< Judges 10 >
1 Lẹ́yìn ikú Abimeleki, ọkùnrin kan láti ẹ̀yà Isakari tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Tola ọmọ Pua, ọmọ Dodo, dìde láti gba Israẹli sílẹ̀. Ní Ṣamiri tí ó wà ní òkè Efraimu ni ó gbé.
After Abimelech died, Tola the son of Puah and grandson of Dodo became the leader to rescue the Israeli people [from their enemies]. He belonged to the tribe of Issachar, but he lived in Shamir [city] in the hilly area where the descendants of Ephraim live.
2 Ó ṣe àkóso Israẹli ní ọdún mẹ́tàlélógún. Nígbà tí ó kú wọ́n sìn ín sí Ṣamiri.
He ruled the Israeli people for 23 years. Then he died and was buried in Shamir.
3 Jairi ti ẹ̀yà Gileadi ni ó dìde lẹ́yìn rẹ̀, ó ṣàkóso Israẹli ní ọdún méjìlélógún.
After Tola died, Jair, from [the] Gilead [region], became the Israelis’ leader, and he ruled them for 22 years.
4 Àwọn ọgbọ̀n ọmọ tí ó n gun ọgbọ̀n kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Wọ́n ṣe àkóso ọgbọ̀n ìlú ní Gileadi, tí a pe orúkọ wọn ní Hafoti-Jairi títí di òní.
He had thirty sons, and each of them had his own donkey to ride on. They each controlled a different town in [the] Gilead [region]. That region is still named ‘The Towns of Jair’.
5 Nígbà tí Jairi kú wọ́n sin ín sí Kamoni.
When Jair died, he was buried in Kamon [city].
6 Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú lójú Olúwa. Wọ́n sin Baali àti Aṣtoreti àti àwọn òrìṣà Aramu, òrìṣà Sidoni, òrìṣà Moabu, òrìṣà àwọn ará Ammoni àti òrìṣà àwọn ará Filistini. Nítorí àwọn ará Israẹli kọ Olúwa sílẹ̀ tí wọn kò sì sìn ín mọ́,
Again the Israelis did things that Yahweh said were wrong/evil. They worshiped [the idols of their god] Baal and [their goddess] Astarte. They also worshiped the gods of the Aram, Sidon, Moab, and Ammon people-groups, and the gods of the Philistia people-group. They abandoned Yahweh and stopped worshiping him.
7 ó bínú sí wọn, ó fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn ará Filistini àti Ammoni láti jẹ ẹ́ ní ìyà.
So Yahweh was very angry with them, and he allowed the Philistia and Ammon people-groups to defeat [IDM] the Israelis.
8 Ní ọdún náà, wọ́n tú wọn ká wọ́n sì pọ́n wọn lójú. Fún ọdún méjìdínlógún ni wọ́n fi ni gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà ní ìlà-oòrùn odò Jordani ní ilẹ̀ àwọn ará Amori lára (èyí nì ní Gileadi).
In that same year, those people started to oppress the Israelis who lived in [the] Gilead [region] on the east side of the Jordan [River]. That was where the Amor people-group also lived. were They caused the Israelis who lived in that region to suffer for 18 years.
9 Àwọn ará Ammoni sì la odò Jordani kọjá láti bá Juda, Benjamini àti àwọn ará ilé Efraimu jagun: Israẹli sì dojúkọ ìpọ́njú tó lágbára.
Then the people of the Ammon people-group crossed the Jordan [River] to fight against the people of the tribes of Judah, Benjamin, and Ephraim. They caused the Israelis’ lives to be very miserable.
10 Nígbà tí èyí ti ṣẹlẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí ọ, nítorí pé àwa ti kọ Ọlọ́run wa sílẹ̀, àwa sì ń sin Baali.”
So the Israelis cried out to Yahweh, saying “We have sinned against you. We have abandoned you, and we have been worshiping [the idols of their god] Baal.”
11 Olúwa sì dáhùn pé, “Ǹjẹ́ nígbà tí àwọn ará Ejibiti, Amori, Ammoni, Filistini,
Yahweh answered them, saying, “When the people of Egypt, and the Amor and Ammon and Philistia people-groups
12 àwọn ará Sidoni, Amaleki pẹ̀lú Maoni ni yín lára, tí ẹ sì ké pè mí fún ìrànlọ́wọ́, ǹjẹ́ èmi kò gbà yín sílẹ̀ kúrò ní ọwọ́ wọn?
and the Sidon and Amalek and Maon people-groups were cruel to you, you cried out to me, and then I rescued you.
13 Síbẹ̀síbẹ̀ ẹ̀yin kọ̀ mí sílẹ̀ láti sin àwọn ọlọ́run mìíràn, torí ìdí èyí, èmi kì yóò sì tún gbà yín mọ́.
But now you have abandoned me again, and you have been worshiping other gods. So I will not rescue you again.
14 Ẹ lọ kí ẹ sì ké pe àwọn òrìṣà tí ẹ̀yin ti yàn fún ara yín. Jẹ́ kí wọn gbà yín sílẹ̀ ní àsìkò ìpọ́njú yín!”
You have chosen those gods [to be the ones that you worship]. So call to them to help you. Allow them to rescue you when you have a lot of trouble!”
15 Àwọn ọmọ Israẹli sì dá Olúwa lóhùn pé, “Àwa ti ṣẹ̀, ṣe ohun tí ó bá fẹ́ pẹ̀lú wa, ṣùgbọ́n, jọ̀wọ́ gbà wá sílẹ̀ náání àsìkò yìí.”
But the Israeli people said to Yahweh, “Truly we have sinned. Punish us in whatever way you wish to, but please rescue us now!”
16 Nígbà náà ni wọ́n kó gbogbo ọlọ́run àjèjì tí ó wà láàrín wọn kúrò wọ́n sì sin Olúwa nìkan, ọkàn rẹ̀ kò sì le gbàgbé ìrora Israẹli mọ́.
Then the Israelis threw away the [idols of the] gods that belonged to other people-groups, and they worshiped Yahweh again. He saw that they were suffering very much, and he felt sorry [IDM] for them.
17 Nígbà tí àwọn ará Ammoni kógun jọ ní Gileadi láti bá Israẹli jà, àwọn ọmọ Israẹli gbárajọpọ̀, wọ́n sì tẹ̀dó ogun ní Mispa.
The Ammon people-group gathered to fight [against the Israelis], and they set up their tents in [the] Gilead [region]. The Israeli men also gathered and set up their tents at Mizpah, [which was a city in Gilead].
18 Àwọn ìjòyè: aṣíwájú àwọn ará Gileadi wí fún ará wọn pé, “Ẹnikẹ́ni tí yóò kọ́ ṣígun si àwọn ará Ammoni ni yóò jẹ́ orí fún gbogbo àwọn tí ń gbé ní Gileadi.”
The Israeli leaders said, “Who will lead our soldiers to attack the Ammon people-group? The one who will lead us will become the leader of all us who live in this Gilead [region].”