< Judges 10 >
1 Lẹ́yìn ikú Abimeleki, ọkùnrin kan láti ẹ̀yà Isakari tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Tola ọmọ Pua, ọmọ Dodo, dìde láti gba Israẹli sílẹ̀. Ní Ṣamiri tí ó wà ní òkè Efraimu ni ó gbé.
Emva kukaAbhimeleki kwasekuvela uThola indodana kaPhuwa indodana kaDodo, indoda yakoIsakari ukukhulula uIsrayeli; wayehlala eShamiri entabeni yakoEfrayimi.
2 Ó ṣe àkóso Israẹli ní ọdún mẹ́tàlélógún. Nígbà tí ó kú wọ́n sìn ín sí Ṣamiri.
Wasesahlulela uIsrayeli iminyaka engamatshumi amabili lantathu. Wafa, wangcwatshelwa eShamiri.
3 Jairi ti ẹ̀yà Gileadi ni ó dìde lẹ́yìn rẹ̀, ó ṣàkóso Israẹli ní ọdún méjìlélógún.
Lemva kwakhe kwavela uJayiri umGileyadi, wahlulela uIsrayeli iminyaka engamatshumi amabili lambili.
4 Àwọn ọgbọ̀n ọmọ tí ó n gun ọgbọ̀n kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Wọ́n ṣe àkóso ọgbọ̀n ìlú ní Gileadi, tí a pe orúkọ wọn ní Hafoti-Jairi títí di òní.
Wayelamadodana angamatshumi amathathu agada amathole abobabhemi angamatshumi amathathu, elemizi engamatshumi amathathu, abayithi yiHavothi-Jayiri kuze kube lamuhla, eselizweni leGileyadi.
5 Nígbà tí Jairi kú wọ́n sin ín sí Kamoni.
UJayiri wasesifa, wangcwatshelwa eKamoni.
6 Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú lójú Olúwa. Wọ́n sin Baali àti Aṣtoreti àti àwọn òrìṣà Aramu, òrìṣà Sidoni, òrìṣà Moabu, òrìṣà àwọn ará Ammoni àti òrìṣà àwọn ará Filistini. Nítorí àwọn ará Israẹli kọ Olúwa sílẹ̀ tí wọn kò sì sìn ín mọ́,
Abantwana bakoIsrayeli basebebuya besenza okubi emehlweni eNkosi, bakhonza oBhali laboAshitarothi, labonkulunkulu beSiriya labonkulunkulu beSidoni labonkulunkulu bakoMowabi labonkulunkulu babantwana bakoAmoni labonkulunkulu bamaFilisti; bayitshiya iNkosi, kabaze bayikhonza.
7 ó bínú sí wọn, ó fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn ará Filistini àti Ammoni láti jẹ ẹ́ ní ìyà.
Ulaka lweNkosi lwaselumvuthela uIsrayeli, yabathengisa ezandleni zamaFilisti lezandleni zabantwana bakoAmoni.
8 Ní ọdún náà, wọ́n tú wọn ká wọ́n sì pọ́n wọn lójú. Fún ọdún méjìdínlógún ni wọ́n fi ni gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà ní ìlà-oòrùn odò Jordani ní ilẹ̀ àwọn ará Amori lára (èyí nì ní Gileadi).
Asebachitha abacindezela abantwana bakoIsrayeli ngalowomnyaka - iminyaka elitshumi leyisificaminwembili, bonke abantwana bakoIsrayeli ababengaphetsheya kweJordani elizweni lamaAmori eliseGileyadi.
9 Àwọn ará Ammoni sì la odò Jordani kọjá láti bá Juda, Benjamini àti àwọn ará ilé Efraimu jagun: Israẹli sì dojúkọ ìpọ́njú tó lágbára.
Njalo abantwana bakoAmoni bachapha iJordani ukuze balwe ngitsho bemelene loJuda njalo bemelene loBhenjamini bemelene lendlu kaEfrayimi; ngalokho uIsrayeli wacindezeleka kakhulu.
