< Joshua 9 >

1 Nísinsin yìí, nígbà tí gbogbo ọba tó wà ní ìwọ̀-oòrùn Jordani gbọ́ nípa nǹkan wọ̀nyí, àwọn náà tí ó wà ní orí òkè àti àwọn tí ó wà ní ẹsẹ̀ òkè, àti gbogbo àwọn tí ó wà ní agbègbè Òkun Ńlá títí ó fi dé Lebanoni (àwọn ọba Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti Jebusi)
Jordan tui kanîloumlah mon dawkvah, tanghling Lebanon mon namran tuipui tengpam pueng kaawm e, Hitnaw, Amornaw, Kanaannaw, Periznaw, Hivnaw, hoi Jebusitnaw e siangpahrang pueng ni kamthang a thai toteh,
2 wọ́n sì kó ara wọn jọ láti bá Joṣua àti Israẹli jagun.
Joshua hoi Isarelnaw tuk hanelah lung kângingcalah a kamkhueng sak awh.
3 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ènìyàn Gibeoni gbọ́ ohun tí Joṣua ṣe sí Jeriko àti Ai,
Hahoi Gibeon kaawm e taminaw ni Jeriko kho, Ai kho dawkvah Joshua ni a sak e hno a thai awh torei teh,
4 wọ́n dá ọgbọ́n ẹ̀tàn. Wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí aṣojú tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn kún fún ẹrù tí a fi àwọn àpò tó ti gbó dì, àti àwọn awọ ọtí wáìnì tó ti gbó tí a tún rán.
huenghai hoi laicei patetlah a kâsak teh, la dawkvah ka pon e yawngyanaw a phu sak awh, ka pon ni teh a bo awh e misurumnaw a sin awh.
5 Àwọn ọkùnrin náà sì wọ bàtà àti aṣọ tí ó ti gbó. Gbogbo oúnjẹ tí wọ́n pèsè fún ara wọn sì bu.
Karuem e a bo awh e khokkhawmnaw a khawm awh teh, karuem e khohnanaw a khohna awh. Amo ka cawt e naw hah lamvon lah a sin awh.
6 Wọ́n sì tọ Joṣua lọ ní ibùdó ní Gilgali, wọ́n sì sọ fún òun àti àwọn ọkùnrin Israẹli pé, “Ìlú òkèrè ní àwọn ti wá, ẹ ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wa.”
Joshua onae Gilgal rim koe a pha toteh, kaimanaw teh, kâhuiko hanelah, kahlatpoung e ram koehoi ka tho awh telah Joshua hoi Isarelnaw koe ati awh.
7 Àwọn ọkùnrin Israẹli sọ fún àwọn ará Hifi pé, “Ṣùgbọ́n bóyá tòsí wa ni ẹ ń gbé. Báwo ni a ó ṣe lè ṣe àdéhùn pẹ̀lú yín?”
Isarel miphunnaw ni nangmanaw teh kaimae teng na o hoi na o hoeh hane hai ka panuek thai awh hoeh. Bangtelah hoi maw lawkkamnae na sak thai telah atipouh navah,
8 “Ìránṣẹ́ rẹ ní àwa í ṣe.” Wọ́n sọ fún Joṣua. Ṣùgbọ́n Joṣua béèrè, “Ta ni yín àti pé níbo ni ẹ̀yin ti wá?”
ahnimouh ni kaimanaw teh, nangmae san doeh telah Joshua koe atipouh awh. Joshua ni nangmanaw teh bangtelae tami maw, na lahoi maw na tho awh telah a pacei.
9 Wọ́n sì dáhùn pé, “Ní ilẹ̀ òkèèrè ní àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wá, nítorí orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ. Nítorí tí àwa ti gbọ́ òkìkí rẹ àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe ní Ejibiti,
Ahnimouh ni nange BAWIPA Cathut min kecu dawk nange na sannaw ni ka hlatpoung e ram koehoi ka tho awh toe. BAWIPA Cathut e kamthang hah Izip ram hoi a sak e hnonaw hoi,
10 àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe sí ọba àwọn Amori méjèèje tí ń bẹ ní òkè Jordani, sí Sihoni ọba Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani, tí wọ́n jẹ ọba ní Aṣtarotu.
