< Joshua 9 >

1 Nísinsin yìí, nígbà tí gbogbo ọba tó wà ní ìwọ̀-oòrùn Jordani gbọ́ nípa nǹkan wọ̀nyí, àwọn náà tí ó wà ní orí òkè àti àwọn tí ó wà ní ẹsẹ̀ òkè, àti gbogbo àwọn tí ó wà ní agbègbè Òkun Ńlá títí ó fi dé Lebanoni (àwọn ọba Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti Jebusi)
Și s-a întâmplat, când au auzit toți împărații de dincoace de Iordan, din dealuri și de la văi și de pe toate țărmurile Mării celei Mari, în dreptul Libanului, că hetiții și amoriții și canaaniții și fereziții și heviții și iebusiții,
2 wọ́n sì kó ara wọn jọ láti bá Joṣua àti Israẹli jagun.
S-au adunat cu un gând, ca să se lupte cu Iosua și cu Israel.
3 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ènìyàn Gibeoni gbọ́ ohun tí Joṣua ṣe sí Jeriko àti Ai,
Și când locuitorii Gabaonului au auzit ce făcuse Iosua Ierihonului și cetății Ai,
4 wọ́n dá ọgbọ́n ẹ̀tàn. Wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí aṣojú tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn kún fún ẹrù tí a fi àwọn àpò tó ti gbó dì, àti àwọn awọ ọtí wáìnì tó ti gbó tí a tún rán.
Au lucrat cu vicleșug și s-au dus și s-au prefăcut ca și când ar fi fost ambasadori și au luat saci vechi pe măgarii lor și burdufuri vechi pentru vin, rupte și cârpite,
5 Àwọn ọkùnrin náà sì wọ bàtà àti aṣọ tí ó ti gbó. Gbogbo oúnjẹ tí wọ́n pèsè fún ara wọn sì bu.
Și sandale vechi și cârpite în picioarele lor și haine vechi pe ei; și toată pâinea merindelor lor era uscată și mucegăită.
6 Wọ́n sì tọ Joṣua lọ ní ibùdó ní Gilgali, wọ́n sì sọ fún òun àti àwọn ọkùnrin Israẹli pé, “Ìlú òkèrè ní àwọn ti wá, ẹ ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wa.”
Și s-au dus la Iosua în tabără, la Ghilgal, și i-au spus lui și bărbaților lui Israel: Noi am venit dintr-o țară îndepărtată; de aceea acum, faceți alianță cu noi.
7 Àwọn ọkùnrin Israẹli sọ fún àwọn ará Hifi pé, “Ṣùgbọ́n bóyá tòsí wa ni ẹ ń gbé. Báwo ni a ó ṣe lè ṣe àdéhùn pẹ̀lú yín?”
Și bărbații lui Israel au spus heviților: Poate că voi locuiți între noi, cum să facem alianță cu voi?
8 “Ìránṣẹ́ rẹ ní àwa í ṣe.” Wọ́n sọ fún Joṣua. Ṣùgbọ́n Joṣua béèrè, “Ta ni yín àti pé níbo ni ẹ̀yin ti wá?”
Iar ei i-au spus lui Iosua: Suntem servitorii tăi. Și Iosua le-a spus: Cine sunteți și de unde veniți?
9 Wọ́n sì dáhùn pé, “Ní ilẹ̀ òkèèrè ní àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wá, nítorí orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ. Nítorí tí àwa ti gbọ́ òkìkí rẹ àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe ní Ejibiti,
Iar ei i-au spus: Servitorii tăi au venit dintr-o țară foarte îndepărtată, datorită numelui DOMNULUI Dumnezeul tău; fiindcă am auzit despre faima lui și despre tot ce a făcut în Egipt,
10 àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe sí ọba àwọn Amori méjèèje tí ń bẹ ní òkè Jordani, sí Sihoni ọba Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani, tí wọ́n jẹ ọba ní Aṣtarotu.
Și despre tot ce a făcut celor doi împărați ai amoriților, care erau dincolo de Iordan, lui Sihon, împăratul Hesbonului, și lui Og, împăratul Basanului, care era în Aștarot.
11 Àwọn àgbàgbà wa àti gbogbo àwọn tí ń gbé ìlú wa sọ fún wa pé, ‘Ẹ mú oúnjẹ lọ́wọ́ fún ìrìnàjò yín, ẹ lọ pàdé wọn, kí ẹ sì sọ fún wọn pé, “Àwa ni ìránṣẹ́ yín, ẹ dá àdéhùn pẹ̀lú wa.”’
De aceea bătrânii noștri și toți locuitorii țării noastre ne-au vorbit, spunând: Luați cu voi merinde pentru drum și mergeți în întâmpinarea lor și spuneți-le: Suntem servitorii voștri și acum, faceți alianță cu noi.
12 Gbígbóná ní a mú oúnjẹ wa wá, nígbà tí a dì í ní ilé ní ọjọ́ tí à ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ yín. Ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí ó ṣe gbẹ àti bí ó sì ṣe bu nísinsin yìí.
Această pâine a noastră, a merindelor, am luat-o caldă din casele noastre în ziua când am ieșit, ca să venim la voi; dar acum, iată, este uscată și mucegăită.
13 Àti ìgò wáìnì wọ̀nyí, tí àwa rọ kún tuntun ni, ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí wọ́n ti sán. Aṣọ àti bàtà wa ni ó sì ti gbó nítorí ìrìnàjò ọ̀nà jíjìn.”
Și aceste burdufuri de vin, pe care le-am umplut, au fost noi și, iată, s-au rupt; și aceste haine ale noastre și sandalele noastre s-au învechit din cauza lungimii foarte mare a drumului.
