< Joshua 9 >

1 Nísinsin yìí, nígbà tí gbogbo ọba tó wà ní ìwọ̀-oòrùn Jordani gbọ́ nípa nǹkan wọ̀nyí, àwọn náà tí ó wà ní orí òkè àti àwọn tí ó wà ní ẹsẹ̀ òkè, àti gbogbo àwọn tí ó wà ní agbègbè Òkun Ńlá títí ó fi dé Lebanoni (àwọn ọba Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti Jebusi)
Əmdi xundaⱪ boldiki, Iordan dǝryasining ƣǝrb tǝripidiki, yǝni taƣliⱪ rayondiki, Xǝfǝlaⱨ oymanliⱪidiki, Uluƣ Dengiz boyidiki, Liwanning uduliƣiqǝ sozulƣan barliⱪ yurtlardiki padixaⱨlar wǝ xuningdǝk Ⱨittiylar, Amoriylar, Ⱪanaaniylar, Pǝrizziylǝr, Ⱨiwiylar, Yǝbusiylarning padixaⱨliri bu ixtin hǝwǝr tapⱪanda,
2 wọ́n sì kó ara wọn jọ láti bá Joṣua àti Israẹli jagun.
ⱨǝmmisi bir bolup Yǝxua bilǝn Israilƣa ⱪarxi jǝng ⱪilƣili ittipaⱪlaxti.
3 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ènìyàn Gibeoni gbọ́ ohun tí Joṣua ṣe sí Jeriko àti Ai,
Əmma Gibeon aⱨaliliri Yǝxuaning Yeriho bilǝn Ayiƣa nemǝ ⱪilƣinini angliƣanda,
4 wọ́n dá ọgbọ́n ẹ̀tàn. Wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí aṣojú tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn kún fún ẹrù tí a fi àwọn àpò tó ti gbó dì, àti àwọn awọ ọtí wáìnì tó ti gbó tí a tún rán.
ular ⱨiylǝ-mikir ixlitip, ɵzlirini [uzun] sǝpǝrdǝ bolƣandǝk kɵrsitip, exǝklǝrgǝ kona taƣar-hurjun bilǝn kona, yirtiⱪ-yamaⱪ xarab tulumlirini artip,
5 Àwọn ọkùnrin náà sì wọ bàtà àti aṣọ tí ó ti gbó. Gbogbo oúnjẹ tí wọ́n pèsè fún ara wọn sì bu.
putliriƣa yamaⱪ qüxkǝn kona kǝxlǝrni kiyip, kona jul-jul eginlǝrni üstigǝ oriƣan idi; ular sǝpǝrgǝ alƣan nanlarning ⱨǝmmisi pahtilixip ⱪurup kǝtkǝnidi.
6 Wọ́n sì tọ Joṣua lọ ní ibùdó ní Gilgali, wọ́n sì sọ fún òun àti àwọn ọkùnrin Israẹli pé, “Ìlú òkèrè ní àwọn ti wá, ẹ ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wa.”
Ular Gilgal qedirgaⱨiƣa berip Yǝxuaning ⱪexiƣa kirip uning bilǝn Israillarƣa: — Biz yiraⱪ yurttin kǝlduⱪ; biz bilǝn ǝⱨdǝ tüzsǝnglar, dedi.
7 Àwọn ọkùnrin Israẹli sọ fún àwọn ará Hifi pé, “Ṣùgbọ́n bóyá tòsí wa ni ẹ ń gbé. Báwo ni a ó ṣe lè ṣe àdéhùn pẹ̀lú yín?”
Lekin Israillar Ⱨiwiylarƣa jawab berip: — Silǝr bizning arimizda turuwatⱪan muxu yǝrliklǝr boluxunglar mumkin; undaⱪta biz silǝr bilǝn ⱪandaⱪmu ǝⱨdǝ tüzimiz? — dedi.
8 “Ìránṣẹ́ rẹ ní àwa í ṣe.” Wọ́n sọ fún Joṣua. Ṣùgbọ́n Joṣua béèrè, “Ta ni yín àti pé níbo ni ẹ̀yin ti wá?”
Ular Yǝxuaƣa: — Biz sening ⱪulliringmiz, dedi. Yǝxua ulardin: — Silǝr kim, ⱪǝyǝrdin kǝldinglar? — dǝp soridi.
9 Wọ́n sì dáhùn pé, “Ní ilẹ̀ òkèèrè ní àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wá, nítorí orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ. Nítorí tí àwa ti gbọ́ òkìkí rẹ àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe ní Ejibiti,
Ular uningƣa jawab berip: — Sening ⱪulliring bolsa Pǝrwǝrdigar Hudayingning namini angliƣanliⱪi üqün naⱨayiti yiraⱪ yurttin kǝldi. Qünki biz Uning nam-xɵⱨritini wǝ Uning Misirda ⱪilƣan ⱨǝmmǝ ixlirini,
10 àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe sí ọba àwọn Amori méjèèje tí ń bẹ ní òkè Jordani, sí Sihoni ọba Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani, tí wọ́n jẹ ọba ní Aṣtarotu.
xundaⱪla Uning Iordanning u tǝripidiki Amoriylarning ikki padixaⱨi, yǝni Ⱨǝxbonning padixaⱨi Siⱨon bilǝn Axtarotta turuⱪluⱪ Baxanning padixaⱨi Ogⱪa nemǝ ⱪilƣinini angliduⱪ.
