< Judges 10 >

1 Lẹ́yìn ikú Abimeleki, ọkùnrin kan láti ẹ̀yà Isakari tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Tola ọmọ Pua, ọmọ Dodo, dìde láti gba Israẹli sílẹ̀. Ní Ṣamiri tí ó wà ní òkè Efraimu ni ó gbé.
Thuutha wa Abimeleku, mũndũ wa mũhĩrĩga wa Isakaru wetagwo Tola mũrũ wa Pua, mũrũ wa Dodo, akĩarahũka ahonokie Isiraeli. Nake agĩtũũra Shamiru, kũu bũrũri ũrĩa ũrĩ irĩma wa Efiraimu.
2 Ó ṣe àkóso Israẹli ní ọdún mẹ́tàlélógún. Nígbà tí ó kú wọ́n sìn ín sí Ṣamiri.
Agĩtiirĩrĩra Isiraeli mĩaka mĩrongo ĩĩrĩ na ĩtatũ; agĩcooka agĩkua, na agĩthikwo kũu Shamiru.
3 Jairi ti ẹ̀yà Gileadi ni ó dìde lẹ́yìn rẹ̀, ó ṣàkóso Israẹli ní ọdún méjìlélógún.
Nake Tola akĩrũmĩrĩrwo nĩ Jairu wa kuuma Gileadi, ũrĩa watiirĩrĩire Isiraeli mĩaka mĩrongo ĩĩrĩ na ĩĩrĩ.
4 Àwọn ọgbọ̀n ọmọ tí ó n gun ọgbọ̀n kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Wọ́n ṣe àkóso ọgbọ̀n ìlú ní Gileadi, tí a pe orúkọ wọn ní Hafoti-Jairi títí di òní.
Jairu aarĩ na ariũ mĩrongo ĩtatũ arĩa mathiiaga mahaicĩte ndigiri mĩrongo ĩtatũ. Maathaga matũũra mĩrongo ĩtatũ kũu Gileadi, marĩa nginya ũmũthĩ metagwo Havothu-Jairu.
5 Nígbà tí Jairi kú wọ́n sin ín sí Kamoni.
Jairu akua aathikirwo kũu Kamonu.
6 Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú lójú Olúwa. Wọ́n sin Baali àti Aṣtoreti àti àwọn òrìṣà Aramu, òrìṣà Sidoni, òrìṣà Moabu, òrìṣà àwọn ará Ammoni àti òrìṣà àwọn ará Filistini. Nítorí àwọn ará Israẹli kọ Olúwa sílẹ̀ tí wọn kò sì sìn ín mọ́,
O rĩngĩ andũ a Isiraeli nĩmekire maũndũ mooru maitho-inĩ ma Jehova. Magĩtungatĩra Mabaali na Maashitorethu, na ngai cia Aramu, na ngai cia Sidoni, na ngai cia Moabi, na ngai cia Aamoni, o na ngai cia Afilisti. Na tondũ andũ a Isiraeli nĩmatiganĩirie Jehova na matiacookire kũmũtungatĩra-rĩ,
7 ó bínú sí wọn, ó fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn ará Filistini àti Ammoni láti jẹ ẹ́ ní ìyà.
akĩrakario nĩo. Akĩmaneana moko-inĩ ma Afilisti na moko-inĩ ma Aamoni,
8 Ní ọdún náà, wọ́n tú wọn ká wọ́n sì pọ́n wọn lójú. Fún ọdún méjìdínlógún ni wọ́n fi ni gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà ní ìlà-oòrùn odò Jordani ní ilẹ̀ àwọn ará Amori lára (èyí nì ní Gileadi).
arĩa maamanyariirire na makĩmahinyĩrĩria mwaka-inĩ ũcio. Nao makĩhinyĩrĩria andũ a Isiraeli othe arĩa maarĩ mwena wa irathĩro wa Rũũĩ rwa Jorodani kũu Gileadi, bũrũri wa Aamori, mĩaka ikũmi na ĩnana.
9 Àwọn ará Ammoni sì la odò Jordani kọjá láti bá Juda, Benjamini àti àwọn ará ilé Efraimu jagun: Israẹli sì dojúkọ ìpọ́njú tó lágbára.
Ningĩ Aamoni makĩringa Rũũĩ rwa Jorodani nĩguo makarũe na andũ a Juda, na andũ a Benjamini, o na nyũmba ya Efiraimu; nakuo Isiraeli gũkĩgĩa na kĩnyariirĩko kĩnene.
