< Joshua 9 >

1 Nísinsin yìí, nígbà tí gbogbo ọba tó wà ní ìwọ̀-oòrùn Jordani gbọ́ nípa nǹkan wọ̀nyí, àwọn náà tí ó wà ní orí òkè àti àwọn tí ó wà ní ẹsẹ̀ òkè, àti gbogbo àwọn tí ó wà ní agbègbè Òkun Ńlá títí ó fi dé Lebanoni (àwọn ọba Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti Jebusi)
Pripetilo se je, ko so vsi kralji, ki so bili na tej strani Jordana, na hribih, v dolinah in po vseh pokrajinah vélikega morja nasproti Libanonu, Hetejci, Amoréjci, Kánaanci, Perizéjci, Hivéjci in Jebusejci, slišali o tem,
2 wọ́n sì kó ara wọn jọ láti bá Joṣua àti Israẹli jagun.
da so se zbrali skupaj, da se soglasno bojujejo z Józuetom in z Izraelom.
3 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ènìyàn Gibeoni gbọ́ ohun tí Joṣua ṣe sí Jeriko àti Ai,
Ko so prebivalci Gibeóna slišali, kaj je Józue storil Jerihi in Aju,
4 wọ́n dá ọgbọ́n ẹ̀tàn. Wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí aṣojú tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn kún fún ẹrù tí a fi àwọn àpò tó ti gbó dì, àti àwọn awọ ọtí wáìnì tó ti gbó tí a tún rán.
so prebrisano storili in odšli ter se naredili kakor, da so bili predstavniki in na svoje osle dali stare vreče in vinske mehove, stare in raztrgane ter jih povezali
5 Àwọn ọkùnrin náà sì wọ bàtà àti aṣọ tí ó ti gbó. Gbogbo oúnjẹ tí wọ́n pèsè fún ara wọn sì bu.
in stare čevlje, zakrpane na njihovih stopalih in stare obleke na njih in ves kruh njihove popotnice je bil suh in drobljiv.
6 Wọ́n sì tọ Joṣua lọ ní ibùdó ní Gilgali, wọ́n sì sọ fún òun àti àwọn ọkùnrin Israẹli pé, “Ìlú òkèrè ní àwọn ti wá, ẹ ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wa.”
Odšli so k Józuetu v tabor pri Gilgálu, in rekli njemu in Izraelovim možem: »Prišli smo iz daljne dežele, zdaj torej sklenite zavezo z nami.«
7 Àwọn ọkùnrin Israẹli sọ fún àwọn ará Hifi pé, “Ṣùgbọ́n bóyá tòsí wa ni ẹ ń gbé. Báwo ni a ó ṣe lè ṣe àdéhùn pẹ̀lú yín?”
Možje iz Izraela so rekli Hivéjcem: »Morda prebivate med nami in kako naj sklenemo zavezo z vami?«
8 “Ìránṣẹ́ rẹ ní àwa í ṣe.” Wọ́n sọ fún Joṣua. Ṣùgbọ́n Joṣua béèrè, “Ta ni yín àti pé níbo ni ẹ̀yin ti wá?”
Ti so Józuetu rekli: »Mi smo tvoji služabniki.« Józue jim je rekel: »Kdo ste? In od kod ste prišli?«
9 Wọ́n sì dáhùn pé, “Ní ilẹ̀ òkèèrè ní àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wá, nítorí orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ. Nítorí tí àwa ti gbọ́ òkìkí rẹ àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe ní Ejibiti,
Rekli so mu: »Iz zelo oddaljene dežele so prišli tvoji služabniki zaradi imena Gospoda, tvojega Boga, kajti slišali smo sloves o njem in vse, kar je storil v Egiptu
10 àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe sí ọba àwọn Amori méjèèje tí ń bẹ ní òkè Jordani, sí Sihoni ọba Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani, tí wọ́n jẹ ọba ní Aṣtarotu.
in vse, kar je storil dvema kraljema Amoréjcev, ki sta bila onkraj Jordana, hešbónskemu kralju Sihónu in bašánskemu kralju Ogu, ki je bil pri Aštarótu.
11 Àwọn àgbàgbà wa àti gbogbo àwọn tí ń gbé ìlú wa sọ fún wa pé, ‘Ẹ mú oúnjẹ lọ́wọ́ fún ìrìnàjò yín, ẹ lọ pàdé wọn, kí ẹ sì sọ fún wọn pé, “Àwa ni ìránṣẹ́ yín, ẹ dá àdéhùn pẹ̀lú wa.”’
Zato so nam naši starešine in vsi prebivalci dežele govorili, rekoč: ›S seboj vzemite živež za potovanje in pojdite, da jih srečate in jim recite: ›Mi smo vaši služabniki, zato zdaj sklenite zavezo z nami.‹‹
12 Gbígbóná ní a mú oúnjẹ wa wá, nígbà tí a dì í ní ilé ní ọjọ́ tí à ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ yín. Ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí ó ṣe gbẹ àti bí ó sì ṣe bu nísinsin yìí.
Ta naš kruh smo vzeli še vročega za našo popotnico iz naših hiš na dan, ko smo šli, da gremo k vam, toda sedaj, glejte, je ta suh in drobljiv.
13 Àti ìgò wáìnì wọ̀nyí, tí àwa rọ kún tuntun ni, ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí wọ́n ti sán. Aṣọ àti bàtà wa ni ó sì ti gbó nítorí ìrìnàjò ọ̀nà jíjìn.”
Ti vinski mehovi, ki smo jih napolnili, so bili novi, in glejte, raztrgani so. Te naše obleke in naši čevlji so postali stari zaradi razloga zelo dolgega potovanja.«
14 Àwọn ọkùnrin Israẹli sì yẹ oúnjẹ wọn wò, wọn kò sì wádìí ní ọwọ́ Olúwa.