11 Àwọn àgbàgbà wa àti gbogbo àwọn tí ń gbé ìlú wa sọ fún wa pé, ‘Ẹ mú oúnjẹ lọ́wọ́ fún ìrìnàjò yín, ẹ lọ pàdé wọn, kí ẹ sì sọ fún wọn pé, “Àwa ni ìránṣẹ́ yín, ẹ dá àdéhùn pẹ̀lú wa.”’
Xunga aⱪsaⱪallirimiz bilǝn yurtta turƣuqi ⱨǝmmǝ hǝlⱪ bizgǝ sɵz ⱪilip: — Ⱪolunglarƣa sǝpǝrgǝ lazimliⱪ ozuⱪ-tülük elip, berip Israillar bilǝn kɵrüxüp ularƣa: «Biz silǝrning ⱪulluⱪunglarda bolimiz; xunga biz bilǝn ǝⱨdǝ tüzünglar», dǝnglar, dǝp bizni ǝwǝtti.
12 Gbígbóná ní a mú oúnjẹ wa wá, nígbà tí a dì í ní ilé ní ọjọ́ tí à ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ yín. Ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí ó ṣe gbẹ àti bí ó sì ṣe bu nísinsin yìí.
Silǝrning ⱪexinglarƣa ⱪarap yolƣa qiⱪⱪan künidǝ biz sǝpirimiz üqün ɵyimizdin alƣan nan issiⱪ idi, mana ⱨazir u ⱪurup, pahtilixip ketiptu.
13 Àti ìgò wáìnì wọ̀nyí, tí àwa rọ kún tuntun ni, ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí wọ́n ti sán. Aṣọ àti bàtà wa ni ó sì ti gbó nítorí ìrìnàjò ọ̀nà jíjìn.”
Bu xarab tulumliri bolsa xarab ⱪaqiliƣanda yengi idi, mana ǝmdi yirtilip ketiptu. Biz kiygǝn bu kiyimlǝr wǝ kǝxlǝr sǝpǝrning intayin uzunluⱪidin konirap kǝtti, — dedi.
14 Àwọn ọkùnrin Israẹli sì yẹ oúnjẹ wọn wò, wọn kò sì wádìí ní ọwọ́ Olúwa.
Xuning bilǝn Israillar ularning ozuⱪ-tülükidin azraⱪ aldi, lekin Pǝrwǝrdigardin yol sorimidi.
15 Nígbà náà ni Joṣua ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wọn láti dá wọn sí, àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn fi ọwọ́ sí àdéhùn náà nípa ṣíṣe ìbúra.
Xundaⱪ ⱪilip, Yǝxua ular bilǝn sülⱨi tüzüp, ularni tirik ⱪoyuxⱪa ular bilǝn ǝⱨd baƣlidi; jamaǝt ǝmirlirimu ularƣa ⱪǝsǝm ⱪilip bǝrdi.
16 Ní ẹ̀yìn ọjọ́ mẹ́ta tí wọ́n ti ṣe àdéhùn pẹ̀lú àwọn ará Gibeoni, àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé aládùúgbò wọn ni wọ́n, tí ń gbé ní tòsí wọn.
Ular ǝⱨdǝ baƣlixip üq kündin keyin, bu hǝlⱪning ɵzlirigǝ ⱪoxna ikǝnlikini, ɵzlirining arisida olturuxluⱪ ikǝnliki ularƣa mǝlum boldi.
17 Bẹ́ẹ̀ ní àwọn ọmọ Israẹli jáde, wọ́n sì dé ìlú wọn ní ọjọ́ kẹta: Gibeoni, Kefira, Beeroti àti Kiriati-Jearimu.
Israillar sǝpirini dawamlaxturup üqinqi küni ularning xǝⱨǝrlirigǝ yetip kǝldi; ularning xǝⱨǝrliri Gibeon, Kǝfiraⱨ, Bǝǝrot bilǝn Kiriat-yearim idi.
18 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli kò si kọlù wọ́n, nítorí pé àwọn àgbàgbà ìjọ ènìyàn ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli. Gbogbo ènìyàn sì kùn sí àwọn àgbàgbà náà,
Jamaǝtning ǝmirliri ilgiri Israilning Hudasi Pǝrwǝrdigarning nami bilǝn ularƣa ⱪǝsǝm ⱪilƣan bolƣaqⱪa, Israillar ularƣa ⱨujum ⱪilmidi. Buning bilǝn pütkül jamaǝt ǝmirlǝr üstidin ƣotuldaxⱪili turdi.
19 ṣùgbọ́n gbogbo àwọn olórí dáhùn pé, “Àwa ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli, a kò sì lè fọwọ́ kàn wọ́n nísinsin yìí.
