< Joshua 9 >

1 Nísinsin yìí, nígbà tí gbogbo ọba tó wà ní ìwọ̀-oòrùn Jordani gbọ́ nípa nǹkan wọ̀nyí, àwọn náà tí ó wà ní orí òkè àti àwọn tí ó wà ní ẹsẹ̀ òkè, àti gbogbo àwọn tí ó wà ní agbègbè Òkun Ńlá títí ó fi dé Lebanoni (àwọn ọba Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti Jebusi)
And whanne these thingis weren herd, alle the kyngis biyende Jordan, that lyueden in the hilly places, and in `the feeldi places, in the coostis of the see, and in the brynke of the greet see, and thei that dwellen bisidis Liban, Ethei, and Ammorrei, Cananei, and Feresey, Euey, and Jebusey,
2 wọ́n sì kó ara wọn jọ láti bá Joṣua àti Israẹli jagun.
weren gaderid togidere to fiyte ayens Josue and Israel, with o wille, and the same sentence.
3 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ènìyàn Gibeoni gbọ́ ohun tí Joṣua ṣe sí Jeriko àti Ai,
And thei that dwelten in Gabaon, herden alle thingis whiche Josue hadde do to Jerico, and to Hay; and thei thouyten felli,
4 wọ́n dá ọgbọ́n ẹ̀tàn. Wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí aṣojú tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn kún fún ẹrù tí a fi àwọn àpò tó ti gbó dì, àti àwọn awọ ọtí wáìnì tó ti gbó tí a tún rán.
and token to hem silf metis, and puttyden elde sackis on assis, and wyn botels brokun and sewid, and ful elde schoon,
5 Àwọn ọkùnrin náà sì wọ bàtà àti aṣọ tí ó ti gbó. Gbogbo oúnjẹ tí wọ́n pèsè fún ara wọn sì bu.
whiche weren sewid togidere with patchis, to `the schewyng of eldenesse; and thei weren clothid with elde clothis; also looues, whiche thei baren for lijflode in the weie, weren harde and brokun in to gobetis.
6 Wọ́n sì tọ Joṣua lọ ní ibùdó ní Gilgali, wọ́n sì sọ fún òun àti àwọn ọkùnrin Israẹli pé, “Ìlú òkèrè ní àwọn ti wá, ẹ ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wa.”
And thei yeden to Josue, that dwellide thanne in tentis in Galgala; and thei seiden to hym, and to al Israel togidere, We comen fro a fer lond, and coueyten to make pees with you. And the men of Israel answeriden to hem,
7 Àwọn ọkùnrin Israẹli sọ fún àwọn ará Hifi pé, “Ṣùgbọ́n bóyá tòsí wa ni ẹ ń gbé. Báwo ni a ó ṣe lè ṣe àdéhùn pẹ̀lú yín?”
and seiden, Lest perauenture ye dwellen in the lond, which is due to vs bi eritage, and we moun not make bond of pees with you.
8 “Ìránṣẹ́ rẹ ní àwa í ṣe.” Wọ́n sọ fún Joṣua. Ṣùgbọ́n Joṣua béèrè, “Ta ni yín àti pé níbo ni ẹ̀yin ti wá?”
And thei seiden to Josue, We ben thi seruauntis. To whiche Josue seide, What men ben ye, and fro whennus camen ye?
9 Wọ́n sì dáhùn pé, “Ní ilẹ̀ òkèèrè ní àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wá, nítorí orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ. Nítorí tí àwa ti gbọ́ òkìkí rẹ àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe ní Ejibiti,
Thei answeriden, Thi seruauntis camen fro a ful fer lond in the name of thi Lord God, for we herden the fame of his power, alle thingis whiche he dide in Egipt,
10 àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe sí ọba àwọn Amori méjèèje tí ń bẹ ní òkè Jordani, sí Sihoni ọba Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani, tí wọ́n jẹ ọba ní Aṣtarotu.
and to twei kyngis of Ammorreis biyendis Jordan; to Seon king of Esebon, and to Og kyng of Basan, that weren in Astroth.
11 Àwọn àgbàgbà wa àti gbogbo àwọn tí ń gbé ìlú wa sọ fún wa pé, ‘Ẹ mú oúnjẹ lọ́wọ́ fún ìrìnàjò yín, ẹ lọ pàdé wọn, kí ẹ sì sọ fún wọn pé, “Àwa ni ìránṣẹ́ yín, ẹ dá àdéhùn pẹ̀lú wa.”’
And the eldere men and alle the dwelleris of oure lond seiden to vs, Take ye metis in youre hondis, for lengeste weie; and go ye to hem, and seie ye, We ben youre seruauntis; make ye boond of pees with vs.
12 Gbígbóná ní a mú oúnjẹ wa wá, nígbà tí a dì í ní ilé ní ọjọ́ tí à ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ yín. Ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí ó ṣe gbẹ àti bí ó sì ṣe bu nísinsin yìí.
And we token hoote looues, whanne we yeden out of oure housis to come to you; now tho ben maad drye and brokun, for greet eldenesse;
13 Àti ìgò wáìnì wọ̀nyí, tí àwa rọ kún tuntun ni, ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí wọ́n ti sán. Aṣọ àti bàtà wa ni ó sì ti gbó nítorí ìrìnàjò ọ̀nà jíjìn.”
we filliden newe botels of wyn; now tho ben brokun and vndoon; the clothis and schoon, with whiche we ben clothid, and whiche we han `in the feet, ben brokun and almost wastid, fro the lengthe of lengere weie.