Možje so vzeli od njihovega živeža, niso pa vprašali za nasvet pri Gospodovih ustih.
15 Nígbà náà ni Joṣua ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wọn láti dá wọn sí, àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn fi ọwọ́ sí àdéhùn náà nípa ṣíṣe ìbúra.
Józue je z njimi sklenil mir in z njimi sklenil zavezo, da jih pusti žive, in princi skupnosti so jim prisegli.
16 Ní ẹ̀yìn ọjọ́ mẹ́ta tí wọ́n ti ṣe àdéhùn pẹ̀lú àwọn ará Gibeoni, àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé aládùúgbò wọn ni wọ́n, tí ń gbé ní tòsí wọn.
Pripetilo pa se je ob koncu treh dni, potem ko so z njimi sklenili zavezo, da so slišali, da so bili njihovi sosedje in da so prebivali med njimi.
17 Bẹ́ẹ̀ ní àwọn ọmọ Israẹli jáde, wọ́n sì dé ìlú wọn ní ọjọ́ kẹta: Gibeoni, Kefira, Beeroti àti Kiriati-Jearimu.
Izraelovi otroci so odpotovali in na tretji dan prišli v njihova mesta. Torej njihova mesta so bila Gibeón, Kefíra, Beerót in Kirját Jearím.
18 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli kò si kọlù wọ́n, nítorí pé àwọn àgbàgbà ìjọ ènìyàn ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli. Gbogbo ènìyàn sì kùn sí àwọn àgbàgbà náà,
Izraelovi otroci jih niso udarili, ker so jim princi skupnosti prisegli pri Gospodu, Izraelovemu Bogu. In vsa skupnost je godrnjala zoper prince.
19 ṣùgbọ́n gbogbo àwọn olórí dáhùn pé, “Àwa ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli, a kò sì lè fọwọ́ kàn wọ́n nísinsin yìí.
Toda vsi princi so vsej skupnosti rekli: »Prisegli smo jim pri Gospodu, Izraelovem Bogu. Sedaj se jih torej ne smemo dotakniti.
20 Èyí ní àwa yóò ṣe sí wọn, àwa yóò dá wọn sí, kí ìbínú kí ó má ba à wá sórí wa, nítorí ìbúra tí a búra fún wọn.”
To jim bomo storili. Celo žive jih bomo pustili, da ne bi bil nad nami bes zaradi prisege, ki smo jim jo prisegli.«
21 Wọ́n tẹ̀síwájú, “Ẹ dá wọn sí, ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí wọn jẹ́ gégigégi àti apọnmi fún gbogbo ìlú.” Àwọn àgbàgbà náà sì mú ìlérí wọn ṣẹ fún wọn.
Princi so jim rekli: »Naj živijo, toda naj bodo drvarji in prinašalci vode vsej skupnosti, « kakor so jim princi obljubili.
22 Nígbà náà ni Joṣua pe àwọn ọmọ Gibeoni jọ pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tàn wá wí pe, ‘Àwa gbé ní ibi tí ó jìnnà sí yín,’ nígbà tí ó jẹ́ pé tòsí wa ní ẹ̀yin ń gbé?
Józue jih je dal poklicati in jim spregovoril, rekoč: »Zakaj ste nas preslepili, rekoč: ›Mi smo zelo daleč od vas, ‹ ko prebivate med nami?
23 Nísinsin yìí, ẹ̀yin di ẹni ègún, ẹ̀yin kò sì ní kúrò ní gégigégi àti apọnmi fún ilé Ọlọ́run mi.”
Zdaj ste torej prekleti in nihče izmed vas naj ne bo prost pred tem, da bi bili sužnji, drvarji in prinašalci vode za hišo mojega Boga.«
24 Wọ́n sì dá Joṣua lóhùn pé, “Nítorí tí a sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ dájúṣáká bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pàṣẹ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, láti fún yín ní gbogbo ilẹ̀ náà, kí ó sì pa gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà run kúrò ní iwájú yín. Nítorí náà, àwa bẹ̀rù ẹ̀mí wa nítorí yín, èyí sì ni ìdí tí a fi ṣe bẹ́ẹ̀.
Józuetu so odgovorili in rekli: »Ker je bilo tvojim služabnikom zagotovo povedano to, kako je Gospod, tvoj Bog, zapovedal svojemu služabniku Mojzesu, da vam da vso deželo in da pred seboj uničite vse prebivalce dežele, zato smo bili zaradi vas boleče prestrašeni za svoja življenja in smo storili to stvar.
25 Nísinsin yìí, àwa wà ní ọwọ́ yín. Ohunkóhun tí ẹ bá rò pé ó yẹ ó si tọ́ lójú yín ní kí ẹ fi wá ṣe.”
In sedaj glej, mi smo v tvoji roki. Kakor se ti zdi dobro in pravilno, da nam storiš, stôri.«
26 Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua sì gbà wọ́n là kúrò ní ọwọ́ àwọn ọmọ Israẹli. Wọn kò sì pa wọ́n.
Tako jim je storil in jih osvobodil iz roke Izraelovih otrok, da jih niso pobili.
27 Ní ọjọ́ náà ni ó sọ àwọn Gibeoni di aṣẹ́gi àti apọnmi fún àwọn ará ìlú àti fún pẹpẹ Olúwa ní ibi tí Olúwa yóò yàn. Báyìí ni wọ́n wà títí di òní yìí.
Józue jih je ta dan naredil za drvarje in prinašalce vode za skupnost in za Gospodov oltar, celo do tega dne, na kraju, ki bi ga izbral.

< Joshua 9 >