14 Àwọn ọkùnrin Israẹli sì yẹ oúnjẹ wọn wò, wọn kò sì wádìí ní ọwọ́ Olúwa.
Și bărbații lui Israel au luat din merindele lor și nu au căutat sfatul gurii DOMNULUI.
15 Nígbà náà ni Joṣua ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wọn láti dá wọn sí, àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn fi ọwọ́ sí àdéhùn náà nípa ṣíṣe ìbúra.
Și Iosua a făcut pace cu ei și a făcut alianță cu ei, ca să îi lase să trăiască; și prinții adunării le-au jurat.
16 Ní ẹ̀yìn ọjọ́ mẹ́ta tí wọ́n ti ṣe àdéhùn pẹ̀lú àwọn ará Gibeoni, àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé aládùúgbò wọn ni wọ́n, tí ń gbé ní tòsí wọn.
Și s-a întâmplat că, la trei zile după ce au făcut alianță cu ei, au auzit că ei erau vecinii lor și că locuiau între ei.
17 Bẹ́ẹ̀ ní àwọn ọmọ Israẹli jáde, wọ́n sì dé ìlú wọn ní ọjọ́ kẹta: Gibeoni, Kefira, Beeroti àti Kiriati-Jearimu.
Și copiii lui Israel au plecat și a treia zi au intrat în cetățile lor. Și cetățile lor erau Gabaon și Chefira și Beerot și Chiriat-Iearim.
18 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli kò si kọlù wọ́n, nítorí pé àwọn àgbàgbà ìjọ ènìyàn ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli. Gbogbo ènìyàn sì kùn sí àwọn àgbàgbà náà,
Și copiii lui Israel nu i-au bătut, deoarece prinții adunării le juraseră pe DOMNUL Dumnezeul lui Israel. Și toată adunarea a cârtit împotriva prinților.
19 ṣùgbọ́n gbogbo àwọn olórí dáhùn pé, “Àwa ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli, a kò sì lè fọwọ́ kàn wọ́n nísinsin yìí.
Și toți prinții au spus către toată adunarea: Le-am jurat pe DOMNUL Dumnezeul lui Israel; de aceea acum, nu ne putem atinge de ei.
20 Èyí ní àwa yóò ṣe sí wọn, àwa yóò dá wọn sí, kí ìbínú kí ó má ba à wá sórí wa, nítorí ìbúra tí a búra fún wọn.”
Aceasta le vom face; îi vom lăsa să trăiască, pentru ca nu cumva furie să vină asupra noastră din cauza jurământului cu care le-am jurat.
21 Wọ́n tẹ̀síwájú, “Ẹ dá wọn sí, ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí wọn jẹ́ gégigégi àti apọnmi fún gbogbo ìlú.” Àwọn àgbàgbà náà sì mú ìlérí wọn ṣẹ fún wọn.
Și prinții le-au spus: Lasă-i să trăiască; dar să fie tăietori de lemne și cărători de apă pentru toată adunarea, așa cum le promiseseră prinții.
22 Nígbà náà ni Joṣua pe àwọn ọmọ Gibeoni jọ pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tàn wá wí pe, ‘Àwa gbé ní ibi tí ó jìnnà sí yín,’ nígbà tí ó jẹ́ pé tòsí wa ní ẹ̀yin ń gbé?
Și Iosua i-a chemat și le-a vorbit, spunând: Pentru ce ne-ați înșelat, zicând: Suntem foarte departe de voi, când de fapt locuiți în mijlocul nostru?
23 Nísinsin yìí, ẹ̀yin di ẹni ègún, ẹ̀yin kò sì ní kúrò ní gégigégi àti apọnmi fún ilé Ọlọ́run mi.”
De aceea acum, sunteți blestemați și nu veți înceta să fiți robi și tăietori de lemne și cărători de apă pentru casa Dumnezeului meu.
24 Wọ́n sì dá Joṣua lóhùn pé, “Nítorí tí a sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ dájúṣáká bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pàṣẹ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, láti fún yín ní gbogbo ilẹ̀ náà, kí ó sì pa gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà run kúrò ní iwájú yín. Nítorí náà, àwa bẹ̀rù ẹ̀mí wa nítorí yín, èyí sì ni ìdí tí a fi ṣe bẹ́ẹ̀.
Și ei au răspuns lui Iosua și au zis: Pentru că s-a spus negreșit servitorilor tăi cum DOMNUL Dumnezeul tău a poruncit lui Moise, servitorul său, să vă dea toată țara și să nimicească pe toți locuitorii țării dinaintea voastră; de aceea ne-am temut foarte mult pentru viețile noastre, din cauza voastră, și am făcut acest lucru.
25 Nísinsin yìí, àwa wà ní ọwọ́ yín. Ohunkóhun tí ẹ bá rò pé ó yẹ ó si tọ́ lójú yín ní kí ẹ fi wá ṣe.”
Și acum, iată, suntem în mâna ta; fă cum este bine și drept în ochii tăi să ne faci.
26 Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua sì gbà wọ́n là kúrò ní ọwọ́ àwọn ọmọ Israẹli. Wọn kò sì pa wọ́n.
Și astfel le-a făcut și i-a eliberat din mâna copiilor lui Israel încât nu i-au ucis.
27 Ní ọjọ́ náà ni ó sọ àwọn Gibeoni di aṣẹ́gi àti apọnmi fún àwọn ará ìlú àti fún pẹpẹ Olúwa ní ibi tí Olúwa yóò yàn. Báyìí ni wọ́n wà títí di òní yìí.
Și în acea zi Iosua i-a făcut tăietori de lemne și cărători de apă pentru adunare și pentru altarul DOMNULUI, până în această zi, în locul pe care l-ar alege el.

< Joshua 9 >