< Joshua 9 >

1 Nísinsin yìí, nígbà tí gbogbo ọba tó wà ní ìwọ̀-oòrùn Jordani gbọ́ nípa nǹkan wọ̀nyí, àwọn náà tí ó wà ní orí òkè àti àwọn tí ó wà ní ẹsẹ̀ òkè, àti gbogbo àwọn tí ó wà ní agbègbè Òkun Ńlá títí ó fi dé Lebanoni (àwọn ọba Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti Jebusi)
A gdy usłyszeli o tym wszyscy królowie, którzy byli po tej stronie Jordanu w górach, na równinach i nad całym brzegiem Morza Wielkiego aż po Liban: Chetyci, Amoryci, Kananejczycy, Peryzzyci, Chiwwici i Jebusyci:
2 wọ́n sì kó ara wọn jọ láti bá Joṣua àti Israẹli jagun.
Zebrali się razem, aby jednomyślnie walczyć przeciw Jozuemu i Izraelowi.
3 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ènìyàn Gibeoni gbọ́ ohun tí Joṣua ṣe sí Jeriko àti Ai,
Lecz mieszkańcy Gibeonu, gdy usłyszeli o tym, co Jozue uczynił z Jerychem i Aj;
4 wọ́n dá ọgbọ́n ẹ̀tàn. Wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí aṣojú tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn kún fún ẹrù tí a fi àwọn àpò tó ti gbó dì, àti àwọn awọ ọtí wáìnì tó ti gbó tí a tún rán.
Użyli podstępu i wyruszyli, udając posłów, i wzięli stare wory na swoje osły i stare, popękane i połatane bukłaki na wino;
5 Àwọn ọkùnrin náà sì wọ bàtà àti aṣọ tí ó ti gbó. Gbogbo oúnjẹ tí wọ́n pèsè fún ara wọn sì bu.
I stare, i połatane obuwie na nogi, stare szaty na siebie, a cały chleb, który ze sobą zabrali w drogę, był suchy i spleśniały.
6 Wọ́n sì tọ Joṣua lọ ní ibùdó ní Gilgali, wọ́n sì sọ fún òun àti àwọn ọkùnrin Israẹli pé, “Ìlú òkèrè ní àwọn ti wá, ẹ ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wa.”
Wtedy przybyli do Jozuego, do obozu w Gilgal, i powiedzieli do niego i do mężczyzn Izraela: Przyszliśmy z dalekiego kraju. Zawrzyjcie więc teraz przymierze z nami.
7 Àwọn ọkùnrin Israẹli sọ fún àwọn ará Hifi pé, “Ṣùgbọ́n bóyá tòsí wa ni ẹ ń gbé. Báwo ni a ó ṣe lè ṣe àdéhùn pẹ̀lú yín?”
Lecz mężczyźni Izraela odpowiedzieli Chiwwitom: A może mieszkacie wśród nas, jakże więc możemy zawrzeć z wami przymierze?
8 “Ìránṣẹ́ rẹ ní àwa í ṣe.” Wọ́n sọ fún Joṣua. Ṣùgbọ́n Joṣua béèrè, “Ta ni yín àti pé níbo ni ẹ̀yin ti wá?”
A oni powiedzieli Jozuemu: Jesteśmy twoimi sługami. I Jozue zapytał ich: Kim jesteście i skąd przybywacie?
9 Wọ́n sì dáhùn pé, “Ní ilẹ̀ òkèèrè ní àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wá, nítorí orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ. Nítorí tí àwa ti gbọ́ òkìkí rẹ àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe ní Ejibiti,
Odpowiedzieli mu: Twoi słudzy przybyli z bardzo dalekiego kraju ze względu na imię PANA, twego Boga. Usłyszeliśmy bowiem o jego sławie oraz o wszystkim, co uczynił w Egipcie;
10 àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe sí ọba àwọn Amori méjèèje tí ń bẹ ní òkè Jordani, sí Sihoni ọba Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani, tí wọ́n jẹ ọba ní Aṣtarotu.