Jordan palang kanîtholah kaawm e Amor siangpahrang Heshbon, Sihon, Ashtaroth kaawm e Bashan Siangpahrang Og dawkvah a sak e pueng hah a thai awh toe.
11 Àwọn àgbàgbà wa àti gbogbo àwọn tí ń gbé ìlú wa sọ fún wa pé, ‘Ẹ mú oúnjẹ lọ́wọ́ fún ìrìnàjò yín, ẹ lọ pàdé wọn, kí ẹ sì sọ fún wọn pé, “Àwa ni ìránṣẹ́ yín, ẹ dá àdéhùn pẹ̀lú wa.”’
Hatdawkvah kaimouh koevah kacuenaw hoi kho ka sak e abuemlah ni lamvon sin awh vaiteh, ahnimouh dawn hanelah cet awh. Maimanaw teh, ahnimae san lah o hane hoi kâhuiko hanelah kâhei awh han telah lawk na thui toe.
12 Gbígbóná ní a mú oúnjẹ wa wá, nígbà tí a dì í ní ilé ní ọjọ́ tí à ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ yín. Ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí ó ṣe gbẹ àti bí ó sì ṣe bu nísinsin yìí.
Nang koe tho hanelah kamthaw hnin vah lamvon hanelah kamamouh im hoi na sin awh e vaiyai teh, ka bethuepcalah, ao rah. Atu khenhaw! ka ke ni teh a mocu toe.
13 Àti ìgò wáìnì wọ̀nyí, tí àwa rọ kún tuntun ni, ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí wọ́n ti sán. Aṣọ àti bàtà wa ni ó sì ti gbó nítorí ìrìnàjò ọ̀nà jíjìn.”
Misur ka kawi e misurumnaw hai a katha e ei, khenhaw! a kâbawng toe. Khohna e, khokkhawmnaw hai ka hlatpoung e lah ao dawkvah a ruem toe ati awh.
14 Àwọn ọkùnrin Israẹli sì yẹ oúnjẹ wọn wò, wọn kò sì wádìí ní ọwọ́ Olúwa.
Isarelnaw ni BAWIPA koe pacei laipalah ahnimae lamvon teh a ca awh.
15 Nígbà náà ni Joṣua ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wọn láti dá wọn sí, àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn fi ọwọ́ sí àdéhùn náà nípa ṣíṣe ìbúra.
Joshua ni hai ahnimouh teh, kâtuknae dawk hoi hlout sak teh, hlout awh nahanelah kâhuikokhai awh. Rangpui kahrawinaw hai thoekâbonae sak.
16 Ní ẹ̀yìn ọjọ́ mẹ́ta tí wọ́n ti ṣe àdéhùn pẹ̀lú àwọn ará Gibeoni, àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé aládùúgbò wọn ni wọ́n, tí ń gbé ní tòsí wọn.
Kâhuikonae a sak awh hnukkhu, hnin thum touh a loum toteh, ahnimanaw teh, kho thung kaawm e telah Isarel miphunnaw a panue awh.
17 Bẹ́ẹ̀ ní àwọn ọmọ Israẹli jáde, wọ́n sì dé ìlú wọn ní ọjọ́ kẹta: Gibeoni, Kefira, Beeroti àti Kiriati-Jearimu.
Hat toteh, apâthum hnin vah, ahnimae khonaw dawk a pha awh. Ahnimouh khonaw teh, Gibeon, Kephirah, Beeroth, Kiriath-Jearim doeh.
18 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli kò si kọlù wọ́n, nítorí pé àwọn àgbàgbà ìjọ ènìyàn ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli. Gbogbo ènìyàn sì kùn sí àwọn àgbàgbà náà,
Rangpui kahrawinaw ni Isarel miphunnaw e BAWIPA Cathut koe thoekâbonae lawkkam a sak awh toung dawkvah Isarel miphunnaw ni ahnimanaw teh thet awh hoeh. Rangpuinaw ni kahrawikungnaw yon a pen awh.
19 ṣùgbọ́n gbogbo àwọn olórí dáhùn pé, “Àwa ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli, a kò sì lè fọwọ́ kàn wọ́n nísinsin yìí.
