< Joshua 9 >

1 Nísinsin yìí, nígbà tí gbogbo ọba tó wà ní ìwọ̀-oòrùn Jordani gbọ́ nípa nǹkan wọ̀nyí, àwọn náà tí ó wà ní orí òkè àti àwọn tí ó wà ní ẹsẹ̀ òkè, àti gbogbo àwọn tí ó wà ní agbègbè Òkun Ńlá títí ó fi dé Lebanoni (àwọn ọba Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti Jebusi)
Volt pedig, midőn meghallották mind a királyok a Jordánon innen, a hegységben, az alföldön és a nagy tenger egész mellékén a Libánon felé: a chitti, az emóri, a kanaáni, a perizzi, a chivvi és a jebúszi –
2 wọ́n sì kó ara wọn jọ láti bá Joṣua àti Israẹli jagun.
összegyülekeztek együvé, hogy harcoljanak egy értelemmel Józsua és Izraél ellen.
3 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ènìyàn Gibeoni gbọ́ ohun tí Joṣua ṣe sí Jeriko àti Ai,
Gibeón lakói pedig hallották, mit tett Józsua Jeríchóval és Ájjal.
4 wọ́n dá ọgbọ́n ẹ̀tàn. Wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí aṣojú tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn kún fún ẹrù tí a fi àwọn àpò tó ti gbó dì, àti àwọn awọ ọtí wáìnì tó ti gbó tí a tún rán.
Cselekedtek tehát ők is ravaszsággal: mentek és tettették magukat követeknek; szereztek ugyanis kopott zsákokat szamaraikra, meg kopott boros tömlőket, repedteket és összefoltozottakat.
5 Àwọn ọkùnrin náà sì wọ bàtà àti aṣọ tí ó ti gbó. Gbogbo oúnjẹ tí wọ́n pèsè fún ara wọn sì bu.
Kopott és megfoldott sarúk lábaikon, megkopott ruhák ő rajtuk; minden élelmi kenyerük pedig elszáradt, morzsákká lett.
6 Wọ́n sì tọ Joṣua lọ ní ibùdó ní Gilgali, wọ́n sì sọ fún òun àti àwọn ọkùnrin Israẹli pé, “Ìlú òkèrè ní àwọn ti wá, ẹ ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wa.”
Elmentek Józsuához a táborba Gilgálba; és szóltak hozzá és Izraél emberéhez: Messze földről jöttünk, most pedig kössetek velünk szövetséget.
7 Àwọn ọkùnrin Israẹli sọ fún àwọn ará Hifi pé, “Ṣùgbọ́n bóyá tòsí wa ni ẹ ń gbé. Báwo ni a ó ṣe lè ṣe àdéhùn pẹ̀lú yín?”
Erre így szólt Izraél embere a chivvihez: Hátha közepettem lakol, miképpen kössek veled szövetséget?
8 “Ìránṣẹ́ rẹ ní àwa í ṣe.” Wọ́n sọ fún Joṣua. Ṣùgbọ́n Joṣua béèrè, “Ta ni yín àti pé níbo ni ẹ̀yin ti wá?”
Mondták Józsuának: Szolgáid vagyunk! S mondta nekik Józsua: Kik vagytok és honnan jöttök?
9 Wọ́n sì dáhùn pé, “Ní ilẹ̀ òkèèrè ní àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wá, nítorí orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ. Nítorí tí àwa ti gbọ́ òkìkí rẹ àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe ní Ejibiti,
Mondták neki: Nagyon messze földről jöttek a te szolgáid, az Örökkévalónak, Istenednek nevéért, mert hallottuk hírét és mindent, amit tett Egyiptomban,
10 àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe sí ọba àwọn Amori méjèèje tí ń bẹ ní òkè Jordani, sí Sihoni ọba Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani, tí wọ́n jẹ ọba ní Aṣtarotu.
és mindazt, amit tett a Jordánon túli emórinak két királyával: Szíchónnal, Chesbón királyával, és Óggal, Básán királyával, aki Astárótban volt.
11 Àwọn àgbàgbà wa àti gbogbo àwọn tí ń gbé ìlú wa sọ fún wa pé, ‘Ẹ mú oúnjẹ lọ́wọ́ fún ìrìnàjò yín, ẹ lọ pàdé wọn, kí ẹ sì sọ fún wọn pé, “Àwa ni ìránṣẹ́ yín, ẹ dá àdéhùn pẹ̀lú wa.”’
És szóltak hozzánk véneink és mind az országunk lakói, mondván: Vegyetek kezetekbe élelmet az útra, s menjetek elejükbe; így szóljatok hozzájuk: szolgáitok vagyunk, most pedig kössetek velünk szövetséget.
12 Gbígbóná ní a mú oúnjẹ wa wá, nígbà tí a dì í ní ilé ní ọjọ́ tí à ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ yín. Ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí ó ṣe gbẹ àti bí ó sì ṣe bu nísinsin yìí.
Ez ami kenyerünk – melegen vettük élelemnek magunknak házainkból, amely napon elindultunk, hogy hozzátok menjünk, és most, íme elszáradt és morzsákká lett.
13 Àti ìgò wáìnì wọ̀nyí, tí àwa rọ kún tuntun ni, ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí wọ́n ti sán. Aṣọ àti bàtà wa ni ó sì ti gbó nítorí ìrìnàjò ọ̀nà jíjìn.”
Ezek a boros tömlők pedig, melyeket újdonan töltöttünk meg, íme megrepedeztek; ezek ami ruháink és saruink pedig elkoptak az igen nagy út miatt.