I o wszystkim, co uczynił dwom królom amoryckim, którzy byli za Jordanem, Sichonowi, królowi Cheszbonu, i Ogowi, królowi Baszanu, który [był] w Asztarot.
11 Àwọn àgbàgbà wa àti gbogbo àwọn tí ń gbé ìlú wa sọ fún wa pé, ‘Ẹ mú oúnjẹ lọ́wọ́ fún ìrìnàjò yín, ẹ lọ pàdé wọn, kí ẹ sì sọ fún wọn pé, “Àwa ni ìránṣẹ́ yín, ẹ dá àdéhùn pẹ̀lú wa.”’
I nasi starsi i wszyscy mieszkańcy naszego kraju nakazali nam: Weźcie ze sobą żywność na drogę, wyjdźcie im naprzeciw i powiedzcie im: Jesteśmy waszymi sługami, zawrzyjcie więc teraz przymierze z nami.
12 Gbígbóná ní a mú oúnjẹ wa wá, nígbà tí a dì í ní ilé ní ọjọ́ tí à ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ yín. Ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí ó ṣe gbẹ àti bí ó sì ṣe bu nísinsin yìí.
Ten nasz chleb był jeszcze ciepły, gdy wzięliśmy go z naszych domów w dniu, kiedy wyruszyliśmy do was; a teraz jest suchy i spleśniały.
13 Àti ìgò wáìnì wọ̀nyí, tí àwa rọ kún tuntun ni, ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí wọ́n ti sán. Aṣọ àti bàtà wa ni ó sì ti gbó nítorí ìrìnàjò ọ̀nà jíjìn.”
I te bukłaki na wino, które napełniliśmy, były nowe, a oto popękały. Także nasze szaty i obuwie zniszczyły się z powodu bardzo długiej podróży.
14 Àwọn ọkùnrin Israẹli sì yẹ oúnjẹ wọn wò, wọn kò sì wádìí ní ọwọ́ Olúwa.
A mężczyźni [Izraela] wzięli z ich żywności, lecz nie radzili się PANA.
15 Nígbà náà ni Joṣua ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wọn láti dá wọn sí, àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn fi ọwọ́ sí àdéhùn náà nípa ṣíṣe ìbúra.
Wtedy Jozue zawarł z nimi pokój i ustanowił z nimi przymierze, że zachowa ich przy życiu. Także naczelnicy zgromadzenia im przysięgli.
16 Ní ẹ̀yìn ọjọ́ mẹ́ta tí wọ́n ti ṣe àdéhùn pẹ̀lú àwọn ará Gibeoni, àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé aládùúgbò wọn ni wọ́n, tí ń gbé ní tòsí wọn.
Lecz po trzech dniach, po zawarciu z nimi przymierza, usłyszeli, że są oni sąsiadami i że mieszkają wśród nich.
17 Bẹ́ẹ̀ ní àwọn ọmọ Israẹli jáde, wọ́n sì dé ìlú wọn ní ọjọ́ kẹta: Gibeoni, Kefira, Beeroti àti Kiriati-Jearimu.
Wtedy synowie Izraela wyruszyli i po trzech dniach dotarli do ich miast. Miastami ich były: Gibeon, Kefira, Beerot i Kiriat-Jearim.
18 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli kò si kọlù wọ́n, nítorí pé àwọn àgbàgbà ìjọ ènìyàn ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli. Gbogbo ènìyàn sì kùn sí àwọn àgbàgbà náà,
I nie wytracili ich synowie Izraela, gdyż naczelnicy zgromadzenia przysięgli im na PANA, Boga Izraela. I całe zgromadzenie szemrało przeciw naczelnikom.
19 ṣùgbọ́n gbogbo àwọn olórí dáhùn pé, “Àwa ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli, a kò sì lè fọwọ́ kàn wọ́n nísinsin yìí.
