< Jude 1 >
1 Juda, ìránṣẹ́ Jesu Kristi àti arákùnrin Jakọbu, Sí àwọn tí a pè, olùfẹ́ nínú Ọlọ́run Baba, tí a pamọ́ fún Jesu Kristi:
Ja, Juda, sługa Jezusa Chrystusa i brat Jakuba, piszę do wszystkich powołanych i ukochanych przez Boga Ojca i chronionych przez Jezusa Chrystusa.
2 Kí àánú, àlàáfíà àti ìfẹ́ kí ó máa jẹ́ tiyín ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Niech Bóg obficie obdarza was pokojem oraz miłością i współczuciem dla innych ludzi!
3 Ẹ̀yin ọ̀rẹ́ mi tòótọ́, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmí ní ìtara láti kọ̀wé sí i yín nípa ìgbàlà tí í ṣe ti gbogbo ènìyàn, n kò gbọdọ̀ má kọ̀wé sí yín, kí ń sì gbà yín ní ìyànjú láti máa jà fitafita fún ìgbàgbọ́, tí a ti fi lé àwọn ènìyàn mímọ́ lọ́wọ́ ní ẹ̀ẹ̀kan ṣoṣo.
Kochani, chciałem napisać do was o naszym wspólnym zbawieniu. Uznałem jednak, że muszę raczej zachęcić was do walki w obronie wiary, która raz na zawsze została przekazana świętym.
4 Nítorí àwọn ènìyàn kan ń bẹ tí wọ́n ń yọ́ wọlé, àwọn ẹni tí a ti yàn láti ìgbà àtijọ́ sí ẹ̀bi yìí, àwọn aláìwà-bí-Ọlọ́run, tí ń yí oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run wa padà sí wọ̀bìà, tí wọn sì ń sẹ́ Olúwa wa kan ṣoṣo náà, àní, Jesu Kristi Olúwa.
Piszę o tym dlatego, że pojawili się wśród was jacyś bezbożni ludzie, którzy twierdzą, że skoro Bóg okazał im łaskę, to mogą teraz prowadzić rozwiązłe życie. W ten sposób odrzucają Jezusa Chrystusa, naszego jedynego Władcę i Pana. Dawno już jednak wydany został na nich wyrok potępienia.
5 Nítòótọ́, ẹ ti mọ nǹkan wọ̀nyí ní ẹ̀ẹ̀kan rí, mo fẹ́ rán an yín létí pé, lẹ́yìn tí Olúwa ti gba àwọn kan là láti ilẹ̀ Ejibiti wá, lẹ́yìn náà ni ó run àwọn tí kò gbàgbọ́.
Dobrze znacie historię wyzwolenia Izraelitów z niewoli w Egipcie. Chciałbym wam jednak przypomnieć, że spośród ludzi, którzy zostali wyzwoleni, Pan zgładził tych, którzy Mu nie uwierzyli.
6 Àti àwọn angẹli tí kò tọ́jú ipò ọlá wọn, ṣùgbọ́n tí wọn fi ipò wọn sílẹ̀, àwọn tí ó pamọ́ sínú ẹ̀wọ̀n àìnípẹ̀kun ní ìsàlẹ̀ òkùnkùn de ìdájọ́ ọjọ́ ńlá nì. (aïdios )
Ukarał również aniołów, którzy nie pozostali tam, gdzie powinni, ale opuścili swoje miejsce. Uwięził ich w ciemnej otchłani, gdzie czekają na dzień Bożego sądu. (aïdios )
7 Àní bí Sodomu àti Gomorra, àti àwọn ìlú agbègbè wọn, ti fi ara wọn fún àgbèrè ṣíṣe, tí wọ́n sì ń tẹ̀lé ará àjèjì lẹ́yìn, àwọn ni ó fi lélẹ̀ bí àpẹẹrẹ, àwọn tí ó ń jìyà iná àìnípẹ̀kun. (aiōnios )
Przypomnijcie sobie również, co się stało z Sodomą i Gomorą oraz okolicznymi miastami. Życie mieszkańców tych miast było rozwiązłe, a ich pragnienia—sprzeczne z naturą. Dlatego kara, którą ponieśli, stała się przykładem kary wiecznego ognia. (aiōnios )
