< Joshua 9 >

1 Nísinsin yìí, nígbà tí gbogbo ọba tó wà ní ìwọ̀-oòrùn Jordani gbọ́ nípa nǹkan wọ̀nyí, àwọn náà tí ó wà ní orí òkè àti àwọn tí ó wà ní ẹsẹ̀ òkè, àti gbogbo àwọn tí ó wà ní agbègbè Òkun Ńlá títí ó fi dé Lebanoni (àwọn ọba Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti Jebusi)
Jordan khotlak, tlang neh kolrhawk kah long khaw, tuili puei langkaeng boeih kah neh Lebanon imdan kah Khitti, Amori, Kanaani, Perizzi, Khivee neh Jebusi manghai rhoek loh boeih a yaak uh.
2 wọ́n sì kó ara wọn jọ láti bá Joṣua àti Israẹli jagun.
Te dongah Joshua vathoh thil ham neh Israel te ol thikat thil ham tun coi uh thae.
3 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ènìyàn Gibeoni gbọ́ ohun tí Joṣua ṣe sí Jeriko àti Ai,
Tedae Gibeon khosa rhoek long khaw Joshua loh Jerikho neh Ai taengah a saii te a yaak.
4 wọ́n dá ọgbọ́n ẹ̀tàn. Wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí aṣojú tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn kún fún ẹrù tí a fi àwọn àpò tó ti gbó dì, àti àwọn awọ ọtí wáìnì tó ti gbó tí a tún rán.
Te dongah amih te taengnah neh a saii uh tih cet uh. Te phoeiah sayuep bangla a laak dongah tolkhui a rhuem, misur tuitang a rhuem, a hep tih a ben te a khuen uh.
5 Àwọn ọkùnrin náà sì wọ bàtà àti aṣọ tí ó ti gbó. Gbogbo oúnjẹ tí wọ́n pèsè fún ara wọn sì bu.
A kho dongkah khokhom rhuem tih tairhi coeng. A pum dongkah himbai khaw rhuem coeng tih a buham buh boeih rhae tih a ap om coeng.
6 Wọ́n sì tọ Joṣua lọ ní ibùdó ní Gilgali, wọ́n sì sọ fún òun àti àwọn ọkùnrin Israẹli pé, “Ìlú òkèrè ní àwọn ti wá, ẹ ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wa.”
Gilgal rhaehhmuen kah Joshua taengla a pha uh vaengah tah Joshua taeng neh Israel hlang rhoek taengah, “Kho hla lamkah ka pawk uh coeng dongah kaimih neh moi bop uh pawn sih,” a ti na uh.
7 Àwọn ọkùnrin Israẹli sọ fún àwọn ará Hifi pé, “Ṣùgbọ́n bóyá tòsí wa ni ẹ ń gbé. Báwo ni a ó ṣe lè ṣe àdéhùn pẹ̀lú yín?”
Tedae Israel hlang rhoek loh Khivee te a doo tih, “Nang he kai khui ah kho na sak khaming, tedae balae tih nang taengah moi ka boh khaw ka boh eh,” a ti nah.
8 “Ìránṣẹ́ rẹ ní àwa í ṣe.” Wọ́n sọ fún Joṣua. Ṣùgbọ́n Joṣua béèrè, “Ta ni yín àti pé níbo ni ẹ̀yin ti wá?”
Joshua taengah khaw, “Kaimih he na sal rhoek ni,” a ti na uh vaengah amih te Joshua loh, “Nangmih te ulae, me lamkah lae na lo uh?” a ti nah.
9 Wọ́n sì dáhùn pé, “Ní ilẹ̀ òkèèrè ní àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wá, nítorí orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ. Nítorí tí àwa ti gbọ́ òkìkí rẹ àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe ní Ejibiti,
Te vaengah anih te, “BOEIPA na Pathen ming kah a thang neh Egypt ah a saii boeih te ka yaak uh dongah na sal rhoek tah kho hla tloe lamkah ha pawk uh coeng.
10 àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe sí ọba àwọn Amori méjèèje tí ń bẹ ní òkè Jordani, sí Sihoni ọba Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani, tí wọ́n jẹ ọba ní Aṣtarotu.