10 Nígbà tí èyí ti ṣẹlẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí ọ, nítorí pé àwa ti kọ Ọlọ́run wa sílẹ̀, àwa sì ń sin Baali.”
Ningĩ andũ a Isiraeli magĩkaĩra Jehova makĩmwĩra atĩrĩ, “Nĩtwĩhĩtie, tũgatiganĩria Ngai witũ, tũgatungatĩra Mabaali.”
11 Olúwa sì dáhùn pé, “Ǹjẹ́ nígbà tí àwọn ará Ejibiti, Amori, Ammoni, Filistini,
Jehova akĩmacookeria atĩrĩ, “Hĩndĩ ĩrĩa andũ a Misiri na Aamori, na Aamoni, na Afilisti,
12 àwọn ará Sidoni, Amaleki pẹ̀lú Maoni ni yín lára, tí ẹ sì ké pè mí fún ìrànlọ́wọ́, ǹjẹ́ èmi kò gbà yín sílẹ̀ kúrò ní ọwọ́ wọn?
na Asidoni, na Aamaleki, o na Amaoni maamũhinyĩrĩirie na mũkĩngaĩra ndĩmũteithie-rĩ, githĩ ndiamũhonokirie kuuma moko-inĩ mao?
13 Síbẹ̀síbẹ̀ ẹ̀yin kọ̀ mí sílẹ̀ láti sin àwọn ọlọ́run mìíràn, torí ìdí èyí, èmi kì yóò sì tún gbà yín mọ́.
No inyuĩ nĩmwandiganĩirie na mũgĩtungatĩra ngai ingĩ, tondũ ũcio ndigacooka kũmũhonokia o na rĩ.
14 Ẹ lọ kí ẹ sì ké pe àwọn òrìṣà tí ẹ̀yin ti yàn fún ara yín. Jẹ́ kí wọn gbà yín sílẹ̀ ní àsìkò ìpọ́njú yín!”
Thiĩi mũgakaĩre ngai icio mwĩthuurĩire. Nĩimũhonokagie hĩndĩ ĩrĩa mũranyamarĩka!”
15 Àwọn ọmọ Israẹli sì dá Olúwa lóhùn pé, “Àwa ti ṣẹ̀, ṣe ohun tí ó bá fẹ́ pẹ̀lú wa, ṣùgbọ́n, jọ̀wọ́ gbà wá sílẹ̀ náání àsìkò yìí.”
No andũ a Isiraeli makĩĩra Jehova atĩrĩ, “Nĩtwĩhĩtie. Ĩka na ithuĩ o ta ũrĩa ũkuona kwagĩrĩire, no rĩrĩ, twagũthaitha ũtũhonokie rĩu.”
16 Nígbà náà ni wọ́n kó gbogbo ọlọ́run àjèjì tí ó wà láàrín wọn kúrò wọ́n sì sin Olúwa nìkan, ọkàn rẹ̀ kò sì le gbàgbé ìrora Israẹli mọ́.
Hĩndĩ ĩyo magĩkĩeheria ngai icio cia kũngĩ gatagatĩ-inĩ kao, na magĩtungatĩra Jehova. Nake ndangĩakirĩrĩirie rĩngĩ kuona Isiraeli makĩnyariirĩka.
17 Nígbà tí àwọn ará Ammoni kógun jọ ní Gileadi láti bá Israẹli jà, àwọn ọmọ Israẹli gbárajọpọ̀, wọ́n sì tẹ̀dó ogun ní Mispa.
Rĩrĩa Aamoni meerirwo moe indo cia mbaara na makĩamba hema ciao kũu Gileadi-rĩ, andũ a Isiraeli makĩũngana na makĩamba hema ciao kũu Mizipa.
18 Àwọn ìjòyè: aṣíwájú àwọn ará Gileadi wí fún ará wọn pé, “Ẹnikẹ́ni tí yóò kọ́ ṣígun si àwọn ará Ammoni ni yóò jẹ́ orí fún gbogbo àwọn tí ń gbé ní Gileadi.”
Atongoria a andũ a Gileadi makĩĩrana atĩrĩ, “Mũndũ ũrĩa ũkwambĩrĩria kũrũa na Aamoni-rĩ, ũcio nĩwe ũgũtuĩka mũnene wa andũ arĩa matũũraga Gileadi.”

< Judges 10 >