8 Bákan náà ni àwọn wọ̀nyí ń sọ ara wọn di èérí nínú àlá wọn, wọ́n ń gan ìjòyè, wọn sì ń sọ̀rọ̀ búburú sí àwọn ọlọ́lá.
Ludzie, którzy wkradli się między was, są do nich podobni. Kierują się bowiem swoimi urojeniami i hańbią własne ciała. Odrzucają władzę Pana i obrażają niebiańskie istoty,
9 Ṣùgbọ́n Mikaeli, olórí àwọn angẹli, nígbà tí ó ń bá Èṣù jiyàn nítorí òkú Mose, kò sọ ọ̀rọ̀-òdì sí i; ṣùgbọ́n ó wí pé, “Olúwa bá ọ wí.”
podczas gdy nawet archanioł Michał, spierając się z diabłem o ciało Mojżesza, nie ośmielił się go oskarżyć. Powiedział tylko: „Niech Pan cię potępi!”.
10 Ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí n sọ̀rọ̀-òdì sí ohun gbogbo ti kò yé wọn: ṣùgbọ́n ohun gbogbo tí wọn mọ̀ nípa èrò ara ni, bí ẹranko tí kò ní ìyè, nípasẹ̀ nǹkan wọ̀nyí ni wọ́n di ẹni ìparun.
Ci zaś, którzy pojawili się wśród was, przeklinają to, o czym nie mają zielonego pojęcia. Skończą jednak jak nierozumne zwierzęta, które kierują się tylko zmysłami.
11 Ègbé ni fún wọn! Nítorí tí wọ́n ti rìn ní ọ̀nà Kaini, wọ́n sì fi ìwọra súré sínú ìṣìnà Balaamu nítorí ère, wọn ṣègbé nínú ìṣọ̀tẹ̀ Kora.
Marny ich los! Poszli bowiem w ślady Kaina, który był mordercą, oraz Baalama, który dla pieniędzy był gotów popełnić zło, a także Korego, który zbuntował się przeciwko Bogu i został za to zgładzony. Ich spotka taki sam los!
12 Àwọn wọ̀nyí ní ó jẹ́ àbàwọ́n nínú àsè ìfẹ́ yín, nígbà tí wọ́n ń bá yín jẹ àsè, àwọn olùṣọ́-àgùntàn ti ń bọ́ ara wọn láìbẹ̀rù. Wọ́n jẹ́ ìkùùkuu láìrọ òjò, tí a ń ti ọwọ́ afẹ́fẹ́ gbá kiri; àwọn igi aláìléso ní àkókò èso, wọ́n kú lẹ́ẹ̀méjì, a sì fà wọ́n tú tigbòǹgbò tigbòǹgbò.
Ludzie ci chętnie zasiadają z wami przy wspólnym stole. Myślą jednak tylko o tym, żeby się najeść, i wciąż sprawiają wam kłopoty. Są jak chmury gnane wiatrem, ale nie dające potrzebnego deszczu, i jak wyrwane z korzeniami, uschnięte drzewa, na których brak owoców.
13 Wọ́n jẹ́ ìjì líle ti ń ru ní ojú omi Òkun, ti ń hó ìfófó ìtìjú wọn jáde; alárìnkiri ìràwọ̀, àwọn tí a pa òkùnkùn biribiri mọ́ dè láéláé. (aiōn )
Ich złe uczynki są jak spienione morskie fale, oni sami zaś—jak zabłąkane gwiazdy, których przeznaczeniem jest wieczna ciemność. (aiōn )
14 Àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú ni Enoku, ẹni keje láti ọ̀dọ̀ Adamu, sọtẹ́lẹ̀ nípa wọn pé, “Kíyèsi i, Olúwa ń bọ̀ pẹ̀lú ẹgbẹẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà ẹgbẹ̀rún àwọn ènìyàn rẹ̀ mímọ́,
Henoch, który żył siedem pokoleń po Adamie, prorokował o nich, mówiąc: „Pan nadchodzi z tysiącami swoich świętych,
15 láti ṣe ìdájọ́ gbogbo ènìyàn, láti dá gbogbo àwọn aláìwà-bí-Ọlọ́run lẹ́bi ní ti gbogbo iṣẹ́ àìwà-bí-Ọlọ́run wọn, ti wọ́n ti fi àìwà-bí-Ọlọ́run ṣe, àti ní ti gbogbo ọ̀rọ̀ líle tí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ aláìwà-bí-Ọlọ́run ti sọ sí i.”
aby osądzić wszystkich ludzi. On ukarze bezbożnych za złe czyny, których się dopuścili, oraz za zuchwałe słowa, którymi obrazili Boga”.
