< Joshua 1 >
1 Lẹ́yìn ikú u Mose ìránṣẹ́ Olúwa, Olúwa sọ fún Joṣua ọmọ Nuni, olùrànlọ́wọ́ ọ Mose,
Sesudah kematian Musa, hamba TUHAN itu, berbicaralah TUHAN kepada Yosua anak Nun. Yosua adalah tangan kanan Musa. Kata TUHAN kepadanya,
2 “Mose ìránṣẹ́ mi ti kú. Nísinsin yìí, ìwọ àti gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí, ẹ múra láti kọjá odò Jordani lọ sí ilẹ̀ tí Èmi ó fi fún wọn fún àwọn ará Israẹli.
“Hamba-Ku Musa sudah meninggal. Karena itu, sekarang bersiaplah dan pimpinlah bangsa Israel menyeberangi sungai Yordan ke negeri yang Aku berikan kepada mereka.
3 Èmi yóò fún un yín ní gbogbo ibi tí ẹ bá fi ẹsẹ̀ ẹ yín tẹ̀, gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe ìlérí fún Mose.
Tetapi seperti janji-Ku kepada Musa, ‘Setiap tempat yang kalian injak sudah Aku berikan kepada kalian.
4 Ilẹ̀ ẹ yín yóò fẹ̀ láti aginjù Lebanoni, àti láti odò ńlá, ti Eufurate—gbogbo orílẹ̀-èdè Hiti títí ó fi dé Òkun Ńlá ní ìwọ̀-oòrùn.
Wilayah kalian akan terbentang dari daerah pegunungan Libanon di utara sampai ke padang belantara di selatan, juga dari sungai Efrat di timur laut, termasuk seluruh tanah orang Het, hingga ke Laut Tengah di barat.’
5 Kì yóò sí ẹnikẹ́ni tí yóò le è dúró níwájú rẹ ní ọjọ́ ayé è rẹ gbogbo. Bí mo ti wà pẹ̀lú u Mose, bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, Èmi kì yóò fi ọ́ sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Èmi kì yóò kọ̀ ọ́.
Yosua, selama kamu hidup, tidak akan ada yang bisa bertahan melawanmu. Aku akan menyertaimu seperti Aku menyertai Musa. Aku tidak akan pernah mengabaikanmu ataupun meninggalkanmu.
6 “Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le, nítorí ìwọ ni yóò ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn wọ̀nyí, láti lè jogún ilẹ̀ tí mo ti búra fún àwọn baba ńlá a wọn láti fi fún wọn.
“Kamu harus kuat dan berani karena kamulah yang akan memimpin bangsa ini untuk menduduki dan memiliki negeri yang sudah Aku janjikan kepada nenek moyang kalian.
7 Jẹ́ alágbára, kí o sì mú àyà le gidigidi. Kí o sì ṣọ́ra láti pa gbogbo òfin tí Mose ìránṣẹ́ mi fún ọ mọ́, má ṣe yà kúrò nínú u rẹ̀ sí ọ̀tún tàbí sí òsì, kí ìwọ kí ó lè ṣe rere níbikíbi tí ìwọ bá ń lọ.
Hanya, pastikan kamu harus benar-benar tegar dan berani. Taatilah seluruh hukum Taurat yang sudah diberikan hamba-Ku Musa kepadamu. Jangan menyimpang dari semua itu supaya kamu berhasil dalam segala langkahmu.
8 Má ṣe jẹ́ kí ìwé òfin yìí kúrò ní ẹnu rẹ, máa ṣe àṣàrò nínú u rẹ̀ ní ọ̀sán àti ní òru, kí ìwọ kí ó lè ṣọ́ra láti ṣe gbogbo nǹkan tí a kọ sí inú u rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dára fún ọ, ìwọ yóò sì ní àṣeyọrí.
Ajarkanlah hukum-hukum dalam kitab Taurat ini kepada bangsa ini. Renungkanlah itu siang dan malam supaya kamu bertindak hati-hati sesuai dengan yang tertulis di dalamnya. Dengan begitu, kamu akan sangat berhasil.
9 Èmi kò ha ti pàṣẹ fún ọ bí? Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le. Má ṣe bẹ̀rù, má sì ṣe rẹ̀wẹ̀sì, nítorí pé Olúwa à rẹ yóò wà pẹ̀lú rẹ ní ibikíbi tí ìwọ bá ń lọ.”