14 Àwọn ọkùnrin Israẹli sì yẹ oúnjẹ wọn wò, wọn kò sì wádìí ní ọwọ́ Olúwa.
Therfor `the sones of Israel token of the metis of hem, and thei axiden not `the mouth of the Lord.
15 Nígbà náà ni Joṣua ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wọn láti dá wọn sí, àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn fi ọwọ́ sí àdéhùn náà nípa ṣíṣe ìbúra.
And Josue made pees with hem. And whanne the boond of pees was maad, he bihiyte, that thei schulden not be slayn; and the princes of the multitude sworen to hem.
16 Ní ẹ̀yìn ọjọ́ mẹ́ta tí wọ́n ti ṣe àdéhùn pẹ̀lú àwọn ará Gibeoni, àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé aládùúgbò wọn ni wọ́n, tí ń gbé ní tòsí wọn.
Forsothe aftir thre daies of the boond of pees maad, thei herden, that thei dwelliden in nyy place, and that thei schulden be among hem.
17 Bẹ́ẹ̀ ní àwọn ọmọ Israẹli jáde, wọ́n sì dé ìlú wọn ní ọjọ́ kẹta: Gibeoni, Kefira, Beeroti àti Kiriati-Jearimu.
And the sones of Israel mouyden tentis, and camen in the thridde dai in to the citees of hem, of whiche citees these ben the names; Gabaon, and Caphira, and Beroth, and Cariathiarym.
18 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli kò si kọlù wọ́n, nítorí pé àwọn àgbàgbà ìjọ ènìyàn ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli. Gbogbo ènìyàn sì kùn sí àwọn àgbàgbà náà,
And thei smytiden not hem, for the princis of the multitude hadden swore to hem in the name of the Lord God of Israel. Therfor al the comyn puple grutchide ayens the princis of Israel;
19 ṣùgbọ́n gbogbo àwọn olórí dáhùn pé, “Àwa ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli, a kò sì lè fọwọ́ kàn wọ́n nísinsin yìí.
whiche answeriden to hem, We sworen to hem in the name of the Lord God of Israel, and therfor we moun not touche hem;
20 Èyí ní àwa yóò ṣe sí wọn, àwa yóò dá wọn sí, kí ìbínú kí ó má ba à wá sórí wa, nítorí ìbúra tí a búra fún wọn.”
but we schulen do this thing to hem, sotheli be thei reserued that thei lyue, lest the ire of the Lord be stirid ayens vs, if we forsweren to hem;
21 Wọ́n tẹ̀síwájú, “Ẹ dá wọn sí, ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí wọn jẹ́ gégigégi àti apọnmi fún gbogbo ìlú.” Àwọn àgbàgbà náà sì mú ìlérí wọn ṣẹ fún wọn.
but so lyue thei, that thei hewe trees, and bere watris, in to the vsis of al the multitude. And while thei spaken these thingis,
22 Nígbà náà ni Joṣua pe àwọn ọmọ Gibeoni jọ pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tàn wá wí pe, ‘Àwa gbé ní ibi tí ó jìnnà sí yín,’ nígbà tí ó jẹ́ pé tòsí wa ní ẹ̀yin ń gbé?
Josue clepide Gabonytis, and seide to hem, Whi wolden ye disseyue vs bi fraude, `that ye seiden, We dwellen ful fer fro you, sithen ye ben in the myddis of vs?
23 Nísinsin yìí, ẹ̀yin di ẹni ègún, ẹ̀yin kò sì ní kúrò ní gégigégi àti apọnmi fún ilé Ọlọ́run mi.”
Therfor ye schulen be `vndur cursyng, and noon schal faile of youre generacioun, hewynge trees and berynge watris, in to the hows of my God.
24 Wọ́n sì dá Joṣua lóhùn pé, “Nítorí tí a sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ dájúṣáká bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pàṣẹ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, láti fún yín ní gbogbo ilẹ̀ náà, kí ó sì pa gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà run kúrò ní iwájú yín. Nítorí náà, àwa bẹ̀rù ẹ̀mí wa nítorí yín, èyí sì ni ìdí tí a fi ṣe bẹ́ẹ̀.
Whiche answeryden, It was told to vs thi seruauntis, that thi Lord God bihiyte to Moises, his seruaunt, that he schulde bitake to you al the lond, and schulde leese alle the dwelleris therof; therfor we dredden greetli, and purueiden to oure lyues, and weren compellid bi youre drede, and we token this counsel.
25 Nísinsin yìí, àwa wà ní ọwọ́ yín. Ohunkóhun tí ẹ bá rò pé ó yẹ ó si tọ́ lójú yín ní kí ẹ fi wá ṣe.”
`Now forsothe we ben in `thin hond; do thou to vs that, that semeth riytful and good to thee.
26 Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua sì gbà wọ́n là kúrò ní ọwọ́ àwọn ọmọ Israẹli. Wọn kò sì pa wọ́n.
Therfor Josue dide, as he seide, and delyuerede hem fro the hondis of the sones of Israel, that thei schulden not be slayn.
27 Ní ọjọ́ náà ni ó sọ àwọn Gibeoni di aṣẹ́gi àti apọnmi fún àwọn ará ìlú àti fún pẹpẹ Olúwa ní ibi tí Olúwa yóò yàn. Báyìí ni wọ́n wà títí di òní yìí.
And in that dai Josue demyde hem to be in to the seruyce of al the puple, and of the auter of the Lord, and to hewe trees, and to bere watris, `til in to present tyme, in the place which the Lord hadde chose.

< Joshua 9 >