14 Àwọn ọkùnrin Israẹli sì yẹ oúnjẹ wọn wò, wọn kò sì wádìí ní ọwọ́ Olúwa.
Erre vettek az emberek élelmükből és az Örökkévaló száját nem kérdezték meg.
15 Nígbà náà ni Joṣua ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wọn láti dá wọn sí, àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn fi ọwọ́ sí àdéhùn náà nípa ṣíṣe ìbúra.
És szerzett velük Józsua békét, kötött velük szövetséget, hogy életben hagyja őket és megesküdtek nekik a község fejedelmei.
16 Ní ẹ̀yìn ọjọ́ mẹ́ta tí wọ́n ti ṣe àdéhùn pẹ̀lú àwọn ará Gibeoni, àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé aládùúgbò wọn ni wọ́n, tí ń gbé ní tòsí wọn.
Történt pedig három nap multán, miután szövetséget kötöttek velük, meghallották, hogy közeléből valók ők és közepette laknak.
17 Bẹ́ẹ̀ ní àwọn ọmọ Israẹli jáde, wọ́n sì dé ìlú wọn ní ọjọ́ kẹta: Gibeoni, Kefira, Beeroti àti Kiriati-Jearimu.
Elindultak Izraél fiai és városaikhoz értek a harmadik napon; városaik pedig Gibeón, Kefíra, Beérót és Kirjat-Jeárim.
18 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli kò si kọlù wọ́n, nítorí pé àwọn àgbàgbà ìjọ ènìyàn ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli. Gbogbo ènìyàn sì kùn sí àwọn àgbàgbà náà,
S nem verték meg őket Izraél fiai, mert megesküdtek nekik a község fejedelmei az Örökkévalóra, Izraél Istenére; és zúgolódott az egész község a fejedelmek ellen.
19 ṣùgbọ́n gbogbo àwọn olórí dáhùn pé, “Àwa ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli, a kò sì lè fọwọ́ kàn wọ́n nísinsin yìí.
Erre mondták mind a fejedelmek az egész községnek: Mi megesküdtünk nekik az Örökkévalóra, Izraél Istenére, most tehát nem nyúlhatunk hozzájuk.
20 Èyí ní àwa yóò ṣe sí wọn, àwa yóò dá wọn sí, kí ìbínú kí ó má ba à wá sórí wa, nítorí ìbúra tí a búra fún wọn.”
Ezt tesszük majd velük és életben hagyjuk őket, hogy ne legyen harag rajtunk az eskü miatt, melyet esküdtünk nekik.
21 Wọ́n tẹ̀síwájú, “Ẹ dá wọn sí, ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí wọn jẹ́ gégigégi àti apọnmi fún gbogbo ìlú.” Àwọn àgbàgbà náà sì mú ìlérí wọn ṣẹ fún wọn.
És szóltak hozzájuk a fejedelmek: hadd éljenek. S lettek favágók és vízmerítők az egész község számára, a miképpen kimondták róluk a fejedelmek.
22 Nígbà náà ni Joṣua pe àwọn ọmọ Gibeoni jọ pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tàn wá wí pe, ‘Àwa gbé ní ibi tí ó jìnnà sí yín,’ nígbà tí ó jẹ́ pé tòsí wa ní ẹ̀yin ń gbé?
És hivatta őket Józsua és beszélt hozzájuk, mondván: Miért csaltatok meg minket, mondván: messzire valók vagyunk tőletek nagyon, holott közepettünk laktok.
23 Nísinsin yìí, ẹ̀yin di ẹni ègún, ẹ̀yin kò sì ní kúrò ní gégigégi àti apọnmi fún ilé Ọlọ́run mi.”
Most tehát átkozottak legyetek; meg ne szűnjék közületek szolga, favágó és vízmerítő, Istenem háza számára.
24 Wọ́n sì dá Joṣua lóhùn pé, “Nítorí tí a sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ dájúṣáká bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pàṣẹ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, láti fún yín ní gbogbo ilẹ̀ náà, kí ó sì pa gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà run kúrò ní iwájú yín. Nítorí náà, àwa bẹ̀rù ẹ̀mí wa nítorí yín, èyí sì ni ìdí tí a fi ṣe bẹ́ẹ̀.
Feleltek Józsuának és mondták: Mivelhogy tudtukra jött szolgáidnak, hogy megparancsolta az Örökkévaló, a te Istened szolgájának, Mózesnek, hogy ha nektek adja az egész országot, elpusztítja előletek mind az ország lakóit: féltettük tehát nagyon lelkeinket tőletek és tettük ezt a dolgot;
25 Nísinsin yìí, àwa wà ní ọwọ́ yín. Ohunkóhun tí ẹ bá rò pé ó yẹ ó si tọ́ lójú yín ní kí ẹ fi wá ṣe.”
most pedig íme kezedben vagyunk; amint jó és helyes szemeidben, hogy tégy velünk, a szerint tégy.
26 Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua sì gbà wọ́n là kúrò ní ọwọ́ àwọn ọmọ Israẹli. Wọn kò sì pa wọ́n.
És tett velük akképpen; így megmentette őket Izraél fiai kezéből, hogy meg nem ölték.
27 Ní ọjọ́ náà ni ó sọ àwọn Gibeoni di aṣẹ́gi àti apọnmi fún àwọn ará ìlú àti fún pẹpẹ Olúwa ní ibi tí Olúwa yóò yàn. Báyìí ni wọ́n wà títí di òní yìí.
És odaadta őket Józsua azon a napon favágókul és vízmerítőkül a község számára és az Örökkévaló oltárának számára mind e mai napig, azon helyre, melyet ki fog választani.

< Joshua 9 >