< Judges 10 >
1 Lẹ́yìn ikú Abimeleki, ọkùnrin kan láti ẹ̀yà Isakari tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Tola ọmọ Pua, ọmọ Dodo, dìde láti gba Israẹli sílẹ̀. Ní Ṣamiri tí ó wà ní òkè Efraimu ni ó gbé.
And there rises after Abimelech, to save Israel, Tola son of Puah, son of Dodo, a man of Issachar, and he is dwelling in Shamir, in the hill-country of Ephraim,
2 Ó ṣe àkóso Israẹli ní ọdún mẹ́tàlélógún. Nígbà tí ó kú wọ́n sìn ín sí Ṣamiri.
and he judges Israel [for] twenty-three years, and he dies, and is buried in Shamir.
3 Jairi ti ẹ̀yà Gileadi ni ó dìde lẹ́yìn rẹ̀, ó ṣàkóso Israẹli ní ọdún méjìlélógún.
And there rises Jair the Gileadite after him, and he judges Israel [for] twenty-two years,
4 Àwọn ọgbọ̀n ọmọ tí ó n gun ọgbọ̀n kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Wọ́n ṣe àkóso ọgbọ̀n ìlú ní Gileadi, tí a pe orúkọ wọn ní Hafoti-Jairi títí di òní.
and he has thirty sons riding on thirty donkey-colts, and they have thirty cities (they call them Havoth-Jair to this day), which [are] in the land of Gilead;
5 Nígbà tí Jairi kú wọ́n sin ín sí Kamoni.
and Jair dies, and is buried in Kamon.
6 Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú lójú Olúwa. Wọ́n sin Baali àti Aṣtoreti àti àwọn òrìṣà Aramu, òrìṣà Sidoni, òrìṣà Moabu, òrìṣà àwọn ará Ammoni àti òrìṣà àwọn ará Filistini. Nítorí àwọn ará Israẹli kọ Olúwa sílẹ̀ tí wọn kò sì sìn ín mọ́,
And the sons of Israel add to do evil in the eyes of YHWH, and serve the Ba‘alim, and Ashtaroth, and the gods of Aram, and the gods of Sidon, and the gods of Moab, and the gods of the sons of Ammon, and the gods of the Philistines, and forsake YHWH, and have not served Him;
7 ó bínú sí wọn, ó fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn ará Filistini àti Ammoni láti jẹ ẹ́ ní ìyà.
and the anger of YHWH burns against Israel, and He sells them into the hand of the Philistines, and into the hand of the sons of Ammon,
8 Ní ọdún náà, wọ́n tú wọn ká wọ́n sì pọ́n wọn lójú. Fún ọdún méjìdínlógún ni wọ́n fi ni gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà ní ìlà-oòrùn odò Jordani ní ilẹ̀ àwọn ará Amori lára (èyí nì ní Gileadi).
and they crush and oppress the sons of Israel in that year; [and for] eighteen years—all the sons of Israel [who] are beyond the Jordan, in the land of the Amorite, which [is] in Gilead.
9 Àwọn ará Ammoni sì la odò Jordani kọjá láti bá Juda, Benjamini àti àwọn ará ilé Efraimu jagun: Israẹli sì dojúkọ ìpọ́njú tó lágbára.
And the sons of Ammon pass over the Jordan to also fight against Judah, and against Benjamin, and against the house of Ephraim, and Israel has great distress.
10 Nígbà tí èyí ti ṣẹlẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí ọ, nítorí pé àwa ti kọ Ọlọ́run wa sílẹ̀, àwa sì ń sin Baali.”
And the sons of Israel cry to YHWH, saying, “We have sinned against You, because we have even forsaken our God, and serve the Ba‘alim.”
11 Olúwa sì dáhùn pé, “Ǹjẹ́ nígbà tí àwọn ará Ejibiti, Amori, Ammoni, Filistini,
And YHWH says to the sons of Israel, “[Have I] not [saved you] from the Egyptians, and from the Amorite, from the sons of Ammon, and from the Philistines?
12 àwọn ará Sidoni, Amaleki pẹ̀lú Maoni ni yín lára, tí ẹ sì ké pè mí fún ìrànlọ́wọ́, ǹjẹ́ èmi kò gbà yín sílẹ̀ kúrò ní ọwọ́ wọn?
And the Zidonians, and Amalek, and Maon have oppressed you, and you cry to Me, and I save you out of their hand;
13 Síbẹ̀síbẹ̀ ẹ̀yin kọ̀ mí sílẹ̀ láti sin àwọn ọlọ́run mìíràn, torí ìdí èyí, èmi kì yóò sì tún gbà yín mọ́.
and you have forsaken Me, and serve other gods, therefore I do not add to save you.
14 Ẹ lọ kí ẹ sì ké pe àwọn òrìṣà tí ẹ̀yin ti yàn fún ara yín. Jẹ́ kí wọn gbà yín sílẹ̀ ní àsìkò ìpọ́njú yín!”
Go and cry to the gods on which you have fixed; they save you in the time of your tribulation.”
15 Àwọn ọmọ Israẹli sì dá Olúwa lóhùn pé, “Àwa ti ṣẹ̀, ṣe ohun tí ó bá fẹ́ pẹ̀lú wa, ṣùgbọ́n, jọ̀wọ́ gbà wá sílẹ̀ náání àsìkò yìí.”
And the sons of Israel say to YHWH, “We have sinned, do to us according to all that is good in Your eyes; only please deliver us this day.”
16 Nígbà náà ni wọ́n kó gbogbo ọlọ́run àjèjì tí ó wà láàrín wọn kúrò wọ́n sì sin Olúwa nìkan, ọkàn rẹ̀ kò sì le gbàgbé ìrora Israẹli mọ́.
And they turn aside the gods of the stranger out of their midst, and serve YHWH, and His soul is grieved with the misery of Israel.
17 Nígbà tí àwọn ará Ammoni kógun jọ ní Gileadi láti bá Israẹli jà, àwọn ọmọ Israẹli gbárajọpọ̀, wọ́n sì tẹ̀dó ogun ní Mispa.
And the sons of Ammon are called together, and encamp in Gilead, and the sons of Israel are gathered together, and encamp in Mizpah.
18 Àwọn ìjòyè: aṣíwájú àwọn ará Gileadi wí fún ará wọn pé, “Ẹnikẹ́ni tí yóò kọ́ ṣígun si àwọn ará Ammoni ni yóò jẹ́ orí fún gbogbo àwọn tí ń gbé ní Gileadi.”
And the people—heads of Gilead—say to one another, “Who [is] the man that begins to fight against the sons of Ammon? He is for head to all inhabitants of Gilead.”