pẹ̀lú Maoni ni yín lára, tí ẹ sì ké pè mí fún ìrànlọ́wọ́, ǹjẹ́ èmi kò gbà yín sílẹ̀ kúrò ní ọwọ́ wọn?
I od Sydończyków, Amalekitów i Mahanitów, którzy was gnębili? Gdy wołaliście do mnie, czy nie wybawiłem was z ich rąk?
13 Síbẹ̀síbẹ̀ ẹ̀yin kọ̀ mí sílẹ̀ láti sin àwọn ọlọ́run mìíràn, torí ìdí èyí, èmi kì yóò sì tún gbà yín mọ́.
Lecz wy mnie opuściliście i służyliście obcym bogom. Dlatego już was więcej nie wybawię.
14 Ẹ lọ kí ẹ sì ké pe àwọn òrìṣà tí ẹ̀yin ti yàn fún ara yín. Jẹ́ kí wọn gbà yín sílẹ̀ ní àsìkò ìpọ́njú yín!”
Idźcie i wołajcie do bogów, których sobie wybraliście. Niech oni was wybawią w czasie waszego ucisku.
15 Àwọn ọmọ Israẹli sì dá Olúwa lóhùn pé, “Àwa ti ṣẹ̀, ṣe ohun tí ó bá fẹ́ pẹ̀lú wa, ṣùgbọ́n, jọ̀wọ́ gbà wá sílẹ̀ náání àsìkò yìí.”
Synowie Izraela odpowiedzieli PANU: Zgrzeszyliśmy. Uczyń z nami, co wydaje się dobre w twoich oczach, tylko wybaw nas, prosimy, dzisiaj.
16 Nígbà náà ni wọ́n kó gbogbo ọlọ́run àjèjì tí ó wà láàrín wọn kúrò wọ́n sì sin Olúwa nìkan, ọkàn rẹ̀ kò sì le gbàgbé ìrora Israẹli mọ́.
Wyrzucili więc obcych bogów spośród siebie i służyli PANU, a [PAN] wzruszył się niedolą Izraela.
17 Nígbà tí àwọn ará Ammoni kógun jọ ní Gileadi láti bá Israẹli jà, àwọn ọmọ Israẹli gbárajọpọ̀, wọ́n sì tẹ̀dó ogun ní Mispa.
Tymczasem synowie Ammona zebrali się i rozbili obóz w Gileadzie. Także synowie Izraela zebrali się i rozbili obóz w Mispie.
18 Àwọn ìjòyè: aṣíwájú àwọn ará Gileadi wí fún ará wọn pé, “Ẹnikẹ́ni tí yóò kọ́ ṣígun si àwọn ará Ammoni ni yóò jẹ́ orí fún gbogbo àwọn tí ń gbé ní Gileadi.”
Wtedy lud i przełożeni Gileadu mówili między sobą: Kto pierwszy podejmie walkę z synami Ammona, ten stanie na czele wszystkich mieszkańców Gileadu.

< Judges 10 >