< Judges 10 >

1 Lẹ́yìn ikú Abimeleki, ọkùnrin kan láti ẹ̀yà Isakari tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Tola ọmọ Pua, ọmọ Dodo, dìde láti gba Israẹli sílẹ̀. Ní Ṣamiri tí ó wà ní òkè Efraimu ni ó gbé.
Ug sunod kang Abimelech dihay mitindog aron sa pagluwas sa Israel, si Tola, ang anak nga lalake ni Pua, anak nga lalake ni Dodo, usa ka tawo sa Issachar; ug siya nagpuyo sa Samir sa mga kabukiran sa Ephraim.
2 Ó ṣe àkóso Israẹli ní ọdún mẹ́tàlélógún. Nígbà tí ó kú wọ́n sìn ín sí Ṣamiri.
Ug siya nagmaghuhukom sa Israel sa kaluhaan ug tolo ka tuig, ug namatay ug gilubong sa Samir.
3 Jairi ti ẹ̀yà Gileadi ni ó dìde lẹ́yìn rẹ̀, ó ṣàkóso Israẹli ní ọdún méjìlélógún.
Ug sunod kaniya mitindog si Jair, ang Galaadihanon; ug siya nagmaghuhukom sa Israel sa kaluhaan ug duha ka tuig.
4 Àwọn ọgbọ̀n ọmọ tí ó n gun ọgbọ̀n kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Wọ́n ṣe àkóso ọgbọ̀n ìlú ní Gileadi, tí a pe orúkọ wọn ní Hafoti-Jairi títí di òní.
Ug siya dunay katloan ka anak nga lalake nga nanagkabayo sa katloan ka nating asno, ug sila adunay katloan ka ciudad nga ginanganlan ug Havoth-Jair hangtud niining adlawa, nga anaa sa yuta sa Galaad.
5 Nígbà tí Jairi kú wọ́n sin ín sí Kamoni.
Ug si Jair namatay, ug gilubong sa Camon.
6 Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú lójú Olúwa. Wọ́n sin Baali àti Aṣtoreti àti àwọn òrìṣà Aramu, òrìṣà Sidoni, òrìṣà Moabu, òrìṣà àwọn ará Ammoni àti òrìṣà àwọn ará Filistini. Nítorí àwọn ará Israẹli kọ Olúwa sílẹ̀ tí wọn kò sì sìn ín mọ́,
Ug ang mga anak sa Israel nagbuhat pag-usab niadtong dautan sa mga mata ni Jehova, ug ming-alagad sa mga Baal, ug sa mga Astaroth, ug sa mga dios sa Siria, ug sa mga dios sa Sidon, ug sa mga dios sa Moab, ug sa mga dios sa mga anak sa Ammon, ug sa mga dios sa mga Filistehanon; ug ilang gibiyaan si Jehova, ug wala mag-alagad kaniya.
7 ó bínú sí wọn, ó fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn ará Filistini àti Ammoni láti jẹ ẹ́ ní ìyà.
Ug ang kasuko ni Jehova misilaub batok sa Israel, ug iyang gibaligya sila ngadto sa kamot sa mga Filistehanon, ug ngadto sa kamot sa mga anak sa Ammon.
8 Ní ọdún náà, wọ́n tú wọn ká wọ́n sì pọ́n wọn lójú. Fún ọdún méjìdínlógún ni wọ́n fi ni gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà ní ìlà-oòrùn odò Jordani ní ilẹ̀ àwọn ará Amori lára (èyí nì ní Gileadi).
Ug sila nagsamok ug nagdaugdaug sa mga anak sa Israel niadtong tuiga: sa napulo ug walo ka tuig sila nagdaugdaug sa tanang mga anak sa Israel nga didto sa unahan sa Jordan sa yuta sa mga Amorehanon, nga didto sa Galaad.
9 Àwọn ará Ammoni sì la odò Jordani kọjá láti bá Juda, Benjamini àti àwọn ará ilé Efraimu jagun: Israẹli sì dojúkọ ìpọ́njú tó lágbára.
Ug ang mga anak sa Ammon mingtabok sa Jordan aron sa pagpakig-away batok sa Juda, ug batok sa Benjamin ug batok sa balay ni Ephraim; busa ang Israel nag-antus sa mapait nga kagul-anan.