16 Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní àwọn ti ń kùn, àwọn aláròyé, ti ń rìn nípa ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ara wọn; wọn ń gbéraga nípa ara wọn, wọ́n sì ń ṣátá àwọn ènìyàn mìíràn fún èrè ara wọn.
Ludzie ci wiecznie narzekają na swój los i kierują się tylko swoimi własnymi pragnieniami. Używają wyszukanych słów i dobrze mówią o tych, od których spodziewają się coś dostać.
17 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin olùfẹ́, ẹ rántí àwọn ọ̀rọ̀ tí a ti sọ ṣáájú láti ọwọ́ àwọn aposteli Olúwa wa Jesu Kristi.
Wy jednak, kochani, pamiętajcie słowa apostołów naszego Pana, Jezusa Chrystusa,
18 Bí wọn ti wí fún yín pé, “Nígbà ìkẹyìn àwọn ẹlẹ́gàn yóò wà, tí wọn yóò máa rìn gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àìwà-bí-Ọlọ́run ti ara wọn.”
którzy mówili: „W czasach ostatecznych pojawią się ludzie wyśmiewający Boże obietnice i kierujący się tylko swoimi bezbożnymi pragnieniami”.
19 Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ni àwọn ẹni tí ń ya ara wọn sí ọ̀tọ̀, àwọn ẹni ti ara, tí wọn kò ni Ẹ̀mí.
Oni to doprowadzają do podziałów, nie mają bowiem Ducha Świętego i myślą tylko o zaspokajaniu swoich pragnień.
20 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, olùfẹ́, ti ẹ ń gbé ara yín ró lórí ìgbàgbọ́ yín tí ó mọ́ jùlọ, ti ẹ ń gbàdúrà nínú Ẹ̀mí Mímọ́.
Ale wy, kochani, budujcie z samych siebie budowlę, opartą na fundamencie świętej wiary. Macie w sobie Ducha Świętego, więc módlcie się!
21 Ẹ máa pa ara yín mọ́ nínú ìfẹ́ Ọlọ́run, bí ẹ̀yin ti ń retí àánú Olúwa wa Jesu Kristi tí yóò mú yín dé ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios )
Trwajcie w Bożej miłości, czekając na dzień, w którym nasz Pan, Jezus Chrystus, okaże wam swoje współczucie i da wam wieczne życie. (aiōnios )
22 Ẹ máa ṣàánú fún àwọn tí ń ṣe iyèméjì.
Bądźcie wyrozumiali dla tych, którzy mają wątpliwości.
23 Ẹ máa gba àwọn ẹlòmíràn là, nípa fífà wọ́n yọ kúrò nínú iná; kí ẹ sì máa ṣàánú pẹ̀lú ìbẹ̀rù kí ẹ sì kórìíra ẹ̀wù tí ara ti sọ di èérí.
Wyrywajcie z ognia tych, którzy giną. Okazujcie współczucie tym, którzy tego potrzebują—nie miejcie jednak nic wspólnego z ich grzechami.
24 Ǹjẹ́ mo fi yín lé ẹni tí o lè pa yín mọ́ kúrò nínú ìkọ̀sẹ̀, tí o sì lè mú yín wá síwájú ògo rẹ̀ láìlábùkù pẹ̀lú ayọ̀ ńlá lọ́wọ́—
Bóg może ochronić was przed upadkiem i sprawić, że—czyści i radośni—będziecie mogli stanąć przed Jego chwalebnym majestatem.
25 tí Ọlọ́run ọlọ́gbọ́n nìkan ṣoṣo, Olùgbàlà wa, ní ògo àti ọláńlá, ìjọba àti agbára, nípasẹ̀ Jesu Kristi Olúwa wa, kí gbogbo ayé tó wà, nísinsin yìí àti títí láéláé! Àmín. (aiōn )
On jest jedynym, prawdziwym Bogiem i Jemu należy się wieczna chwała, uwielbienie, moc i władza. Oddajmy Mu więc cześć, poprzez naszego Pana, Jezusa Chrystusa. Amen! (aiōn )