I wszyscy naczelnicy powiedzieli do całego zgromadzenia: Przysięgliśmy im na PANA, Boga Izraela, dlatego teraz nie możemy ich tknąć.
20 Èyí ní àwa yóò ṣe sí wọn, àwa yóò dá wọn sí, kí ìbínú kí ó má ba à wá sórí wa, nítorí ìbúra tí a búra fún wọn.”
Tak więc postąpimy z nimi: zachowamy ich przy życiu, żeby nie spadł na nas gniew z powodu przysięgi, którą im złożyliśmy.
21 Wọ́n tẹ̀síwájú, “Ẹ dá wọn sí, ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí wọn jẹ́ gégigégi àti apọnmi fún gbogbo ìlú.” Àwọn àgbàgbà náà sì mú ìlérí wọn ṣẹ fún wọn.
Ponadto naczelnicy powiedzieli im: Niech pozostaną przy życiu, ale niech rąbią drewno i noszą wodę dla całego zgromadzenia – zgodnie z tym, co obiecali naczelnicy.
22 Nígbà náà ni Joṣua pe àwọn ọmọ Gibeoni jọ pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tàn wá wí pe, ‘Àwa gbé ní ibi tí ó jìnnà sí yín,’ nígbà tí ó jẹ́ pé tòsí wa ní ẹ̀yin ń gbé?
Potem Jozue wezwał ich i zapytał: Dlaczego nas oszukaliście, mówiąc: Jesteśmy z bardzo daleka, skoro mieszkacie wśród nas?
23 Nísinsin yìí, ẹ̀yin di ẹni ègún, ẹ̀yin kò sì ní kúrò ní gégigégi àti apọnmi fún ilé Ọlọ́run mi.”
Teraz więc jesteście przeklęci i nie przestaniecie być niewolnikami rąbiącymi drewno i noszącymi wodę dla domu mego Boga.
24 Wọ́n sì dá Joṣua lóhùn pé, “Nítorí tí a sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ dájúṣáká bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pàṣẹ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, láti fún yín ní gbogbo ilẹ̀ náà, kí ó sì pa gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà run kúrò ní iwájú yín. Nítorí náà, àwa bẹ̀rù ẹ̀mí wa nítorí yín, èyí sì ni ìdí tí a fi ṣe bẹ́ẹ̀.
Oni odpowiedzieli Jozuemu: Oznajmiono dokładnie twoim sługom, że PAN, twój Bóg, rozkazał swemu słudze Mojżeszowi dać wam całą ziemię i zgładzić przed wami wszystkich mieszkańców tej ziemi. Dlatego bardzo się baliśmy o nasze życie z waszego powodu i dlatego tak postąpiliśmy.
25 Nísinsin yìí, àwa wà ní ọwọ́ yín. Ohunkóhun tí ẹ bá rò pé ó yẹ ó si tọ́ lójú yín ní kí ẹ fi wá ṣe.”
A teraz oto jesteśmy w twoich rękach. Uczyń z nami to, co uważasz za dobre i słuszne.
26 Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua sì gbà wọ́n là kúrò ní ọwọ́ àwọn ọmọ Israẹli. Wọn kò sì pa wọ́n.
I postąpił tak z nimi, i wybawił ich z rąk synów Izraela, żeby ich nie zabili.
27 Ní ọjọ́ náà ni ó sọ àwọn Gibeoni di aṣẹ́gi àti apọnmi fún àwọn ará ìlú àti fún pẹpẹ Olúwa ní ibi tí Olúwa yóò yàn. Báyìí ni wọ́n wà títí di òní yìí.
I w tym dniu Jozue nakazał im narąbać drewna i nosić wodę dla zgromadzenia oraz dla ołtarza PANA w miejscu, które miał wybrać. I jest tak aż do dziś.

< Joshua 9 >