Te dongah Jordan rhalvang kah Amori manghai rhoi, Heshbon manghai Sihon neh Ashtaroth kah Bashan manghai Oga taengah a saii boeih te khaw.
11 Àwọn àgbàgbà wa àti gbogbo àwọn tí ń gbé ìlú wa sọ fún wa pé, ‘Ẹ mú oúnjẹ lọ́wọ́ fún ìrìnàjò yín, ẹ lọ pàdé wọn, kí ẹ sì sọ fún wọn pé, “Àwa ni ìránṣẹ́ yín, ẹ dá àdéhùn pẹ̀lú wa.”’
Te dongah kaimih kah a hamca rhoek neh ka khohmuen kah khosa boeih loh kaimih he ng'uen uh tih, ‘Na kut dongah longpueng kah ham lampu khuen uh lamtah amih aka doe la cet uh laeh. Te vaengah amih te, “Kaimih he na sal rhoek ni, kaimih neh paipi saii uh pawn sih,” ti nah,’ a ti.
12 Gbígbóná ní a mú oúnjẹ wa wá, nígbà tí a dì í ní ilé ní ọjọ́ tí à ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ yín. Ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí ó ṣe gbẹ àti bí ó sì ṣe bu nísinsin yìí.
‘Nangmih taengla lo ham ka hlah uh hnin ah ka im kah buh bae kan cun uh dae tahae ah daeh tih a ap om coeng he.
13 Àti ìgò wáìnì wọ̀nyí, tí àwa rọ kún tuntun ni, ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí wọ́n ti sán. Aṣọ àti bàtà wa ni ó sì ti gbó nítorí ìrìnàjò ọ̀nà jíjìn.”
Tuitang he khaw misur a thai ni ka loei uh dae vik ueth coeng he. Ka himbai neh ka khokhom longpueng te set puet ah hmawn boeih coeng,’ ti na uh,” a ti nah.
14 Àwọn ọkùnrin Israẹli sì yẹ oúnjẹ wọn wò, wọn kò sì wádìí ní ọwọ́ Olúwa.
Te vaengah BOEIPA yilka a dawt uh mueh la amih kah buhcun te a hlang rhoek loh a paco uh.
15 Nígbà náà ni Joṣua ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wọn láti dá wọn sí, àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn fi ọwọ́ sí àdéhùn náà nípa ṣíṣe ìbúra.
Te dongah Joshua loh amih neh rhoepnah a saii tih amih hing sak ham paipi khaw a saii. Khoboei rhaengpuei long khaw amih taengah ol a caeng uh.
16 Ní ẹ̀yìn ọjọ́ mẹ́ta tí wọ́n ti ṣe àdéhùn pẹ̀lú àwọn ará Gibeoni, àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé aládùúgbò wọn ni wọ́n, tí ń gbé ní tòsí wọn.
Tedae amih neh moi a boh uh phoeikah hnin thum dongah amih te a kaepvai neh a yoei kah khosa rhoek ni tila a yaak uh.
17 Bẹ́ẹ̀ ní àwọn ọmọ Israẹli jáde, wọ́n sì dé ìlú wọn ní ọjọ́ kẹta: Gibeoni, Kefira, Beeroti àti Kiriati-Jearimu.
Te dongah Israel ca rhoek loh cet uh tih a hnin thum dongah tah amih kah khopuei la pawk uh. Te vaengah amih kah khopuei la Gibeon, Kephirah, Beeroth neh Kiriathjearim om.
18 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli kò si kọlù wọ́n, nítorí pé àwọn àgbàgbà ìjọ ènìyàn ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli. Gbogbo ènìyàn sì kùn sí àwọn àgbàgbà náà,
Israel Pathen BOEIPA rhang neh khoboei rhaengpuei loh amih taengah a toemngam coeng dongah Israel ca rhoek loh amih te tloek uh van pawh. Te dongah khoboei rhoek te rhaengpuei loh boeih a rhaehba tak.
19 ṣùgbọ́n gbogbo àwọn olórí dáhùn pé, “Àwa ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli, a kò sì lè fọwọ́ kàn wọ́n nísinsin yìí.