10 Nígbà tí èyí ti ṣẹlẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí ọ, nítorí pé àwa ti kọ Ọlọ́run wa sílẹ̀, àwa sì ń sin Baali.”
Ug ang mga anak sa Israel mingtu-aw ngadto kang Jehova, nga nanag-ingon: Kami nakasala batok kanimo tungod kay gibiyaan namo ang among Dios, ug nagaalagad sa mga Baal.
11 Olúwa sì dáhùn pé, “Ǹjẹ́ nígbà tí àwọn ará Ejibiti, Amori, Ammoni, Filistini,
Ug si Jehova miingon sa mga anak sa Israel: Wala ba ako magluwas kaninyo gikan sa mga Egiptohanon, ug gikan sa mga Amorehanon, gikan sa mga anak sa Ammon, ug gikan sa mga Filistehanon?
12 àwọn ará Sidoni, Amaleki pẹ̀lú Maoni ni yín lára, tí ẹ sì ké pè mí fún ìrànlọ́wọ́, ǹjẹ́ èmi kò gbà yín sílẹ̀ kúrò ní ọwọ́ wọn?
Sa mga Sidonianhon usab, ug sa mga Amalecanhon, ug sa mga Maonhanon, nanagdaugdaug kaninyo; ug kamo mingtu-aw kanako, ug giluwas ko kamo gikan sa ilang kamot.
13 Síbẹ̀síbẹ̀ ẹ̀yin kọ̀ mí sílẹ̀ láti sin àwọn ọlọ́run mìíràn, torí ìdí èyí, èmi kì yóò sì tún gbà yín mọ́.
Bisan pa niini, kamo mingbiya kanako, ug nag-alagad sa laing dios: sa ingon niini dili na ako magaluwas kaninyo.
14 Ẹ lọ kí ẹ sì ké pe àwọn òrìṣà tí ẹ̀yin ti yàn fún ara yín. Jẹ́ kí wọn gbà yín sílẹ̀ ní àsìkò ìpọ́njú yín!”
Panlakaw kamo, ug sangpita ang mga dios nga inyong gipili; paluwasa sila kaninyo sa panahon sa inyong kagul-anan.
15 Àwọn ọmọ Israẹli sì dá Olúwa lóhùn pé, “Àwa ti ṣẹ̀, ṣe ohun tí ó bá fẹ́ pẹ̀lú wa, ṣùgbọ́n, jọ̀wọ́ gbà wá sílẹ̀ náání àsìkò yìí.”
Ug ang mga anak sa Israel miingon kang Jehova: Kami nakasala; buhata kanamo ang bisan unsang maayo kanimo; luwasa lamang kami, niining adlawa, kami nangamuyo kanimo.
16 Nígbà náà ni wọ́n kó gbogbo ọlọ́run àjèjì tí ó wà láàrín wọn kúrò wọ́n sì sin Olúwa nìkan, ọkàn rẹ̀ kò sì le gbàgbé ìrora Israẹli mọ́.
Ug gisalikway nila ang laing mga dios gikan sa taliwala nila, ug nanag-alagad kang Jehova; ug ang iyang kalag nagsubo tungod sa kaalaut sa Israel.
17 Nígbà tí àwọn ará Ammoni kógun jọ ní Gileadi láti bá Israẹli jà, àwọn ọmọ Israẹli gbárajọpọ̀, wọ́n sì tẹ̀dó ogun ní Mispa.
Unya ang mga anak sa Ammon nagkatigum, ug nagpahaluna sa Galaad. Ug ang mga anak sa Israel nanaghiusa pagkatapok ug nanagpahaluna sa Mizpa.
18 Àwọn ìjòyè: aṣíwájú àwọn ará Gileadi wí fún ará wọn pé, “Ẹnikẹ́ni tí yóò kọ́ ṣígun si àwọn ará Ammoni ni yóò jẹ́ orí fún gbogbo àwọn tí ń gbé ní Gileadi.”
Ug ang katawohan, ang mga principe sa Galaad, miingon sa usa ug usa: Kinsang tawohana siya nga mosugod sa pagpakig-away batok sa mga anak sa Ammon? Siya mahimong pangulo sa tanang mga molupyo sa Galaad.

< Judges 10 >