Sekali lagi Aku tegaskan: Kamu harus kuat dan berani! Jangan takut ataupun patah semangat, karena Aku, TUHAN Allahmu, menyertai ke mana pun kamu pergi.”
10 Báyìí ni Joṣua pàṣẹ fún olórí àwọn ènìyàn rẹ̀,
Lalu Yosua memerintahkan para pemimpin bangsa Israel,
11 “Ẹ la ibùdó já, kí ẹ sì sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Ẹ pèsè oúnjẹ yín sílẹ̀. Ní ìwòyí ọ̀túnla, ẹ̀yin yóò la Jordani yìí kọjá, láti gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín láti ní.’”
“Berkelilinglah ke seluruh perkemahan dan perintahkanlah semua orang untuk menyiapkan persediaan makanan, karena besok lusa kita akan menyeberangi sungai Yordan untuk mulai merebut dan menduduki negeri yang sudah diberikan TUHAN Allah menjadi milik kita.”
12 Ṣùgbọ́n Joṣua sọ fún àwọn ará a Reubeni, àwọn ará Gadi àti fún ìdajì ẹ̀yà Manase pé,
Kepada ketiga suku yang sudah memiliki daerah mereka, yaitu suku Ruben, Gad, dan separuh suku Manasye, Yosua berkata,
13 “Rántí àṣẹ tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pa fún yín: ‘Olúwa Ọlọ́run yín á fún yin ní ìsinmi, òun yóò sì fún un yín ní ilẹ̀ yìí.’
“Ingatlah perkataan Musa, hamba TUHAN itu, ketika dia menyuruh kalian menduduki bagian negeri ini di sebelah timur sungai Yordan. Dia berkata, ‘Inilah negeri yang TUHAN Allahmu berikan kepada kalian, sebagai tempat untuk kalian dapat hidup dengan tenang.
14 Àwọn ìyàwó yín, àwọn ọmọ yín àti àwọn ẹran ọ̀sìn yín lè dúró ní ilẹ̀ tí Mose fún un yin ní ìlà-oòrùn Jordani; ṣùgbọ́n gbogbo àwọn jagunjagun un yín, pẹ̀lú ìhámọ́ra ogun gbọdọ̀ kọjá síwájú àwọn arákùnrin yín. Ẹ̀yin yóò sì rán àwọn arákùnrin yín lọ́wọ́
Anak-istri dan ternak kalian boleh tinggal di sini, di negeri yang sudah diberikan Musa di sebelah timur sungai Yordan. Tetapi pasukan kalian harus memimpin suku-suku lainnya menyeberangi sungai Yordan dengan bersenjata lengkap dan membantu mereka berperang,
15 títí Olúwa yóò fi fún wọn ní ìsinmi, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún un yín, àti títí tí àwọn pẹ̀lú yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún wọn. Lẹ́yìn náà, ẹ̀yin lè padà sí ilẹ̀ ìní in yín, tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún un yin ní agbègbè ìlà-oòrùn ti Jordani.”
sampai mereka memiliki negeri yang TUHAN berikan kepada mereka dan hidup dengan tenang sama seperti kalian. Barulah setelah itu kalian boleh kembali ke tanahmu sendiri, yang sudah diberikan Musa kepadamu di sebelah timur sungai Yordan.’”
16 Nígbà náà ni wọ́n dá Joṣua lóhùn pé, “Ohunkóhun tí ìwọ pàṣẹ fún wa ni àwa yóò ṣe, ibikíbi tí ìwọ bá rán wa ni àwa yóò lọ.
Jawab mereka kepada Yosua, “Semua yang engkau perintahkan akan kami laksanakan, dan ke mana pun engkau mengutus kami, kami akan pergi.
17 Gẹ́gẹ́ bí àwa ti gbọ́rọ̀ sí Mose nínú ohun gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni àwa yóò máa gbọ́ tìrẹ. Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe wà pẹ̀lú u Mose.
Kami akan taat kepadamu sama seperti kami taat kepada Musa. Semoga TUHAN Allah kita menyertaimu sama seperti Dia menyertai Musa.
18 Ẹnikẹ́ni tí ó bá tàpá sí ọ̀rọ̀ rẹ, tí kò sì ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ nínú ohun gbogbo tí ìwọ yóò pàṣẹ fún wọn, pípa ni a ó pa á. Kí ìwọ sá à ṣe gírí, kí ó sì mú àyà le!”
Setiap orang yang melawan engkau dan tidak menaati perintahmu biarlah dihukum mati. Yang terpenting, engkau harus kuat dan berani!”