Te dongah rhaengpuei boeih taengah khoboei rhoek boeih loh, “Israel Pathen BOEIPA rhang neh mamih loh amih taengah n'toemngam uh coeng dongah amih te ben ham a coeng moenih.
20 Èyí ní àwa yóò ṣe sí wọn, àwa yóò dá wọn sí, kí ìbínú kí ó má ba à wá sórí wa, nítorí ìbúra tí a búra fún wọn.”
Amih te hing sak ham he n'saii uh van daengah ni amih taengah n'toemngam uh olhlo loh mamih soah thinhul bat la a om pawt eh,” a ti na uh.
21 Wọ́n tẹ̀síwájú, “Ẹ dá wọn sí, ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí wọn jẹ́ gégigégi àti apọnmi fún gbogbo ìlú.” Àwọn àgbàgbà náà sì mú ìlérí wọn ṣẹ fún wọn.
Te dongah amih te, “Khoboei rhoek tah hing uh mai saeh. Khoboei rhoek loh amih taengkah a thui vanbangla rhaengpuei boeih kah thing top neh tui than la om uh saeh,” a ti na uh.
22 Nígbà náà ni Joṣua pe àwọn ọmọ Gibeoni jọ pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tàn wá wí pe, ‘Àwa gbé ní ibi tí ó jìnnà sí yín,’ nígbà tí ó jẹ́ pé tòsí wa ní ẹ̀yin ń gbé?
Te dongah Joshua loh amih te a khue tih a voek. Amih te, “Balae tih kaimih nan phok uh tih, ‘Kaimih he khohla tloe lamkah ni,’ na ti uh. Tedae nangmih he kaimih khui kah khosa rhoek ni.
23 Nísinsin yìí, ẹ̀yin di ẹni ègún, ẹ̀yin kò sì ní kúrò ní gégigégi àti apọnmi fún ilé Ọlọ́run mi.”
Te dongah nangmih tah thaephoei thil la om vetih na khui lamkah sal pataeng lohnaa mueh la ka Pathen im ham thing top neh tui than la om laeh,” a ti nah.
24 Wọ́n sì dá Joṣua lóhùn pé, “Nítorí tí a sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ dájúṣáká bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pàṣẹ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, láti fún yín ní gbogbo ilẹ̀ náà, kí ó sì pa gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà run kúrò ní iwájú yín. Nítorí náà, àwa bẹ̀rù ẹ̀mí wa nítorí yín, èyí sì ni ìdí tí a fi ṣe bẹ́ẹ̀.
Te dongah Joshua te a doo uh tih, “BOEIPA na Pathen loh nangmih taengah khohmuen pum a paek ham a sal Moses a uen tih khohmuen kah khosa boeih khaw na mikhmuh lamloh a mitmoeng sak te na sal rhoek taengah a thui, a thui vaengah ka hinglu ham khaw nangmih te mat kang rhih uh dongah ni hekah hno he ka saii uh.
25 Nísinsin yìí, àwa wà ní ọwọ́ yín. Ohunkóhun tí ẹ bá rò pé ó yẹ ó si tọ́ lójú yín ní kí ẹ fi wá ṣe.”
Tedae kaimih he na kut dongah ka om uh. Kaimih taengah na saii ham tueng tah na mikhmuh ah then tih thuem na ti bangla saii mai,” a ti na uh.
26 Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua sì gbà wọ́n là kúrò ní ọwọ́ àwọn ọmọ Israẹli. Wọn kò sì pa wọ́n.
Te tlam te amih a saii van tih amih te Israel ca kut lamloh a huul coeng dongah amih te ngawn uh pawh.
27 Ní ọjọ́ náà ni ó sọ àwọn Gibeoni di aṣẹ́gi àti apọnmi fún àwọn ará ìlú àti fún pẹpẹ Olúwa ní ibi tí Olúwa yóò yàn. Báyìí ni wọ́n wà títí di òní yìí.
Te vaeng khohnin ah amih te tihnin duela rhaengpuei neh a hmuen tuek ah BOEIPA hmueihtuk ham thing top neh tui than la Joshua loh a khueh.

< Joshua 9 >