Kahrawikungnaw ni maimanaw teh Isarel miphunnaw e BAWIPA Cathut koe thoebonae lawkkam toung dawkvah, ahnimanaw hah tek thai awh mahoeh toe.
20 Èyí ní àwa yóò ṣe sí wọn, àwa yóò dá wọn sí, kí ìbínú kí ó má ba à wá sórí wa, nítorí ìbúra tí a búra fún wọn.”
Ahnimouh koe thoebonae sak awh toung dawkvah, a lungkhueknae phat langvaih tie a taki awh. A hringnae hlout sak dawkvah bangtelamaw ti han tie teh,
21 Wọ́n tẹ̀síwájú, “Ẹ dá wọn sí, ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí wọn jẹ́ gégigégi àti apọnmi fún gbogbo ìlú.” Àwọn àgbàgbà náà sì mú ìlérí wọn ṣẹ fún wọn.
Kahrawikungnaw ni lawk a kam e patetlah a hringnae hlout sak vaiteh, rangpuinaw hanelah thing ka bouk hane, tui ka do hanelah o sak han telah rangpuinaw koe atipouh.
22 Nígbà náà ni Joṣua pe àwọn ọmọ Gibeoni jọ pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tàn wá wí pe, ‘Àwa gbé ní ibi tí ó jìnnà sí yín,’ nígbà tí ó jẹ́ pé tòsí wa ní ẹ̀yin ń gbé?
Joshua ni ahnimanaw a kaw teh, nangmanaw teh kaimae teng na o awh nahlangva, ka hlatpoung koehoi ka tho e na kâti awh teh, bangkongmaw kaimouh na dum awh.
23 Nísinsin yìí, ẹ̀yin di ẹni ègún, ẹ̀yin kò sì ní kúrò ní gégigégi àti apọnmi fún ilé Ọlọ́run mi.”
Atuteh nangmanaw ni thoe na kâbo awh toung dawkvah, san lah na o awh vaiteh, kaie Cathut e im hanelah, thing bouk, tuido, e thaw buet touh hai na hlout awh mahoeh, atipouh.
24 Wọ́n sì dá Joṣua lóhùn pé, “Nítorí tí a sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ dájúṣáká bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pàṣẹ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, láti fún yín ní gbogbo ilẹ̀ náà, kí ó sì pa gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà run kúrò ní iwájú yín. Nítorí náà, àwa bẹ̀rù ẹ̀mí wa nítorí yín, èyí sì ni ìdí tí a fi ṣe bẹ́ẹ̀.
Ahnimouh ni hai hete ram pueng hah nangmanaw na poe teh, khocaramca pueng teh, nangmae hmalah be thei hanelah, nange BAWIPA Cathut ni amae san Mosi koe lawk a thui tie hah, kaimouh ni khei ka thai awh teh ka panue awh dawkvah, nangmae kut dawk due hanelah ka takipoung dawkvah, hete hno hah ka sak awh toe.
25 Nísinsin yìí, àwa wà ní ọwọ́ yín. Ohunkóhun tí ẹ bá rò pé ó yẹ ó si tọ́ lójú yín ní kí ẹ fi wá ṣe.”
Atu kaimouh teh nange kut dawk ka o awh. Kaimouh dawk na sak hanelah a kamcu tie na pouk e patetlah sak yawkaw telah Joshua koe atipouh awh.
26 Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua sì gbà wọ́n là kúrò ní ọwọ́ àwọn ọmọ Israẹli. Wọn kò sì pa wọ́n.
Hottelah Joshua ni a sak teh, ahnimae a hring hlout nahanelah, Isarelnaw e kut dawk hoi a rungngang.
27 Ní ọjọ́ náà ni ó sọ àwọn Gibeoni di aṣẹ́gi àti apọnmi fún àwọn ará ìlú àti fún pẹpẹ Olúwa ní ibi tí Olúwa yóò yàn. Báyìí ni wọ́n wà títí di òní yìí.
BAWIPA ni a rawi e hmuen koe thuengnae khoungroe hane hoi rangpuinaw hanelah ahnimanaw ni atu totouh thing a bouk awh teh, tui do nahanelah, hatnae tueng dawkvah lawk a tâtueng awh.

< Joshua 9 >