10 Nígbà tí èyí ti ṣẹlẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí ọ, nítorí pé àwa ti kọ Ọlọ́run wa sílẹ̀, àwa sì ń sin Baali.”
Abantwana bakoIsrayeli basebekhala eNkosini besithi: Sonile kuwe, njalo ngoba sitshiyile uNkulunkulu wethu, sasesikhonza oBhali.
11 Olúwa sì dáhùn pé, “Ǹjẹ́ nígbà tí àwọn ará Ejibiti, Amori, Ammoni, Filistini,
INkosi yasisithi ebantwaneni bakoIsrayeli: Kangilikhululanga yini kumaGibhithe lakumaAmori lakubantwana bakoAmoni lakumaFilisti?
12 àwọn ará Sidoni, Amaleki pẹ̀lú Maoni ni yín lára, tí ẹ sì ké pè mí fún ìrànlọ́wọ́, ǹjẹ́ èmi kò gbà yín sílẹ̀ kúrò ní ọwọ́ wọn?
AmaSidoni lawo lamaAmaleki lamaMahoni alicindezela, laselikhala kimi, ngalikhulula esandleni sawo.
13 Síbẹ̀síbẹ̀ ẹ̀yin kọ̀ mí sílẹ̀ láti sin àwọn ọlọ́run mìíràn, torí ìdí èyí, èmi kì yóò sì tún gbà yín mọ́.
Kanti lina lingitshiyile lakhonza abanye onkulunkulu; ngakho kangisayikulikhulula.
14 Ẹ lọ kí ẹ sì ké pe àwọn òrìṣà tí ẹ̀yin ti yàn fún ara yín. Jẹ́ kí wọn gbà yín sílẹ̀ ní àsìkò ìpọ́njú yín!”
Hambani liyekhala kubonkulunkulu elibakhethileyo; kabalikhulule bona ngesikhathi sokuhlupheka kwenu.
15 Àwọn ọmọ Israẹli sì dá Olúwa lóhùn pé, “Àwa ti ṣẹ̀, ṣe ohun tí ó bá fẹ́ pẹ̀lú wa, ṣùgbọ́n, jọ̀wọ́ gbà wá sílẹ̀ náání àsìkò yìí.”
Abantwana bakoIsrayeli-ke bathi eNkosini: Sonile; yenza wena kithi njengakho konke okuhle emehlweni akho; kuphela sikhulule, siyakuncenga, lamuhla.
16 Nígbà náà ni wọ́n kó gbogbo ọlọ́run àjèjì tí ó wà láàrín wọn kúrò wọ́n sì sin Olúwa nìkan, ọkàn rẹ̀ kò sì le gbàgbé ìrora Israẹli mọ́.
Basebesusa onkulunkulu bezizweni phakathi kwabo, bakhonza iNkosi; umphefumulo wayo wasudabuka ngohlupho lukaIsrayeli.
17 Nígbà tí àwọn ará Ammoni kógun jọ ní Gileadi láti bá Israẹli jà, àwọn ọmọ Israẹli gbárajọpọ̀, wọ́n sì tẹ̀dó ogun ní Mispa.
Kwasekubizelwa ndawonye abantwana bakoAmoni, bamisa inkamba eGileyadi, labantwana bakoIsrayeli babuthana bamisa inkamba eMizipa.
18 Àwọn ìjòyè: aṣíwájú àwọn ará Gileadi wí fún ará wọn pé, “Ẹnikẹ́ni tí yóò kọ́ ṣígun si àwọn ará Ammoni ni yóò jẹ́ orí fún gbogbo àwọn tí ń gbé ní Gileadi.”
Labantu, iziphathamandla zeGileyadi, bathi omunye komunye: Ngubani umuntu ozaqala ukulwa emelene labantwana bakoAmoni? Uzakuba yinhloko phezu kwabo bonke abahlali beGileyadi.