< Judges 10 >

1 Lẹ́yìn ikú Abimeleki, ọkùnrin kan láti ẹ̀yà Isakari tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Tola ọmọ Pua, ọmọ Dodo, dìde láti gba Israẹli sílẹ̀. Ní Ṣamiri tí ó wà ní òkè Efraimu ni ó gbé.
Povstal pak po Abimelechovi k obhajování Izraele Tola, syn Fua, syna Dodova, muž z pokolení Izachar, a ten bydlil v Samir na hoře Efraim.
2 Ó ṣe àkóso Israẹli ní ọdún mẹ́tàlélógún. Nígbà tí ó kú wọ́n sìn ín sí Ṣamiri.
I soudil Izraele za třimecítma let, a umřev, pochován jest v Samir.
3 Jairi ti ẹ̀yà Gileadi ni ó dìde lẹ́yìn rẹ̀, ó ṣàkóso Israẹli ní ọdún méjìlélógún.
Po něm povstal Jair Galádský, a soudil Izraele za dvamecítma let.
4 Àwọn ọgbọ̀n ọmọ tí ó n gun ọgbọ̀n kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Wọ́n ṣe àkóso ọgbọ̀n ìlú ní Gileadi, tí a pe orúkọ wọn ní Hafoti-Jairi títí di òní.
A měl třidceti synů, kteříž jezdili na třidcíti mezcích; a měli třidceti měst, kteráž sloula vsi Jairovy až do dnešního dne, a ty jsou v zemi Galád.
5 Nígbà tí Jairi kú wọ́n sin ín sí Kamoni.
I umřel Jair, a pochován jest v Kamon.
6 Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú lójú Olúwa. Wọ́n sin Baali àti Aṣtoreti àti àwọn òrìṣà Aramu, òrìṣà Sidoni, òrìṣà Moabu, òrìṣà àwọn ará Ammoni àti òrìṣà àwọn ará Filistini. Nítorí àwọn ará Israẹli kọ Olúwa sílẹ̀ tí wọn kò sì sìn ín mọ́,
Opět pak synové Izraelští činili to, což jest zlého před očima Hospodinovýma; nebo sloužili Bálům a Astarot, to jest, bohům Syrským, bohům Sidonským a bohům Moábským, tolikéž i bohům synů Ammon, i bohům Filistinským, tak že opustili Hospodina, a nesloužili jemu.
7 ó bínú sí wọn, ó fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn ará Filistini àti Ammoni láti jẹ ẹ́ ní ìyà.
Protož roznítila se prchlivost Hospodinova na Izraele, a vydal je v ruku Filistinských a v ruku Ammonitských,
8 Ní ọdún náà, wọ́n tú wọn ká wọ́n sì pọ́n wọn lójú. Fún ọdún méjìdínlógún ni wọ́n fi ni gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà ní ìlà-oòrùn odò Jordani ní ilẹ̀ àwọn ará Amori lára (èyí nì ní Gileadi).
Kteříž stírali a potlačovali syny Izraelské toho roku, i potom za osmnácte let, všecky syny Izraelské, kteříž byli před Jordánem v zemi Amorejského, kteráž jest v Galád.
9 Àwọn ará Ammoni sì la odò Jordani kọjá láti bá Juda, Benjamini àti àwọn ará ilé Efraimu jagun: Israẹli sì dojúkọ ìpọ́njú tó lágbára.
Přešli pak Ammonitští i Jordán, aby bojovali také proti Judovi, a proti Beniaminovi, i proti domu Efraimovu; i byl Izrael náramně ssoužen.
10 Nígbà tí èyí ti ṣẹlẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí ọ, nítorí pé àwa ti kọ Ọlọ́run wa sílẹ̀, àwa sì ń sin Baali.”
Tedy volali synové Izraelští k Hospodinu, řkouce: Zhřešiliť jsme tobě, tak že jsme opustili tě Boha svého, a sloužili jsme Bálům.
11 Olúwa sì dáhùn pé, “Ǹjẹ́ nígbà tí àwọn ará Ejibiti, Amori, Ammoni, Filistini,
Ale Hospodin řekl synům Izraelským: Zdaliž jsem od Egyptských a od Amorejských a od Ammonitských a Filistinských,
12 àwọn ará Sidoni, Amaleki pẹ̀lú Maoni ni yín lára, tí ẹ sì ké pè mí fún ìrànlọ́wọ́, ǹjẹ́ èmi kò gbà yín sílẹ̀ kúrò ní ọwọ́ wọn?
Tolikéž od Sidonských, a Amalechitských, i od Maonitských, vás ssužujících, když jste volali ke mně, nevysvobodil vás z ruky jejich?
13 Síbẹ̀síbẹ̀ ẹ̀yin kọ̀ mí sílẹ̀ láti sin àwọn ọlọ́run mìíràn, torí ìdí èyí, èmi kì yóò sì tún gbà yín mọ́.
A vy opustili jste mne a sloužili jste bohům cizím, protož nevysvobodím vás více.
14 Ẹ lọ kí ẹ sì ké pe àwọn òrìṣà tí ẹ̀yin ti yàn fún ara yín. Jẹ́ kí wọn gbà yín sílẹ̀ ní àsìkò ìpọ́njú yín!”
Jděte a volejte k bohům, kteréž jste sobě zvolili; oni nechť vás vysvobodí v čas ssoužení vašeho.
15 Àwọn ọmọ Israẹli sì dá Olúwa lóhùn pé, “Àwa ti ṣẹ̀, ṣe ohun tí ó bá fẹ́ pẹ̀lú wa, ṣùgbọ́n, jọ̀wọ́ gbà wá sílẹ̀ náání àsìkò yìí.”
I řekli synové Izraelští Hospodinu: Zhřešili jsme; učiň s námi, cožť se dobře líbí, a však vysvoboď nás, prosíme, v tento čas.
16 Nígbà náà ni wọ́n kó gbogbo ọlọ́run àjèjì tí ó wà láàrín wọn kúrò wọ́n sì sin Olúwa nìkan, ọkàn rẹ̀ kò sì le gbàgbé ìrora Israẹli mọ́.
Protož vyvrhše bohy cizí z prostředku svého, sloužili Hospodinu, a zželelo se duši jeho nad trápením Izraele.
17 Nígbà tí àwọn ará Ammoni kógun jọ ní Gileadi láti bá Israẹli jà, àwọn ọmọ Israẹli gbárajọpọ̀, wọ́n sì tẹ̀dó ogun ní Mispa.
Svolali se pak Ammonitští, a položili se v Galád; shromáždili se také synové Izraelští, a položili se v Masfa.
18 Àwọn ìjòyè: aṣíwájú àwọn ará Gileadi wí fún ará wọn pé, “Ẹnikẹ́ni tí yóò kọ́ ṣígun si àwọn ará Ammoni ni yóò jẹ́ orí fún gbogbo àwọn tí ń gbé ní Gileadi.”
I řekli lid s knížaty Galád jedni druhým: Kdokoli počne bojovati proti Ammonitským, bude vůdce všech obyvatelů Galád.

< Judges 10 >