Lekin ǝmirlǝrning ⱨǝmmisi pütkül jamaǝtkǝ: — Biz ularƣa Israilning Hudasi Pǝrwǝrdigarning [nami] bilǝn ⱪǝsǝm ⱪilip bǝrgǝqkǝ, ularƣa ⱪol tǝgküzǝlmǝymiz.
20 Èyí ní àwa yóò ṣe sí wọn, àwa yóò dá wọn sí, kí ìbínú kí ó má ba à wá sórí wa, nítorí ìbúra tí a búra fún wọn.”
Biz ularƣa ⱪilƣan ⱪǝsǝmimiz tüpǝylidin, üstimizgǝ ƣǝzǝp qüxmǝsliki üqün ularni tirik ⱪalduruxmiz kerǝk; ularƣa xundaⱪ ⱪilmisaⱪ bolmaydu, dedi.
21 Wọ́n tẹ̀síwájú, “Ẹ dá wọn sí, ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí wọn jẹ́ gégigégi àti apọnmi fún gbogbo ìlú.” Àwọn àgbàgbà náà sì mú ìlérí wọn ṣẹ fún wọn.
Andin ǝmirlǝr jamaǝtkǝ yǝnǝ: — Ularni tirik ⱪoyunglar; ⱨalbuki, ular pütkül jamaǝt üqün otun yarƣuqi wǝ su toxuƣuqilar bolidu, dedi. Bu ix ǝmirlǝr jamaǝtkǝ degǝndǝk boldi.
22 Nígbà náà ni Joṣua pe àwọn ọmọ Gibeoni jọ pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tàn wá wí pe, ‘Àwa gbé ní ibi tí ó jìnnà sí yín,’ nígbà tí ó jẹ́ pé tòsí wa ní ẹ̀yin ń gbé?
U waⱪitta Yǝxua ularni qaⱪirip ularƣa: — Silǝr arimizdiki yǝrliklǝr turup, nemixⱪa biz yiraⱪtin kǝlduⱪ, dǝp bizni aldidinglar?
23 Nísinsin yìí, ẹ̀yin di ẹni ègún, ẹ̀yin kò sì ní kúrò ní gégigégi àti apọnmi fún ilé Ọlọ́run mi.”
Buning üqün silǝr ǝmdi lǝnǝtkǝ ⱪelip, aranglarda Hudayimning ɵyi üqün otun yaridiƣan wǝ su toxuydiƣan ⱪul boluxtin birǝr adǝmmu mustǝsna bolmaydu, — dedi.
24 Wọ́n sì dá Joṣua lóhùn pé, “Nítorí tí a sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ dájúṣáká bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pàṣẹ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, láti fún yín ní gbogbo ilẹ̀ náà, kí ó sì pa gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà run kúrò ní iwájú yín. Nítorí náà, àwa bẹ̀rù ẹ̀mí wa nítorí yín, èyí sì ni ìdí tí a fi ṣe bẹ́ẹ̀.
Xuning bilǝn ular Yǝxuaƣa jawab berip: — Pǝrwǝrdigar Hudayingning Ɵz ⱪuli bolƣan Musaƣa ǝmr ⱪilip, barliⱪ zeminni silǝrgǝ berixkǝ, xundaⱪla zeminda turuwatⱪanlarning ⱨǝmmisini aldinglardin yoⱪitixⱪa wǝdǝ ⱪilƣanliⱪi ⱪulliring bolƣan peⱪirlarƣa eniⱪ mǝlum ⱪilindi; xunga biz silǝrning tüpǝylinglardin jenimizdin jǝzmǝn ayrilip ⱪalimiz dǝp wǝⱨimigǝ qüxüp, bu ixni ⱪilip salduⱪ.
25 Nísinsin yìí, àwa wà ní ọwọ́ yín. Ohunkóhun tí ẹ bá rò pé ó yẹ ó si tọ́ lójú yín ní kí ẹ fi wá ṣe.”
Əmdi biz ⱪolungƣa qüxtuⱪ; nǝziringgǝ nemǝ yahxi wǝ durus kɵrünsǝ xuni ⱪilƣin, — dedi.
26 Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua sì gbà wọ́n là kúrò ní ọwọ́ àwọn ọmọ Israẹli. Wọn kò sì pa wọ́n.
Yǝxua ǝnǝ xundaⱪ ⱪilix bilǝn ularni Israilning ⱪolidin ⱪutⱪuzdi; Israillar ularni ɵltürmidi.
27 Ní ọjọ́ náà ni ó sọ àwọn Gibeoni di aṣẹ́gi àti apọnmi fún àwọn ará ìlú àti fún pẹpẹ Olúwa ní ibi tí Olúwa yóò yàn. Báyìí ni wọ́n wà títí di òní yìí.
Lekin xu küni Yǝxua Pǝrwǝrdigar tallaydiƣan jayda jamaǝt üqün wǝ Pǝrwǝrdigarning ⱪurbangaⱨi üqün ularni otun yarƣuqilar wǝ su toxuƣuqilar dǝp bekitti. Ular bügüngǝ ⱪǝdǝr xundaⱪ ⱪilip kǝlmǝktǝ.

< Joshua 9 >